< Liczb 1 >

1 I mówił Pan do Mojżesza na puszczy Synaj, w namiocie zgromadzenia pierwszego dnia miesiąca wtórego, roku wtórego, po wyjściu ich z ziemi Egipskiej, temi słowy:
Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ní aginjù Sinai nínú àgọ́ àjọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì ní ọdún kejì tí àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ó wí pé,
2 Obliczcie sumę wszystkiego zgromadzenia synów Izraelskich według narodów ich, i według domów ojców ich według imion ich, każdego mężczyznę według głów ich.
“Ka gbogbo àgbájọ ènìyàn Israẹli nípa ẹbí wọn, àti nípa ìdílé baba wọn, to orúkọ wọn olúkúlùkù ọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
3 Ode dwudziestu lat, i wyżej, wszystkich wychodzących na wojnę z Izraela; policzycie je według hufców ich, ty i Aaron.
Ìwọ àti Aaroni ni kí ẹ kà gbogbo ọmọkùnrin Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn láti ọmọ ogún ọdún sókè, àwọn tí ó tó lọ sójú ogun.
4 I będzie z wami z każdego pokolenia jeden mąż, któryby przedniejszy był w domu ojców swoich.
Kí ẹ mú ọkùnrin kọ̀ọ̀kan láti inú olúkúlùkù ẹ̀yà kí ó sì wá pẹ̀lú yín, kí olúkúlùkù jẹ́ olórí ilé àwọn baba rẹ̀.
5 A teć są imiona mężów, którzy z wami będą; z pokolenia Rubenowego Elizur, syn Sedeurów.
“Orúkọ àwọn ọkùnrin tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nìyí: “Láti ọ̀dọ̀ Reubeni, Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
6 Z pokolenia Symeonowego Salamijel, syn Surysaddajów.
Láti ọ̀dọ̀ Simeoni, Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
7 Z pokolenia Judowego Naason, syn Aminadabów.
Láti ọ̀dọ̀ Juda, Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
8 Z pokolenia Isascharowego Natanael syn Suharów.
Láti ọ̀dọ̀ Isakari, Netaneli ọmọ Suari.
9 Z pokolenia Zabulonowego Elijab, syn Helonów.
Láti ọ̀dọ̀ Sebuluni, Eliabu ọmọ Heloni.
10 Z synów Józefowych, z pokolenia Efraimowego Elisama, syn Ammiudów; z pokolenia Manasesowego Gamalijel, syn Pedasurów.
Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Josẹfu: láti ọ̀dọ̀ Efraimu, Eliṣama ọmọ Ammihudu. Láti ọ̀dọ̀ Manase, Gamalieli ọmọ Pedasuri.
11 Z pokolenia Benjaminowego Abidan, syn Gedeonów.
Láti ọ̀dọ̀ Benjamini, Abidani ọmọ Gideoni.
12 Z pokolenia Danowego Achyjezer, syn Ammisadajów.
Láti ọ̀dọ̀ Dani, Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
13 Z pokolenia Aserowego Pagijel, syn Ochranów.
Láti ọ̀dọ̀ Aṣeri, Pagieli ọmọ Okanri.
14 Z pokolenia Gadowego Elijazaf, syn Duelów.
Láti ọ̀dọ̀ Gadi, Eliasafu ọmọ Deueli.
15 Z pokolenia Neftalimowego Achyra, syn Enanów.
Láti ọ̀dọ̀ Naftali, Ahira ọmọ Enani.”
16 Ci zwoływani będą najzacniejsi z ludu książęta w pokoleniach ojców swych; wodzami wojsk Izraelskich będą.
Àwọn wọ̀nyí ni wọ́n yàn nínú àwùjọ ènìyàn, olórí àwọn ẹ̀yà baba wọn. Àwọn ni olórí àwọn ẹbí Israẹli.
17 Przyzwali tedy do siebie Mojżesz i Aaron mężów tych, którzy z imienia mianowani są.
Mose àti Aaroni mú àwọn ènìyàn tí a dárúkọ wọ̀nyí
18 I zebrali wszystko zgromadzenie dnia pierwszego miesiąca wtórego, i przyznawali się do rodzajów swych według familii swych, według domów ojców swych i według liczby imion, od dwudziestu lat i wyżej, według osób swych.
wọ́n sì pe gbogbo àwùjọ ènìyàn Israẹli jọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì. Àwọn ènìyàn sì dárúkọ baba ńlá wọn nípa ẹbí àti ìdílé wọn. Wọ́n sì ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọmọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan láti ọmọ ogún ọdún sókè,
19 Jako rozkazał Pan Mojżeszowi, tak je policzył na puszczy Synaj.
gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose. Bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe kà wọ́n nínú aginjù Sinai.
