< Kapłańska 14 >

1 Potem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Tać jest ustawa około trędowatego w dzień oczyszczenia jego: przywiedziony będzie do kapłana.
“Èyí ni àwọn ìlànà fún ẹni tí ààrùn ẹ̀tẹ̀ bá mú ní àkókò ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀, bí a bá mú un tọ àlùfáà wá.
3 A wynijdzie kapłan precz za obóz: a obaczyli kapłan, że oto uleczona jest zaraza trądu, trądem zarażonego,
Kí àlùfáà yẹ̀ ẹ́ wò ní ẹ̀yìn ibùdó bí ara rẹ̀ bá ti yá kúrò nínú ààrùn ẹ̀tẹ̀ náà.
4 Tedy rozkaże kapłan temu, który się oczyszcza, aby wziął dwa wróble żywe i zdrowe, i drzewo cedrowe, i jedwabiu karmazynowego, i hizopu.
Kí àlùfáà pàṣẹ pé kí a mú ààyè ẹyẹ mímọ́ méjì, igi kedari, òdòdó àti ẹ̀ka hísópù wá fún ẹni tí a fẹ́ wẹ̀mọ́.
5 I rozkaże kapłan zabić jednego wróbla nad naczyniem glinianem, nad wodą żywą.
Kí àlùfáà pàṣẹ pé kí wọn pa ọ̀kan nínú àwọn ẹyẹ náà sórí omi tí ó mọ́ tó wà nínú ìkòkò amọ̀.
6 Wróbla tedy żywego weźmie, i drzewo cedrowe, i jedwab karmazynowy i hizop, a omoczy to wszystko z wróblem żywym we krwi wróbla zabitego nad wodą żywą.
Lẹ́yìn náà kí ó ri ààyè ẹyẹ pẹ̀lú igi kedari, òdòdó àti ẹ̀ka hísópù bọ inú ẹ̀jẹ̀ ẹyẹ tí a ti pa sínú omi náà.
7 I pokropi tego, który się oczyszcza od trądu, siedem kroć, i ogłosi go być czystym, a puści wróbla żywego w pole.
Ìgbà méje ni kí o wọ́n omi yìí sí ara ẹni tí a fẹ́ wẹ̀mọ́ kúrò nínú ààrùn ara náà kí ó ju ààyè ẹyẹ náà sílẹ̀ ní ìta gbangba.
8 A ten, który się oczyszcza, upierze szaty swoje, i ogoli wszystkie włosy swoje, a umyje się wodą, i czystym będzie. Potem wnijdzie do obozu, a będzie mieszkał przed namiotem swoim przez siedem dni.
“Ẹni tí a fẹ́ wẹ̀mọ́ náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, fá gbogbo irun rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, lẹ́yìn èyí ó ti di mímọ́. Lẹ́yìn náà ó le wá sínú ibùdó ṣùgbọ́n kí ó wà lẹ́yìn àgọ́ rẹ̀ ní ọjọ́ méje.
9 Potem dnia siódmego ogoli wszystkie włosy swe, głowę swą, i brodę swą, i brwi nad oczyma swemi, i wszystkie inne włosy swe ogoli; przytem upierze szaty swe, i ciało swe omyje wodą, a tak oczyszczon będzie.
Kí ó fá gbogbo irun rẹ̀ ní ọjọ́ keje: irun orí rẹ̀, irùngbọ̀n rẹ̀, irun ìpéǹpéjú rẹ̀, àti gbogbo irun rẹ̀ tókù. Kí ó fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì mọ́.
10 A dnia ósmego weźmie dwu baranków zupełnych, i owcę jednę roczną, zupełną, i trzy dziesiąte części efy mąki pszennej na ofiarę śniedną, zmieszaną z oliwą, i miarkę oliwy,
“Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àgbò aláìlábùkù méjì àti abo ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan tí wọn kò ní àlébù wá, pẹ̀lú ìdámẹ́wàá nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun tí à pòpọ̀ mọ́ òróró fún ọrẹ ohun jíjẹ àti òsùwọ̀n lógù òróró kan.
11 Tedy kapłan, który oczyszcza człowieka, który ma być oczyszczony, postawi z temi rzeczami przed Panem, u drzwi namiotu zgromadzenia.
