< Kapłańska 11 >

1 Potem mówił Pan do Mojżesza i do Aarona, i rzekł do nich: Powiedzcie synom Izraelskim, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
2 Te są zwierzęta, które jeść będziecie ze wszystkich zwierząt, które są na ziemi,
“Ẹ sọ fún àwọn ara Israẹli pé, ‘Nínú gbogbo ẹranko tí ń gbé lórí ilẹ̀, àwọn wọ̀nyí ni ẹ le jẹ.
3 Wszelkie bydlę, które ma rozdzielone stopy, i rozdwojone kopyta, a przeżuwa, to jeść będziecie.
Gbogbo ẹranko tí pátákò ẹsẹ̀ rẹ̀ bá là tí ó sì ń jẹ àpọ̀jẹ.
4 Ale z tych jeść nie będziecie, które tylko przeżuwają, i z tych, które tylko kopyta dwoją: Wielbłąd, który choć przeżuwa, ale kopyta rozdzielonego nie ma, nieczystym wam będzie.
“‘Àwọn mìíràn wà tó ń jẹ àpọ̀jẹ nìkan. Àwọn mìíràn wà tó jẹ́ pé pátákò ẹsẹ̀ wọn nìkan ni ó là, ìwọ̀nyí ni ẹ kò gbọdọ̀ jẹ fún àpẹẹrẹ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìbákasẹ ń jẹ àpọ̀jẹ kò ya pátákò ẹsẹ̀, àìmọ́ ni èyí jẹ́.
5 Także królik, który choć przeżuwa, ale kopyta rozdzielonego nie ma, nieczystym wam będzie.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gara (ẹranko tí ó dàbí ehoro tí ń gbé inú àpáta) ń jẹ àpọ̀jẹ; aláìmọ́ ni èyí jẹ́ fún yín.
6 Zając też, choć przeżuwa, ale kopyta rozdzielonego nie ma, nieczystym wam będzie.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ehoro ń jẹ àpọ̀jẹ, ṣùgbọ́n kò ya pátákò ẹsẹ̀; aláìmọ́ ni èyí jẹ́ fún yín.
7 Świnia także, choć ma rozdzielone stopy i rozdwojone kopyto, ale iż nie przeżuwa, nieczystą wam będzie.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹlẹ́dẹ̀ ya pátákò ẹsẹ̀ ṣùgbọ́n kì í jẹ àpọ̀jẹ; aláìmọ́ ni èyí jẹ́ fún yín.
8 Mięsa ich nie będziecie jeść, ani ścierwu ich dotykać się będziecie, nieczyste wam będą.
Ẹ má ṣe jẹ ẹran wọn, ẹ kò sì gbọdọ̀ fọwọ́ kan òkú wọn. Àìmọ́ ni wọ́n jẹ́ fún yín.
9 To jeść będziecie ze wszystkich rzeczy żyjących w wodach, wszystko co ma skrzele i łuskę, w wodach, w morzu, i w rzekach, to jeść będziecie.
“‘Nínú gbogbo ohun tí Ọlọ́run dá tí ń gbé inú omi Òkun, àti nínú odò: èyíkéyìí tí ó bá ní lẹbẹ àti ìpẹ́ ni ẹ lè jẹ́.
10 Wszystko zaś, co nie ma skrzeli i łuski w morzu i w rzekach, cokolwiek się rucha w wodach i każda rzecz żywiąca, która jest w wodach obrzydliwością wam będzie.
Ṣùgbọ́n nínú gbogbo ẹ̀dá tí ń gbé inú òkun àti nínú odò tí kò ní lẹbẹ àti ìpẹ́, yálà nínú gbogbo àwọn tí ń rákò tàbí láàrín gbogbo àwọn ẹ̀dá alààyè yòókù tí ń gbé inú omi àwọn ni kí ẹ kórìíra.
11 Obrzydliwością będą wam; mięsa ich jeść nie będziecie, a ścierwem ich brzydzić się będziecie.
Nígbà tí ẹ ti kórìíra wọn ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹran wọn: ẹ gbọdọ̀ kórìíra òkú wọn.
