< Jozuego 13 >

1 I zstarzał się Jozue, a był zeszły w leciech. I rzekł Pan do niego: Tyś się zstarzał, a zszedłeś w leciech, a ziemi zostawa bardzo wiele ku posiadaniu.
Nígbà tí Joṣua sì darúgbó tí ọjọ́ orí rẹ̀ sì pọ̀ jọjọ, Olúwa sọ fún un pé, “Ìwọ ti darúgbó púpọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ilẹ̀ sì kù lọ́pọ̀lọ́pọ̀ fún yín láti gbà.
2 Tać jest ziemia, która pozostawa: Wszystkie granice Filistynów, i wszyscy Gessurytowie,
“Èyí ni ilẹ̀ tí ó kù: “gbogbo àwọn agbègbè àwọn Filistini, àti ti ara Geṣuri:
3 Od Nilu, który oblewa Egipt, aż do granicy Akaronu na północy, przynależy Chananejczykowi, pięcioro księstw Filistyńskich; Asackie, i Asdodziejskie, Askalońskie, Getejskie, i Akaronicki, i Hawejczycy.
láti odò Ṣihori ní ìlà-oòrùn Ejibiti sí agbègbè Ekroni ìhà àríwá, gbogbo rẹ̀ ni a kà kún Kenaani (agbègbè ìjòyè Filistini márùn-ún ní Gasa, Aṣdodu, Aṣkeloni, Gitti àti Ekroni; ti àwọn ará Affimu);
4 Od południa wszystka ziemia Chananejska, i Mara, które jest Sydończyków aż do Afeka, i aż do granicy Amorejczyka;
láti gúúsù; gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Kenaani, láti Arah ti àwọn ará Sidoni títí ó fi dé Afeki, agbègbè àwọn ará Amori,
5 I ziemia Giblitów ze wszystkim Libanem na wschód słońca, od Baalgad pod górę Hermon, aż gdzie chodzą do Emat.
àti ilẹ̀ àwọn ará Gebali; àti gbogbo àwọn Lebanoni dé ìlà-oòrùn, láti Baali-Gadi ní ìsàlẹ̀ òkè Hermoni dé Lebo-Hamati.
6 Wszystkie mieszkające na górach od Libanu aż do wód gorących, wszystkie Sydończyki Ja wypędzę przed syny Izraelskimi; tylko ją podziel Izraelitom w dziedzictwo, jakom ci rozkazał.
“Ní ti gbogbo àwọn olùgbé agbègbè òkè, láti Lebanoni sí Misrefoti-Maimu, àní, gbogbo àwọn ará Sidoni, èmi fúnra mi ní yóò lé wọn jáde ní iwájú àwọn ará Israẹli. Kí o ri dájú pé o pín ilẹ̀ yí fún Israẹli ní ilẹ̀ ìní, gẹ́gẹ́ bí mo ṣe fi àṣẹ fún ọ,
7 Przetoż teraz rozdziel tę ziemię w dziedzictwo, dziewięciorgu pokoleniu, i połowie pokolenia Manasesowego.
pín ilẹ̀ yìí ní ilẹ̀ ìní fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án àti ìdajì ẹ̀yà Manase.”
8 Gdyż z drugą połową Rubenitowie i Gadytowie wzięli dziedzictwo swoje, które im dał Mojżesz za Jordanem na wschód słońca, jako im dał Mojżesz, sługa Pański;
Àwọn ìdajì ẹ̀yà Manase tí ó kù, àti àwọn Reubeni àti àwọn Gadi ti gba ilẹ̀ ìní, tí Mose ti fún wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.
9 Od Aroer, które jest nad brzegiem potoku Arnon, i miasto, które jest w pośrodku potoku, i wszystkę równinę Medeba aż do Dybon;
Ó sì lọ títí láti Aroeri tí ń bẹ létí àfonífojì Arnoni, àti láti ìlú náà tí ń bẹ ní àárín àfonífojì náà, àti pẹ̀lú gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Medeba títí dé Diboni.
10 I wszystkie miasta Sehona, króla Amorejskiego, który królował w Hesebon, aż do granicy synów Ammonowych;
Gbogbo ìlú Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó ṣe àkóso ní Heṣboni, títí dé ààlà àwọn ará Ammoni.
11 Także Galaad, i granice Gessurytów, i Machatytów, i wszystkę górę Hermon, i wszystko Basan aż do Salecha;
Àti Gileadi, ní agbègbè àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, gbogbo òkè Hermoni àti gbogbo Baṣani títí dé Saleka,
12 Wszystko królestwo Oga w Basan, który królował w Astarot, i w Edrej; ten był pozostał z Refaimitów, a pobił je Mojżesz i wygładził je.
ìyẹn, gbogbo ilẹ̀ ọba Ogu ní Baṣani, tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei, ẹni tí ó kù nínú àwọn Refaimu ìyókù. Mose ti ṣẹ́gun wọn, ó sì ti gba ilẹ̀ wọn.
13 Ale nie wygnali synowie Izraelscy Gessurytów i Machatytów; przetoż mieszkał Gessur i Machat w pośród Izraelczyków aż do dnia tego.
Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli kò lé àwọn ará Geṣuri àti Maakati jáde, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé ní àárín àwọn ará Israẹli títí di òní yìí.
14 Tylko pokoleniu Lewi nie dał dziedzictwa; ofiary ogniste Pana Boga Izraelskiego są dziedzictwem jego, jako mu powiedział Bóg.
Ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Lefi ni kò fi ogún kankan fún, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ pé ọrẹ àfinásun sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ni ogún tiwọn, gẹ́gẹ́ bí o ti ṣèlérí fún wọn.
