< Nehemiasza 6 >

1 A gdy usłyszał Sanballat, i Tobijasz, i Giesem Arabczyk, i inni nieprzyjaciele nasi, żem zbudował mur, a że w nim nie zostawało żadnej rozwaliny, chociażem jeszcze wtenczas nie był przyprawił wrót do bram:
Nígbà tí Sanballati, Tobiah Geṣemu ará Arabia àti àwọn ọ̀tá wa tókù gbọ́ pé, mo ti tún odi náà mọ, kò sì sí àlàfo kankan tí ó ṣẹ́kù nínú rẹ̀—bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò ì tí ì ri àwọn ìlẹ̀kùn ibodè ní àkókò náà.
2 Tedy posłał Sanballat, i Giesem do mnie mówiąc: Przyjdź, a zejdźmy się społem we wsiach, które są na polu Ono. Ale oni myślili uczynić mi co złego.
Sanballati àti Geṣemu rán iṣẹ́ yìí sí mi pé, “Wá jẹ́ kí a jọ pàdé pọ̀ nínú ọ̀kan lára àwọn ìletò ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ono.” Ṣùgbọ́n wọ́n ń gbèrò láti ṣe mí ní ibi;
3 Przetoż posłałem do nich posłów, wskazując: Zacząłem robotę wielką, przetoż nie mogę zjechać; bo przeczżeby miała ustać ta robota, gdybym jej zaniechawszy jechał do was?
bẹ́ẹ̀ ni mo rán oníṣẹ́ padà pẹ̀lú èsì yìí pé, “Èmi ń ṣe iṣẹ́ ńlá kan, èmi kò le è sọ̀kalẹ̀ wá. Èéṣe tí iṣẹ́ náà yóò fi dúró, nígbà tí mo bá fi í sílẹ̀ tí mo sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá?”
4 Tedy posłali do mnie w tejże sprawie po cztery kroć. A jam im odpowiedział temiż słowy.
Wọ́n rán iṣẹ́ náà sí mi nígbà mẹ́rin ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, mo sì fún wọn ní èsì bákan náà fún ìgbà kọ̀ọ̀kan.
5 Potem Sanballat posłał do mnie w tejże sprawie piąty raz sługę swego i list otwarty, w ręce jego,
Ní ìgbà karùn-ún, Sanballati rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sí mi pẹ̀lú irú iṣẹ́ kan náà, lẹ́tà kan tí a kò fi sínú àpò ìwé wà ní ọwọ́ rẹ̀
6 W którym to było napisane: Jest posłuch między narodami, jako Gasmus powiada, że ty i Żydowie myślicie się z mocy wybić, a że ty dlatego budujesz mur, abyś był nad nimi królem ich, jako się to pokazuje.
tí a kọ sínú un rẹ̀ pé, “A ròyìn rẹ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, Geṣemu sì sọ pé, òtítọ́ ni, pé ìwọ àti àwọn Júù ń gbèrò láti ṣọ̀tẹ̀, nítorí náà ni ẹ ṣe ń mọ odi. Síwájú sí i, gẹ́gẹ́ bí ìròyìn yìí, ìwọ sì ń gbèrò láti di ọba wọn
7 Do tego, żeś i proroków postanowił, aby powiadali o tobie w Jeruzalemie, mówiąc: On jest królem w Judzie. Teraz tedy dojdzie to króla; przetoż przyjdź, a naradzimy się spółecznie.
àti pé ó ti yan àwọn wòlíì kí wọn lè kéde nípa rẹ̀ ní Jerusalẹmu: ‘Ọba kan wà ní Juda!’ Nísinsin yìí, ìròyìn yìí yóò padà sí ọ̀dọ̀ ọba; nítorí náà wá, jẹ́ kí a bá ara wa sọ̀rọ̀.”
8 Alem posłał do niego, mówiąc: Nie jest to, co powiadasz; ale sam sobie to wymyślasz.
Mo dá èsì yìí padà sí i pé, “Kò sí ohun kan nínú irú ohun tí ìwọ sọ tí ó ṣẹlẹ̀; ìwọ kàn rò wọ́n ní orí ara rẹ ni.”
9 Albowiem oni wszyscy straszyli nas, mówiąc: Osłabieją ręce ich przy robocie, i nie dokonają; prztoż teraz, o Boże! zmocnij ręce moje.
Gbogbo wọn múra láti dẹ́rùbà wá, wọ́n ń rò ó wí pé, “Ọwọ́ wọn kò ní ran iṣẹ́ náà, àti wí pé wọn kò ní parí rẹ̀.” Ṣùgbọ́n mo gbàdúrà pé, “Nísinsin yìí Ọlọ́run fi agbára fún ọwọ́ mi.”
