< Jeremiasza 7 >

1 Słowo, które się stało do Jeremijasza od Pana, mówiąc:
Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
2 Staw się w bramie domu Pańskiego, a opowiadaj tam to słowo, i mów: Słuchajcie słowa Pańskiego wszystek Judo, którzy wchodzicie do bram ich, abyście się kłaniali Panu.
“Dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yí: “‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ọ̀nà yí wọlé láti wá sin Olúwa.
3 Tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski: Polepszajcie dróg swoich, i przedsięwzięcia swego, a sprawię to, abyście mieszkali na tem miejscu.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Tún àwọn ọ̀nà yín ṣe, èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ gbé ilẹ̀ yìí.
4 Nie pokładajcie nadziei swej w słowach kłamliwych, mówiąc: Kościół Pański, kościół Pański, kościół Pański jest!
Má ṣe gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn gbọ́ kí ẹ sì wí pé, “Èyí ni tẹmpili Olúwa ilé tẹmpili Olúwa, ilé tẹmpili Olúwa!”
5 Ale jeźliże polepszając polepszycie dróg swoich, i przedsięwzięcia swego; jeźliże sprawiedliwy sąd czynić będziecie między mężem a między bliźnim jego;
Bí ẹ̀yin bá tún ọ̀nà yín àti iṣẹ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ sì ń bá ara yín lò ní ọ̀nà tó tọ́.
6 Przychodnia, sierotki i wdowy nie uciśniecie, i krwi niewinnej nie rozlejecie na tem miejscu, a za bogami cudzymi nie pójdziecie na swe złe:
Bí ẹ kò bá fi ara ni àwọn àlejò, àwọn ọmọ aláìní baba àti àwọn opó tí ẹ kò sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, bí ẹ kò bá sì tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn sí ìpalára ara yín.
7 Tedy sprawię, abyście mieszkali na tem miejscu w ziemi, którąm dał ojcom waszym, od wieku aż na wieki.
Nígbà náà ni èmi yóò jẹ́ kí ẹ gbé ìbí yìí, nílẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé.
8 Oto wy pokładacie nadzieję swoję w słowach kłamliwych, które nie pomogą.
Ẹ wò ó, ẹ ń gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò níláárí gbọ́.
9 Izali kradnąc, zabijając, i cudzołożąc, i krzywoprzysięgając, i kadząc Baalowi, a chodząc za bogami obcymi, których nie znacie,
“‘Ẹ̀yin yóò ha jalè, kí ẹ pànìyàn, kí ẹ ṣe panṣágà, kí ẹ búra èké, kí ẹ sun tùràrí sí Baali, kí ẹ sì tọ ọlọ́run mìíràn tí ẹ̀yin kò mọ̀ lọ?
10 Przecież chodzić a stawać będziecie przed obliczem mojem w tym domu, który nazwany jest od imienia mego, i mówić: Wybawieniśmy, abyśmy czynili te wszystkie obrzydliwości?
Nígbà náà ni kí ó wá dúró ní iwájú nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, “Kí ẹ wá wí pé àwa yè,” àwa yè láti ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra wọ̀nyí bí?
11 Azaż jaskinią łotrowską jest dom ten przed oczyma waszemi, który nazwany jest od imienia mego? Oto widzęć Ja to, mówi Pan.
Ṣé ilé yìí, tí a fi orúkọ mi pè ti di ihò àwọn ọlọ́ṣà lọ́dọ̀ yín ni? Èmi ti ń wò ó! ni Olúwa wí.
12 Ale idźcie przynajmniej na miejsce moje, które było w Sylo, gdziem był sprawił przybytek imieniowi memu z początku, a obaczcie, com mu uczynił dla złości ludu mego Izraelskiego.
“‘Ẹ lọ nísinsin yìí sí Ṣilo níbi ti mo kọ́ fi ṣe ibùgbé fún orúkọ mi, kí ẹ sì rí ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú Israẹli tí í ṣe ènìyàn mi.
13 Przetoż teraz, ponieważ czynicie te wszystkie sprawy, mówi Pan, a gdy mówię do was rano wstawając a to ustawicznie, a nie słuchacie, gdy wołam na was, a nie ozywacie się:
Nígbà tí ẹ̀yin ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí ni èmi bá a yín sọ̀rọ̀ léraléra ni Olúwa wí ẹ̀yin kò gbọ́, èmi pè yín, ẹ̀yin kò dáhùn.