15 A tak oddał Mojżesz pokoleniu synów Rubenowych dziedzictwo według familii ich.
Èyí ni Mose fi fún ẹ̀yà Reubeni ni agbo ilé sí agbo ilé,
16 I była granica ich od Aroer, które jest nad brzegiem potoku Arnon, i miasto, które jest w pośród potoku, i wszystka równina ku Medeba.
láti agbègbè Aroeri ní etí Arnoni Jọ́ọ́jì àti láti ìlú tí ń bẹ láàrín Jọ́ọ́jì, àti gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ìkọjá Medeba
17 Hesebon, i wszystkie miasta jego, które były w równinie; Dybon i Bamot Baal, i Bet Baal Meon;
sí Heṣboni àti gbogbo ìlú rẹ̀ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú Diboni, Bamoti Baali, Beti-Baali-Mioni,
18 I Jassa, i Cedymot, i Mefaat;
Jahisa, Kedemoti, Mefaati,
19 I Karyjataim, i Sebama, i Saratasar na górze w dolinie;
Kiriataimu, Sibma, Sereti Ṣahari lórí òkè ní àfonífojì.
20 I Betfegor, i Asdod, Fazga, i Betyjesymot.
Beti-Peori, gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga, àti Beti-Jeṣimoti
21 Wszystkie też miasta w równinie, i wszystko królestwo Sehona, króla Amorejskiego, który królował w Hesebon, którego zabił Mojżesz, i książęta Madyjańskie Ewi, i Recem, i Sur, i Hur, i Reba; książęta Sehonowe, obywatele ziemi.
gbogbo ìlú tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti gbogbo agbègbè Sihoni ọba Amori, tí ó ṣe àkóso Heṣboni. Mose sì ti ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ ìjòyè Midiani, Efi, Rekemu, Suri, Huri àti Reba, àwọn ọmọ ọba pawọ́pọ̀ pẹ̀lú Sihoni tí ó gbé ilẹ̀ náà.
22 I Balaama, syna Boerowego, wieszczka, zabili synowie Izraelscy mieczem z innymi pobitymi.
Ní àfikún àwọn tí a pa ní ogun, àwọn ọmọ Israẹli fi idà pa Balaamu ọmọ Beori alásọtẹ́lẹ̀.
23 Była tedy granica synów Rubenowych Jordan z granicami swemi. Toć jest dziedzictwo synów Rubenowych według domów ich, miast i wsi ich.
Ààlà àwọn ọmọ Reubeni ni etí odò Jordani. Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ ni ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Reubeni ní agbo ilé ní agbo ilé.
24 Dał też Mojżesz pokoleniu Gad, synom Gadowym, według domów ich dziedzictwo.
Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ẹ̀yà Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
25 A były ich granice Jazer i wszystkie miasta Galaad, i połowa ziemi synów Ammonowych aż do Aroer, które jest przeciw Rabba;
Agbègbè ìlú Jaseri, gbogbo ìlú Gileadi àti ìdajì orílẹ̀-èdè àwọn ọmọ ará Ammoni títí dé Aroeri, ní ẹ̀bá Rabba;
26 I od Hesebon aż do Ramat Massa i Betonim, a od Mahanaim aż do granicy Dabir.
àti láti Heṣboni lọ sí Ramati-Mispa àti Betonimu, àti láti Mahanaimu sí agbègbè ìlú Debiri,
27 W dolinie też Beram, i Betnimra, i Sochot, i Safon, ostatek królestwa Sehona, króla Hesebońskiego, Jordan i pogranicze jego aż do końca morza Cynneret za Jordanem na wschód słońca.
àti ní àfonífojì Beti-Haramu, Beti-Nimra, Sukkoti àti Safoni pẹ̀lú ìyókù agbègbè ilẹ̀ Sihoni ọba Heṣboni (ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani, agbègbè rẹ̀ títí dé òpin Òkun Kinnereti).
28 Toć jest dziedzictwo synów Gad według domów ich, miast i wsi ich.
Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ jẹ́ ogún àwọn ọmọ Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
29 Nadto dał Mojżesz osiadłość połowie pokolenia Manasesowego, i była ta połowa pokolenia synów Manasesowych według domów ich.
Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ìdajì ẹ̀yà Manase, èyí ni pé, fún ìdajì ìdílé irú-ọmọ Manase, ní agbo ilé ní agbo ilé.
30 Była granica ich od Machanaim wszystko Basan i wszystko królestwo Oga, króla Basańskiego, i wszystkie wsi Jairowe, które są w Basan, sześćdziesiąt miast.
Ilẹ̀ náà fẹ̀ dé Mahanaimu àti gbogbo Baṣani, gbogbo agbègbè ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani, èyí tí í ṣe ibùgbé Jairi ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú,
31 I połowę Galaad, i Astarot, i Erdej, miasta królestwa Oga w Basan, dał synom Machyra, syna Manasesowego, połowie synów Machyrowych według domów ich.
ìdajì Gileadi, àti Aṣtarotu àti Edrei (àwọn ìlú ọba Ogu ní Baṣani). Èyí ni fún irú àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase fún ààbọ̀ àwọn ọmọ Makiri, ní agbo ilé ní agbo ilé.
32 Teć są osiadłości, które podzielił Mojżesz w polach Moabskich za Jordanem przeciw Jerychu na wschód słońca.
Èyí ni ogún tí Mose fi fún wọn nígbà tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu ní ìhà kejì Jordani ní ìlà-oòrùn Jeriko.
33 Ale pokoleniu Lewi nie dał Mojżesz dziedzictwa; bo Pan, Bóg Izraelski, sam jest dziedzictwem ich, jako im powiedział.
Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yà Lefi, Mose kò fi ogún fún un; Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ní ogún wọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí fún wọn.

< Jozuego 13 >