< Jeremiasza 38 >

1 I usłyszał Sefatyjasz, syn Matanowy, i Godolijasz, syn Fassurowy, i Juchal, syn Selemijaszowy, i Fassur, syn Melchijaszowy, słowa, które Jeremijasz mówił do wszystkiego ludu, mówiąc:
Ṣefatia ọmọ Mattani, Gedaliah ọmọ Paṣuri, Jehukali ọmọ Ṣelemiah, àti Paṣuri ọmọ Malkiah, gbọ́ ohun tí Jeremiah ń sọ fún àwọn ènìyàn nígbà tí ó sọ wí pé,
2 Tak mówi Pan: Ktoby został w tem mieście, zginie od miecza, od głodu i od moru; ale ktoby wyszedł do Chaldejczyków, żyć będzie, a będzie mu dusza jego za korzyść, i żyw zostanie.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Ẹnikẹ́ni tó bá dúró nínú ìlú yìí yóò kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn; ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tó bá lọ sí Babeli yóò yè; yóò sá àsálà, yóò sì yè.’
3 Tak mówi Pan: Pewnie podane będzie to miasto w ręce wojska króla Babilońskiego, i weźmie je.
Àti pé èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Ìdánilójú wà wí pé a ó fi ìlú náà lé ọwọ́ àwọn ọmọ-ogun ọba Babeli; tí yóò sì kó wa nígbèkùn.’”
4 Przetoż rzekli oni książęta do króla: Niech umrze ten mąż, ponieważ on osłabia ręce mężów walecznych, pozostałych w tem mieście, i ręce wszystkiego ludu, mówiąc do nich takie słowa; albowiem ten mąż nie szuka pokoju ludowi temu, ale złego.
Nígbà náà ni àwọn ìjòyè wí fún ọba pé, “Ó yẹ kí a pa ọkùnrin yìí; ó ń kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ-ogun tókù nínú ìlú pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn nípa ohun tí ó ń sọ fún wọn. Ọkùnrin yìí kò fẹ́ ìre fún àwọn ènìyàn bí kò ṣe ìparun.”
5 Tedy rzekł król Sedekijasz: Oto jest w ręce waszej; bo król nic zgoła nie może przeciwko wam.
Sedekiah ọba sì wí pé, “Ó wà lọ́wọ́ yín. Ọba kò lè ṣe ohunkóhun láti takò yín.”
6 A tak wzięli Jeremijasza, który był w sieni straży, i wrzucili go do dołu Malchyjasza, syna królewskiego, i puścili Jeremijasza po powrozach; a w tym dole nie było nic wody, tylko błoto, a tak tonął Jeremijasz w onem błocie.
Wọ́n gbé Jeremiah sọ sínú ihò Malkiah, ọmọ ọba, tí ó wà ní àgbàlá ilé túbú; wọ́n fi okùn sọ Jeremiah kalẹ̀ sí ìsàlẹ̀ ihò; kò sì ṣí omi nínú ihò náà bí kò ṣe ẹrọ̀fọ̀, Jeremiah sì rì sínú ẹrọ̀fọ̀ náà.
7 Ale gdy usłyszał Ebedmelech Murzyn, dworzanin, który był w domu królewskim, że Jeremijasza podano do dołu, (a król siedział w bramie Benjaminowej, )
Ṣùgbọ́n, Ebedimeleki, ará Kuṣi ìjòyè nínú ààfin ọba gbọ́ pé wọ́n ti ju Jeremiah sínú kànga. Nígbà tí ọba jókòó ní ẹnu-bodè Benjamini.
8 Wnet wyszedł Ebedmelech z domu królewskiego, i rzekł do króla, mówiąc:
Ebedimeleki jáde kúrò láàfin ọba, ó sì sọ fún un pé,
9 Królu, panie mój! źle uczynili ci mężowie wszystko, co uczynili Jeremijaszowi prorokowi, że go wrzucili do tego dołu; boćby był umarł na pierwszem miejscu od głodu, ponieważ już niemasz żadnego chleba w mieście.
“Olúwa mi ọba, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti ṣe ohun búburú sí Jeremiah wòlíì Ọlọ́run. Wọ́n ti gbé e sọ sínú kànga níbi tí kò sí oúnjẹ kankan nínú ìlú mọ́.”
10 Przetoż rozkazał król Ebedmelechowi Murzynowi, mówiąc: Weźmij z sobą stąd trzydzieści mężów, a wyciągnij Jeremijasza proroka z tego dołu, niżby umarł.
Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Ebedimeleki ará Kuṣi pé, “Mú ọgbọ̀n ọkùnrin láti ibí pẹ̀lú rẹ, kí ẹ sì fa wòlíì Jeremiah sókè láti inú ihò, kí ó tó kú.”
11 Tedy wziął Ebedmelech onych mężów z sobą, i wszedł do domu królewskiego pod skarbnicę, i nabrał stamtąd starych szmacisk podartych, szmacisk, mówię, zbótwiałych, które spuścił do Jeremijasza do onego dołu po powrozach.
Ebedimeleki kó àwọn ọkùnrin náà pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n lọ sínú yàrá kan nínú ààfin ọba. Ó mú àwọn aṣọ àkísà àti okùn tọ Jeremiah lọ nínú kànga.
12 I rzekł Ebidmelech Murzyn do Jeremijasza: Nuże podłóż te stare podarte i zbótwiałe szmaciska pod pachy rąk twoich pod powrozy; i uczynił tak Jeremijasz.
Ebedimeleki ará Kuṣi sọ fún Jeremiah pé, “Fi àkísà àti okùn bọ abẹ́ abíyá rẹ, Jeremiah sì ṣe bẹ́ẹ̀.”
13 I wyciągnęli tedy Jeremijasza powrozami, i dobyli go z onego dołu; i siedział Jeremijasz w sieni straży.
Báyìí ni wọ́n ṣe fi okùn yọ Jeremiah jáde, wọ́n sì mu un gòkè láti inú ihò wá, Jeremiah sì wà ní àgbàlá ilé túbú.
14 Tedy posłał król Sedekijasz i wziął Jeremijasza proroka do siebie do trzecich drzwi, które były przy domu Pańskim. I rzekł król Jeremijaszowi: Spytam cię o jednę rzecz, nie taj nic przedemną.
Nígbà náà ni ọba Sedekiah ránṣẹ́ pe, Jeremiah òjíṣẹ́ Ọlọ́run àti láti mú un wá sí ẹnu ibodè kẹta nílé Olúwa. Ọba sì sọ fún Jeremiah pé, “Èmi yóò bi ọ́ ní ohun kan; má sì ṣe fi ohun kan pamọ́ fún mi.”
15 I rzekł Jeremijasz do króla Sedekijasza: Jeźlić co powiem, pewnie mię zabijesz? A jeźlić co poradzę, nie usłuchasz mię.
Jeremiah sì sọ fún Sedekiah pé, “Tí mo bá fún ọ ní èsì, ṣé o kò nípa mí? Tí mo bá gbà ọ́ nímọ̀ràn, o kò ní gbọ́ tèmi.”
16 Tedy przysiągł król Sedekijasz Jeremijaszowi potajemnie, mówiąc: Jeko żyje Pan, który nam tę duszę stworzył, że cię nie zabiję, ani cię wydam w rękę mężów tych, którzy szukają duszy twojej.
Ṣùgbọ́n ọba Sedekiah búra ní ìkọ̀kọ̀ fún Jeremiah wí pé, “Dájúdájú bí Olúwa ti ń bẹ, ẹni tí ó fún wa ní ẹ̀mí, èmi kò nípa ọ́ tàbí fà ọ́ fún àwọn tó ń lépa ẹ̀mí rẹ.”
17 I rzekł Jeremijasz do Sedekijasza: Tak mówi Pan, Bóg zastępów, Bóg Izraelski: Jeźli dobrowolnie wynijdziesz do książąt króla Babilońskiego, tedy żyć będzie dusza twoja, a to miasto nie będzie spalone ogniem; a tak żyw zostaniesz ty i dom twój;
Nígbà náà ni Jeremiah sọ fún Sedekiah pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Àyàfi bí o bá jọ̀wọ́ ara rẹ fún àwọn olóyè ọba Babeli, a ó dá ẹ̀mí rẹ sí àti pé ìlú yìí kò ní di jíjó ní iná; ìwọ àti ilé rẹ yóò sì wà láààyè.
18 Ale jeźli nie wynijdziesz do książąt króla Babilońskiego, pewnie będzie podane to miasto w rękę Chaldejczyków, i spalą je ogniem, a i ty nie ujdziesz ręki ich.
Ṣùgbọ́n tí o kò bá jọ̀wọ́ ara rẹ fún àwọn ìjòyè ọba Babeli, a ó fa ìlú yìí lé ọwọ́ àwọn Babeli. Wọn yóò sì fi iná sun ún, ìwọ gan an kò ní le sá mọ́ wọn lọ́wọ́.’”
