< Księga Sędziów 10 >

1 I powstał po Abimelechu na obronę Izraela Tola, syn Fui, syna Dodowego, mąż z pokolenia Isascharowego, a ten mieszkał w Samir na górze Efraim.
Lẹ́yìn ikú Abimeleki, ọkùnrin kan láti ẹ̀yà Isakari tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tola ọmọ Pua, ọmọ Dodo, dìde láti gba Israẹli sílẹ̀. Ní Ṣamiri tí ó wà ní òkè Efraimu ni ó gbé.
2 I sądził Izraela przez dwadzieścia i trzy lata, potem umarł, i pogrzbion jest w Samir.
Ó ṣe àkóso Israẹli ní ọdún mẹ́tàlélógún. Nígbà tí ó kú wọ́n sìn ín sí Ṣamiri.
3 A po nim powstał Jair Galaadczyk, który sądził Izraela przez dwadzieścia i dwa lata.
Jairi ti ẹ̀yà Gileadi ni ó dìde lẹ́yìn rẹ̀, ó ṣàkóso Israẹli ní ọdún méjìlélógún.
4 A ten miał trzydzieści synów, którzy jeździli na trzydziestu ośląt, a mieli trzydzieści miast, które zwano Awot Jair aż po dzisiejszy dzień w ziemi Galaadskiej.
Àwọn ọgbọ̀n ọmọ tí ó n gun ọgbọ̀n kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n ṣe àkóso ọgbọ̀n ìlú ní Gileadi, tí a pe orúkọ wọn ní Hafoti-Jairi títí di òní.
5 I umarł Jair, a pogrzebion jest w Kamon.
Nígbà tí Jairi kú wọ́n sin ín sí Kamoni.
6 Lecz znowu synowie Izraelscy czynili złe przed oczyma Pańskiemi, a służąc Baalowi, i Astaratowi, i bogom Syryjskim, i bogom Sydońskim, i bogom Moabskim, i bogom synów Ammon, i nawet bogom Filistyńskim, a opuściwszy Pana, nie służyli mu.
Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú lójú Olúwa. Wọ́n sin Baali àti Aṣtoreti àti àwọn òrìṣà Aramu, òrìṣà Sidoni, òrìṣà Moabu, òrìṣà àwọn ará Ammoni àti òrìṣà àwọn ará Filistini. Nítorí àwọn ará Israẹli kọ Olúwa sílẹ̀ tí wọn kò sì sìn ín mọ́,
7 Przetoż się wzruszył gniewem Pan przeciw Izraelowi, i podał je w ręce Filistynów, i w ręce synów Ammonowych.
ó bínú sí wọn, ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ará Filistini àti Ammoni láti jẹ ẹ́ ní ìyà.
8 Którzy trapili i uciskali syny Izraelskie od onego roku przez osiemnaście lat, wszystkie syny Izraelskie, którzy byli przed Jordanem w ziemi Amorejczyka, która jest w Galaad.
Ní ọdún náà, wọ́n tú wọn ká wọ́n sì pọ́n wọn lójú. Fún ọdún méjìdínlógún ni wọ́n fi ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní ìlà-oòrùn odò Jordani ní ilẹ̀ àwọn ará Amori lára (èyí nì ní Gileadi).
9 Przeprawili się też synowie Ammonowi za Jordan, aby walczyli z Judą, i z Benjaminem, także i z domem Efraimowym, i ścisnęli Izraelczyki bardzo.
Àwọn ará Ammoni sì la odò Jordani kọjá láti bá Juda, Benjamini àti àwọn ará ilé Efraimu jagun: Israẹli sì dojúkọ ìpọ́njú tó lágbára.
10 Tedy wołali synowie Izraelscy do Pana, mówiąc: Zgrzeszyliśmy tobie, żeśmy opuścili ciebie, Boga naszego, i służyliśmy Baalom.
Nígbà tí èyí ti ṣẹlẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí ọ, nítorí pé àwa ti kọ Ọlọ́run wa sílẹ̀, àwa sì ń sin Baali.”
11 Ale Pan rzekł do synów Izraelskich: Izalim was od Egipczyków, i od Amorejczyków, od synów Ammonowych, i od Filistynów,
Olúwa sì dáhùn pé, “Ǹjẹ́ nígbà tí àwọn ará Ejibiti, Amori, Ammoni, Filistini,
12 I od Sydończyków, i Amalekitów, i Mahanitów, którzy was trapili, gdyście wołali do mnie, nie wybawił z ręki ich?
àwọn ará Sidoni, Amaleki pẹ̀lú Maoni ni yín lára, tí ẹ sì ké pè mí fún ìrànlọ́wọ́, ǹjẹ́ èmi kò gbà yín sílẹ̀ kúrò ní ọwọ́ wọn?
13 Aleście wy mię opuścili, a służyliście bogom cudzym; przetoż was więcej nie wybawię.
Síbẹ̀síbẹ̀ ẹ̀yin kọ̀ mí sílẹ̀ láti sin àwọn ọlọ́run mìíràn, torí ìdí èyí, èmi kì yóò sì tún gbà yín mọ́.
14 Idźcież, a wołajcie do bogów, któreście sobie obrali; oni niechaj was wybawią czasu ucisku waszego.
Ẹ lọ kí ẹ sì ké pe àwọn òrìṣà tí ẹ̀yin ti yàn fún ara yín. Jẹ́ kí wọn gbà yín sílẹ̀ ní àsìkò ìpọ́njú yín!”
15 I odpowiedzieli synowie Izraelscy Panu: Zgrzeszyliśmy; uczyńże ty z nami, co się zda dobrego w oczach twoich, tylko wybaw nas prosimy dnia tego.
Àwọn ọmọ Israẹli sì dá Olúwa lóhùn pé, “Àwa ti ṣẹ̀, ṣe ohun tí ó bá fẹ́ pẹ̀lú wa, ṣùgbọ́n, jọ̀wọ́ gbà wá sílẹ̀ náání àsìkò yìí.”
16 I wyrzucili bogi cudze z pośrodku siebie, a służyli Panu, i użalił się Pan utrapienia Izraelskiego.
Nígbà náà ni wọ́n kó gbogbo ọlọ́run àjèjì tí ó wà láàrín wọn kúrò wọ́n sì sin Olúwa nìkan, ọkàn rẹ̀ kò sì le gbàgbé ìrora Israẹli mọ́.
17 Zebrali się tedy synowie Ammonowi, a położyli się obozem w Galaad; zebrali się też i synowie Izraelscy, a położyli się obozem w Masfa.
Nígbà tí àwọn ará Ammoni kógun jọ ní Gileadi láti bá Israẹli jà, àwọn ọmọ Israẹli gbárajọpọ̀, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Mispa.
18 Tedy rzekł lud i przełożeni w Galaad między sobą: Kto się naprzód pocznie potykać z syny Ammonowymi, ten będzie hetmanem nad wszystkimi mieszkającymi w Galaad.
Àwọn ìjòyè: aṣíwájú àwọn ará Gileadi wí fún ará wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọ́ ṣígun si àwọn ará Ammoni ni yóò jẹ́ orí fún gbogbo àwọn tí ń gbé ní Gileadi.”

< Księga Sędziów 10 >