< Księga Sędziów 4 >

1 Potem znowu synowie Izraelscy czynili złe przed oczyma Pańskiemi po śmierci Aodowej.
Lẹ́yìn ikú Ehudu, àwọn ènìyàn Israẹli sì tún ṣẹ̀, wọ́n ṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa.
2 I podał je Pan w ręce Jabina, króla Chananejskiego, który królował w Hasor, a hetman wojska jego był Sysara, a sam mieszkał w Haroset pogańskiem.
Nítorí náà Olúwa jẹ́ kí Jabini, ọba àwọn Kenaani, ẹni tí ó jẹ ọba ní Hasori, ṣẹ́gun wọn. Orúkọ olórí ogun rẹ̀ ni Sisera ẹni tí ń gbé Haroseti-Hagoyimu.
3 Tedy wołali synowie Izraelscy do Pana; albowiem miał dziewięć set wozów żelaznych, a srodze uciskał syny Izraelskie przez dwadzieścia lat.
Nítorí tí ó ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún kẹ̀kẹ́ ogun irin, ó sì ń pọ́n Israẹli lójú gidigidi fún ogún ọdún, Israẹli ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́.
4 A Debora, niewiasta prorokini, żona Lapidotowa, sądziła Izraela na on czas.
Debora, wòlíì obìnrin, aya Lapidoti ni olórí àti aṣíwájú àwọn ará Israẹli ní àsìkò náà.
5 I mieszkała pod palmą Debora między Rama i między Betel na górze Efraim, i chodzili do niej synowie Izraelscy na sąd.
Òun a máa jókòó ṣe ìdájọ́ ní abẹ́ igi ọ̀pẹ tí a sọ orúkọ rẹ̀ ní ọ̀pẹ Debora láàrín Rama àti Beteli ní ilẹ̀ òkè Efraimu, àwọn ará Israẹli a sì máa wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti yanjú èdè-àìyedè tí wọ́n bá ní sí ara wọn, tàbí láti gbọ́ ohùn Olúwa láti ẹnu rẹ̀.
6 Która posławszy przyzwała Baraka, syna Abinoemowego, z Kades Neftalim, mówiąc do niego: Izali nie rozkazał Pan, Bóg Izraelski: idź, a zbierz lud na górze Tabor, a weźmij z sobą dziesięć tysięcy mężów z synów Neftalimowych, i z synów Zabulonowych?
Ní ọjọ́ kan, ó ránṣẹ́ pe Baraki ọmọ Abinoamu, ẹni tí ń gbé ní Kedeṣi ní ilẹ̀ Naftali, ó sì wí fún un pé, “Olúwa, Ọlọ́run Israẹli pa á ní àṣẹ fún un pé, ‘Kí ó kó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn akọni ọkùnrin jọ láti ẹ̀yà Naftali àti ẹ̀yà Sebuluni bí ẹgbẹ́ ogun, kí o sì síwájú wọn lọ sí òkè Tabori.
7 I przywiodę do ciebie ku rzece Cyson Sysarę, hetmana wojska Jabinowego, i wozy jego, i mnóstwo jego, a podam go w ręce twoje.
Èmi yóò sì fa Sisera olórí ogun Jabini, pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun rẹ àti àwọn ogun rẹ, sí odò Kiṣoni èmi yóò sì fi lé ọ lọ́wọ́ ìwọ yóò sì ṣẹ́gun wọn níbẹ̀.’”
8 I rzekł do niej Barak: Jeźli pójdziesz ze mną, pójdę, a jeźli nie pójdziesz ze mną, nie pójdę.
Baraki sì dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ tí ìwọ ó bá bá mi lọ, ṣùgbọ́n tí ìwọ kì yóò bá bá mi lọ, èmi kì yóò lọ.”
9 Która odpowiedziała: Jać w prawdzie pójdę z tobą, ale nie będzie z sławą twoją ta droga, którą ty pójdziesz; albowiem w rękę niewieścią poda Pan Sysarę. A tak wstawszy Debora, szła z Barakiem do Kades.
