< Jeremiasza 51 >

1 Tak mówi Pan: Oto Ja wzbudzę przeciwko Babilonowi, i przeciwko tym, którzy mieszkają w pośród powstawających przeciwko mnie, wiatr zaraźliwy;
Ohùn ti Olúwa wí nìyìí: “Wò ó èmi yóò ru afẹ́fẹ́ apanirun sókè sí Babeli àti àwọn ènìyàn Lebikamai,
2 I poślę na Babiilon przewiewaczy, którzy go przewiewać będą, i wypróżnią ziemię jego, gdyż będą przeciwko niemu zewsząd w dzień ucisku.
Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn sí Babeli láti fẹ́ ẹ, tí yóò sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di òfo; wọn yóò takò ó ní gbogbo ọ̀nà ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.
3 Do tego, który mocno ciągnie łuk swój, a postępuje w pancerzu swoim, rzekę: Nie folgujcie młodzieńcom jego, wygładźcie wszystko wojsko jego.
Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀, jáde tàbí kí ó di ìhámọ́ra rẹ̀. Má ṣe dá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sí; pátápátá ni kí o pa àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
4 Niech polegną pobici w ziemi Chaldejskiej, a poprzebijani po ulicach jego.
Gbogbo wọn ni yóò ṣubú ní Babeli, tí wọn yóò sì fi ara pa yánnayànna ní òpópónà.
5 Bo nie jest opuszczony Izrael i Juda od Boga swego, od Pana zastępów, choć ziemia ich pełna jest przestępstwa przeciwko Świętemu Izraelskiemu.
Nítorí pé Juda àti Israẹli ni Ọlọ́run wọn tí í ṣe Olúwa àwọn ọmọ-ogun, kò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọn kún fún kìkì ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Israẹli.
6 Uciekajcie z pośrodku Babilonu, a niech zachowa każdy duszę swoję, abyście nie byli zatraceni w nieprawości jego; bo czas będzie pomsty Pańskiej, sam mu zapłatę odda.
“Sá kúrò ní Babeli! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Àsìkò àti gbẹ̀san Olúwa ni èyí; yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.
7 Byłci Babilon kubkiem złotym w ręce Pańskiej, upajającym wszystkę ziemię; wino jego piły narody, dlatego poszalały narody;
Ife wúrà ni Babeli ní ọwọ́ Olúwa; ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí. Gbogbo orílẹ̀-èdè mu ọtí rẹ̀, wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.
8 Ale nagle upadnie Babilon, i starty będzie; rozkwilcie się nad nim, nabierzcie olejku balsamowego dla boleści jego, owa się wyleczy.
Babeli yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́. Ẹ hu fun un! Ẹ mú ìkunra fún ìrora rẹ, bóyá yóò le wo ọ́ sàn.
9 Leczyliśmy Babilon, ale nie jest uleczony. Opuśćmyż go, a pójdźmy każdy do ziemi swej; bo sąd jego aż do nieba sięga, i wyniósł się aż pod obłoki.
“‘À bá ti wo Babeli sàn, ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀, kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè, ó ga àní títí dé òfúrufú.’
10 Wywiódł Pan sprawiedliwości nasze. Pójdźcie, a opowiadajmy na Syonie dzieło Pana, Boga naszego.
“‘Olúwa ti dá wa láre, wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Sioni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa ti ṣe.’
11 Wyostrzcie strzały, sporządżcie tarcze. Wzbudził Pan ducha królów Medskich; bo przeciwko Babilonowi zamysł jego, aby go wytracił, gdyż pomsta Pańska jest pomsta kościoła jego.
“Ṣe ọfà rẹ ní mímú, mú àpáta! Olúwa ti ru ọba Media sókè, nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Babeli run. Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
12 Podnieście chorągiew na murach Babilońskich, przyczyńcie straży, postawcie stróżów, nagotujcie zasadzki; bo i umyślił Pan i wykona, co wyrzekł przeciwko obywatelom Babilońskim.
