< Księga Sędziów 13 >

1 Potem znowu synowie Izraelscy czynili złe przed oczyma Pańskiemi, i podał je Pan w ręce Filistynów przez czterdzieści lat.
Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Olúwa sì fi wọ́n lé àwọn ará Filistini lọ́wọ́ fún ogójì ọdún.
2 Tedy był mąż niektóry z Saraa, z pokolenia Dan, imieniem Manue, a żona jego była niepłodną, i nie rodziła.
Ọkùnrin ará Sora kan wà, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Manoa láti ẹ̀yà Dani. Aya rẹ̀ yàgàn kò sì bímọ.
3 I ukazał się Anioł Pański onej niewieście, a rzekł do niej: Otoś teraz niepłodną, aniś rodziła; ale poczniesz i porodzisz syna.
Angẹli Olúwa fi ara han obìnrin náà, ó sì wí fún un pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yàgàn, ìwọ kò sì tí ì bímọ, ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.
4 Przetoż się teraz strzeż, abyś nie piła wina, i napoju mocnego, i abyś nie jadła nic nieczystego;
Báyìí rí i dájúdájú pé ìwọ kò mu wáìnì tàbí ọtí líle kankan àti pé ìwọ kò jẹ ohun aláìmọ́ kankan,
5 Bo oto poczniesz i porodzisz syna, a brzytwa nie postoi na głowie jego, bo Nazarejczykiem Bożym będzie to dziecię zaraz z żywota; a on pocznie wybawiać Izraela z ręki Filistynów.
nítorí ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan. Má ṣe fi abẹ kan orí rẹ̀, nítorí pé Nasiri, ẹni ìyàsọ́tọ̀ fún Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀. Òun ni yóò bẹ̀rẹ̀ ìdáǹdè àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ọwọ́ àwọn ará Filistini.”
6 Tedy przyszła niewiasta, i powiedziała to mężowi swemu, mówiąc: Mąż Boży przyszedł do mnie, którego oblicze było jako oblicze Anioła Bożego, bardzo straszne, i nie pytałam go, skąd był, ani mi imienia swego oznajmił.
Nígbà náà ni obìnrin náà tọ ọkọ rẹ̀ lọ, o sì sọ fún un wí pé, “Ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ mí wá. Ó jọ angẹli Ọlọ́run, ó ba ènìyàn lẹ́rù gidigidi. Èmi kò béèrè ibi tí ó ti wá, òun náà kò sì sọ orúkọ rẹ̀ fún mi.
7 Tylko mi rzekł: Oto, poczniesz i porodzisz syna; przetoż teraz nie pij wina, ani napoju mocnego, ani jedz co nieczystego; bo Nazarejczykiem Bożym będzie to dziecię zaraz z żywota aż do dnia śmierci swojej.
Ṣùgbọ́n ó sọ fún mi wí pé, ‘Ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan, fún ìdí èyí, má ṣe mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ má ṣe jẹ ohunkóhun tí í ṣe aláìmọ́, nítorí pé Nasiri Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀ títí di ọjọ́ ikú rẹ̀.’”
8 Tedy się modlił Manue Panu, mówiąc: Proszę Panie mój, mąż Boży, któregoś posłał, niech przyjdzie proszę znowu do nas, a nauczy nas, co czynić mamy z dziecięciem, które się narodzi?
Nígbà náà ni Manoa gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Háà Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ènìyàn Ọlọ́run tí ìwọ rán sí wa padà tọ̀ wá wá láti kọ́ wa bí àwa yóò ti ṣe tọ́ ọmọ tí àwa yóò bí náà.”
9 I wysłuchał Bóg głos Manuego; bo przyszedł Anioł Boży znowu do niewiasty onej, gdy siedziała na polu; ale Manue, mąż jej, nie był z nią.
Ọlọ́run fetí sí ohùn Manoa, angẹli Ọlọ́run náà tún padà tọ obìnrin náà wá nígbà tí ó wà ní oko ṣùgbọ́n ọkọ rẹ̀ Manoa kò sí ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
10 Tedy kwapiąc się ona niewiasta, bieżała, i opowiedziała mężowi swemu, i rzekła mu: Oto mi się ukazał mąż on, który był przyszedł przedtem do mnie.
Nítorí náà ni obìnrin náà ṣe yára lọ sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó fi ara hàn mí ní ọjọ́sí ti tún padà wá.”
11 A wstawszy Manue szedł za żoną swoją; a przyszedłszy do onego męża, rzekł mu: Tyżeś jest ten mąż, któryś mówił z żoną moją? A on rzekł: Jam jest.
Manoa yára dìde, ó sì tẹ̀lé aya rẹ̀, nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ ọkùnrin náà ó ní, “Ǹjẹ́ ìwọ ni o bá obìnrin yìí sọ̀rọ̀?” Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Èmi ni.”
12 I rzekł Manue: Niech się teraz spełni słowo twoje; ale cóż będzie za obyczaj dziecięcia, i co za sprawa jego?
Manoa bi ọkùnrin náà pé, “Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ kí ni yóò jẹ́ ìlànà fún ìgbé ayé àti iṣẹ́ ọmọ náà?”