12 Owa cokolwiek nie ma skrzeli i łuski w wodach, obrzydliwością wam będzie.
Ohunkóhun tí ń gbé inú omi tí kò ní lẹbẹ àti ìpẹ́ gbọdọ̀ jásí ìríra fún yín.
13 Tem się też brzydzić będzie z ptastwa, i jeść ich nie będziecie, bo są obrzydliwością; jako orła, i gryfa, i morskiego orła,
“‘Àwọn ẹyẹ wọ̀nyí ni ẹ gbọdọ̀ kórìíra tí ẹ kò gbọdọ̀ jẹ wọ́n torí pé ohun ìríra ni wọ́n: idì, oríṣìíríṣìí igún,
14 I sępa, i kani, według rodzaju ich;
àwòdì àti onírúurú àṣá,
15 Każdego kruka według rodzaju jego;
onírúurú ẹyẹ ìwò,
16 Także strusia, i sowy i wodnej kani i jastrzębia, według rodzaju ich;
Òwìwí, onírúurú ògòǹgò, onírúurú ẹ̀lúùlú, onírúurú àwòdì,
17 I puchacza, i norka i lelka,
Òwìwí kéékèèké, onírúurú òwìwí,
18 I łabędzia, i bąka, i bociana,
Òwìwí funfun àti òwìwí ilẹ̀ pápá, àti àkàlà,
19 I czapli, i sojki, według rodzaju ich, i dudka, i nietoperza.
àkọ̀, onírúurú òòdẹ̀, atọ́ka àti àdán.
20 Wszystko, co się czołga po ziemi skrzydła mając, a na czterech nogach chodzi, obrzydliwością wam będzie.
“‘Gbogbo kòkòrò tí ń fò tí ó sì ń fi ẹsẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rìn ni wọ́n jẹ́ ìríra fún yín,
21 Wszakże jeść będziecie wszystko, co się czołga po ziemi skrzydła mające, co na czterech nogach chodzi, co ma w nogach ścięgneczka przedłuższe ku skakaniu na nich po ziemi.
irú àwọn kòkòrò oniyẹ̀ẹ́ tí wọn sì ń fi ẹsẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rìn tí ẹ le jẹ nìyí, àwọn kòkòrò tí wọ́n ní ìṣẹ́po ẹsẹ̀ láti máa fi fò lórí ilẹ̀.
22 Te z nich jeść będziecie: Szarańczą według rodzaju jej, i koniki według rodzaju ich, i skoczki według rodzaju ich, i chrząszcze według rodzaju ich.
Nínú àwọn wọ̀nyí ni ẹ lè jẹ onírúurú eṣú, onírúurú ìrẹ̀ àti onírúurú tata.
23 Wszystko zaś, co się czołga po ziemi skrzydlaste, cztery nogi mające, obrzydliwością wam będzie;
Ṣùgbọ́n gbogbo ohun ìyókù tí ń fò, tí ń rákò, tí ó ní ẹsẹ̀ mẹ́rin, òun ni kí ẹ̀yin kí ó kà sí ìríra fún yín.
24 Bo się niemi pokalacie. Kto by się dotknął zdechliny ich, nie będzie czystym aż do wieczora;
“‘Nípa àwọn wọ̀nyí ni ẹ le fi sọ ara yín di àìmọ́. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan òkú wọn yóò di aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
25 A ktobykolwiek nosił ścierw ich, upierze szaty swoje, i będzie nieczystym aż do wieczora.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbé òkú wọn gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, yóò sì jẹ́ aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
26 Wszelkie bydlę, które ma rozdzieloną stopę, a kopyta rozdwojonego nie ma, ani też przeżuwa, nieczyste wam będzie; kto by się go dotknął, nieczystym będzie.
“‘Àwọn ẹranko tí pátákò wọn kò là tan tàbí tí wọn kò jẹ àpọ̀jẹ jẹ́ àìmọ́ fún yín. Ẹni tí ó bá fọwọ́ kan òkú èyíkéyìí nínú wọn yóò jẹ́ aláìmọ́.
27 A cokolwiek chodzi na łapach swych ze wszystkich zwierząt, które chodzą na czterech nogach, nieczyste wam będzie; kto by się dotknął ścierwu ich, nieczystym będzie aż do wieczora.