20 I było synów Rubena, pierworodnego Izraelowego, rodzajów ich według familii ich, według domów ojców ich, według liczby imion, według osób ich, wszystkiego pogłowia męskiego od dwudziestu lat i wyżej, wszystkich wychodzących na wojnę;
Láti ìran Reubeni tí í ṣe àkọ́bí Israẹli, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn, lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
21 Naliczono ich z pokolenia Rubenowego czterdzieści i sześć tysięcy i pięć set.
Àwọn tí a kà ní ẹ̀yà Reubeni jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlélógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
22 Z synów Symeonowych rodzajów ich, według familii ich, według domów ojców ich, naliczonych jego, według liczby imion, według osób ich, wszystkiego pogłowia męskiego od dwudziestu lat i wyżej, wszystkich wychodzących na wojnę;
Láti ìran Simeoni, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n kà, wọ́n sì to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
23 Naliczono ich z pokolenia Symeonowego pięćdziesiąt i dziewięć tysięcy i trzy sta.
Iye àwọn tí á kà nínú ẹ̀yà Simeoni jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ó lé ọ̀ọ́dúnrún.
24 Z synów Gadowych rodzajów ich według familii ich, według domów ojców ich, według liczby imion, od dwudziestu lat i wyżej, wszystkich wychodzących na wojnę.
Láti ìran Gadi, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí ẹbí àti ìdílé wọn.
25 Naliczono ich z pokolenia Gadowego czterdzieści i pięć tysięcy i sześć set i pięćdziesiąt.
Iye àwọn tí a kà nínú ẹ̀yà Gadi jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé àádọ́talélẹ́gbẹ̀jọ.
26 Z synów Judowych rodzajów ich według familii ich, według domów ojców ich, według liczby imion, od dwudziestu lat i wyżej, wszystkich wychodzących na wojnę;
Láti ìran Juda, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
27 Naliczono ich z pokolenia Judowego siedemdziesiąt i cztery tysiące i sześć set.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Juda jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógójì ó lé ẹgbẹ̀ta.
28 Z pokolenia Isascharowego rodzajów ich według familii ich, według domów ojców ich, według liczby imion, od dwudziestu lat i wyżej, wszystkich wychodzących na wojnę;
Láti ìran Isakari, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
29 Naliczono ich z pokolenia Isascharowego pięćdziesiąt i cztery tysiące i cztery sta.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Isakari jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
30 Z synów Zabulonowych rodzajów ich według familii ich, według domów ojców ich, według liczby imion, od dwudziestu lat i wyżej, wszystkich wychodzących na wojnę;
Láti ìran Sebuluni, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
31 Naliczono ich z pokolenia Zabulonowego pięćdziesiąt i siedem tysięcy i cztery sta.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Sebuluni jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
32 Z synów Józefowych, a naprzód z synów Efraimowych, rodzajów ich według familii ich, według domów ojców ich, według liczby imion, od dwudziestu lat i wyżej, wszystkich wychodzących na wojnę;
Láti inú àwọn ọmọ Josẹfu. Láti ìran Efraimu, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
33 Naliczono ich z pokolenia Efraimowego czterdzieści tysięcy i pięć set.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Efraimu jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
34 Z synów zaś Manasesowych rodzajów ich według familii ich, według domów ojców ich, według liczby imion, od dwudziestu lat i wyżej, wszystkich wychodzących na wojnę;
Láti ìran Manase, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
35 Naliczono ich z pokolenia Manasesowego trzydzieści i dwa tysiące i dwieście.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Manase jẹ́ ẹgbàá ẹẹ́rìndínlógún ó lé igba.
36 Z synów Benjaminowych rodzajów ich, według familii ich, według domów ojców ich, według liczby imion, od dwudziestu lat i wyżej, wszystkich wychodzących na wojnę;
Láti ìran Benjamini, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
37 Naliczono ich z pokolenia Benjaminowego trzydzieści i pięć tysięcy i cztery sta.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Benjamini jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógún ó lé egbèje.
