< Jozuego 20 >

1 POtem rzekł Pan do Jozuego, mówiąc:
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Joṣua pé,
2 Powiedz synom Izraelskim, i rzecz: Oddzielcie sobie miasta ucieczki, o którychem mówił do was przez Mojżesza;
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn yan àwọn ìlú ààbò, gẹ́gẹ́ bí mo ti pàṣẹ fún ọ láti ẹnu Mose,
3 Aby tam uciekł mężobójca, coby zabił człowieka nie chcąc, z niewiadomości; i będą wam dla ucieczki przed tym, któryby się krwi chciał mścić.
kí ẹni tí ó bá ṣèèṣì pa ènìyàn tàbí tí ó bá pa ènìyàn láìmọ̀-ọ́n-mọ̀ lè sálọ sí ibẹ̀, fún ààbò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó pa.
4 I uciecze do jednego z miast, a stanie u wrót bramy miejskiej, i opowie starszym miasta onego sprawę swoję; i przyjmą go do miasta między się, i dadzą mu miejsce, a będzie mieszkał z nimi.
Nígbà tí ó bá sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú wọ̀nyí, yóò sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àtiwọ ibodè ìlú, kí ó sì ṣe àlàyé ara rẹ̀ ní iwájú àwọn àgbàgbà ìlú náà. Nígbà náà ni wọn yóò gbà á sí ìlú wọn, wọn yóò sì fun ní ibùgbé láàrín wọn.
5 A gdy go będzie gonił ten, któryby się chciał mścić krwi, tedy nie wydadzą mężobójcy w ręce jego; albowiem nie chcąc zabił bliźniego swego, a nie mając żadnej waśni, z nim przedtem.
Bí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ bá ń lépa rẹ̀, wọn kò gbọdọ̀ fi àwọn ọ̀daràn náà lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí ó pa aládùúgbò rẹ̀ láìmọ̀, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí.
6 I będzie mieszkał w onem mieście, a stanie przed zebraniem na sąd, i aż do śmierci kapłana wielkiego, który będzie za onych dni; tedy się wróci mężobójca, i przyjdzie do miasta swego i do domu swego, do miasta, z którego uciekł.
Òun ó sì máa gbé inú ìlú náà, títí yóò fi jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn àti títí ikú olórí àlùfáà tí ó ń ṣiṣẹ́ ìsìn nígbà náà. Nígbà náà ó lè padà sí ilé rẹ̀ ní ìlú tí ó ti sá wá.”
7 I oddzieli Kades w Galilei na górze Neftali, a Sychem na górze Efraim, i miasto Arba, które jest Hebron, na górze Juda.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yan Kedeṣi ní Galili ní ìlú òkè Naftali, Ṣekemu ní ìlú òkè Efraimu, àti Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) ní ìlú òkè Juda.
8 Z drugiej zasię strony Jordanu, gdzie leży Jerycho od wschodu słońca, oddzieli Bosor na puszczy, w równinie z pokolenia Rubenowego, i Ramot w Galaad z pokolenia Gad, przytem Golan w Basen z pokolenia Manasesowego.
Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani ti Jeriko, wọ́n ya Beseri ní aginjù ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ẹ̀yà Reubeni, Ramoti ní Gileadi ní ẹ̀yà Gadi, àti Golani ní Baṣani ní ẹ̀yà Manase.
9 Teć były miasta dla ucieczki wszystkim synom Izraelskim, i cudzoziemcom, którzy mieszkali w pośrodku ich, aby tam uciekł każdy, kto by kogo zabił z nieobaczenia, a nie był zamordowan przez tego, któryby się krwi chciał mścić, ażby pierwej stanął przed zgromadzeniem.
Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé ní àárín wọn tí ó ṣèèṣì pa ẹnìkan lè sálọ sí àwọn ìlú tí a yà sọ́tọ̀ wọ̀nyí, kí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má sì ṣe pa á kí ó to di àkókò tí yóò jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn.

< Jozuego 20 >