< Micheasza 3 >

1 Przetoż mówię: Słuchajcie przedniejsi w Jakóbie, i wodzowie domu Izraelskiego! izali wy nie macie być powiadomi sądu?
Nígbà náà, ni mo wí pé, “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin olórí Jakọbu, ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli. Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò ha ni í gba òdodo bí.
2 Ale oni nienawidzą dobrego, a miłują złe; odzierają lud z skóry ich, i mięso ich z kości ich;
Ẹ̀yin tí ó kórìíra ìre, tí ẹ sì fẹ́ràn ibi; ẹ̀yin tí ẹ fa awọ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi ya kúrò lára wọn àti ẹran-ara wọn kúrò ní egungun wọn;
3 A jedzą mięso ludu mojego, a skórę ich z nich zdzierają, i kości ich łamią, i rąbią je jako do garnca, a jako mięso do kotła.
àwọn tí ó jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi, wọn sì bọ́ awọ ara wọn kúrò lára wọn. Wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́; wọn sì gé e sí wẹ́wẹ́ bí ẹran inú ìkòkò, bí ẹran inú agbada?”
4 Tedy do Pana wołać będą, a nie wysłucha ich, owszem, zakryje oblicze swoje przed nimi czasu onego, tak jako oni wykonywali złe przedsięwzięcia swoje.
Nígbà náà ni wọn yóò kígbe sí Olúwa, ṣùgbọ́n òun kì yóò dá wọn lóhùn. Ní àkókò náà ni òun yóò fi ojú rẹ̀ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, nítorí ibi tí wọ́n ti ṣe.
5 Tak mówi Pan o tych prorokach, którzy w błąd zawodzą lud mój, a kąsając zębami swemi opowiadają pokój, a przeciwko temu, któryby im nic do gęby nie dał, wojnę podnoszą.
Báyìí ni Olúwa wí, “Ní ti àwọn Wòlíì tí ń ṣi àwọn ènìyàn mi lọ́nà, tí ẹnìkan bá fún wọn ní oúnjẹ, wọn yóò kéde àlàáfíà; ṣùgbọ́n tí kò bá fi nǹkan sí wọn ní ẹnu, wọn yóò múra ogun sí i.
6 Dlatego się wam widzenie obróci w noc, a wieszczba wasza w ciemność; bo tym prorokom słońce zajdzie, a dzień im się zaćmi.
Nítorí náà òru yóò wá sórí yín, tí ẹ̀yin kì yóò sì rí ìran kankan, òkùnkùn yóò sì kùn fún yín, tí ẹ̀yin kì yóò sì lè sọtẹ́lẹ̀. Oòrùn yóò sì wọ lórí àwọn wòlíì ọjọ́ yóò sì ṣókùnkùn lórí wọn.
7 I będą się wstydzili oni widzący, a wieszczkowie się zapłoną, a ci wszyscy zakryją zwierzchnią wargę swoję, przeto, że nie będzie żadnej odpowiedzi Bożej.
Ojú yóò sì ti àwọn wòlíì àwọn alásọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú yóò sì gba ìtìjú. Gbogbo wọn ni yóò bo ojú wọn, nítorí kò sí ìdáhùn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
8 Alem ja napełniony siłą ducha Pańskiego i sądem i mocą, abym oznajmił Jakóbowi przestępstwa jego, a Izraelowi grzech jego.
Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi kún fún agbára pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, láti sọ ìré-òfin-kọjá Jakọbu fún un, àti láti sọ ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli fún un.
9 Słuchajcież już tego przedniejsi w domu Jakóbowym, i wodzowie domu Izraelskiego, którzy macie sąd w obrzydliwości, a co jest sprawiedliwego, podwracacie.
Gbọ́ ẹ̀yin olórí ilé Jakọbu, àti ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli, tí ó kórìíra òdodo tí ó sì yí òtítọ́ padà;
10 Każdy buduje Syon krwią, a Jeruzalem nieprawością.
tí ó kọ́ Sioni pẹ̀lú ìtàjẹ̀ sílẹ̀, àti Jerusalẹmu pẹ̀lú ìwà búburú.
11 Przedniejsi jego sądzą według darów, a kapłani jego za zapłatę uczą, a prorocy jego za pieniądze prorokują; a przecie na Panu polegają, mówiąc: Izali nie jest Pan w pośrodku nas? Nie przyjdzieć na nas nic złego.
Àwọn olórí rẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀, àwọn àlùfáà rẹ̀ sì ń kọ́ni nítorí owó ọ̀yà àwọn wòlíì rẹ̀ pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ nítorí owó. Síbẹ̀, wọn gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, wọ́n sì wí pé, “Nítòótọ́, Olúwa wà pẹ̀lú wa! Ibi kan kì yóò bá wa.”
12 Przetoż Syon dla was jako pole poorany będzie, a Jeruzalem w gromady gruzu obrócone będzie, a góra domu Bożego w wysokie lasy.
Nítorí náà, nítorí tiyín, ni a ó ṣe ro Sioni bí oko, Jerusalẹmu yóò sì di ebè àti òkè tẹmpili bí i ibi gíga igbó.

< Micheasza 3 >