Gbé àsíá sókè sí odi Babeli! Ẹ ṣe àwọn ọmọ-ogun gírí, ẹ pín àwọn olùṣọ́ káàkiri, ẹ ṣètò àwọn tí yóò sá pamọ́ Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde, òfin rẹ̀ sí àwọn ará Babeli.
13 O ty, który mieszkasz nad wodami wielkiemi! o bogaty w skarby! przyszedł koniec twój, kres łakomstwa twego.
Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀, tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé, àní àsìkò láti ké ọ kúrò!
14 Przysiągł Pan zastępów na duszę swoję, że cię napełni ludźmi, jako chrząszczami, którzy uczynią nad tobą okrzyk wojenny.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀, Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú, wọn yóò yọ ayọ̀, ìṣẹ́gun lórí rẹ.
15 Onci to jest, który uczynił ziemię mocą swoją, który utwierdził okrąg świata mądrością swoją, i roztropnością swoją rozpostarł niebiosa;
“Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀, o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.
16 Który gdy głos wypuszcza, wody na niebie szumią, a który sprawuje, aby występowały pary od kończyn ziemi, i błyskawice ze dżdżem przywodzi, a wywodzi wiatr z skarbów swoich.
Nígbà tí ará omi ọ̀run hó ó mú kí òfúrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.
17 Tak zgłupiał każdy człowiek, że tego nie zna, że pohańbiony bywa złotnik od obrazu rytego; bo kłamstwem jest ulanie jego, a niemasz w nich ducha.
“Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọ tí kò sì ní ìmọ̀, olúkúlùkù alágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀. Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn; wọn kò ní èémí nínú.
18 Marnością są a dzieło błędów; zginą czasu nawiedzenia swego.
Asán ni wọ́n, àti iṣẹ́ ìsìnà, nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn ó ṣègbé.
19 Nie takowyć jest dział Jakóbowy; bo on jest który wszystko stworzył, a Izrael jest prętem dziedzictwa jego; Pan zastępów imię jego.
Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jakọbu kó rí bí ìwọ̀nyí; nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo, àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
20 Młotemeś ty moim kruszącym, orężem wojennym, abym pokruszył przez cię narody, i poburzył przez cię królestwa;
“Ìwọ ni kùmọ̀ ogun ohun èlò ogun mi, ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀-èdè túútúú, èmi ó bà àwọn ilé ọba jẹ́.
21 Abym pokruszył przez cię konia i jezdnego, abym pokruszył przez cię wóz i tego, co na nim jeździ;
Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀; èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lú èmi ó pa awakọ̀,
22 Abym pokruszył przez cię męża i niewiastę, abym pokruszył przez cię starca i dziecię, abym pokruszył przez cię młodzieńca i pannę;
pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin, pẹ̀lú rẹ, mo pa àgbàlagbà àti ọmọdé, pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.
23 Abym pokruszył przez cię pasterza i trzodę jego, abym pokruszył przez cię oracza, i sprzężaj jego, abym pokruszył przez cię książąt i hetmanów.
Èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ olùṣọ́-àgùntàn, àti agbo àgùntàn rẹ̀ túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ àgbẹ̀ àti àjàgà màlúù túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ túútúú.
24 Ale już oddam Babilonowi, i wszystkim obywatelom Chaldejskim za wszystkie złości ich, które czynili Syonowi przed oczyma waszemi, mówi Pan.
“Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Babeli àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Sioni,” ni Olúwa wí.
25 Otom Ja jest przeciwko tobie, o góro każąca! mówi Pan, która kazisz wszystkę ziemię, i wyciągnę rękę moję przeciwko tobie, a zwalę cię z skał, i uczynię cię górą spalenia;
“Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirun ìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,” ni Olúwa wí. “Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ, èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta, Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.
26 A nie wezmą z ciebie kamienia do węgła, ani kamienia do gruntów; bo pustynią wieczną będziesz, mówi Pan.
A kò ní mú òkúta kankan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbí fún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò di ahoro títí ayé,” ní Olúwa wí.