10 A gdym wszedł w dom Semejasza, syna Delajaszowego, syna Mehetabelowego, który był w zawarciu, rzekł mi: Zejdźmy się do domu Bożego, w pośród kościoła, i zamknijmy drzwi kościelne; bo przyjdą, chcąc cię zabić, a w nocy przyjdą, aby cię zabili.
Ní ọjọ́ kan mo lọ sí ilé Ṣemaiah ọmọ Delaiah, ọmọ Mehetabeeli, ẹni tí a há mọ́ sínú ilé rẹ̀. Ó wí pé, “Jẹ́ kí a pàdé ní ilé Ọlọ́run nínú tẹmpili, kí o sì jẹ́ kí a pa àwọn ìlẹ̀kùn tẹmpili dé, nítorí àwọn ènìyàn ń bọ̀ láti pa ọ́, ní òru ni wọn yóò wá láti pa ọ́.”
11 Któremum rzekł: Takowyżby mąż, jakim ja jest, miał uciekać? Któż takowy, jakom ja, coby wszedłszy do kościoła, żyw został? Nie wnijdę.
Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí irú ènìyàn bí èmi sálọ? Tàbí kí ènìyàn bí èmi sálọ sínú tẹmpili láti gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là? Èmi kò ní lọ!”
12 I poznałem, że go Bóg nie posłał ale proroctwo mówił przeciwko mnie, bo go Tobijasz i Sanballat byli przenajęli.
Èmi wòye pé Ọlọ́run kò rán an, ṣùgbọ́n ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí mi nítorí Tobiah àti Sanballati ti bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀.
13 Przeto bowiem przenajęty był, abym się uląkł, i tak uczynił, i zgrzeszył, ażeby mi to u nich było na złe imię, czemby mi urągali.
Wọ́n bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀ láti dẹ́rùbà mí nítorí kí èmi lè dẹ́ṣẹ̀ nípa ṣíṣe èyí, kí wọn lè bà mí lórúkọ jẹ́, kí n sì di ẹni ẹ̀gàn.
14 Pomnijże, o Boże mój! na Tobijasza i Sanballata, według takowych uczynków ich: także na Noadyję prorokinię, i na innych proroków, którzy mię straszyli.
A! Ọlọ́run mi, rántí Tobiah àti Sanballati, nítorí ohun tí wọ́n ti ṣe; kí o sì tún rántí Noadiah wòlíì obìnrin àti àwọn wòlíì tókù tí wọ́n ń gbèrò láti dẹ́rùbà mí.
15 A tak dokonany jest on mur dwudziestego i piątego dnia miesiąca Elul, pięćdziesiątego i drugiego dnia.
Bẹ́ẹ̀ ni a parí odi náà ní ọjọ́ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù Eluli, láàrín ọjọ́ méjìléláàádọ́ta.
16 A gdy to usłyszeli wszyscy nieprzyjaciele nasi, i widzieli to wszyscy narodowie, którzy byli około nas, upadło im bardzo serce;
Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ èyí, gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká bẹ̀rù jìnnìjìnnì sì mú wọn, nítorí wọ́n wòye pé iṣẹ́ yìí di ṣíṣe pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run wa.
17 Bo poznali, że się ta sprawa od Boga naszego stała. W oneż dni wiele przedniejszych z Judy listy swe często posyłali do Tobijasza, także od Tobijasza przychodziły do nich.
Bákan náà, ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọlọ́lá Juda ń kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ lẹ́tà ránṣẹ́ sí Tobiah, èsì láti ọ̀dọ̀ Tobiah sì ń wá sí ọ̀dọ̀ wọn.
18 Bo wiele ich było w Judzie, co się z nim sprzysięgli, gdyż on był zięciem Sechanijasza, syna Arachowego; a Jochanan, syn jego, pojął był córkę Mesullama, syna Barachyjaszowego.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Juda ti mulẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí ó jẹ́ àna Ṣekaniah ọmọ Arah (Sanballati fẹ́ ọmọ Ṣekaniah), ọmọ rẹ̀ Jehohanani sì tún fẹ́ ọmọbìnrin Meṣullamu ọmọ Berekiah.
19 Nadto i dobroczynność jego opowiadali przedemną, i słowa moje odnosili mu; a listy posyłał Tobijasz, aby mię straszył.
Síwájú sí í, wọ́n túbọ̀ ń ròyìn iṣẹ́ rere rẹ̀ fún mi, wọ́n sì ń sọ ohun tí mo sọ fún un. Tobiah sì ń kọ àwọn lẹ́tà ránṣẹ́ sí mi láti dẹ́rùbà mí.

< Nehemiasza 6 >