< Kapłańska 17 >

1 Tedy rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Mów do Aarona i do synów jego, i do wszystkich synów Izraelskich, a powiedz im: Tać jest rzecz, którą przykazał Pan mówiąc:
“Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli: ‘Ohun tí Olúwa pàṣẹ nìyí,
3 Ktobykolwiek z domu Izraelskiego zabił wołu, albo owcę, albo kozę w obozie, albo kto by zabił za obozem,
bí ẹnikẹ́ni nínú ìdílé Israẹli bá pa màlúù tàbí ọ̀dọ́-àgùntàn tàbí àgbò nínú ibùdó tàbí bí ó bá pa á lẹ́yìn ibùdó
4 A do drzwi namiotu zgromadzenia nie przywiódłby tego, aby ofiarował ofiarę Panu, przed przybytkiem Pańskim, krwi winien będzie on mąż, krew przelał; przetoż wytracony będzie on mąż z pośrodku ludu swego.
tí kò sì mú un wá sí ibi àgọ́ ìpàdé láti fi rú ẹbọ sí Olúwa níwájú àgọ́ ìpàdé, ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni kí ẹ kà sí ẹni náà lọ́rùn: torí pé ó ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹni náà ni a ó sì gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
5 Synowie tedy Izraelscy przywiodą ofiary swoje, które zabijali na polu; przywiodą je Panu do drzwi namiotu zgromadzenia, do kapłana; a tak niechaj sprawują ofiary spokojne Panu.
Èyí rí bẹ́ẹ̀ kí àwọn ọmọ Israẹli le è máa mú ẹbọ wọn tí wọn ti rú ní ìta gbangba wá sí iwájú Olúwa: wọ́n gbọdọ̀ mú un wá síwájú àlùfáà àní sí Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n sì rú wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa.
6 I wyleje kapłan krew na ołtarz Pański u drzwi namiotu zgromadzenia, a spali tłustość ku wdzięcznej wonności Panu.
Àlùfáà náà yóò sì fi ẹ̀jẹ̀ náà wọ́n ibi pẹpẹ Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, yóò sì sun ọ̀rá rẹ̀ ní òórùn dídùn sí Olúwa.
7 I nie będą ofiarować więcej ofiar swych dyjabłom, z którymi cudzołożyli; ta ustawa wieczna będzie im w narodziech ich.
Nítorí náà, kí wọn má ṣe rú ẹbọ wọn sí ère ẹranko mọ́, nínú èyí tí wọ́n ti ṣe àgbèrè tọ̀ lọ. Èyí yóò sì jẹ́ ìlànà títí láé láti ìran dé ìran wọn tí ń bọ̀.’
8 Nadto im jeszcze powiedz: Jeźliby kto z domu Izraelskiego, albo z przychodniów między wami mieszkających chciał ofiarować ofiarę całopalenia, albo inszą ofiarę,
“Kí ó sọ fún wọn pé, ‘Ọkùnrin yówù kí ó jẹ́ ní ìdílé Israẹli tàbí ti àwọn àlejò tí ń gbé láàrín wọn tí ó bá rú ẹbọ sísun tàbí ṣe ẹbọ
9 A do drzwi namiotu zgromadzenia nie przywiódłby jej, aby ją ofiarował Panu, wytracony będzie człowiek ten z ludu swego.
tí kò sì mú un wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé láti fi rú ẹbọ sí Olúwa irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
10 A ktobykolwiek z domu Izraelskiego, albo z przychodniów którzy by gośćmi byli między nimi, jadł krew jaką, postawię rozgniewaną twarz swą przeciwko człowiekowi krew jedzącemu, i wygładzę go z pośrodku ludu jego.
“‘Bí ẹnikẹ́ni bá jẹ ẹ̀jẹ̀ yálà nínú ìdílé Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín wọn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni náà tí ó jẹ ẹ̀jẹ̀, èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
11 Albowiem dusza wszelkiego ciała we krwi jego jest; a Ja dałem ją wam na ołtarz ku oczyszczeniu dusz waszych; bo krew jest, która duszę oczyszcza.
Nítorí pé nínú ẹ̀jẹ̀ ni ẹ̀mí ẹ̀dá wà, èmi sì ti fi fún yín lórí pẹpẹ fún ètùtù ọkàn yín: nítorí pé ẹ̀jẹ̀ ni a fi ń ṣe ètùtù fún ẹ̀mí ènìyàn.
12 Dla tegoż powiedziałem synom Izraelskim: Żaden między wami nie będzie jadał krwi; ani przychodzień, który gościem jest między wami, nie będzie jadał krwi.
Ìdí nìyí tí mo fi sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ọ̀kankan nínú yín kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àlejò kan tí ń ṣe àtìpó nínú yín kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀.
13 I ktobykolwiek z synów Izraelskich, albo z przychodniów, którzy są gośćmi między wami, goniąc ułowił jakie zwierzę albo ptaka, co się godzi jeść, tedy krew z niego wypuści, i zasypie ją piaskiem.
“‘Ẹnikẹ́ni yálà nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé láàrín wọn, tí ó bá pa ẹranko tàbí ẹyẹ tí ó yẹ fún jíjẹ gbọdọ̀ ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sílẹ̀ kí ó sì bò ó mọ́lẹ̀.
14 Bo dusza każdego ciała jest krew jego, która jest miasto duszy jego; przetożem powiedział synom Izraelskim: Krwi wszelkiego ciała jeść nie będziecie; bo dusza wszelkiego ciała jest krew jego; kto by ją kolwiek jadł, wytracony będzie.
Torí pé ẹ̀mí gbogbo ẹ̀dá ni ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, torí náà ni mo fi kìlọ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ ohun abẹ̀mí kankan, torí pé nínú ẹ̀jẹ̀ ohun abẹ̀mí wọ̀nyí ni ẹ̀mí wọn wà, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹ́ ni a ó gé kúrò.
15 Jeźliby też kto jadł co zdechłego, albo od zwierza rozszarpanego, tak w domu zrodzony, jako przychodzień, tedy upierze szaty swoje i omyje się wodą, a nieczystym będzie aż do wieczora; potem czysty będzie.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohun tí ó kú sílẹ̀ fúnra rẹ̀, tàbí èyí tí ẹranko búburú pa kálẹ̀ yálà onílé tàbí àlejò, ó ní láti fọ aṣọ rẹ̀. Kí ó sì fi omi wẹ ara rẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di àṣálẹ́ lẹ́yìn èyí ni yóò tó di mímọ́.
16 Ale jeźliby nie uprał szat swoich, a ciała swego nie omył, poniesie nieprawość swoję.
Ṣùgbọ́n bí ó bá kọ̀ láti wẹ ara rẹ̀ tí kò sì fọ aṣọ rẹ̀ náà: ẹ̀bi rẹ̀ yóò wà lórí ara rẹ̀.’”

< Kapłańska 17 >