< Hioba 40 >

1 A tak odpowiedział Pan Ijobowi, i rzekł:
Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
2 Izali ten, co wiedzie spór z Wszechmogącym, uczyć go będzie? a kto chce strofować Boga, niech na to odpowie.
“Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
3 Zatem odpowiedział Ijob Panu, i rzekł:
Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
4 Otom ja lichy, cóż ci mam odpowiedzieć? Rękę moję włożę na usta moje.
“Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
5 Mówiłem raz i drugi, ale więcej nie odpowiem, i nic więcej nie przydam.
Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
6 Nadto odpowiedział Pan Ijobowi z wichru, i rzekł:
Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
7 Przepasz teraz jako mąż biodra swe: będę cię pytał, a ty mi daj sprawę;
“Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
8 Izali wniwecz obrócisz sąd mój? a obwinisz mię, abyś się sam usprawiedliwił?
“Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
9 Izali masz ramię jako Bóg? a głosem zagrzmisz jako on?
Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
10 Ozdóbże się teraz zacnością i dostojnością, a w chwałę i w ochędóstwo oblecz się.
Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
11 Rozpostrzyj popędliwość gniewu twego, a patrz na każdego pysznego, i poniż go.
Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
12 Spojrzyjże na każdego hardego a skróć go, a zetrzyj niepobożnych na miejscu ich.
Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
13 Zakryj ich pospołu w prochu, a oblicza ich zawiąż w skrytości.
Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
14 Tedyć i Ja przyznam, że cię może zachować prawica twoja.
Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
15 Oto teraz słoń, któregom uczynił jako i ciebie, trawę je jako wół.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
16 Oto teraz moc jego jest w biodrach jego, a siła jego w pępku brzucha jego.
Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
17 Rusza ogonem swoim, jako chce, choć jest jako drzewo cedrowe; żyły łona jego są powikłane jako latorośli.
Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
18 Kości jego jako trąby miedziane; gnaty jego jako drąg żelazny.
Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
19 On jest przedniejszym z uczynków Bożych; który go uczynił, sam nań natrzeć może mieczem swoim.
Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
20 Jemuć pastwę góry przynoszą, a wszystek zwierz polny tam igra.
Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
21 Pod cienistem drzewem lega w skrytościach trzciny i błota.
Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
22 Okrywają go drzewa cieniste cieniem swoim, a ogarniają go wierzby nad potokami.
Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
23 Oto zatrzymuje strumień, że się nie spieszy; tuszy sobie, iż Jordan wypije gębą swoją.
Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
24 Azali go kto przed oczyma jego ułapi? albo powrozy przeciągnie przez nozdrze jego?
Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?

< Hioba 40 >