< Jeremiasza 5 >

1 Obchodźcie ulice Jeruzalemskie, a upatrujcie teraz, i obaczcie, a szukajcie po ulicach jego, jeźli znajdziecie męża, jeźli kto jest coby czynił sąd i szukał prawdy, a przepuszczę mu.
“Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
2 Ale choć mówią: Jako żyje Pan, tedy przecię krzywo przysięgają.
Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
3 O Panie! izali oczy twoje nie patrzą na prawdę? Bijesz ich, ale ich nie boli; wniwecz ich obracasz, ale nie chcą przyjąć karania; zatwardzili oblicza swe nad opokę, nie chcą się nawrócić.
Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
4 Tedym Ja rzekł: Podobno ci nędzni są, głupio sobie poczynają; bo nie są powiadomi drogi Pańskiej, i sądu Boga swego.
Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
5 Pójdę do celniejszych, i będę mówił do nich; bo oni są powiadomi drogi Pańskiej, i sądu Boga swego; ale i ci wespół połamali jarzmo, potargali związki.
Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
6 Przetoż ich pobije lew z lasu, wilk wieczorny wygubi ich, lampart czyhać będzie u miast ich. Ktokolwiek wyjdzie z nich, rozszarpany będzie; bo się rozmnożyły przestępstwa ich, i zmogły się odwrócenia ich.
Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
7 Jestże co, dlaczegobym ci miał przepuścić? Synowie twoi opuścili mię, a przysięgają przez onych, którzy nie są bogami. Jakom ich jedno nakarmił, zaraz cudzołożą, a do domu wszetecznicy hurmem się walą.
“Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
8 Rano wstawając są jako konie wytuczone, każdy z nich rży do żony bliźniego swego.
Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
9 Izali dlatego nawiedzić ich nie mam? mówi Pan; izali się nad takim narodem nie ma mścić dusza moja?
Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
10 Wstąpcie na mury jego, a rozwalcie je, wszakże ich do gruntu nie znoście; znieście filarzyki murów jego, gdyż nie są Pańskie.
“Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
11 Wielce zaiste wystąpił przeciwko mnie dom Izraelski i dom Judzki, mówi Pan.
Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
12 Zadali kłamstwo Panu, i rzekli: Nie tak, nie przyjdzieć na nas nic złego, a miecza i głodu nie doznamy.
Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
13 A ci prorocy pominą z wiatrem, a żadnego słowa Bożego niemasz u nich; i owszem tak się im samym stanie.
Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
14 Przetoż tak mówi Pan, Bóg zastępów: Ponieważeście to mówili, oto Ja kładę słowa moje w usta twoje za ogień, a lud ten za drwa, i pożre ich.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
15 Oto Ja przywiodę na was naród z daleka, o domie Izraelski! mówi Pan, naród mocny, naród starodawny, naród, którego języka umieć nie będziesz, ani zrozumiesz, co mówi.
Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
16 Którego sajdak jako grób otwarty, wszyscy są mężni.
Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
17 I zjedzą urodzaj twój, i chleb twój: pożrą synów twoich i córki twoje; poje trzody twoje i woły twoje; poje winną macicę twoję, i figi twoje, a miasta twoje obronne, w których ty ufasz, mieczem znędzi.
Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
18 A wszakże i w one dni, mówi Pan, końca z wami nie uczynię.
“Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
19 Albowiem gdy rzeczecie: Przeczże nam Pan, Bóg nasz, to wszystko czyni? Tedy im odpowiesz: Jakoście mię opuścili, a służyli bogom cudzym w ziemi waszej, tak służyć będziecie cudzoziemcom w ziemi nie waszej.
Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
20 Oznajmijcie to domowi Jakóbowemu, a rozgłoście w Judzie, mówiąc:
“Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
21 Słuchajcież teraz tego, ludu głupi! który niemasz serca, który oczy mając, a nie widzisz, który uszy mając, a nie słyszysz.
Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
22 I nie będziecież się mnie bali? mówi Pan; a przed obliczem mojem nie będziecież się lękali? którym położył morzu piasek za granicę ustawą wieczną, a nie przestąpi jej. Choć się wzruszą, wszakże nie przemogą; choć się wzburzą wały jego, wszakże nie przeskoczą go.
Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
23 Ale ten lud ma serce ociążałe i odporne; odstąpili odemnie i odeszli;
Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
24 Ani rzekli w sercu swem: Bójmy się już Pana, Boga naszego, który daje deszcz i w jesieni i na wiosnę czasu swego, który tygodni pewnych i żniwa naszego przestrzega.
Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
25 Ale nieprawości wasze odwróciły to, a grzechy wasze zahamowały to dobro od was.
Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
26 Bo się znajdują w ludu moim niezbożnicy, którzy czyhają jako łowcy, rozciągają sieci, zastawiają sidła, a łapią ludzi.
“Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
27 Jako klatka pełna ptaków, tak domy ich pełne są zdrady; przetoż się wzmogli i zbogacili.
Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
28 Roztyli, lśnią się, i innych w złościach przewyższają; sprawy nie sądzą, ani sprawy sierotki; wszakże się im szczęści, chociaż sprawy ubogiego nie rozsądzili.
wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
29 Izali dlatego nie nawiedzę ich? mówi Pan; izali się nad narodem takowym nie będzie mścić dusza moja?
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
30 Rzecz dziwna i sroga dzieje się w tej ziemi:
“Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
31 Prorocy kłamliwie prorokują, a kapłani panują przez ręce ich, a lud mój kocha się w tem; czegożbyście na ostatek nie uczynili?
Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?

< Jeremiasza 5 >