Àlùfáà tí ó pè é ní mímọ́, yóò mú ẹni náà tí a ó sọ di mímọ́ àti ọrẹ rẹ̀ wá síwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
12 Potem weźmie kapłan barana jednego, i będzie go ofiarował na ofiarę za występek, z oną miarką oliwy, i będzie to tam i sam obracał na ofiarę obracania przed obliczem Pańskiem.
“Kí àlùfáà mú ọ̀kan nínú àwọn àgbò àti lógù òróró kí ó sì fi rú ẹbọ ẹ̀bi. Kí ó sì fì wọ́n níwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì.
13 Zabije też baranka onego na miejscu, gdzie biją ofiary za grzech i ofiarę całopalenia, na miejscu świętem; bo jako ofiara za grzech tak ofiara za występek należy kapłanowi; rzecz najświętsza jest.
Kí ó pa àgbò náà ní ibi mímọ́ níbi tí wọ́n ti ń pa ẹran ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ọrẹ ẹbọ sísun. Bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, ẹbọ ẹ̀bi náà jẹ́ ti àlùfáà: ó jẹ́ mímọ́ jùlọ.
14 I weźmie kapłan krwi z ofiary za występek, i pomaże kapłan koniec ucha prawego onemu, który się oczyszcza; także palec wielki u prawej ręki jego i palec wielki u prawej nogi jego.
Kí àlùfáà mú nínú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀bi náà kí ó fi sí etí ọ̀tún ẹni náà tí a ó wẹ̀mọ́, kí ó tún fi sí àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti orí àtàǹpàkò ẹsẹ̀ ọ̀tún rẹ̀.
15 Weźmie też kapłan z onej miarki oliwy, a naleje na dłoń swoję lewą;
Àlùfáà yóò sì mú díẹ̀ nínú lógù òróró, yóò sì dà á sí àtẹ́lẹwọ́ òsì ara rẹ̀.
16 A omoczy palec swój prawy w oliwie, która jest na lewej dłoni jego, i pokropi oliwą z palca swego siedem kroć przed obliczem Pańskiem.
Yóò sì ti ìka ìfábẹ̀lá ọ̀tún rẹ̀ bọ inú òróró àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀, yóò sì wọ́n díẹ̀ nínú rẹ̀ níwájú Olúwa nígbà méje.
17 A z ostatku oliwy, która jest na dłoni jego, pomaże kapłan koniec ucha prawego onemu, który się oczyszcza, i wielki palec prawej ręki jego, także wielki palec prawej nogi jego z onejże krwi, która jest ofiarą za występek.
Àlùfáà yóò mú lára òróró tí ó kù ní àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀ yóò fi sí etí ọ̀tún, àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún àti àtàǹpàkò ẹsẹ̀ ọ̀tún ẹni tí à ó wẹ̀mọ́, lórí ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀bi.
18 A coby zostało oliwy, która jest na dłoni kapłanowej, pomaże tem głowę onego, który się oczyszcza; i tak go oczyści kapłan przed obliczem Pańskiem.
Àlùfáà yóò fi òróró tí ó kù ní àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀ ra orí ẹni tí a ó wẹ̀mọ́, yóò sì ṣe ètùtù fún un níwájú Olúwa.
19 Uczyni także kapłan ofiarę za grzech, i oczyści tego, który się oczyszcza, od nieczystości jego, a potem zabije ofiarę całopalenia.
“Àlùfáà yóò sì rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, yóò ṣe ètùtù fún ẹni tí a ó wẹ̀ kúrò nínú àìmọ́ rẹ̀, lẹ́yìn náà àlùfáà yóò pa ẹran ọrẹ ẹbọ sísun.
20 I ofiarować będzie kapłan ofiarę całopalenia, i ofiarę śniedną na ołtarzu; tak oczyści go kapłan, i czystym będzie.
Kí àlùfáà kí ó sì rú ẹbọ sísun, àti ẹbọ ohun jíjẹ lórí pẹpẹ, kí àlùfáà kí ó sì ṣe ètùtù fún un, òun yóò sì di mímọ́.
21 A jeźliby kto był tak ubogi, iżby tego nie przemógł, tedy weźmie baranka jednego na ofiarę za występek na podnoszenie dla oczyszczenia swego, i jednę dziesiątą część efy mąki pszennej zagniecionej z oliwą na ofiarę śniedną i miarkę oliwy.