Debora dá a lóhùn pé, “ó dára, èmi yóò bá ọ lọ. Ṣùgbọ́n ọlá ìṣẹ́gun tí o ń lọ yìí kò ní jẹ́ tìrẹ, nítorí Olúwa yóò fi Sisera lé obìnrin lọ́wọ́,” báyìí Debora bá Baraki lọ sí Kedeṣi.
10 Zebrał tedy Barak Zabulona i Neftalima do Kades, a wywiódł z sobą dziesięć tysięcy mężów, z którym też szła i Debora.
Nígbà tí Baraki pe ẹ̀yà Sebuluni àti ẹ̀yà Naftali sí Kedeṣi ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá akíkanjú ọkùnrin ogun tẹ̀lé e, Debora pẹ̀lú bá wọn lọ.
11 Ale Heber Cynejczyk odłączył się od Cynejczyków, od synów Hobaby, świekra Mojżeszowego, i rozbił namiot swój aż do Elon w Sananim, które jest w Kades.
Ǹjẹ́ Heberi ọmọ Keni, ti ya ara rẹ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Keni, àní àwọn ọmọ Hobabu, àna Mose, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ títí dé ibi igi óákù Saananimu, tí ó wà ni agbègbè Kedeṣi.
12 I powiedziano Sysarze, iż wyszedł Barak, syn Abinoemów na górę Tabor.
Nígbà tí a sọ fún Sisera pé Baraki ọmọ Abinoamu ti kó ogun jọ sí òkè Tabori,
13 Przetoż zebrał Sysara wszystkie wozy swoje, dziewięć set wozów żelaznych, i wszystek lud, który miał ze sobą od Haroset pogańskiego aż do rzeki Cyson.
Sisera kó gbogbo kẹ̀kẹ́ ogun irin rẹ̀ tí ṣe ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, láti Haroseti tí àwọn orílẹ̀-èdè wá sí odò Kiṣoni.
14 Tedy rzekła Debora do Baraka: Wstań; albowiem tenci jest dzień, w który podał Pan Sysarę w ręce twoje; izali Pan nie idzie przed tobą? A tak zszedł Barak z góry Tabor, a dziesięć tysięcy mężów za nim.
Debora sì wí fún Baraki pé, “Lọ! Lónìí ni Olúwa fi Sisera lé ọ lọ́wọ́, Olúwa ti lọ síwájú rẹ.” Baraki sì síwájú, àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì tẹ̀lé e lẹ́yìn, wọ́n sì kọjá sí òkè Tabori.
15 I poraził Pan Sysarę, i wszystkie wozy, i wszystko wojsko jego ostrzem miecza przed Barakiem, a skoczywszy Sysara z wozu, uciekał pieszo.
Olúwa sì mú ìdàrúdàpọ̀ wá sí àárín ogun Sisera, Olúwa sì fi ojú idà ṣẹ́gun Sisera àti àwọn oníkẹ̀kẹ́ ogun àti ọmọ-ogun orí ilẹ̀ ní iwájú Baraki. Sisera sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì fi ẹsẹ̀ sálọ.
16 Ale Barak gonił wozy i wojsko aż do Haroset pogańskiego; i poległo wszystko wojsko Sysarowe od ostrza miecza, tak iż z nich i jeden nie został.
Baraki àti àwọn ogun rẹ̀ sì lé àwọn ọ̀tá náà, àwọn ọmọ-ogun orílẹ̀ àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun wọn títí dé Haroseti ti àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo ogun Sisera sì ti ojú idà ṣubú, kò sí ọ̀kan tí ó lè sálà tàbí tí ó wà láààyè.
17 A Sysara uciekł pieszo do namiotu Jaeli, żony Hebera Cynejczyka; albowiem był pokój między Jabinem, królem Hasor, i między domem Hebera Cynejczyka.