38 Z synów Danowych rodzajów ich według familii ich, według domów ojców ich, według liczby imion, od dwudziestu lat i wyżej, wszystkich wychodzących na wojnę;
Láti ìran Dani, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
39 Naliczono ich z pokolenia Danowego sześćdziesiąt i dwa tysiące i siedemset.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Dani jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
40 Z synów Aserowych rodzajów ich według familii ich, według domów ojców ich, według liczby imion, od dwudziestu lat i wyżej, wszystkich wychodzących na wojnę;
Láti ìran Aṣeri, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
41 Naliczono ich z pokolenia Aserowego czterdzieści tysięcy i jeden i pięć set.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Aṣeri jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
42 Z synów Neftalimowych rodzajów ich według familii ich, według domów ojców ich, według liczby imion, od dwudziestu lat i wyżej, wszystkich wychodzących na wojnę;
Láti ìran Naftali, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún ó lé, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
43 Naliczono ich z pokolenia Neftalimowego pięćdziesiąt i trzy tysiące i cztery sta.
Iye àwọn tí a kà nínú ẹ̀yà Naftali jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
44 Cić są policzeni, które policzył Mojżesz i Aaron, i książęta Izraelskie, dwanaście mężów, którzy byli wybrani po jednemu z domów ojców swych.
Wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn tí Mose àti Aaroni kà, pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn olórí méjìlá fún Israẹli, tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ṣojú fún ìdílé rẹ̀.
45 I było wszystkich policzonych synów Izraelskich według domów ojców ich, od dwudziestu lat i wyżej, wszystkich wychodzących na wojnę z Izraela;
Gbogbo ọmọkùnrin Israẹli tó jẹ́ ọmọ ogún ọdún sókè, tó sì lè lọ sójú ogun ni wọ́n kà gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
46 Było wszystkich policzonych sześć kroć sto tysięcy i trzy tysiące, i pięć set i pięćdziesiąt.
Àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé egbèjìdínlógún dín làádọ́ta.
47 Ale Lewitowie według pokolenia ojców swych nie byli policzeni między nimi.
A kò ka àwọn ìdílé ẹ̀yà Lefi mọ́ àwọn ìyókù.
48 Bo rozkazał był Pan Mojżeszowi, mówiąc:
Nítorí Olúwa ti sọ fún Mose pé,
49 Tylko pokolenia Lewi nie będziesz liczył, a sumy ich nie policzysz między syny Izraelskie;
“Ìwọ kò gbọdọ̀ ka ẹ̀yà Lefi, tàbí kí o kà wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Israẹli.
50 Ale postanowisz Lewity nad przybytkiem świadectwa, i nad wszystkiem naczyniem jego, i nad wszystkiem co należy do niego. Oni nosić będą przybytek i wszystkie naczynia jego; oni też służyć będą w nim, a około przybytku obozem się kłaść będą.
Dípò èyí yan àwọn ọmọ Lefi láti jẹ́ alábojútó àgọ́ ẹ̀rí, lórí gbogbo ohun èlò àti ohun gbogbo tó jẹ́ ti àgọ́ ẹ̀rí. Àwọn ni yóò máa gbé àgọ́ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, wọn ó máa mójútó o, kí wọn ó sì máa pàgọ́ yí i ká.
51 A gdy się będzie ruszał przybytek, składać go będą Lewitowie; także gdy stanowić się będzie przybytek, stawiać go będą Lewitowie; a kto by obcy do niego przystąpił, umrze.
Ìgbàkígbà tí àgọ́ yóò bá tẹ̀síwájú, àwọn ọmọ Lefi ni yóò tú palẹ̀, nígbàkígbà tí a bá sì tún pa àgọ́, àwọn ọmọ Lefi náà ni yóò ṣe é. Àlejò tó bá súnmọ́ tòsí ibẹ̀, pípa ni kí ẹ pa á
52 I będą stawać obozem synowie Izraelscy, każdy według pułków swoich, i każdy pod chorągwią swoją, w wojsku swem.
kí àwọn ọmọ Israẹli pa àgọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn olúkúlùkù ní ibùdó tirẹ̀ lábẹ́ ọ̀págun tirẹ̀.
53 Ale Lewitowie kłaść się będą obozem około przybytku świadectwa, aby nie przyszedł gniew mój na zgromadzenie synów Izraelskich: i będą Lewitowie trzymać straż u przybytku świadectwa.
Àwọn ọmọ Lefi yóò jẹ́ alábojútó àti olùtọ́jú àgọ́ ẹ̀rí náà, kí ìbínú má ba à sí lára ìjọ àwọn ọmọ Israẹli; kí àwọn ọmọ Lefi sì máa ṣe ìtọ́jú àgọ́ ẹ̀rí náà.”
54 Uczynili tedy synowie Izraelscy według wszystkiego, co był rozkazał Pan Mojżeszowi, tak uczynili.
Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun gbogbo gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.

< Liczb 1 >