< Jozuego 18 >

1 Tedy się zebrało wszystko zgromadzenie synów Izraelskich do Sylo, i postawili tam namiot zgromadzenia, gdy ziemia była od nich opanowana.
Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli péjọ ní Ṣilo, wọ́n si kọ́ àgọ́ ìpàdé ní ibẹ̀. Gbogbo ilẹ̀ náà sì wà ní abẹ́ àkóso wọn,
2 A zostało było z synów Izraelskich, którym było nie oddzielono dziedzictwa ich, siedmioro pokolenia.
ṣùgbọ́n ó ku ẹ̀yà méje nínú àwọn ọmọ Israẹli tí kò tí ì gba ogún ìní wọn.
3 Tedy rzekł Jozue do synów Izraelskich: Dokądże zaniedbywacie wnijść, abyście posiedli ziemię, którą wam dał Pan, Bóg ojców waszych?
Báyìí ni Joṣua sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe dúró pẹ́ tó, kí ẹ tó gba ilẹ̀ ìní tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín ti fi fún yín?
4 Obierzcie między sobą po trzech męża z każdego pokolenia, które poślę, aby wstawszy obeszli ziemię, a rozpisali ją według dziedzictwa ich, potem się wrócą do mnie.
Ẹ yan àwọn ọkùnrin mẹ́ta nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Èmi yóò rán wọn jáde láti lọ bojú wo ilẹ̀ náà káàkiri, wọn yóò sì ṣe àpèjúwe rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìní ẹni kọ̀ọ̀kan. Nígbà náà ni wọn yóò padà tọ̀ mí wá.
5 I rozdzielą ją na siedem części: Juda stanie na granicach swoich od południa, a dom Józefów stanie na granicach swoich od północy.
Ẹ̀yin yóò sì pín ilẹ̀ náà sí ọ̀nà méje kí Juda dúró sí ilẹ̀ rẹ̀ ni ìhà gúúsù àti ilé Josẹfu ní ilẹ̀ rẹ̀ ní ìhà àríwá.
6 Wy tedy rozpiszecie ziemię na siedem części a przyniesiecie tu do mnie: tedy wam rzucę los tu przed Panem, Bogiem naszym.
Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá kọ àpèjúwe ọ̀nà méjèèje ilẹ̀ náà, ẹ mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi ní ibí, èmi ó sì ṣẹ́ kèké fún yín ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.
7 Albowiem Lewitowie nie mają działu między wami, gdyż kapłaństwo Pańskie jest dziedzictwo ich; ale Gad, i Ruben, i połowa pokolenia Manasesowego wzięli dziedzictwa swe za Jordanem na wschód słońca, które im oddał Mojżesz, sługa Pański.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi kò ní ìpín ní àárín yín, nítorí iṣẹ́ àlùfáà. Olúwa ni ìní wọ́n. Gadi, Reubeni àti ìdajì ẹ̀yà Manase, ti gba ìní wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani. Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.”
8 Przetoż wstawszy mężowie oni odeszli; a Jozue rozkazał tym, którzy szli, aby rozpisali ziemię, mówiąc: Idźcie a obejdźcie ziemię, i popiszcie ją, a potem wróćcie się do mnie, a tu wam rzucę los przed PAnem w Sylo.
Bí àwọn ọkùnrin náà ti bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn láti fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà, Joṣua pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà káàkiri, kí ẹ sì kọ àpèjúwe rẹ̀. Lẹ́yìn náà kí ẹ padà tọ̀ mí wá, kí èmi kí ò lè ṣẹ́ kèké fún yin ní ibí ní Ṣilo ní iwájú Olúwa.”
9 Odeszli tedy mężowie oni i obchodzili ziemię, i opisywali ją według miast na siedem części w księgi; potem się wrócili do Jozuego, do obozu w Sylo.
Báyìí ni àwọn ọkùnrin náà lọ, wọ́n sì la ilẹ̀ náà já. Wọ́n sì kọ àpèjúwe rẹ̀ sí orí ìwé kíká ní ìlú, ní ọ̀nà méje, wọ́n sì padà tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Ṣilo.
10 Rzucił im los Jozue w Sylo przed Panem, a podzielił tam Jozue ziemię synom Izraelskim według działów ich.
Joṣua sì ṣẹ́ gègé fún wọn ní Ṣilo ní iwájú Olúwa, Joṣua sì pín ilẹ̀ náà fún àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn ní ibẹ̀.
11 Tedy padł los pokoleniu synów Benjaminowych według domów ich, a przyszła granica losu ich między syny Judowe, i między syny Józefowe.
Ìbò náà sì wá sórí ẹ̀yà Benjamini, ní agbo ilé, agbo ilé. Ilẹ̀ ìpín wọn sì wà láàrín ti ẹ̀yà Juda àti Josẹfu.
12 I była granica ich ku stronie północnej od Jordanu, a szła taż granica po bok Jerycha od północy, ciągnąc się na górę ku zachodowi, a kończyła się przy puszczy Betawen.
Ní ìhà àríwá ààlà wọn bẹ̀rẹ̀ ní Jordani, ó kọjá lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Jeriko ní ìhà àríwá, ó sì forí lé ìwọ̀-oòrùn sí ìlú òkè, jáde sí aginjù Beti-Afeni.
