< Jozuego 2 >

1 A tak posłał Jozue, syn Nunów, z Syttim dwóch szpiegów potajemnie, mówiąc: Idźcie, wypatrujcie ziemię, i Jerycho. Szli tedy i weszli do niektórej niewiasty wszetecznej, której imię Rachab, i odpoczęli tam.
Nígbà náà ni Joṣua ọmọ Nuni rán àwọn ayọ́lẹ̀wò méjì jáde ní àṣírí láti Ṣittimu. Ó sì wí pé, “Ẹ lọ wo ilẹ̀ náà, pàápàá Jeriko.” Wọ́n sì lọ, wọ́n wọ ilé panṣágà kan, tí à ń pè ní Rahabu wọ́n sì dúró síbẹ̀.
2 I powiedziano to królowi Jerycha, mówiąc: Oto, mężowie jacyś przyszli tu tej nocy z synów Izraelskich, aby przeszpiegowali tę ziemię.
A sì sọ fún ọba Jeriko, “Wò ó! Àwọn ará Israẹli kan wá ibí ní alẹ́ yìí láti wá yọ́ ilẹ̀ yí wò.”
3 Tedy posłał król Jerycha do Rachaby, mówiąc: Wywiedź męże, którzy przyszli do ciebie, a weszli do domu twego; bo na przeszpiegowanie wszystkiej ziemi przyszli.
Ọba Jeriko sì ránṣẹ́ sí Rahabu pé, “Mú àwọn ọkùnrin nì tí ó tọ̀ ọ́ wá, tí ó wọ inú ilé rẹ jáde wá, nítorí wọ́n wá láti yọ́ gbogbo ilẹ̀ yìí wò ni.”
4 Ale wziąwszy ona niewiasta tych dwóch mężów, skryła je, i rzekła: Prawdać jest, przyszli do mnie mężowie; alem nie wiedziała, skąd byli.
Ṣùgbọ́n obìnrin náà ti mú àwọn ọkùnrin méjì náà o sì fi wọ́n pamọ́. Ó sì wí pé, “Lóòtítọ́ ní àwọn ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ibi tí wọ́n ti wá.
5 A gdy bramę zamykano w zmierzch, oni mężowie wyszli; i nie wiem, dokąd poszli; gońcież ich co najrychlej, bo ich dościgniecie.
Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, nígbà tí ó tó àkókò láti ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè, àwọn ọkùnrin náà sì jáde lọ. Èmi kò sì mọ ọ̀nà tí wọ́n gbà lọ. Ẹ lépa wọn kíákíá. Ẹ̀yin yóò bá wọn.”
6 A ona wwiodła je była na dach, i tam je przykryła lnem nietartym, który była rozstawiła na dachu.
(Ṣùgbọ́n ó ti mú wọn gòkè àjà ó sì fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ pòròpòrò ọkà tó tò jọ sí orí àjà.)
7 Mężowie tedy wysłani gonili je drogą ku Jordanu aż do brodu; a bramę zamkniono, skoro wyszli ci, którzy szli za nimi w pogoń.
Àwọn ọkùnrin náà jáde lọ láti lépa àwọn ayọ́lẹ̀wò náà ní ọ̀nà tí ó lọ sí ìwọdò Jordani, bí àwọn tí ń lépa wọn sì ti jáde, wọ́n ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè.
8 A tak pierwej niż posnęli, ona wstąpiła do nich na dach;
Kí àwọn ayọ́lẹ̀wò náà tó sùn ní alẹ́, ó gòkè tọ̀ wọ́n lọ lókè àjà.
9 I rzekła do onych mężów: Wiem, że wam dał Pan ziemię tę; bo strach wasz przypadł na nas, i osłabiali wszyscy obywatele tej ziemi przed wami.
Ó sì sọ fún wọn, “Èmi mọ̀ pé Olúwa ti fún un yín ní ilẹ̀ yìí àti pé ẹ̀rù u yín ti sọ wá di ojo dé ibi pé ìdí gbogbo àwọn tí ó n gbé ilẹ̀ yìí ti di omi nítorí i yín.
10 Bośmy słyszeli, jako wysuszył Pan wody morza czerwonego przed wami, gdyście wychodzili z Egiptu, i coście uczynili dwom królom Amorejskim, którzy byli z onej strony Jordanu, Sehonowi, i Ogowi, któreście pobili.
Àwa ti gbọ́ bí Olúwa ti mú omi Òkun Pupa gbẹ níwájú u yín nígbà tí ẹ̀yin jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ohun tí ẹ̀yin ṣe sí Sihoni àti Ogu, àwọn ọba méjèèjì ti Amori ti ìlà-oòrùn Jordani, tí ẹ̀yin parun pátápátá.
11 Co gdyśmy usłyszeli, upadło serce nasze i nie ostał się więcej duch w nikim przed wami; albowiem Pan, Bóg wasz, jest Bogiem na niebie wzgórę, i na ziemi nisko.
Bí a ti gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ọkàn wa pami kò sì sí okun kankan fún wa mọ́ nítorí i yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni Ọlọ́run ní òkè ọ̀run àti ní ayé.
