< Malachiasza 3 >

1 Oto ja posyłam Anioła mego, który zgotuje drogę przed obliczem mojem; a zarazem przyjdzie do kościoła swego Panujący, którego wy szukacie, i Anioł przymierza, którego wy żądacie; oto, przyjdzie, mówi Pan zastępów.
“Wò ó, Èmi yóò ran ìránṣẹ́ mi, yóò tún ọ̀nà ṣe ṣáájú mi. Nígbà náà ni Olúwa, tí ẹ̀yin ń wa, yóò dé ni òjijì sí tẹmpili rẹ̀; àní oníṣẹ́ májẹ̀mú náà, tí inú yín dùn sí, yóò dé,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
2 Lecz któż będzie mógł znieść dzień przyjścia jego? I kto się ostoi, gdy on się okaże? Bo on jest jako ogień roztapiający, i jako mydło blecharzów.
Ṣùgbọ́n ta ni o lè fi ara da ọjọ́ dídé rẹ̀? Ta ni yóò sì dúró nígbà tí ó bá fi ara hàn? Nítorí òun yóò dàbí iná ẹni tí ń da fàdákà àti bi ọṣẹ alágbàfọ̀.
3 I będzie siedział roztapiając i wyczyszczając srebro, i oczyści syny Lewiego, i przepławi je jako złoto i jako srebro, i będą ofiarować Panu dar w sprawiedliwości.
Òun yóò sì jókòó bí ẹni tí n yọ́, tí ó sì ń da fàdákà; yóò wẹ àwọn ọmọ Lefi mọ́, yóò sì tún wọn dàbí wúrà àti fàdákà, kí wọn bá a lè mú ọrẹ òdodo wá fún Olúwa,
4 Tedy Panu będzie wdzięczna ofiara od Judy i od Jeruzalemu, jako za dni pierwszych i jako za lat starodawnych.
nígbà náà ni ọrẹ Juda àti ti Jerusalẹmu yóò jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ àtijọ́, àti gẹ́gẹ́ bí ọdún ìgbàanì.
5 Ale się do was przybliżę z sądem, i będę świadkiem prędkim przeciwko czarownikom, i przeciwko cudzołożnikom, i przeciwko krzywoprzysiężcom, i przeciwko tym, którzy krzywdę czyniąc zatrzymywają zapłatę najemnikowi, wdowie i sierocie i cudzoziemcowi krzywdę czynią, a nie boją się mnie, mówi Pan zastępów.
“Èmi ó sì súnmọ́ yin fún ìdájọ́. Èmi yóò sì yára ṣe ẹlẹ́rìí sí àwọn oṣó, sí àwọn panṣágà, sí àwọn abúra èké, àti àwọn tí ó fi ọ̀yà alágbàṣe pọn wọn lójú, àti àwọn tí ó ni àwọn opó àti àwọn aláìní baba lára, àti sí ẹni tí kò jẹ́ kí àjèjì rí ìdájọ́ òdodo gbà, tí wọn kò sì bẹ̀rù mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
6 Gdyż ja Pan nie odmieniam się, przetoż wy, synowie Jakóbowi! nie jesteście zniszczeni.
“Èmi Olúwa kò yípadà. Nítorí náà ni a kò ṣe run ẹ̀yin ọmọ Jakọbu.
7 Zaraz ode dni ojców waszych odstąpiliście od ustaw moich, a nie strzegliście ich; nawróćcież się do mnie, a nawrócę się do was, mówi Pan zastępów. Ale mówicie: W czemże się nawrócimy?
Láti ọjọ́ àwọn baba ńlá yín wá ni ẹ̀yin tilẹ̀ ti kọ ẹ̀yìn sí ìlànà mi, tí ẹ kò sì pa wọ́n mọ́. Ẹ padà wá sí ọ̀dọ̀ mi, Èmi yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa yóò ṣe padà?’
8 Izali człowiek ma Boga złupić, że wy mnie łupicie? Wszakże mówicie: W czemże cię łupimy? W dziesięcinach i w ofiarach.
“Ènìyàn yóò ha ja Ọlọ́run ni olè bí? Síbẹ̀ ẹ̀yin ti jà mí ní olè. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe jà ọ́ ní olè?’ “Nípa ìdámẹ́wàá àti ọrẹ.