“Bí ẹni náà bá jẹ́ tálákà tí kò sì le è kó gbogbo nǹkan wọ̀nyí wá, kí ó mú ọ̀dọ́ àgbò kan bí ẹbọ ẹ̀bi, tí yóò fì, láti ṣe ètùtù fún un, pẹ̀lú ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun dídára, a pò mọ́ òróró fún ọrẹ ohun jíjẹ òsùwọ̀n lógù òróró
22 Nad to dwie synogarlice, albo dwoje gołąbiąt, czego dostać może, z których jedno będzie na ofiarę za grzech, a drugie na ofiarę całopalenia;
àti àdàbà méjì tàbí ẹyẹlé méjì èyí tí agbára rẹ̀ ká, ọ̀kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun.
23 I przyniesie je w ósmy dzień oczyszczenia swego do kapłana, do drzwi namiotu zgromadzenia, przed obliczność Pańską.
“Kí ó mú wọn wá ní ọjọ́ kẹjọ fún ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀ síwájú àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé níwájú Olúwa.
24 Weźmie tedy kapłan baranka ofiary za występek, i miarkę oliwy; i będzie to obracał tam i sam kapłan na ofiarę obracania przed Panem.
Àlùfáà náà yóò sì mú ọ̀dọ́-àgùntàn ẹbọ ẹ̀bi pẹ̀lú lógù òróró yóò sì fì wọ́n níwájú Olúwa bí ẹbọ fífì.
25 A zabije baranka na ofiarę za występek: a wziąwszy kapłan ze krwi ofiary za występek, pomaże koniec ucha prawego temu, który się oczyszcza; i palec wielki prawej ręki jego, i palec wielki prawej nogi jego.
Kí ó pa ọ̀dọ́-àgùntàn ẹbọ ẹ̀bi kí ó sì mú lára ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Kí ó fi sí etí ọ̀tún, àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún àti àtàǹpàkò ẹsẹ̀ ọ̀tún ẹni tí a ó ṣe ìwẹ̀nùmọ́ fún.
26 Oliwy także naleje kapłan na lewą dłoń swoję.
Àlùfáà yóò sì da díẹ̀ lára òróró náà sí àtẹ́lẹwọ́ òsì ara rẹ̀.
27 I kropić będzie kapłan palcem swoim prawym z oliwy, która jest na lewej ręce jego siedem kroć przed obliczem Pańskiem.
Yóò sì fi ìka ìfábẹ̀lá ọ̀tún rẹ̀ wọ́n òróró tí ó wà ní àtẹ́lẹwọ́ òsì rẹ̀ nígbà méje níwájú Olúwa.
28 Pomaże też kapłan oną oliwą, która jest na dłoni jego, koniec ucha prawego temu, który się oczyszcza; także wielki palec prawej ręki jego, i wielki palec prawej nogi jego na miejscu krwi z ofiary za występek;
Àlùfáà yóò sì mú lára òróró ọwọ́ rẹ̀ sí etí ọ̀tún, àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún àti àtàǹpàkò ẹsẹ̀ ọ̀tún ẹni tí a ń ṣe ìwẹ̀nùmọ́ fún ní ibi kan náà tí wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀bi sí.
29 A ostatkiem oliwy, która jest na dłoni kapłana, pomaże głowę onego, który się oczyszcza, aby go oczyścił przed Panem.
Kí àlùfáà fi ìyókù nínú òróró ọwọ́ rẹ̀ sí orí ẹni náà tí a ń ṣe ìwẹ̀nùmọ́ fún, láti ṣe ètùtù fún un ní iwájú Olúwa.
30 Także uczyni z jedną synogarlicą, albo z jednem gołębięciem, czegokolwiek z tych dostać może.
Lẹ́yìn náà kí ó fi àdàbà tàbí ọmọ ẹyẹlé rú ẹbọ níwọ̀n tí agbára rẹ̀ mọ.
31 Czego dostać mógł, jedno z tych będzie ofiarą za grzech, a drugie na ofiarę całopalenia z ofiarą śniedną; a tak oczyści kapłan tego, który się oczyszcza przed obliczem Pańskiem.
Ọ̀kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ, àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù níwájú Olúwa ní ipò ẹni tí a fẹ́ wẹ̀mọ́.”
32 A tać jest ustawa o tym, na którym by była zaraza trądu, który wszystkiego mieć nie może ku oczyszczeniu swemu.
Òfin nìyí fún ẹnikẹ́ni tí ó bá ní ààrùn ara tí ó le ran tí kò sì lágbára láti rú ẹbọ tí ó yẹ fún ìwẹ̀nùmọ́ bí a ti fi lélẹ̀.
