< Kapłańska 27 >

1 Potem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé.
2 Mów do synów Izraelskich, a powiedz im: Gdyby człowiek ślubem poślubił duszę Panu, według szacunku twego da okup.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Bí ẹnìkan bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ pàtàkì láti ya ènìyàn kan sọ́tọ̀ fún Olúwa nípa sísan iye tí ó tó,
3 A będzie tak szacunek twój: Za mężczyznę od dwudziestu lat aż do sześćdziesiąt lat, będzie szacunek twój pięćdziesiąt syklów srebra według wagi świątnicy.
kí iye owó ọkùnrin láti ọmọ ogún ọdún sí ọgọ́ta ọdún jẹ́ àádọ́ta òsùwọ̀n ṣékélì fàdákà, gẹ́gẹ́ bí òsùwọ̀n ṣékélì ti ibi mímọ́ Olúwa.
4 A jeźli jest biała głowa szacunek twój będzie trzydzieści syklów,
Bí ẹni náà bá jẹ obìnrin, kí iye owó rẹ̀ jẹ́ ọgbọ̀n òsùwọ̀n ṣékélì.
5 A jeźli od piątego roku aż do dwudziestego roku, tedy będzie szacunek twój za mężczyznę dwadzieścia syklów a za białą głowę dziesięć syklów.
Bí ẹni náà bá jẹ́ ọmọ ọdún márùn-ún sí ogún ọdún, kí iye owó rẹ̀ jẹ́ ogún ṣékélì fún ọkùnrin àti òsùwọ̀n ṣékélì mẹ́wàá fún obìnrin.
6 A jeźli za dziecię od jednego miesiąca aż do pięciu lat, tedy będzie szacunek twój za mężczyznę pięć syklów srebra, a za dzieweczkę szacunek twój trzy sykle srebra.
Bí ẹni náà bá jẹ́ ọmọ oṣù kan sí ọdún márùn-ún, kí iye owó rẹ̀ jẹ́ òsùwọ̀n ṣékélì fàdákà márùn-ún fún ọkùnrin àti òsùwọ̀n ṣékélì fàdákà mẹ́ta fún obìnrin.
7 A jeźli od sześćdziesiąt lat i wyżej będzieli mężczyzna tedy będzie szacunek twój piętnaście syklów a za białą głowę dziesięć syklów.
Bí ẹni náà bá jẹ́ ọmọ ọgọ́ta ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ, kí iye owó rẹ̀ jẹ́ òsùwọ̀n ṣékélì mẹ́ẹ̀ẹ́dógún fún ọkùnrin àti òsùwọ̀n ṣékélì mẹ́wàá fún obìnrin.
8 Lecz jeźliby był tak ubogi, żeby nie mógł oddać szacunku twego, tedy go stawią przed kapłana, i oszacuje go kapłan, według przemożenia tego który ślubował, oszacuje go kapłan.
Bí ẹnìkan tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́ bá tálákà púpọ̀ dé bi pé kò lè san iye owó náà, kí a mú ẹni náà wá síwájú àlùfáà, àlùfáà yóò sì dá iye owó tí ó lè san lé e gẹ́gẹ́ bí agbára ẹni náà tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́.
9 Jeźliby też bydlę z tych, które się ofiarują na ofiarę Panu, poślubił, każde, które odda Panu będzie święte.
“‘Bí ẹ̀jẹ́ tí ó jẹ́ bá jẹ́ ẹranko èyí tí ó jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fún Olúwa, irú ẹran bẹ́ẹ̀ tí a bá fi fún Olúwa di mímọ́.
10 Nie odmieni go, ani da innego za nie, lepszego za gorsze, albo gorszego za lepsze; jeźliby też jakokolwiek odmienił bydlę za bydlę, tedy i ono, i to, które za nie dano będzie święte.
Ẹni tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́ náà kò gbọdọ̀ pàrọ̀ ẹran mìíràn, yálà kí ó pàrọ̀ èyí tí ó dára sí èyí tí kò dára tàbí èyí tí kò dára sí èyí tí ó dára. Bí ó bá ṣe bẹ́ẹ̀ ti Olúwa ni ẹranko méjèèjì.
11 A jeźliby które nie czyste bydlę poślubił z tych, co nie bywają ofiarowane Panu, tedy stawi to bydlę przed kapłana,
Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ ní ti ẹranko àìmọ́ tí a fi tọrẹ: èyí tí kò jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà bí i ọrẹ fún Olúwa. Kí ọkùnrin náà mú ọrẹ náà lọ fún àlùfáà.