12 Przetoż teraz przysiężcie mi proszę przez Pana, iż jakom ja uczyniła z wami miłosierdzie, także uczyńcie i wy z domem ojca mego miłosierdzie, a dajcie mi znak pewny,
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ jọ̀wọ́ ẹ búra fún mi ní ti Olúwa pé ẹ̀yin yóò ṣe àánú fún ìdílé mi, nítorí pé mo ti ṣe yín ní oore. Ẹ̀yin yóò fún mi ní àmì tó dájú:
13 Iż zachowacie żywo ojca mego i matkę moję, i bracią moję, i siostry moje, i wszystko, co ich jest, a wybawicie dusze nasze od śmierci.
pé ẹ̀yin yóò dá ẹ̀mí baba àti ìyá mi sí; arákùnrin mi àti arábìnrin mi, àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, àti pé ẹ̀yin yóò gbà wá là lọ́wọ́ ikú.”
14 I odpowiedzieli jej oni mężowie: Dusza nasza będzie za was na śmierć, jeźli nie wydacie tej sprawy naszej, i będzie to, gdy nam poda Pan tę ziemię, że uczynimy z tobą miłosierdzie i prawdę.
“Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”
15 I spuściła je na powrozie z okna; bo dom jej był przy murze i ona na murze mieszkała.
Nígbà náà ní ó fi okùn sọ̀ wọ́n kalẹ̀ ní ojú u fèrèsé, nítorí ilé tí ó ń gbé wà ní ara odi ìlú.
16 I rzekła im: Na górę idźcie, by się snać nie spotkali z wami, którzy was gonią: i tam się kryjcie przez trzy dni, aż się wrócą, którzy was gonią, a potem pójdziecie drogą waszą.
Ó sì ti sọ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí orí òkè, kí ẹ sì fi ara pamọ́ níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta kí àwọn tí ń lépa yín má ba à rí i yín títí tí wọn yóò fi darí. Lẹ́yìn náà kí ẹ máa bá ọ̀nà yín lọ.”
17 I rzekli jej mężowie oni: Będziemy wolni od przysięgi tej, którąś nas poprzysięgła,
Àwọn arákùnrin náà sì sọ fún un pé, “Kí ọrùn un wa ba à lè mọ́ kúrò nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú yìí.
18 Jeźli, gdy wnijdziemy do ziemi, tego czerwonego sznuru nie uwiążesz u okna, po którymeś nas spuściła, a ojca twego, i matki twojej, i braci twojej, i wszystkiego domu ojca twego nie zbierzeszli do siebie w dom;
Nígbà tí àwa bá wọ ilé è rẹ, ìwọ yóò so okùn aláwọ̀ aró yìí sí ojú fèrèsé èyí tí ìwọ fi sọ̀ wá kalẹ̀, kí ìwọ kí ó mú baba rẹ, ìyá rẹ, àwọn arákùnrin in rẹ àti gbogbo ìdílé è rẹ kí wọ́n wá sí inú ilé è rẹ.
19 Albowiem ktobykolwiek wyszedł ze drzwi domu twego, krew jego będzie na głowę jego, a my będziemy bez winy; ale każdego, ktokolwiek będzie z tobą w domu, krew jego obróci się na głowę naszę, jeźli się go kto rękę dotknie.
Bí ẹnikẹ́ni bá jáde sí ìta láti inú ilé è rẹ sí inú ìgboro ìlú, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò sì wà ní orí ara rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí i rẹ̀. Fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wà nínú ilé pẹ̀lú rẹ, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí i wa bí ẹnikẹ́ni bá fi ọwọ́ kàn án.
20 Lecz jeźli wydasz tę sprawę naszę, tedy będziemy wolni od przysięgi twojej, którąś nas poprzysięgła.
Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò bọ́ nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú.”
21 I odpowiedziała; Jakoście powiedzieli, niechże tak będzie. Tedy je wypuściła, i poszli; i uwiązała sznur czerwony w onem oknie.
Ó dáhùn pé, “Ó dára bẹ́ẹ̀. Ẹ jẹ́ kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí sọ.” Ó sì rán wọn lọ wọ́n sì lọ. Ó sì so okùn òdòdó náà sí ojú fèrèsé.
22 A odszedłszy przyszli na górę, i zostali tam przez trzy dni, aż się wrócili, którzy je gonili; bo ich szukali ci, którzy je gonili, po wszystkich drogach, ale nie znaleźli.
Nígbà tí wọ́n kúrò, wọ́n sì lọ sí orí òkè wọ́n sì dúró ní ibẹ̀ ní ọjọ́ mẹ́ta, títí àwọn alépa fi wá wọn ní gbogbo ọ̀nà wọ́n sì padà láìrí wọn.
23 I wrócili się oni dwaj mężowie, a zstąpiwszy z góry, przeprawili się, i przyszli do Jozuego, syna Nunowego, i powiedzieli mu wszystko, co się z nimi działo;
Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin méjì náà padà. Wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, wọ odò, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ọmọ Nuni wọ́n sì sọ fún un gbogbo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wọn.
24 I mówili do Jozuego: Dał Pan w ręce nasze tę wszystkę ziemię; bo się strwożyli wszyscy obywatele ziemi przed twarzą naszą.
Wọ́n sì sọ fún Joṣua, “Nítòótọ́ ni Olúwa tí fi gbogbo ilẹ̀ náà lé wa lọ́wọ́; gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà ni ìbẹ̀rùbojo ti mú nítorí i wa.”

< Jozuego 2 >