27 Podnieście chorągiew w ziemi, trąbcie w trąbę między narodami, zgotujcie przeciwko niemu narody, zwołajcie przeciwko niemu królestwa Ararad, Minny, i Aschenas; postanówcie przeciwko niemu hetmana, przywiedźcie konie jako chrząszcze najeżone;
“Gbé àsíá sókè ní ilẹ̀ náà! Fọn ìpè láàrín àwọn orílẹ̀-èdè! Sọ àwọn orílẹ̀-èdè di mímọ́ sórí rẹ̀, pe àwọn ìjọba yìí láti dojúkọ ọ́: Ararati, Minini àti Aṣkenasi. Yan olùdarí ogun láti kọlù ú, rán àwọn ẹṣin sí i bí ọ̀pọ̀ eṣú.
28 Zgotujcie przeciwko niemu narody, królów Medskich, książąt ich, i wszystkich hetmanów ich, ze wszystką ziemią władzy ich;
Sọ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú àwọn ọba Media di mímọ́ sórí rẹ̀, àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ ọba lé lórí.
29 Tedy zadrży ziemia, i rozboleje się, gdy wykonane będą przeciwko Babilonowi myśli Pańskie, aby obrócił ziemię Babilońską w pustynię, aby została bez obywatela.
Ilẹ̀ wárìrì síyìn-ín sọ́hùn-ún, nítorí pé ète Olúwa, sí Babeli dúró, láti ba ilẹ̀ Babeli jẹ́ lọ́nà tí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.
30 Przestaną mocarze Babilońscy walczyć, usiądą w zamkach, ustanie męstwo ich, będą jako niewiasty; zapali mieszkania ich, pokruszone będą zawory ich.
Gbogbo àwọn jagunjagun Babeli tó dáwọ́ ìjà dúró sínú àgọ́ wọn. Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin. Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun, gbogbo irin ẹnu-ọ̀nà wọn ti di fífọ́.
31 Goniec spotka drugiego gońca, a poseł zabieży posłowi, aby opowiedzieli królowi Babilońskiemu, iż wzięto miasto jego z jednej strony,
Ìránṣẹ́ kan ń tẹ̀lé òmíràn láti sọ fún ọba Babeli pé gbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.
32 A iż brody ubieżono, i jeziora wypalano ogniem, a mężowie waleczni ustraszeni są.
Odò tí ó sàn kọjá kò sàn mọ́ ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”
33 Bo tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski: Córka Babilońska jest jako bojewisko, czas deptania jej przyszedł; jeszcze maluczko, a przyjdzie czas żniwa jej.
Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli sọ nìyìí: “Ọmọbìnrin Babeli dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”
34 Pożarł mię, potarł mię Nabuchodonozor, król Babiloński, uczynił mię naczyniem próżnem, połknął mię jako smok, napełnił brzuch swój rozkoszami mojemi, i wygnał mię.
“Nebukadnessari ọba Babeli tó jẹ wá run, ó ti mú kí ìdààmú bá wa, ó ti sọ wá di àgbá òfìfo. Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì. Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀, lẹ́yìn náà ni ó pọ̀ wá jáde.
35 Gwałt mnie i ciału memu uczyniony niech przyjdzie na Babilon, mówi obywatelka Syońska, a krew moja na obywateli Chaldejskich, mówi Jeruzalem.
Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe sí ẹran-ara wa wà lórí Babeli,” èyí tí àwọn ibùgbé Sioni wí. “Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogbo àwọn tí ń gbé Babeli,” ni Jerusalẹmu wí.
36 Przetoż tak mówi Pan: Oto się Ja zastawię o krzywdę twoję, a pomszczę się za cię; bo wysuszę morze jego, wysuszę i źródła jego.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lórí ohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san, èmi yóò mú kí omi Òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.
37 I będzie Babilon obrócony w mogiły, w mieszkanie smoków, w zdumienie, i w poświstanie, i będzie bez obywatela.
Babeli yóò parun pátápátá, yóò sì di ihò àwọn akátá, ohun ẹ̀rù àti àbùkù, ibi tí ènìyàn kò gbé.
38 Pospołu jako lwy ryczeć będą, a skomleć jako szczenięta lwie.
Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramù bí ọmọ kìnnìún.