33 Rzekł potem Pan do Mojżesza i do Aarona, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé.
34 Gdy wnijdziecie do ziemi Chananejskiej, którą Ja wam dawam w osiadłość, a dopuściłbym zarazę trądu na który dom osiadłości waszej:
“Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ Kenaani tí mo fi fún yín ní ìní, tí mo sì fi ààrùn ẹ̀tẹ̀ sínú ilé kan ní ilẹ̀ ìní yín.
35 Tedy on, którego dom jest, przyjdzie i opowie to kapłanowi, mówiąc: Jakoby zaraza trądu zda mi się być w domu moim,
Kí ẹni tí ó ní ilé náà lọ sọ fún àlùfáà pé, ‘Èmi tí rí ohun tí ó jọ ààrùn ẹ̀tẹ̀ ní ilé mi.’
36 Rozkaże tedy kapłan wyprzątnąć dom pierwej niż sam wnijdzie, aby oglądał zarazę onę, iżby się nic nie splugawiło, coby było w domu, a potem kapłan wnijdzie, aby oglądał on dom.
Àlùfáà yóò pàṣẹ kí ẹnikẹ́ni tàbí ohunkóhun má ṣe wà nínú ilé náà, kí ó tó lọ yẹ ẹ̀tẹ̀ náà wò, kí ohunkóhun nínú ilé náà má bá à di àìmọ́. Lẹ́yìn èyí àlùfáà yóò wọlé lọ láti yẹ ilé náà wò.
37 A oglądając onę zarazę, ujrzeli zarazę na ścianie domu, jakoby dołki czarne, przyzieleńszym, albo przyczerwieńszym, a na spojrzeniu byłoby głębsze niż ściana.
Yóò yẹ ààrùn náà wò, bí ààrùn náà bá ti wà lára ògiri ilé náà nípa àmì àwọ̀ ewé tàbí àmì pupa tí ó sì jinlẹ̀, ju ara ògiri lọ.
38 Tedy wynijdzie kapłan z domu onego przede drzwi, i zamknie on dom przez siedem dni.
Àlùfáà yóò jáde kúrò nínú ilé náà, yóò sì ti ìlẹ̀kùn ilé náà pa fún ọjọ́ méje.
39 Wróci się potem kapłan dnia siódmego i obejrzy; a jeźli się rozszerzyła zaraza na ścianach domu onego,
Àlùfáà yóò padà wá yẹ ilé náà wò ní ọjọ́ keje. Bí ààrùn náà bá ti tàn ká ara ògiri.
40 Rozkaże kapłan wyłamać ono kamienie, na którem by była zaraza, i wyrzucić je precz za miasto na miejsce nieczyste;
Àlùfáà yóò pàṣẹ kí a yọ àwọn òkúta tí ààrùn náà ti bàjẹ́ kúrò kí a sì kó wọn dànù sí ibi tí a kà sí àìmọ́ lẹ́yìn ìlú.
41 A dom rozkaże wewnątrz oskrobać wszędy w około; i wyrzucą on proch który oskrobali, precz za miasto na miejsce nieczyste;
Yóò sì mú kí wọ́n ha ògiri inú ilé náà yíká. Gbogbo ohun tí wọ́n fi rẹ́ ilé náà tí ó ti ha ni kí wọ́n kó dànù sí ibi tí a kà sí àìmọ́ lẹ́yìn ìlú náà.
42 I wezmą kamienie insze i wprawią na miejsce innych kamieni; i wapna też inszego wezmą a potynkują dom.
Òkúta mìíràn ni kí wọ́n fi dípò àwọn tí a ti yọ dànù, kí wọ́n sì rẹ́ ilé náà pẹ̀lú àwọn ohun ìrẹ́lé tuntun.
43 A jeźliby się odnowiła ona zaraza, i rozszerzyła się po domu po wyrzuceniu kamienia, i po wyskrobaniu domu i po tynkowaniu jego:
“Bí ààrùn yìí bá tún farahàn lẹ́yìn tí a ti yọ àwọn òkúta wọ̀nyí tí a sì ti ha ilé náà ti a sì tún rẹ́ ẹ.
44 Tedy wnijdzie kapłan; a ujrzeli, że się rozszerzyła ona zaraza po domu, trąd jest jadowity w domu onym, nieczysty jest.