Nínú gbogbo ẹranko tí ń fi ẹsẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rìn, àwọn tí ń fi èékánná wọn rìn jẹ́ aláìmọ́ fún yín, ẹni tí ó bá fọwọ́ kan òkú wọn yóò jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
28 A kto by nosił ścierw ich, upierze odzienie swe, a nieczystym będzie aż do wieczora, bo nieczyste wam są.
Ẹni tí ó bá gbé òkú wọn gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, yóò sì jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́. Wọ̀nyí jẹ́ àìmọ́ fún yín.
29 Także i te za nieczyste mieć będziecie między płazami, które się włóczą po ziemi, łasica, i mysz, i żaba według rodzajów swoich;
“‘Nínú gbogbo ẹranko tí ń rìn lórí ilẹ̀ ìwọ̀nyí ni ó jẹ́ àìmọ́ fún yín: Asé, eku àti oríṣìíríṣìí aláǹgbá,
30 I jeż, i jaszczurka, i tchórz, i ślimak, i kret.
Ọmọnílé, alágẹmọ, aláǹgbá, ìgbín àti ọ̀gà.
31 Te nieczyste wam będą między wszystkiemi płazami; kto by się dotknął zdechliny ich, nieczystym będzie aż do wieczora.
Nínú gbogbo ohun tí ń rìn lórí ilẹ̀, ìwọ̀nyí jẹ́ àìmọ́ fún yín. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan òkú wọn yóò di aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
32 A każda rzecz, na którą by co zdechłego z tych rzeczy upadło, nieczysta będzie, tak drzewiane naczynie, jako szata, tak skóra, jako wór; owa każde naczynie, w którem co sprawują, do wody włożone będzie, i nieczyste zostanie aż do wieczora, potem czyste będzie.
Bí ọ̀kan nínú wọn bá kú tí wọ́n sì bọ́ sórí nǹkan kan, bí ó ti wù kí irú ohun náà wúlò tó, yóò di aláìmọ́ yálà aṣọ ni a fi ṣe é ni tàbí igi, irun aṣọ tàbí àpò, ẹ sọ ọ́ sínú omi yóò jẹ́ aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́ lẹ́yìn náà ni yóò tó di mímọ́.
33 Wszelkie zaś naczynie gliniane, w które by co z tych rzeczy wpadło, ze wszystkiem, coby w niem było, nieczyste się stanie, a samo stłuczone będzie.
Bí èyíkéyìí nínú wọn bá bọ́ sínú ìkòkò amọ̀, gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀ ti di àìmọ́. Ẹ gbọdọ̀ fọ ìkòkò náà.
34 Każda też potrawa, którą jadają, gdyby wody nieczystej do niej wlano, nieczystą będzie; i wszelki napój, który pijają z każdego takiego naczynia, nieczystym będzie.
Bí omi inú ìkòkò náà bá dà sórí èyíkéyìí nínú oúnjẹ tí ẹ̀ ń jẹ oúnjẹ náà di aláìmọ́. Gbogbo ohun mímu tí a lè mú jáde láti inú rẹ̀ di àìmọ́.
35 Owa wszystko, na coby upadło co z onych zdechlin, nieczyste będzie; piec i ognisko rozwalone będą, bo nieczyste są, i za nieczyste wam będą.
Gbogbo ohun tí èyíkéyìí nínú òkú wọn bá já lé lórí di àìmọ́. Yálà ààrò ni tàbí ìkòkò ìdáná wọn gbọdọ̀ di fífọ́. Wọ́n jẹ́ àìmọ́. Ẹ sì gbọdọ̀ kà wọ́n sí àìmọ́.
36 Ale studnia i cysterna, i każde zgromadzenie wód czyste będą; coby się jednak dotknęło ścierwu tych rzeczy, nieczyste będzie.
Bí òkú wọn bá bọ́ sínú omi tàbí kànga tó ní omi nínú, omi náà kò di aláìmọ́ ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá yọ òkú wọn jáde tí ó fi ọwọ́ kàn án yóò di aláìmọ́.