13 I odpowiedział Anioł Pański Manuemu: Wszystkiego, com powiedział żonie twojej, niech się strzeże.
Angẹli Olúwa náà dáhùn wí pé, “Aya rẹ gbọdọ̀ ṣe gbogbo ohun tí mo ti sọ fún un
14 Żadnej rzeczy, która pochodzi z winnej macicy, niechaj nie je; także wina ani napoju mocnego, niech nie pije, ani żadnej rzeczy nieczystej niech nie je, a com jej kolwiek przykazał, tego niech przestrzega.
kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ó bá ti inú èso àjàrà jáde wá, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn tàbí jẹ ohunkóhun tí ó bá jẹ́ aláìmọ́. Ó ní láti ṣe ohun gbogbo tí mo ti pàṣẹ fún un.”
15 Tedy rzekł Manue do Anioła Pańskiego: Daj się proszę zatrzymać, a nagotujemy przed cię koźlątko z stada.
Manoa sọ fún angẹli Olúwa náà pé, “Jọ̀wọ́ dára dúró títí àwa yóò fi pèsè ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan fún ọ.”
16 Ale Anioł Pański odpowiedział Manuemu: Choćbyś mię zatrzymał, nie będę jadł chleba twego; ale jeźli będziesz chciał sprawić całopalenie, ofiarujże je Panu; bo nie wiedział Manue, żeby on był Anioł Pański.
Angẹli Olúwa náà dá Manoa lóhùn pé, “Bí ẹ̀yin tilẹ̀ dá mi dúró, èmi kì yóò jẹ ọ̀kankan nínú oúnjẹ tí ẹ̀yin yóò pèsè. Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá fẹ́ ẹ pèsè ọrẹ ẹbọ sísun, kí ẹ sì fi rú ẹbọ sí Olúwa.” (Manoa kò mọ̀ pé angẹli Olúwa ní i ṣe.)
17 Tedy rzekł Manue do Anioła Pańskiego: Cóż za imię twoje? abyśmy, gdy się spełni słowo twoje, uczcili cię.
Manoa sì béèrè lọ́wọ́ angẹli Olúwa náà pé, “Kí ni orúkọ rẹ, kí àwa bá à lè fi ọlá fún ọ nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ?”
18 Któremu odpowiedział Anioł Pański: Przeczże pytasz o imię moje, które jest dziwne?
Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa náà dáhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ ń béèrè orúkọ mi? Ìyanu ni, ó kọjá ìmọ̀.”
19 Wziął tedy Manue koźlę z stada, i ofiarę śniedną, i ofiarował to na opoce Panu, i uczynił cud, a Manue i żona jego patrzyli na to.
Lẹ́yìn náà ni Manoa mú ọ̀dọ́ ewúrẹ́, pẹ̀lú ẹbọ ọkà, ó sì fi rú ẹbọ lórí àpáta kan sí Olúwa. Nígbà tí Manoa àti ìyàwó dúró tí wọn ń wò Olúwa ṣe ohun ìyanu kan.
20 A gdy wstępował płomień z ołtarza ku niebu, tedy wstąpił Anioł Pański w płomieniu ołtarzowym, a Manue, i żona jego widząc to, upadli na twarze swe na ziemię.
Bí ẹ̀là ahọ́n iná ti là jáde láti ibi pẹpẹ ìrúbọ náà sí ọ̀run, angẹli Olúwa gòkè re ọ̀run láàrín ahọ́n iná náà. Nígbà tí wọ́n rí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí, Manoa àti aya rẹ̀ wólẹ̀ wọ́n sì dojúbolẹ̀.
21 A potem nie ukazał się więcej Anioł Pański Manuemu, ani żonie jego; i poznał Manue, że to był Anioł Pański.
Nígbà tí angẹli Olúwa náà kò tún fi ara rẹ̀ han Manoa àti aya rẹ̀ mọ́, Manoa wá mọ̀ pé angẹli Olúwa ni.
22 I rzekł Manue do żony swojej: Koniecznie pomrzemy, bośmy Boga widzieli.
Manoa sọ fún aya rẹ̀ pé, “Dájúdájú àwa yóò kú nítorí àwa ti fi ojú rí Ọlọ́run.”
23 Któremu odpowiedziała żona jego: Gdyby nas chciał Pan zabić, nie przyjąłby z rąk naszych całopalenia, i ofiary śniednej, aniby nam był okazał tego wszystkiego, aniby nam na ten czas był objawił takowych rzeczy.
Ṣùgbọ́n ìyàwó rẹ̀ dáhùn pé, “Bí Olúwa bá ní èrò àti pa wá kò bá tí gba ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà wa, tàbí fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn wá tó sọ nǹkan ìyanu yìí fún wa.”
24 Porodziła tedy ona niewiasta syna, i nazwała imię jego Samson; i rosło dziecię, a błogosławił mu Pan.
Obìnrin náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Samsoni. Ọmọ náà dàgbà Olúwa sì bùkún un.
25 I począł go Duch Pański umacniać w obozie Dan między Saraa i między Estaol.
Ẹ̀mí Olúwa sì bẹ̀rẹ̀ sí ru sókè nígbà tí ó wà ní Mahane-Dani ní agbede-méjì Sora àti Eṣtaoli.

< Księga Sędziów 13 >