Àlùfáà yóò tún lọ yẹ̀ ẹ́ wò bí ààrùn náà bá tún gbilẹ̀ sí i nínú ilé náà: ẹ̀tẹ̀ apanirun ni èyí, ilé náà jẹ́ aláìmọ́.
45 Zatem rozwalą on dom, kamienie jego, i drzewo jego i wszystko wapno domu onego, a wyniosą precz za miasto na miejsce nieczyste.
Wíwó ni kí a wó o, gbogbo òkúta ilé náà, àwọn igi àti gbogbo ohun tí a fi rẹ́ ẹ ni kí a kó jáde nínú ìlú sí ibi tí a kà sí àìmọ́.
46 A ten kto by wszedł do domu onego, po wszystkie dni, póki był zawarty, nieczystym będzie aż do wieczora.
“Ẹni tí ó bá wọ inú ilé náà lẹ́yìn tí a ti tì í, yóò di aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
47 A kto by spał w onym domu, upierze szaty swoje; także kto by jadł w tymże domu, upierze szaty swoje.
Ẹni tí ó bá sùn nínú ilé náà tàbí tí ó bá jẹun nínú rẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀.
48 Lecz jeźliby wyszedłszy kapłan obaczył, iż się nie szerzy zaraza po domu po tynkowaniu jego, tedy osądzi kapłan, że dom on jest czysty; bo uleczona jest zaraza ona.
“Bí àlùfáà bá wá yẹ̀ ẹ́ wò tí ààrùn náà kò gbilẹ̀ mọ́ lẹ́yìn tí a ti rẹ́ ilé náà: kí àlùfáà pe ilé náà ní mímọ́, torí pé ààrùn náà ti lọ.
49 A weźmie na oczyszczenie onego domu dwu wróblów, i drzewo cedrowe, i jedwabiu, karmazynu, i hizopu;
Láti sọ ilé yìí di mímọ́. Àlùfáà yóò mú ẹyẹ méjì àti igi kedari òdòdó àti hísópù.
50 I zabije wróbla jednego nad naczyniem glinianem, nad wodą żywą;
Yóò sì pa ọ̀kan nínú àwọn ẹyẹ náà sórí omi tí ó mọ́ nínú ìkòkò amọ̀.
51 A wziąwszy drzewo cedrowe i hizop, i jedwab karmazynowy, i wróbla żywego, omoczy to wszystko we krwi wróbla zabitego i w wodzie żywej, a pokropi ten dom siedem kroć.
Kí ó ri igi kedari, hísópù, òdòdó àti ààyè ẹyẹ náà bọ inú ẹ̀jẹ̀ òkú ẹyẹ àti omi tí ó mọ́ náà kí ó fi wọ́n ilẹ̀ náà lẹ́ẹ̀méje.
52 I tak oczyści on dom krwią wróbla onego, i wodą żywą i wróblem żywym i drzewem cedrowem, i hizopem, i jedwabiem czerwonym.
Yóò fi ẹ̀jẹ̀ ẹyẹ náà, omi tí ó mọ́, ààyè ẹyẹ, igi kedari, hísópù àti òdòdó sọ ilé náà di mímọ́.
53 Potem puści wróbla żywego precz za miasto w pole; tak oczyści on dom, i czystym będzie.
Kí àlùfáà ju ààyè ẹyẹ náà sílẹ̀ lẹ́yìn ìlú. Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún ilé náà. Ilé náà yóò sì mọ́.”
54 Tać jest ustawa o każdej zarazie trądu, i plamy czarnej:
Àwọn wọ̀nyí ni ìlànà fún èyíkéyìí ààrùn àwọ̀ ara tí ó le è ràn ká, fún làpálàpá,
55 I o trądzie na szacie i na domu;
àti fún ẹ̀tẹ̀ nínú aṣọ, àti ti ilé,
56 I o sadzelu, i o świerzbie, i o białej plamie,
fún ara wíwú, fún èélá àti ibi ara tí ó ń dán yàtọ̀.
57 Żeby poznać, gdy kto jest nieczystym, i gdy kto czystym. Tać jest ustawa około trądu.
Láti mú kí a mọ̀ bóyá nǹkan mọ́ tàbí kò mọ́. Ìwọ̀nyí ni àwọn òfin fún ààrùn àwọ̀ ara tí ó ń ràn ká àti ẹ̀tẹ̀.

< Kapłańska 14 >