13 A stamtąd idzie ta granica do Luz, od strony południowej Luzy, która jest Betel, a puszcza się ta granica do Attarot Adar podle góry, która jest od południa Betoron dolnego.
Láti ibẹ̀ ààlà náà tún kọjá lọ sí ìhà gúúsù ní ọ̀nà Lusi (tí í ṣe Beteli) ó sì dé Atarotu-Addari, ní orí òkè tí ó wà ní gúúsù Beti-Horoni.
14 I bieży ta granica kołem po bok morza na południe od góry, która jest przeciw Betoron, na południe, i kończy się w Karyjat Baal, które jest Karyjat Jarym, miasto synów Judowych; a toć jest strona zachodnia.
Láti òkè tí ó kọjú sí Beti-Horoni ní gúúsù ààlà náà yà sí gúúsù ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó sì jáde sí Kiriati-Baali (tí í ṣe Kiriati-Jearimu), ìlú àwọn ènìyàn Juda. Èyí ni ìhà ìwọ̀-oòrùn.
15 Strona zasię na południe od końca Karyjat Jarym; a wychodzi ta granica ku morzu, i bieży ku źródłu wód Neftoa.
Ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ ní ìpẹ̀kun Kiriati-Jearimu ní ìwọ̀-oòrùn, ààlà náà wà ní ibi ìsun omi Nefitoa.
16 I ciągnie się ta granica do końca góry, która jest przeciwko dolinie synów Ennon, a jest w dolinie Refaim na północy, i idzie przez dolinę Refaim na północy, i idzie przez dolinę Ennon po stronie Jebuzejczyka na południe, stamtąd bieży do źródła Rogiel.
Ààlà náà lọ sí ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè tí ó kọjú sí àfonífojì Beni-Hinnomu, àríwá àfonífojì Refaimu. O sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí àfonífojì Hinnomu sí apá gúúsù gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè ìlú Jebusi, ó sì lọ bẹ́ẹ̀ títí dé En-Rogeli.
17 A idzie kołem od północy, a dochodzi do Ensemes, a wychodzi do Gelilot, które jest przeciwko górze, wstępując do Adommim, bieżąc stamtąd do kamienia Bohena, syna Rubenowego.
Nígbà náà ni ó yípo sí ìhà àríwá, ó sì lọ sí Ẹni-Ṣemeṣi, ó tẹ̀síwájú dé Geliloti tí ó kọjú sí òkè Adummimu, ó sì sọ̀kalẹ̀ sí ibi Òkúta Bohani ọmọ Reubeni.
18 Stamtąd idzie ku stroni, która jest przeciwko równinom na północy, i ciągnie się ku Araba.
Ó tẹ̀síwájú títí dé gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Araba, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí aginjù.
19 Stamtąd bieży ta granica ku stronie Betogla na północy, a kończy się u skały morza słonego na północy, ku końcowi Jordanu na południe; toć jest granica południowa.
Nígbà náà ni ó lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Hogla, ó sì jáde ní àríwá etí bèbè Òkun Iyọ̀, ní ẹnu odò Jordani ní gúúsù. Èyí ni ààlà ti gúúsù.
20 Jordan zaś kończy ją ku stronie na wschód słońca; a toć jest dziedzictwo synów Benjaminowych według granic ich w okrąg, wedle domów ich.
Odò Jordani sí jẹ́ ààlà ní ìhà ìlà-oòrùn. Ìwọ̀nyí ní àwọn ààlà ti ó sàmì sí ìní àwọn ìdílé Benjamini ní gbogbo àwọn àyíká wọn.
21 Były tedy te miasta pokolenia synów Benjaminowych według domów ich: Jerycho i Betagal, i dolina Kasys.
Ẹ̀yà Benjamini ní agbo ilé, agbo ilé ni àwọn ìlú wọ̀nyí: Jeriko, Beti-Hogla, Emeki-Keṣiṣi,
22 I Betaraba, i Samraim, i Betel;
Beti-Araba, Semaraimu, Beteli,
23 I Awim, i Afara, i Ofera;
Affimu, Para, Ofira
24 I Kafar Hammonaj, i Ofni, i Gaba, i miast dwanaście, i wsi ich;
Kefari, Ammoni, Ofini àti Geba; àwọn ìlú méjìlá àti ìletò wọn.
25 Gabon, i Rama, i Berot;
Gibeoni, Rama, Beeroti,
26 I Misfe, i Kafara, i Mosa;
Mispa, Kefira, Mosa,
27 I Rekiem, i Jerefel, i Tarela;
Rekemu, Irpeeli, Tarala,
28 I Sela, Elef, i Jebuz (które jest Jeruzalem), Gibeat, Kiryjat, miast czternaście, i wsi ich. toć jest dziedzictwo synów Benjaminowych według domów ich.
Ṣela, Haelefi, ìlú Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu), Gibeah àti Kiriati, àwọn ìlú mẹ́rìnlá àti ìletò wọn. Èyí ni ìní Benjamini fún ìdílé rẹ̀.

< Jozuego 18 >