14 Przetoż uczynię domowi temu, który nazwany jest od imienia mego, w którym wy ufacie, i miejscu temu, którem wam dał i ojcom waszym, jakom uczynił Sylo;
Nítorí náà, èmi yóò ṣe ohun tí mo ṣe sí Ṣilo sí ilé náà tí a fi orúkọ mi pè, ilé tẹmpili nínú èyí tí ẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ààyè tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba yín.
15 I odrzucę was od oblicza mego, jakom odrzucił braci waszych, wszystko nasienie Efraimowe.
Èmi yóò tú kúrò ní iwájú mi gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí àwọn arákùnrin yín, àwọn ará Efraimu.’
16 Ty tedy nie módl się za tym ludem, ani podnoś za nim głosu modlitwy, i nie przyczyniaj się do mnie; bo cię nie wysłucham.
“Nítorí náà má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn; ma ṣe bẹ̀ mí, nítorí èmi kì yóò tẹ́tí sí ọ.
17 Azaż sam nie widzisz, co oni broją w miastach Judzkich i po ulicach Jeruzalemskich?
Ṣé ìwọ kò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
18 Synowie zbierają drwa, a ojcowie rozniecają ogień, a żony ich rozczyniają ciasto, aby czyniły placki królowej niebieskiej, i sprawowały mokre ofiary bogom cudzym, aby mię do gniewu pobudzali.
Àwọn ọmọ ṣa igi jọ, àwọn baba fi iná sí i, àwọn ìyá sì po ìyẹ̀fun láti ṣe àkàrà fún ayaba ọ̀run, wọ́n tú ẹbọ ọrẹ mímu sí àwọn ọlọ́run àjèjì láti ru bínú mi sókè.
19 Izali to przeciwko mnie jest, że mię do gniewu wzruszają? mówi Pan; izali to nie raczej przeciwko nim, ku pohańbieniu twarzy ich?
Ṣùgbọ́n ṣe èmi ni wọ́n fẹ́ mú bínú? ni Olúwa wí. Ǹjẹ́ kì í ṣe pé wọ́n kúkú ń pa ara wọn lára sí ìtìjú ara wọn?
20 Przetoż tak mówi panujący Pan: Oto gniew mój i popędliwość moja będzie wylana na to miejsce, na ludzi i na bydlęta, i na drzewa polne, i na owoce ziemi, i zapali się, a nie ugaśnie.
“‘Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò tú ìbínú àti ìrunú mi sí orílẹ̀ yìí ènìyàn àti ẹranko, igi, pápá àti èso orí ilẹ̀, yóò sì jó tí kò ní ṣe é pa.”
21 Tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski: Całopalenie wasze przydajcie do ofiar waszych, a jedzcie mięso.
“‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Tẹ̀síwájú kí ẹ kó ẹbọ sísun yín àti àwọn ẹbọ yòókù papọ̀ kí ẹ̀yin kí ó sì jẹ ẹran wọ́n fúnra yín.
22 Bom nie mówił z ojcami waszymi, anim im przykazał onego dnia, któregom ich wywiódł z ziemi Egipskiej, o całopaleniu i ofiarach;
Ní tòsí nígbà tí mo mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti tí mo sì bá wọn sọ̀rọ̀. N kò pàṣẹ fún wọn lórí ẹbọ sísun lásán.
23 Ale tom im przykazał, mówiąc: Słuchajcie głosu mojego, i będę Bogiem waszym, a wy będziecie ludem moim; a chodźcie każdą drogą, którąm wam przykazał, aby wam dobrze było.
Mo pàṣẹ fún wọn báyìí pé; gbọ́ tèmi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi. Máa rìn ní ojú ọ̀nà tí mo pàṣẹ fún yín, kí ó lè dára fún yín.
24 Lecz nie posłuchali, ani nakłonili ucha swego, aby chodzili za radami i za uporem serca swego złego; i obrócili się grzbietem, a nie twarzą.
Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, wọn kò sì fetísílẹ̀ dípò èyí wọ́n ń tẹ̀ sí ọ̀nà agídí ọkàn wọn. Dípò kí wọn tẹ̀síwájú wọ́n ń rẹ̀yìn.
25 Ode dnia, którego wyszli ojcowie wasi z ziemi egipskiej, aż do dnia tego, posyłałem do was wszystkich sług moich proroków, co dzień rano wstawając i posyłając;
Láti ìgbà tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní Ejibiti títí di òní, ni èmi ti ń rán àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì sí yín.
26 A wszakże nie słuchali mię, i nie nakłonili ucha swego, ale zatwardziwszy kark swój, gorzej czynili niźeli ojcowie ich.
Wọn kò gbọ́ wọn kò sì fetísílẹ̀. Wọ́n wa ọrùn le, wọn wa ọrùn kì, wọ́n sì hu ìwà ìbàjẹ́ ju àwọn baba ńlá wọn.’
27 Gdy im będziesz mówił te wszystkie słowa, i ciebie nie usłuchają; a gdy na nich wołać będziesz, nie ozwąć się.
“Nígbà tí ìwọ bá sọ gbogbo èyí fún wọn, wọn kì yóò gbọ́ tirẹ̀, nígbà tí ìwọ bá sì pè wọ́n, wọn kì yóò dáhùn.
28 Przetoż mów do nich: Ten jest naród, który nie słucha głosu Pana, Boga swego, ani przyjmuje nauki; zginęła prawda, i odjęta jest od ust ich.
Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ tàbí kí ó ṣe ìgbọ́ràn sí ìbáwí. Ọ̀rọ̀ òtítọ́ kò sí ní ètè wọn.
29 Ogól włosy swe i odrzuć, a narzekaj głośno na miejscach wysokich; bo odrzucił Pan i opuścił rodzaj, na który się bardzo gniewa.
“‘Gé irun yín kí ẹ sì dàánù, pohùnréré ẹkún lórí òkè, nítorí Olúwa ti kọ ìran yìí tí ó wà lábẹ́ ìbínú rẹ̀ sílẹ̀.
30 Zaiste synowie Judzcy czynili złość przed oczyma mojemi, mówi Pan; nastawiali obrzydliwości swych w tym domu, który nazwany jest od imienia mojego, aby go splugawili.
“‘Àwọn ènìyàn Juda ti ṣe búburú lójú mi, ni Olúwa wí. Wọ́n ti to àwọn ère ìríra wọn jọ sí ilé tí a fi orúkọ mi pè wọ́n sì ti sọ ọ́ di àìmọ́.
31 Nadto pobudowali wyżyny Tofet, które jest w dolinie syna Hennomowego, aby palili synów swych i córki swe ogniem, czegom nie rozkazał, ani wstąpiło na serce moje.
Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga ti Tofeti ní àfonífojì Beni-Hinnomu láti sun àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn nínú iná èyí tí èmi kò pàṣẹ tí kò sì wá sí ọkàn mi.
32 Dlatego oto dni idą, mówi Pan, gdy to więcej nie będzie zwano Tofet, ani dolina syna Hennomowego, ale dolina morderstwa; i będą pogrzebywać w Tofet; bo indziej miejsca nie będzie.
Nítorí náà kíyèsára ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí, nígbà tí àwọn ènìyàn kò ní pè é ní Tafeti tàbí àfonífojì ti Beni-Hinnomu; ṣùgbọ́n yóò ma jẹ àfonífojì ìparun, nítorí wọn yóò sin òkú sí Tofeti títí kò fi ní sí ààyè mọ́.
33 I będą trupy ludu tego pokarmem ptastwu niebieskiemu, i zwierzowi ziemskiemu, a nie będzie, ktoby odegnał.
Nígbà náà ni òkú àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀, kò sì ní sí ẹnìkan tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
34 I uczynię, że ustanie w miastach Judzkich, i w ulicach Jeruzalemskich głos radości, i głos wesela, głos oblubieńca, i głos oblubienicy; bo ziemia będzie spustoszona.
Èmi yóò mú òpin bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú àti ohùn àwọn tọkọtaya ní àwọn ìlú Juda àti ní ìgboro Jerusalẹmu, nítorí tí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.

< Jeremiasza 7 >