< Hioba 1 >

1 Był mąż w ziemi Uz, imieniem Ijob; a ten mąż był doskonały, i szczery, i bojący się Boga, a odstępujący od złego.
Ọkùnrin kan wà ní ilẹ̀ Usi, orúkọ ẹni tí í jẹ́ Jobu; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́, ó dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó kórìíra ìwà búburú.
2 I urodziło mu się siedm synów, a trzy córki.
A sì bi ọmọkùnrin méje àti ọmọbìnrin mẹ́ta fún un.
3 A miał dobytku siedm tysięcy owiec, i trzy tysiące wielbłądów, i pięć set jarzm wołów, i pięć set oślic, i czeladzi bardzo wiele, tak, iż on mąż był najmożniejszym nad wszystkich ludzi na wschód słońca.
Ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ìbákasẹ, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta àjàgà ọ̀dá màlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì pọ̀; bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin yìí sì pọ̀jù gbogbo àwọn ará ìlà-oòrùn lọ.
4 I schadzali się synowie jego, a sprawowali uczty, każdy w domu swym, dnia swojego; i posyłali, a wzywali trzy siostry swoje, aby jadały i pijały z nimi.
Àwọn ọmọ rẹ̀ a sì máa lọ í jẹun àsè nínú ilé ara wọn, olúkúlùkù ní ọjọ́ rẹ̀; wọn a sì máa ránṣẹ́ pé arábìnrin wọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta láti jẹun àti láti pẹ̀lú wọn.
5 A gdy wkoło obeszły dni uczty, posyłał Ijob, a poświęcał ich, a wstawając rano sprawował całopalenia według liczby ich wszystkich; bo mówił Ijob: Podobno zgrzeszyli synowie moi, a złorzeczyli Bogu w sercach swych. Tak czynił Ijob po one wszystkie dni.
Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ àsè wọn pé yíká, ni Jobu ránṣẹ́ lọ í yà wọ́n sí mímọ́, ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì rú ẹbọ sísun níwọ̀n iye gbogbo wọn; nítorí tí Jobu wí pé: bóyá àwọn ọmọ mi ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣọpẹ́ fún Ọlọ́run lọ́kàn wọn. Bẹ́ẹ̀ ní Jobu máa ń ṣe nígbà gbogbo.
6 I stało się niektórego dnia, gdy przyszli synowie Boży, aby stanęli przed Panem, że też przyszedł i szatan między nich.
Ǹjẹ́ ó di ọjọ́ kan, nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá í pé níwájú Olúwa, Satani sì wá pẹ̀lú wọn.
7 Tedy rzekł Pan do szatana: Skąd idziesz? I odpowiedział szatan Panu, i rzekł: Okrążałem ziemię, i przechadzałem się po niej.
Olúwa sì bi Satani wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Nígbà náà ní Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Ní ìlọsíwá-sẹ́yìn lórí ilẹ̀ ayé, àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”
8 I rzekł Pan do szatana: Przypatrzyłżeś się słudze memu Ijobowi, że mu niemasz równego na ziemi? Mąż to doskonały i szczery, bojący się Boga, i odstępujący od złego.
Olúwa sì sọ fún Satani pé, “Ìwọ ha kíyèsi Jobu ìránṣẹ́ mi, pé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí í ṣe olóòtítọ́, tí ó sì dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ti ó sì kórìíra ìwà búburú.”
9 I odpowiedział szatan Panu i rzekł: Izaż się Boga Ijob darmo boi?
Nígbà náà ni Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Jobu ha bẹ̀rù Ọlọ́run ní asán bí?”
10 Azażeś go ty nie ogrodził, i domu jego, i wszystkiego co ma, w około zewsząd? Błogosławiłeś sprawom rąk jego, i dobytek jego rozmnożył się na ziemi;
“Ìwọ kò ha ti ṣọgbà yìí ká, àti yí ilé rẹ̀ àti yí ohun tí ó ní ká, ní ìhà gbogbo? Ìwọ bùsi iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì ń pọ̀ si ní ilẹ̀.
11 Ale ściągnij tylko rękę twoję a dotknij wszystkiego, co ma: obaczysz, jeźlić w oczy złorzeczyć nie będzie.
Ǹjẹ́, nawọ́ rẹ nísinsin yìí, kí ó sì fi tọ́ ohun gbogbo tí ó ni; bí kì yóò sì bọ́hùn ni ojú rẹ.”
