< Lamentacje 5 >

1 Wspomnij, Panie! na to, co się nam przydało; wejrzyj a obacz pohańbienie nasze.
Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
2 Dziedzictwo nasze obrócone jest do obcych, a domy nasze do cudzoziemców.
Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
3 Sierotamiśmy a bez ojca; matki nasze są jako wdowy.
Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
4 Wody nasze za pieniądze pijemy, drwa nasze za pieniądze kupujemy.
A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
5 Na szyi swej prześladowanie cierpiemy, pracujemy, a nie dadzą nam odpocząć.
Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
6 Egipczykom podajemy rękę i Assyryjczykom, żebyśmy się nasycili chleba.
Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
7 Ojcowie nasi zgrzeszyli, niemasz ich, a my nieprawość ich ponosimy.
Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
8 Niewolnicy panują nad nami, niemasz, ktoby nas wybawił z ręki ich.
Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
9 Z odwagą duszy naszej szukamy chleba swego dla strachu miecza i na puszczy.
Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
10 Skóra nasza jako piec zczerniała od srogości głodu.
Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
11 Niewiasty w Syonie pogwałcono; i panny w miastach Judzkich.
Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
12 Książęta ręką ich powieszeni są, a osoby starszych nie mają w uczciwości.
Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
13 Młodzięców do żarn biorą, a młodzieniaszkowie po drwami padają.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
14 Starcy w bramach więcej nie siadają, a młodzieńcy przestali pieśni swoje.
Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
15 Ustało wesele serca naszego, pląsanie nasze w kwilenie się obróciło.
Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
16 Spadła korona z głowy naszej; biada nam, żeśmy zgrzeszyli!
Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
17 Dlategoż mdłe jest serce nasze, dlatego zaćmione są oczy nasze;
Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
18 Dla góry Syońskiej, że jest spustoszona, liszki chodzą po niej.
Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
19 Ty, Panie! trwasz na wieki, a stolica twoja od narodu do narodu.
Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
20 Przeczże nas na wieki zapominasz, a opuszczasz nas przez tak długi czas?
Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
21 Nawróć nas do siebie, o Panie! a nawróceni będziemy; odnów dni nasze, jako z dawna były.
Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
22 Bo izali nas cale odrzucisz, a gniewać się będziesz na nas tak bardzo?
àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.

< Lamentacje 5 >