< Jozuego 23 >

1 I stało się po niemałym czasie, gdy odpoczynek dał Pan Izraelowi od wszystkich nieprzyjaciół ich okolicznie, a Jozue się zstarzał, i był zeszłym w leciech,
Lẹ́yìn ọjọ́ pípẹ́, nígbà tí Olúwa sì ti fún Israẹli ní ìsinmi kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn tí ó yí wọn ká, nígbà náà Joṣua sì ti di arúgbó.
2 Że przyzwał Jozue wszystkiego Izraela, starszych jego, i przedniejszych jego, i sędziów jego, i przełożonych jego, i rzekł do nich. Jam się zstarzał a zszedłem w leciech.
Ó sì pe gbogbo Israẹli jọ: àgbàgbà wọn, olórí wọn, adájọ́ àti àwọn ìjòyè, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti pọ̀ ní ọdún èmi ti di arúgbó.
3 A wyście widzieli wszystko, co uczynił Pan, Bóg wasz, wszystkim tym narodom przed obliczem waszem: bo Pan, Bóg wasz sam walczył za was.
Ẹ̀yin tìkára yín sì ti rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀nyí nítorí yín, Olúwa Ọlọ́run yín ni ó jà fún yín.
4 Obaczcież, rozdzieliłem wam losem te narody pozostałe w dziedzictwo między pokolenia wasze od Jordanu, i wszystkie narody, którem wytracił, aż do morza wielkiego na zachód słońca.
Ẹ rántí bí mo ṣe pín ogún ìní fún àwọn ẹ̀yà yín ní ilẹ̀ orílẹ̀-èdè gbogbo tí ó kù; àwọn orílẹ̀-èdè tí mo ti ṣẹ́gun ní àárín Jordani àti Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
5 A Pan, Bóg wasz, sam je wypędzi od twarzy waszej, i wyżenie je od obliczności waszej, i posiędziecie dziedzicznie ziemię ich, jako wam to powiedział Pan, Bóg wasz.
Olúwa Ọlọ́run yín fúnra rẹ̀ yóò lé wọn jáde kúrò ní ọ̀nà yín, yóò sì tì wọ́n jáde ní iwájú yín, ẹ̀yin yóò sì gba ilẹ̀ ìní wọn, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún yín.
6 Zmacniajcież się bardzo, abyście strzegli a czynili wszystko, co napisano w księgach Zakonu Mojżeszowego, nie odstępując od niego na prawo ani na lewo.
“Ẹ jẹ́ alágbára gidigidi, kí ẹ sì ṣọ́ra láti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun tí a kọ sí inú ìwé òfin Mose, láìyí padà sí ọ̀tún tàbí sí òsì.
7 Ani się też mieszajcie z temi narodami, które zostały z wami; ani imienia bogów ich nie wspominajcie, ani przysięgajcie przez nie, ani im służcie, ani się im kłaniajcie;
Ẹ má ṣe ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ṣẹ́kù láàrín yín; ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà wọn tàbí kí ẹ fi wọ́n búra. Ẹ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n tàbí ki ẹ tẹríba fún wọn.
8 Ale się Pana, Boga waszego, trzymajcie, jakoście czynili aż do dnia tego.
Ṣùgbọ́n ẹ di Olúwa Ọlọ́run yín mú ṣinṣin gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ń ṣe tẹ́lẹ̀ títí di àkókò yìí.
9 Bo jako wypędził Pan od oblicza waszego narody wielkie i możne, i nie oparł się wam nikt aż do dnia tego:
“Olúwa ti lé àwọn orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára kúrò níwájú yín; títí di òní yìí kò sí ẹnìkan tí ó le dojúkọ yín.
10 Tak mąż jeden z was będzie uganiał tysiąc; albowiem Pan, Bóg wasz, on walczy za wami, jako wam obiecał.
Ọ̀kan nínú yín lé ẹgbẹ̀rún ọ̀tá, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín jà fún yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí.
11 Przetoż przestrzegajcie z pilnością, abyście miłowali Pana, Boga waszego.
Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ ṣọ́ra gidigidi láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín.
12 Bo jeźli się cale odwrócicie, a przystaniecie do tych pozostałych narodów, do tych, które zostawają między wami, i spowinowacicie się z nimi, a będziecie się mieszać z nimi, one też z wami:
“Ṣùgbọ́n bí ẹ bá yí padà, tí ẹ sì gba ìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú àwọn tó ṣẹ́kù lára àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù láàrín yín, tí ẹ sì ń fọmọ fún ara yín ní ìyàwó, tí ẹ sì bá wọn ní àjọṣepọ̀.
13 Wiedźcież wiedząc, żeć nie będzie więcej Pan, Bóg wasz, wyganiał tych narodów od twarzy waszej; ale będą wam sidłem, i zawadą, i biczem na boki wasze, i cierniem na oczy wasze, póki nie wyginiecie z tej przewybornej ziemi, którą wam dał Pan, Bóg wasz.
Nígbà náà ni ẹ ó mọ̀ dájú pé Olúwa Ọlọ́run yín kì yóò lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde mọ́ kúrò níwájú yín. Dípò èyí, wọn yóò jẹ́ ìkẹ́kùn àti tàkúté fún un yín, pàṣán ní ẹ̀yin yín àti ẹ̀gún ní ojú yín, títí ẹ ó fi ṣègbé kúrò ní ilẹ̀ dáradára yí, èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fi fún yín.
14 A oto, ja idę dziś w drogę wszystkiej ziemi; poznajcież tedy ze wszystkiego serca waszego, i ze wszystkiej duszy waszej, żeć nie chybiło żadne słowo ze wszystkich słów najlepszych, które mówił Pan, Bóg wasz o was; wszystkie się nad wami wypełniły, a nie chybiło z nich żadne słowo.
“Nísinsin yìí èmi ti fẹ́ máa lọ sí ibi tí àwọn àgbà ń rè. Ẹ mọ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti àyà yín pé, kò sí ohun kan tí ó kùnà nínú àwọn ìlérí rere gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín. Gbogbo ìlérí tó ti ṣe kò sí ọ̀kan tí ó kùnà.
15 Przetoż jako się wypełniło nad wami każde słowo dobre, które mówił Pan, Bóg wasz, do was, tak przywiedzie Pan na was każde słowo złe, aż was wytraci z ziemi tej przewybornej, którą wam dał Pan, Bóg wasz.
Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí ìlérí dáradára gbogbo ti Olúwa Ọlọ́run yín ti wá sí ìmúṣẹ, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò mú ibi gbogbo tí ó ti kìlọ̀ wá sí orí yín, títí yóò fi pa yín run kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.
16 Jeźli przestąpicie przymierze Pana, Boga waszego, który wam rozkazał, a szedłszy służyć będziecie bogom obcym, i kłaniać się im będziecie, tedy się rozpali popędliwość Pańska przeciwko wam, i zginiecie prędko z tej przewybornej ziemi, którą wam dał.
Bí ẹ bá sẹ̀ sí májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín, èyí tí ó pàṣẹ fún un yín, tí ẹ bá sì lọ tí ẹ sì sin àwọn òrìṣà tí ẹ sì tẹ orí ba fún wọn, ìbínú gbígbóná Olúwa yóò wá sórí i yín, ẹ̀yin yóò sì ṣègbé kíákíá kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.”

< Jozuego 23 >