12 Tedy rzekł Pan do szatana: Oto wszystko co ma, jest w ręce twojej: tylko nań nie ściągaj ręki twej. I odszedł szatan od oblicza Pańskiego.
Olúwa sì dá Satani lóhùn wí pé, “Kíyèsi i, ohun gbogbo tí ó ní ń bẹ ní ìkáwọ́ rẹ, kìkì òun tìkára rẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ rẹ kàn.” Bẹ́ẹ̀ ni Satani jáde lọ kúrò níwájú Olúwa.
13 Stało się tedy niektórego dnia, gdy synowie jego i córki jego jedli, i pili wino w domu brata swego pierworodnego:
Ó sì di ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, tí wọ́n mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n wọn ọkùnrin,
14 Przybieżał poseł do Ijoba i rzekł: Woły orały, a oślice się pasły podle nich:
oníṣẹ́ kan sì tọ Jobu wá wí pé, “Àwọn ọ̀dá màlúù ń tulẹ̀, àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì ń jẹ ní ẹ̀gbẹ́ wọn,
15 I przypadli Sabejczycy, i zabrali je, a sługi pozabijali ostrzem miecza; a uszedłem tylko ja, ja sam, abym ci oznajmił.
àwọn ará Sabeani sì kọlù wọ́n, wọ́n sì ń kó wọn lọ pẹ̀lú, wọ́n ti fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa, èmi nìkan ṣoṣo ní ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ.”
16 A gdy ten jeszcze mówił, przyszedł drugi, i rzekł: Ogień Boży spadł z nieba i spalił owce i sługi, i pożarł ich; a uszedłem tylko ja, ja sam, abym ci oznajmił.
Bí ó ti ń sọ ní ẹnu; ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé, “Iná ńlá Ọlọ́run ti ọ̀run bọ́ sí ilẹ̀, ó sì jó àwọn àgùntàn àti àwọn ìránṣẹ́; èmi nìkan ṣoṣo ní ó sálà láti ròyìn fún ọ.”
17 A gdy ten jeszcze mówił, przyszedł i inny, i rzekł: Chaldejczycy, rozsadziwszy się na trzy hufce, wypadli na wielbłądy, i zabrali je, i sługi pozabijali ostrzem miecza; a uszedłem tylko ja, ja sam, abym ci oznajmił.
Bí ó sì ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan sì dé pẹ̀lú tí ó wí pé, “Àwọn ará Kaldea píngun sí ọ̀nà mẹ́ta, wọ́n sì kọlù àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì kó wọn lọ, pẹ̀lúpẹ̀lú wọ́n sì fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa; èmi nìkan ṣoṣo ni ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ!”
18 A gdy ten jeszcze mówił, przybieżał i inny, a rzekł: Synowie twoi, i córki twoje jedli i pili wino w domu brata swego pierworodnego;
Bí ó ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin ń jẹ, wọ́n ń mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n.
19 A oto wiatr gwałtowny przypadł od onej strony pustyni, i uderzył na cztery węgły domu, tak, że upadł na dzieci, i pomarły; a uszedłem tylko ja, ja sam, abym ci oznajmił.
Sì kíyèsi i, ẹ̀fúùfù ńlá ńlá ti ìhà ijù fẹ́ wá kọlu igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilé, ó sì wó lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wọ́n sì kú, èmi nìkan ṣoṣo ni ó yọ láti ròyìn fún ọ.
20 Tedy wstał Ijob, i rozdarł płaszcz swój, i ogolił głowę swą, a upadłszy na ziemię, uczynił Panu pokłon,
Nígbà náà ni Jobu dìde, ó sì fa aṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya, ó sì fá orí rẹ̀ ó wólẹ̀ ó sì gbàdúrà
21 I rzekł: Nagim wyszedł z żywota matki mojej, i nagim się zaś tamże wrócę; Pan dał, Pan też wziął, niech będzie imię Pańskie błogosławione.
wí pé, “Ní ìhòhò ní mo ti inú ìyá mi jáde wá, ni ìhòhò ní èmi yóò sì tún padà lọ. Olúwa fi fún ni, Olúwa sì gbà á lọ, ìbùkún ni fún orúkọ Olúwa.”
22 W tem wszystkiem nie zgrzeszył Ijob, a nie przypisał Bogu nic nieprzystojnego.
Nínú gbogbo èyí Jobu kò ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi òmùgọ̀ pe Ọlọ́run lẹ́jọ́.

< Hioba 1 >