19 Tedy rzekł król Sedekijasz do Jeremijasza: Bardzo się boję Żydów, którzy pouciekali do Chaldejczyków, bym snać nie był wydany w rękę ich, a szydziliby ze mnie.
Ọba Sedekiah sọ fún Jeremiah pé, “Mò ń bẹ̀rù àwọn Júù tó ti sálọ sí ilẹ̀ Babeli, nítorí pé àwọn ará Babeli lè fà mí lé wọn lọ́wọ́ láti fìyà jẹ mí.”
20 I rzekł Jeremijasz: Nie wydadzą, słuchaj proszę głosu Pańskiego, któryć ja opowiadam, a będzieć dobrze, i żyć będzie dusza twoja;
Jeremiah sì dáhùn wí pé, “Wọn kò ní fi ọ́ lé e lọ́wọ́. Pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́ nípa ṣíṣe ohun tí mo sọ fún ọ; yóò sì dára fún ọ, ẹ̀mí rẹ yóò sì wà.
21 A jeźli się będziesz zbraniał wynijść, tedy to jest słowo, które mi Pan pokazał:
Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá kọ̀ láti jọ̀wọ́ ara rẹ, èyí ni ohun tí Olúwa ti fihàn mí.
22 Że oto wszystkie niewiasty, które zostały w domu króla Judzkiego, będą wywiedzione do książąt króla Babilońskiego, a te same rzeką: Namówili cię, i otrzymali to na tobie przyjaciele twoi, że ulgnęły w błocie nogi twoje, i cofnęły się nazad.
Gbogbo àwọn obìnrin tókù ní ààfin ọba Juda ni wọn yóò kó jáde fún àwọn ìjòyè ọba Babeli. Àwọn obìnrin náà yóò sì sọ fún ọ pé: “‘Àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì borí rẹ. Ẹsẹ̀ rẹ rì sínú ẹrọ̀fọ̀; àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti fi ọ́ sílẹ̀.’
23 Wszystkie także żony twoje i synów twoich wywiodą do Chaldejczyków, i ty sam nie ujdziesz ręki ich, owszem ręką króla Babilońskiego będziesz pojmany, i to miasto spalą ogniem.
“Wọn yóò kó àwọn ìyàwó àti ọmọ rẹ wá sí Babeli. Ìwọ gan an kò ní bọ́ níbẹ̀, ọba Babeli yóò mú ọ, wọn yóò sì jó ìlú yìí kanlẹ̀.”
24 Tedy rzekł Sedekijasz do Jeremijasza: Niechaj nikt nie wie o tem, abyś nie umarł;
Nígbà náà ni Sedekiah sọ fún Jeremiah pé, “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni mọ̀ nípa ọ̀rọ̀ yìí, tàbí kí o kú.
25 A jeźliby książęta usłyszawszy, żem mówił z tobą, przyszli do ciebie, i rzeklić: Powiedz nam, proszę, coś mówił z królem, nie taj przed nami, a nie zabijemy cię: co z tobą król mówił?
Tí àwọn ìjòyè bá mọ̀ pé mo bá ọ sọ̀rọ̀, tí wọ́n bá wá bá ọ wí pé, ‘Sọ fún wa ohun tí o bá ọba sọ tàbí ohun tí ọba sọ fún ọ; má ṣe fi pamọ́ fún wa tàbí kí a pa ọ́,’
26 Tedy im rzeczesz: Przełożyłem prośbę moję przed królem, aby mię zaś nie kazał odwiść do domu Jonatanowego, żebym tam nie umarł.
nígbà náà kí o sọ fún wọn, ‘Mò ń bẹ ọba láti má jẹ́ kí n padà lọ sí ilé Jonatani láti lọ kú síbẹ̀.’”
27 A zeszli się wszyscy książęta do Jeremijasza, i pytali go; który im powiedział według tego wszsytkiego, jako mu był król rozkazał. A tak milcząc odeszli od niego, gdyż się to było nie ogłosiło.
Gbogbo àwọn olóyè sì wá sí ọ̀dọ̀ Jeremiah láti bi í léèrè, ó sì sọ gbogbo ohun tí ọba ní kí ó sọ. Wọn kò sì sọ ohunkóhun mọ́, nítorí kò sí ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ tí òun àti ọba jọ sọ.
28 A Jeremijasz siedział w sieni straży aż do onego dnia, którego wzięto Jeruzalem, gdzie był, gdy dobywano Jeruzalemu.
Jeremiah wà nínú àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́ títí di ọjọ́ tí wọ́n fi kó Jerusalẹmu:

< Jeremiasza 38 >