12 I oszacuje kapłan bądź dobre, bądź złe, a jako je oszacuje kapłan, tak będzie.
Kí àlùfáà díye lé e, gẹ́gẹ́ bí ó ti dára tàbí bí ó ti bàjẹ́ sí. Iye owó náà ni kí ó jẹ́.
13 A jeźliby je kto odkupić chciał, przyda piątą część nad szacunek twój.
Bí ẹni náà bá fẹ́ rà á padà, ó gbọdọ̀ san iye owó rẹ̀ àti ìdá ogún iye owó náà láfikún.
14 Jeźliby też kto poświęcił dom swój, żeby był święty Panu, tedy go oszacuje kapłan bądź dobry, bądź zły; jako go oszacuje kapłan, tak zostanie.
“‘Bí ẹnikẹ́ni bá ya ilẹ̀ rẹ̀ sí mímọ́ fún Olúwa: kí àlùfáà kó sọ iye tí yóò san gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ náà ti dára tàbí bàjẹ́ sí, iye owó náà ni kí ó jẹ́.
15 A gdyby ten, który poświęcił, chciał odkupić dom swój, przyda piątą część pieniędzy na szacunek twój, i będzie jego.
Bí ẹni tí ó yá ilé náà sí mímọ́ bá fẹ́ rà á padà. Jẹ́ kí ó fi ìdámárùn-ún owó ìdíyelé rẹ̀ kún ún, yóò si jẹ́ tirẹ̀.
16 Jeźli też kto część roli z dziedzictwa swego poświęcił Panu tedy będzie szacunek twój według zasiewku jej; gdzie się wysieje chomer jęczmienia, za pięćdziesiąt syklów srebra szacowane będzie.
“‘Bí ẹnìkan bá sì ya ara ilẹ̀ ìdílé rẹ̀ sí mímọ́ fún Olúwa. Iye tí ó bá jẹ́ ni kí wọ́n ṣètò gẹ́gẹ́ bí iye èso tí a ó fi gbìn ín. Àádọ́ta ṣékélì fàdákà fún òsùwọ̀n homeri irúgbìn barle.
17 Jeźli do miłościwego lata poświęcił rolę swoję, według szacunku twego zostanie.
Bí ó ba ṣe pé ní ọdún ìdásílẹ̀ ni ó ya ilẹ̀ náà sí mímọ́. Iye owó tí wọn sọtẹ́lẹ̀ náà ni kí o san.
18 Ale jeźliżby po miłościwem lecie poświęcił rolę twoję tedy kapłan obrachuje mu pieniądze według lat zostawających do miłościwego lata i umniejszy mu się z szacunku twego.
Bí ó bá ya ilẹ̀ náà sí mímọ́ lẹ́yìn ọdún ìdásílẹ̀ kí àlùfáà sọ iye owó tí yóò san fún ọdún tókù kí ọdún ìdásílẹ̀ mìíràn tó pé iye owó tí ó gbọdọ̀ jẹ yóò dínkù.
19 A chciałliby odkupić rolą, ten, który ją poświęcił, przyda piątą część pieniędzy do szacunku twego i zostanie przy niej.
Bí ẹni tí ó ya ilẹ̀ sí mímọ́ bá fẹ́ rà á padà, kí ó san iye owó náà pẹ̀lú àfikún ìdámárùn-ún. Ilẹ̀ náà yóò sì di tirẹ̀.
20 Ale gdzie by nie odkupił roli onej, a sprzedana by była rola komu inszemu, nie może być odkupiona.
Bí kò bá ra ilẹ̀ náà padà tàbí bí ó bá tà á fún ẹlòmíràn kò le è ri rà padà mọ́.
21 I będzie ona rola, gdy wynijdzie miłościwe lato święta Panu, jako rola poświęcona a przyjdzie w osiadłość kapłanowi.
Bí a bá fi ilẹ̀ náà sílẹ̀ ní ọdún ìdásílẹ̀ yóò di mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ tí a fi fún Olúwa. Yóò sì di ohun ìní àlùfáà.
22 A jeźliby kto rolą kupioną, która nie była z ról dziedzictwa jego poślubił Panu.
“‘Bí ẹnikẹ́ni bá ya ilẹ̀ tí ó ti rà tí kì í ṣe ilẹ̀ ìdílé rẹ̀ sí mímọ́ fún Olúwa.
23 Tedy porachuje mu kapłan sumę szacunku twego aż do roku miłościwego, i da szacunek ten dnia onego za rzecz poświęconą Panu.
Kí àlùfáà sọ iye tí ó tọ títí di ọdún ìdásílẹ̀. Kí ọkùnrin náà sì san iye owó náà ní ọjọ́ náà gẹ́gẹ́ bí ohun mímọ́ sí Olúwa.