37 A jeźliby upadło nieco z ścierwu ich na jakie nasienie, które siane bywa, czyste zostanie.
Bí òkú ẹranko wọ̀nyí bá bọ́ sórí ohun ọ̀gbìn tí ẹ fẹ́ gbìn wọ́n sì jẹ́ mímọ́.
38 Ale jeźliby na nasienie w wodzie moczone upadło co z ścierwu ich, nieczyste wam będzie.
Ṣùgbọ́n bí ẹ bá ti da omi sí ohun ọ̀gbìn náà tí òkú wọn sì bọ́ sí orí rẹ̀ àìmọ́ ni èyí fún un yín.
39 Jeźliby zdechło bydlę, które jadacie: kto by się dotknął ścierwu jego, nieczystym będzie aż do wieczora.
“‘Bí ẹran kan bá kú nínú àwọn tí ẹ lè jẹ, ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan òkú rẹ̀ yóò di aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
40 A kto by jadł ścierw jego, upierze szaty swoje, i nieczystym będzie aż do wieczora; ten, coby precz wynosił on ścierw, upierze szaty swoje, i nieczystym będzie aż do wieczora.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ èyíkéyìí nínú òkú ẹranko náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, yóò sì di aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́. Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbé òkú ẹranko yóò fọ aṣọ rẹ̀ yóò sì wà ní àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
41 Wszelki także płaz, co się czołga po ziemi, obrzydliwością jest; nie będziecie go jeść.
“‘Ìríra ni gbogbo ohun tí ń rìn káàkiri lórí ilẹ̀ jẹ́, ẹ kò gbọdọ̀ jẹ wọ́n.
42 Cokolwiek się czołga po brzuchu, i cokolwiek na czterech albo więcej nogach się włóczy między wszystkim płazem, który się czołga po ziemi, nie będziecie ich jeść, bo obrzydliwością są.
Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ń rìn ká orí ilẹ̀ yálà ó ń fàyàfà tàbí ó ń fi ẹsẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rìn, tàbí ó ń fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹsẹ̀ rìn ìríra ni èyí.
43 Nie plugawcie dusz waszych wszelkim płazem, który się czołga po ziemi, i nie mażcie się niemi, byście nie byli splugawieni przez nie;
Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ fi ohun kan tí ń rákò, sọ ara yín di ìríra, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ fi wọ́n sọ ara yín di aláìmọ́, tí ẹ̀yin yóò fi ti ipa wọn di eléèérí.
44 Albowiem Jam jest Pan Bóg wasz: przetoż poświęcajcie się, a bądźcie świętymi, bom Ja święty jest; a nie plugawcie dusz waszych żadnym płazem, który się czołga po ziemi.
Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kí ẹ sì jẹ́ mímọ́ torí pé mo jẹ́ mímọ́. Ẹ má ṣe sọ ara yín di àìmọ́ nípasẹ̀ ohunkóhun tí ń rìn káàkiri lórí ilẹ̀.
45 Bom Ja jest Pan, którym was wywiódł z ziemi Egipskiej, abym wam był za Boga; przetoż bądźcie świętymi, bom Ja święty jest.
Èmi ni Olúwa tí ó mú yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá láti jẹ́ Ọlọ́run yín torí náà, ẹ jẹ́ mímọ́ torí pé mímọ́ ni èmi.
46 Tać jest ustawa około bydła, i ptastwa, i wszelkiej duszy żywej, która się rucha w wodach, i wszelkiej duszy żywej, która się czołga po ziemi.
“‘Àwọn wọ̀nyí ni ìlànà fún ẹranko, ẹyẹ, gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń gbé inú omi àti àwọn ẹ̀dá tí ó ń rìn lórí ilẹ̀.
47 Ku rozeznaniu między nieczystem i między czystem, a między zwierzęty, które się jeść godzi, i między zwierzęty, których się jeść nie godzi.
Ẹ gbọdọ̀ mọ ìyàtọ̀ láàrín àìmọ́ àti mímọ́ láàrín ẹ̀dá alààyè, tí ẹ le jẹ àti èyí tí ẹ kò le jẹ.’”

< Kapłańska 11 >