Ṣùgbọ́n Sisera ti fi ẹsẹ̀ sálọ sí àgọ́ Jaeli aya Heberi ẹ̀yà Keni: nítorí ìbá dá ọ̀rẹ́ àlàáfíà wà láàrín Jabini ọba Hasori àti ìdílé Heberi ti ẹ̀yà Keni.
18 A wyszedłszy Jael przeciwko Sysarze, rzekła do niego: Skłoń się panie mój, skłoń się do mnie, nie bój się; i skłonił się do niej do namiotu, i przykryła go kocem.
Jaeli sì jáde síta láti pàdé Sisera, ó sì wí fún un pé, “Wọlé sínú àgọ́ mi, Olúwa mi, wọlé wá má ṣe bẹ̀rù nítorí pé ààbò ń bẹ fún ọ.” Ó sì yà sínú àgọ́ rẹ̀, ó sì fi aṣọ bò ó.
19 Tedy rzekł do niej: Daj mi proszę, napić się trochę wody, bom upragnął; a ona otworzywszy łagiew mleka, dała mu się napić, i przykryła go.
Sisera wí pé, “Òrùngbẹ ń gbẹ́ mí, jọ̀wọ́ fún mi ní omi mu.” Ó sì ṣí awọ wàrà kan, ó sì fún un mu ó sì tún daṣọ bò ó padà.
20 I rzekł do niej: Stój we drzwiach u namiotu; a jeźliby kto przyszedł, i pytał cię, mówiąc: Jestże tu kto? tedy rzeczesz: Nie masz.
Sisera sọ fún Jaeli pé, “Kí ó dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, àti pé bí ẹnikẹ́ni bá béèrè bóyá òun wà níbẹ̀ kí ó sọ pé, ‘Kò sí ẹnìkankan ní ibẹ̀.’”
21 Potem wzięła Jael, żona Heberowa, gwóźdź od namiotu, wzięła też i młot w rękę swą, a wszedłszy do niego po cichu, przebiła gwoździem skroń jego aż utknął w ziemi, (bo był twardo usnął, będąc spracowanym, ) i umarł.
Ṣùgbọ́n Jaeli ìyàwó Heberi mú ìṣó àgọ́ tí ó mú àti òòlù ní ọwọ́ rẹ̀, ó sì yọ́ wọ inú ibi tí ó sùn, nígbà tí ó ti sùn fọnfọn, nígbà náà ni ó kan ìṣó náà mọ́ òkè ìpéǹpéjú rẹ̀, ó sì wọlé ṣinṣin, ó sì kú.
22 A oto, Barak gonił Sysarę, i wyszła Jael przeciwko niemu, i rzekła mu: Pójdź, a ukażęć męża, którego szukasz. I wyszedł do niej, a oto Sysara leżał umarły, a gwóźdź w skroni jego.
Nígbà tí Baraki dé bí ó ti ń lépa Sisera, Jaeli láti pàdé rẹ̀, wá, èmi yóò fi ẹni tí ìwọ ń wá hàn ọ́, báyìí ni ó tẹ̀lé e wọ inú àgọ́ lọ, kíyèsi Sisera dùbúlẹ̀ síbẹ̀ pẹ̀lú ìṣó àgọ́ ní agbárí rẹ̀ tí a ti kàn mọ́lẹ̀ ṣinṣin tí ó sì ti kú.
23 A tak poniżył Bóg dnia onego Jabina, króla Chananejskiego, przed syny Izraelskimi.
Ní ọjọ́ náà ni Ọlọ́run ṣẹ́gun Jabini ọba àwọn ará Kenaani ní iwájú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
24 I nacierała ręka synów Izraelskich tem bardziej, a ciężka była Jabinowi, królowi Chananejskiemu, aż zgładzili tegoż Jabina, króla Chananejskiego.
Ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli sì le, ó sì ń lágbára síwájú àti síwájú sí i lára Jabini ọba Kenaani, títí wọ́n fi run òun àti àwọn ènìyàn rẹ̀.

< Księga Sędziów 4 >