< Hioba 4 >

1 Tedy odpowiedział Elifas Temańczyk, i rzekł:
Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani dáhùn wí pé,
2 Jeźli będziemy mówili z tobą, nie będzie ci to przykro? Ale któż się może od mówienia zatrzymać?
“Bí àwa bá fi ẹnu lé e, láti bá ọ sọ̀rọ̀, ìwọ o ha banújẹ́? Ṣùgbọ́n ta ni ó lè pa ọ̀rọ̀ mọ́ ẹnu láìsọ?
3 Otoś ich wiele uczył, i ręceś mdłe potwierdzał.
Kíyèsi i, ìwọ sá ti kọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn, ìwọ ṣá ti mú ọwọ́ aláìlera le.
4 Upadającego wspierały mowy twoje, a kolana zemdlone posilałeś.
Ọ̀rọ̀ rẹ ti gbé àwọn tí ń ṣubú lọ dúró, ìwọ sì ti mú eékún àwọn tí ń wárìrì lera.
5 A teraz, gdy to na cię przyszło, niecierpliwie znosisz, a iż cię dotknęło, trwożysz sobą.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ó dé bá ọ, ó sì rẹ̀ ọ́, ó kọlù ọ́; ara rẹ kò lélẹ̀.
6 Azaż pobożność twoja nie była ufnością twoją, a uprzejmość spraw twoich oczekiwaniem twojem?
Ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ kò ha jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ àti ìdúró ọ̀nà rẹ kò ha sì jẹ́ ìrètí rẹ?
7 Wspomnij proszę, kto kiedy niewinny zginął? albo gdzieby ludzie szczerzy zniszczeli?
“Èmi bẹ̀ ọ́ rántí, ta ni ó ṣègbé rí láìṣẹ̀? Tàbí níbo ni a gbé gé olódodo kúrò rí?
8 Jakom widał, że ci, którzy orali złość, i rozsiewali przewrotność, toż też zasię żęli.
Àní bí èmi ti rí i pé, àwọn tí ń ṣe ìtulẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀, tí wọ́n sì fún irúgbìn ìwà búburú, wọn a sì ká èso rẹ̀ náà.
9 Bo tchnieniem Bożem giną, a od ducha gniewu jego niszczeją.
Nípa ìfẹ́ sí Ọlọ́run wọn a ṣègbé, nípa èémí ìbínú rẹ̀ wọn a parun.
10 Ryk lwi, i głos lwicy, i zęby lwiąt wytrącają.
Bíbú ramúramù kìnnìún àti ohùn òǹrorò kìnnìún àti eyín àwọn ẹgbọrọ kìnnìún ní a ká.
11 Lew ginie, iż nie ma łupu, i szczenięta lwie rozproszone bywają.
Kìnnìún kígbe, nítorí àìrí ohun ọdẹ, àwọn ẹgbọrọ kìnnìún sísanra ni a túká kiri.
12 Nadto doszło mię słowo potajemnie, i pojęło ucho moje cokolwiek z niego.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí a fi ohun àṣírí kan hàn fún mi, etí mi sì gbà díẹ̀ nínú rẹ̀.
13 W rozmyślaniu widzenia nocnego, gdy przypada twardy sen na ludzi,
Ní ìrò inú lójú ìran òru, nígbà tí oorun èjìká kùn ènìyàn.
14 Zdjął mię strach i lękanie, które wszystkie kości moje przestraszyło.
Ẹ̀rù bà mí àti ìwárìrì tí ó mú gbogbo egungun mi jí pépé.
15 A duch szedł przed twarzą moją, tak, iż włosy wstały na ciele mojem.
Nígbà náà ni ẹ̀mí kan kọjá lọ ní iwájú mi, irun ara mi dìde dúró ṣánṣán.
16 Stanął, a nie znałem twarzy jego, kształt tylko jakiś był przed oczyma memi; uciszyłem się, i słyszałem głos mówiący:
Ó dúró jẹ́ẹ́, ṣùgbọ́n èmi kò le wo àpẹẹrẹ ìrí rẹ̀, àwòrán kan hàn níwájú mi, ìdákẹ́rọ́rọ́ wà, mo sì gbóhùn kan wí pé,
17 Izali człowiek może być sprawiedliwszy niżeli Bóg; albo mąż czystszy niż Stworzyciel jego?
‘Ẹni kíkú le jẹ́ olódodo ju Ọlọ́run, ènìyàn ha le mọ́ ju ẹlẹ́dàá rẹ̀ bí?
18 Oto w sługach jego niemasz doskonałości, a w Aniołach swoich znalazł niedostatek;
Kíyèsi i, òun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, nínú àwọn angẹli rẹ̀ ní ó sì rí ẹ̀ṣẹ̀.
19 Daleko więcej w tych, co mieszkają w domach glinianych, których grunt jest na prochu, i starci bywają snadniej niżeli mól.
Mélòó mélòó àwọn tí ń gbé inú ilé amọ̀, ẹni tí ìpìlẹ̀ wọ́n jásí erùpẹ̀ tí yóò di rírun kòkòrò.
20 Od poranku aż do wieczora bywają starci; a iż tego nie uważają, na wieki zginą.
A pa wọ́n run láàrín òwúrọ̀ àti àṣálẹ́ wọ́n sì parun títí láé, láìrí ẹni kà á sí.
21 Azaż zacność ich nie pomija z nimi? umierają, ale nie w mądrości.
A kò ha ké okùn iye wọ́n kúrò bí? Wọ́n kú, àní láìlọ́gbọ́n?’

< Hioba 4 >