9 Zgołaście przeklęci, iż mię tak łupicie, wy i wszystek naród wasz.
Ríré ni a ó fi yín ré: gbogbo orílẹ̀-èdè yìí, nítorí ẹ̀yin ti jà mi lólè.
10 Znieście wszystkę dziesięcinę do szpichleża, aby była żywność w domu moim, a doświadczcie mię teraz w tem, mówi Pan zastępów; jeźli wam nie otworzę okien niebieskich, a nie wyleję na was błogosławieństwa, tak że go nie będziecie mieli gdzie podziać;
Ẹ mú gbogbo ìdámẹ́wàá wá sí ilé ìṣúra, kí oúnjẹ bá à lè wà ní ilé mi, ẹ fi èyí dán mi wò,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “kí ẹ sì wò bí èmi kò bá ní sí àwọn fèrèsé ọ̀run fún yin, kí èmi sì tú ìbùkún àkúnwọ́sílẹ̀ jáde fún yín, tó bẹ́ẹ̀ tí kì yóò sì ààyè láti gbà á.
11 I zgromię dla was pożerającego, a nie popsuję wam urodzaju ziemskiego, i nie pochybi winna macica na polu, mówi Pan zastępów.
Èmi yóò sì bá kòkòrò ajẹnirun wí nítorí yín, òun kò sì ni run èso ilẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni àjàrà inú oko yín kò ní rẹ̀ dànù,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
12 I będą was błogosławić wszyscy narodowie; bo wy będziecie ziemią rozkoszną, mówi Pan zastępów.
“Nígbà náà ni gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì pè yín ni alábùkún fún, nítorí tiyín yóò jẹ́ ilẹ̀ tí ó wu ni,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
13 Zmocniły się przeciwko mnie słowa wasze, mówi Pan; wszakże mówicie: Cóżeśmy mówili przeciwko tobie?
“Ẹ̀yin ti sọ ọ̀rọ̀ líle sí mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Síbẹ̀ ẹ̀yin béèrè pé, ‘Ọ̀rọ̀ kín ni àwa sọ sí ọ?’
14 Mówiliście: Próżna to Bogu służyć, a cóż za pożytek, choć będziemy strzedz rozkazania jego, i będziemy smętnie chodzić, bojąc się Pana zastępów?
“Ẹ̀yin ti wí pé, ‘Asán ni láti sin Ọlọ́run. Kí ni àwa jẹ ní èrè, nígbà tí àwa ti pa ìlànà rẹ mọ́, tí àwa sì ń rìn kiri bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ní iwájú Olúwa àwọn ọmọ-ogun?
15 Owszem, pyszne mamy za błogosławione, ponieważ się ci budują, którzy czynią niezbożność, a którzy kuszą Boga, zachowani bywają.
Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí àwa pé agbéraga ni alábùkún fún. Ní òtítọ́ ni àwọn ti ń ṣe búburú ń gbèrú sí i, kódà àwọn ti ó dán Ọlọ́run wò ni a dá sí.’”
16 Tedy rozmawiali o tem ci, którzy się boją Pana, każdy z bliźnim swoim. I obaczył Pan, a usłyszał, i napisano księgę pamiątki przed obliczem jego dla bojących się Pana i myślących o imieniu jego.
Nígbà náà ni àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa ń ba ara wọn sọ̀rọ̀, Olúwa sì tẹ́tí sí i, ó sì gbọ́. A sì kọ ìwé ìrántí kan níwájú rẹ̀, fún àwọn tí o bẹ̀rù Olúwa, tiwọn sì bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ̀.
17 Cić mi będą, mówi Pan zastępów, w dzień, który Ja uczynię, własnością; i zmiłuję się nad nimi, jako się zmiłowywa ojciec nad synem swoim, który mu służy.
“Wọn yóò sì jẹ́ tèmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ni ọjọ́ náà, tí èmi ó dá; èmi yóò sì da wọ́n sí gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí máa ń dá ọmọ rẹ̀ tí yóò sìn ín sí.
18 Tedy się nawrócicie, a obaczycie różność między sprawiedliwym i niezbożnym, między tym, który służy Bogu, i między tym, który mu nie służy.
Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìyàtọ̀, ìyàtọ̀ láàrín olódodo àti ẹni búburú, láàrín ẹni tí ń sìn Ọlọ́run, àti ẹni tí kò sìn ín.

< Malachiasza 3 >