< Hioba 35 >

1 Nadto mówił Elihu, i rzekł:
Elihu sì wí pe:
2 I mniemasz, żeś to z rozsądkiem rzekł: Sprawiedliwość moja przechodzi Boską?
“Ìwọ rò pé èyí ha tọ́, tí ìwọ wí pé, òdodo mi ni èyí níwájú Ọlọ́run?
3 Boś powiedział: Cóż mi pomoże? a co wezmę za pożytek, choćbym nie grzeszył?
Nítorí tí ìwọ wí pé èrè kí ní yóò jásí fún ọ, tàbí èrè kí ni èmi yóò fi jẹ́ ju èrè ẹ̀ṣẹ̀ mi lọ.
4 Ale ja tobie dowodnie odpowiem, i towarzyszom twoim z tobą.
“Èmi ó dá ọ lóhùn àti àwọn ẹgbẹ́ rẹ pẹ̀lú rẹ.
5 Spojrzyj w niebo, a obacz; przypatrz się obłokom, jako są wyższe nad cię.
Síjú wo ọ̀run; kí o rí i, kí ó sì bojú wo àwọsánmọ̀ tí ó ga jù ọ́ lọ.
6 Jeźli zgrzeszysz, cóż uczynisz przeciwko niemu? a jeźliby były rozmnożone nieprawości twoje, cóż mu uczynisz?
Bí ìwọ bá dẹ́ṣẹ̀, kí ni ìwọ fi sẹ̀ sí? Tàbí bí ìrékọjá rẹ di púpọ̀, kí ni ìwọ fi èyí nì ṣe sí i?
7 Jeźlibyś był sprawiedliwym, cóż mu dasz? albo cóż weźmie z ręki twojej?
Bí ìwọ bá sì ṣe olódodo, kí ni ìwọ fi fún un, tàbí kí ni òun rí gbà láti ọwọ́ rẹ wá?
8 Człowiekowi podobnemu tobie niezbożność twoja zaszkodzi, a synowi człowieczemu pomoże sprawiedliwość twoja.
Ìwà búburú rẹ ni fún ènìyàn bí ìwọ; òdodo rẹ sì ni fún ọmọ ènìyàn.
9 Z mnóstwa uciśnionych, którzy do tego przywiedzieni są; aby narzekali i wołali dla ramienia mocarzów,
“Nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìninilára, wọ́n mú ni kígbe; wọ́n kígbe nípa apá àwọn alágbára.
10 Żaden nie mówi: Gdzież jest Bóg, stworzyciel mój, choć on daje śpiewanie i w nocy?
Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó wí pé, ‘Níbo ni Ọlọ́run Ẹlẹ́dàá mi wà tí ó sì fi orin fún mi ní òru;
11 Choć nas wyucza nad bydlęta ziemskie, a nad ptastwo niebieskie czyni nas mędrszymi.
tí òun kọ́ wa ní ẹ̀kọ́ jù àwọn ẹranko ayé lọ, tí ó sì mú wa gbọ́n ju àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run lọ?’
12 Tedy wołająli dla hardości złych, on ich nie wysłuchuje.
Nígbà náà ni wọ́n ń ké ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò dáhùn nítorí ìgbéraga ènìyàn búburú.
13 Bo obłudy nie wysłucha Bóg, a Wszechmocny nie patrzy na nich.
Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ asán; bẹ́ẹ̀ ní Olódùmarè kì yóò kà á sí.
14 Dopieroż nie wysłucha ciebie, ponieważ mówisz: Nie widzisz tego; osądźże się przed nim, a oczekuj go,
Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ìwọ wí pé ìwọ kì í rí i, ọ̀rọ̀ ìdájọ́ ń bẹ níwájú rẹ, ẹni tí ìwọ sì gbọdọ̀ dúró dè.
15 Gdyż cię jedno trochę nawiedził gniew jego, jakoby nie wiedział wielkości grzechów twoich.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí nítorí tí ìbínú rẹ̀ kò tí fìyà jẹ ni, òun kò ni ka ìwà búburú si?
16 Przetoż Ijob próżno otwiera usta swe, a bez umiejętności rozmnaża słowa swoje.
Nítorí náà ní Jobu ṣe ya ẹnu rẹ̀ lásán ó sọ ọ̀rọ̀ di púpọ̀ láìsí ìmọ̀.”

< Hioba 35 >