39 Gdy się zapalą, uczynię im ucztę, i tak ich upoję, że krzyczeć i snem wiecznym zasnąć muszą, tak, aby nie ocucili, mówi Pan.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè, èmi yóò ṣe àsè fún wọn, èmi yóò jẹ́ kí wọn mutí yó tí wọn yóò máa kọ fun ẹ̀rín, lẹ́yìn náà, wọn yóò sun oorun, wọn kì yóò jí,” ni Olúwa wí.
40 Powiodę ich jako baranki ku zabiciu, jako barany i kozły.
“Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn tí a fẹ́ pa, gẹ́gẹ́ bí àgbò àti ewúrẹ́.
41 Jakożby dobyty mógł być Sesach? Jakożby wzięta być mogła chwała wszystkiej ziemi? Jakożby mógł przyjść na spustoszenie Babilon między narodami?
“Báwo ni Ṣeṣaki yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé. Irú ìpayà wo ni yóò bá Babeli láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!
42 Wystąpi przeciwko Babilonowi morze, mnóstwem wałów jego okryte będzie.
Òkun yóò ru borí Babeli, gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Babeli.
43 Miasta jego będą spustoszeniem, ziemią suchą i pustą, ziemią, w której miastach nikt nie będzie mieszkał, ani będzie chodził przez nią syn człowieczy.
Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro, ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.
44 Nawiedzę też Bela w Babilonie, i wydrę, co był połknął, z gęby jego; i nie będą się więcej do niego zbiegać narody, i mury także Babilońskie upadną.
Èmi yóò fi ìyà jẹ Beli ti Babeli àti pé èmi yóò jẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì. Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò jùmọ̀ sàn lọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ mọ́. Ní òótọ́ odi Babeli yóò sì wó.
45 Wyjdźcie z pośrodku jego, ludu mój! a wybaw każdy duszę swoję przed gniewem zapalczywości Pańskiej.
“Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ ẹ̀yin ènìyàn mi! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Sá fún ìbínú ńlá Olúwa.
46 A nie bądźcie miękkiego serca, ani się lękajcie wieści, którą będzie słychać w tej ziemi; gdy przyjdzie jednego roku nowina, potem drugiego roku wieść i gwałt w ziemi, a pan na pana.
Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrú tàbí kí o bẹ̀rù nígbà tí a bá gbọ́ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa; àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí, òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipá ní ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.
47 Przetoż oto dni przyjdą, w które Ja nawiedzę bałwany ryte Babilońskie, a wszystka ziemia jego pohańbiona będzie, i wszyscy pobici jego polegną w pośrodku niego.
Nítorí ìgbà náà yóò wá dandan nígbà tí èmi yóò fi ìyà jẹ àwọn òrìṣà Babeli; gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó dójútì gbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárín rẹ̀.
48 I będą nad Babilonem śpiewać niebiosa i ziemia, i wszystko, co na nich jest, gdy z północy przyjdą nań pustoszyciele, mówi Pan.
Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn, yóò sì kọrin lórí Babeli: nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,” ni Olúwa wí.
49 Jako Babilon poraził onych pobitych Izraelskich, tak z Babilonu polegną pobici po wszystkiej ziemi.
“Babiloni gbọdọ̀ ṣubú nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni Israẹli, gẹ́gẹ́ bí àwọn ti a pa ní gbogbo ayé nítorí Babeli.
50 O którzyście uszli miecza, idźcie, nie stójcie! wspominajcie z daleka na Pana, a Jeruzalem niech wstępuje na serce wasze.
Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró. Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè, ẹ sì jẹ́ kí Jerusalẹmu wá sí ọkàn yín.”
51 Rzeczcie: Wstydzimy się, że słyszymy urąganie; hańba okryła twarzy nasze, bo cudzoziemcy wchodzą do świątnic domu Pańskiego.
“Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn: ìtìjú ti bò wá lójú nítorí àwọn àjèjì wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”
52 Przetoż oto dni przychodzą, mówi Pan, że nawiedzę ryte bałwany jego, a po wszystkiej ziemi jego zraniony stękać będzie.
“Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fínfín rẹ̀, àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa kérora já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀.
53 Chociażby Babilon wstąpił na niebo, i obwarował na wysokości moc swoję, przecie odemnie przyjdą pustoszyciele jego, mówi Pan.
Bí Babeli tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run, bí ó sì ṣe ìlú olódi ní òkè agbára rẹ, síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,” ní Olúwa wí.
54 Głos wołania z Babilonu, a starcie wielkie z ziemi Chaldejskiej;
“Ìró igbe láti Babeli, àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kaldea!
55 Bo Pan Babilon zburzy i wytraci z niego głos wielki, choćby huczały wały ich jako wody wielkie, i wydany był szum głosu ich.
Nítorí pé Olúwa ti ṣe Babeli ní ìjẹ, ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀; àwọn ọ̀tá wọn sì ń hó bi omi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.
56 Gdy nań, to jest na Babilon, pustoszyciel przyciągnie pojmani będą mocarze jego, pokruszone będą łuki ich; bo Bóg nagrody, Pan nagrodzi im sowicie;
Nítorí pé afiniṣèjẹ dé sórí rẹ̀, àní sórí Babeli; a mú àwọn akọni rẹ̀, a ṣẹ́ gbogbo ọrun wọn: nítorí Ọlọ́run ẹ̀san ni Olúwa, yóò san án nítòótọ́.
57 Opoi książąt jego i mędrców jego, wodzów jego, i urzędników jego, i mocarzy jego, aby zasnęli snem wiecznym, a nie ocucili, mówi król, Pan zastępów imię jego.
Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí, àti àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀ àti àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti àwọn akọni rẹ̀, wọn ó sì sun oorun láéláé, wọn kì ó sì jí mọ́,” ní ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
58 Tak mówi Pan zastępów: Mur Babiloński szeroki do gruntu zburzony będzie, i bramy jego wysokie ogniem spalone będą, a ludzie darmo pracować będą, a narody przy ogniu pomdleją.
Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Odi Babeli gbígbòòrò ní a ó wó lulẹ̀ pátápátá, ẹnu-bodè gíga rẹ̀ ní a ó sì fi iná sun: tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn ti ṣiṣẹ́ lásán, àti àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣiṣẹ́ fún iná, tí àárẹ̀ sì mú wọn.”
59 Toć jest słowo, które rozkazał Jeremijasz prorok Sarajaszowi, synowi Neryjasza, syna Maasejaszowego, gdy odszedł od Sedekijasza, króla Judzkiego, do Babilonu, roku czwartego królowania jego; (a Sarajasz był książęciem w Menucha.)
Ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì pàṣẹ fún Seraiah, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, nígbà tí o ń lọ ni ti Sedekiah, ọba Juda, sí Babeli ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Seraiah yìí sì ní ìjòyè ibùdó.
60 Gdy zapisał Jeremijasz wszystko złe, które przyjść miało na Babilon, w księgi jedne, wszystkie te słowa, które są napisane przeciwko Babilonowi.
Jeremiah sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Babeli sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí a kọ sí Babeli.
61 I rzekł Jeremijasz do Sarajasza: Gdy przyjdziesz do Babilonu, i oglądasz go, tedy przeczytasz te wszystkie słowa,
Jeremiah sì sọ fún Seraiah pé, “Nígbà tí ìwọ bá dé Babeli, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
62 A rzeczesz: O Panie! tyś mówił przeciwko miejscu temu, że je wytracisz, aby w niem nie mieszkał nikt, ani z ludzi ani z bydląt, ale żeby było pustkami wiecznemi.
Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’
63 A gdy do końca przeczytasz te księgi, przywiążesz do nich kamień, i wrzucisz je w pośród Eufratesa,
Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárín odò Eufurate.
64 A rzeczesz: Tak zatopiony będzie Babilon, a nie powstanie więcej z tego złego, które Ja nań przywiodę, choć ustawać będą. Aż dotąd słowa Jeremijaszowe.
Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Babeli yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’” Títí dé ìhín ni ọ̀rọ̀ Jeremiah.

< Jeremiasza 51 >