24 A w miłościwe lato wróci się rola od tego, od kogo ją kupiono, do tego, który dziedzicznie trzymał rolą onę.
Ní ọdún ìdásílẹ̀ ilẹ̀ náà yóò padà di ti ẹni tí ó ni í, lọ́wọ́ ẹni tí a ti rà á.
25 A każdy szacunek twój będzie wedle sykla świątnicy, a dwadzieścia pieniędzy sykiel waży.
Gbogbo iye owó wọ̀nyí gbọdọ̀ wà ní ìbámu pẹ̀lú ṣékélì ibi mímọ́, ogún gera.
26 Wszakże pierworodnego, a które prawem pierworodztwa bywa ofiarowane Panu z bydła, nikt go nie poświęci, bądź wół bądź owca, ponieważ Pańskie są.
“‘Kò sí ẹni tí ó gbọdọ̀ ya gbogbo àkọ́bí ẹran sọ́tọ̀. Èyí jẹ́ ti Olúwa nípasẹ̀ òfin àkọ́bí: yálà akọ màlúù ni tàbí àgùntàn, ti Olúwa ni.
27 A jeźliby z bydląt nieczystych było, odkupi je według szacunku twego, i przyda piątą część nad to; a jeźliby go nie odkupiono, niechże sprzedane będzie według szacunku twego.
Bí ó bá jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ẹran tí kò mọ́, nígbà náà ni kí ó rà á padà gẹ́gẹ́ bí ìdíyelé rẹ̀, kí ó sì fi ìdámárùn-ún lé e, tàbí bí a kò bá rà á padà kí ẹ tà á gẹ́gẹ́ bí ìdíyelé rẹ̀.
28 Każda jednak rzecz poślubiona, którą by kto poślubił Panu ze wszystkiego, co ma z ludzi, i z bydła, i z ról osiadłości swojej, nie będzie sprzedawana, ani odkupowana; bo wszelka rzecz poślubiona najświętsza jest Panu.
“‘Ohun tí a bá yà sí mímọ́ pátápátá láti ọwọ́ ẹnikẹ́ni sí Olúwa tàbí ẹranko tàbí ilẹ̀ tí ó jogún, òun kò gbọdọ̀ tà á kí ó rà á padà. Gbogbo ohun ìyàsọ́tọ̀ bẹ́ẹ̀ di mímọ́ jùlọ fún Olúwa.
29 Wszelkie bydlę poślubione, które się pod ślubem oddawa, od człowieka nie będzie odkupione, ale śmiercią umrze.
“‘Ẹni tí ẹ bá ti yà sọ́tọ̀ fún pípa, ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ rà á padà, pípa ni kí ẹ pa á.
30 Wszystkie także dziesięciny ziemi z nasienia ziemi, z owocu drzewa, Pańskie są; bo poświęcone są Panu.
“‘Gbogbo ìdámẹ́wàá ilẹ̀ náà yálà tí èso ilẹ̀ ni, tàbí tí èso igi, ti Olúwa ni. Mímọ́ ni fún Olúwa.
31 Ale kto by chciał odkupić co z dziesięcin swoich, piątą część ceny przyda do nich.
Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ ra ìdámẹ́wàá nǹkan rẹ̀ padà, o gbọdọ̀ fi márùn-ún kún un.
32 Także wszystkie dziesięciny z rogatego bydła, i z drobnego bydła, wszystkiego, co przechodzi pod laską pasterską, każde dziesiąte będzie poświęcone Panu.
Gbogbo ìdámẹ́wàá àgbò àti ẹran ọ̀sìn, àní ìdámẹ́wàá ẹran tó bá kọjá lábẹ́ ọ̀pá darandaran kí ó jẹ́ mímọ́ fún Olúwa.
33 Nie będzie przebierał między dobrem albo złem, ani go odmieniać będzie; a jeźliby je jakokolwiek odmienił, będzie to i ono odmienione poświęcone, nie ma być odkupione.
Ènìyàn kò gbọdọ̀ wádìí bóyá ó dára tàbí kò dára, kò sì gbọdọ̀ pààrọ̀ rẹ̀. Bí ó bá pààrọ̀ rẹ̀: àti èyí tí ó pààrọ̀ àti èyí tí ó fi pààrọ̀ ni kí ó jẹ́ mímọ́. Wọn kò gbọdọ̀ rà á padà.’”
34 Teć są przykazania, które rozkazał Pan Mojżeszowi do synów Izraelskich na górze Synaj.
Àwọn àṣẹ wọ̀nyí ni Olúwa pa fún Mose fún àwọn ọmọ Israẹli ní orí òkè Sinai.

< Kapłańska 27 >