< Jeremiasza 36 >

1 I stało się roku czwartego Joakima, syna Jozyjaszowego, króla Judzkiego; stało się, mówię, to słowo do Jeremijasza od Pana, mówiąc:
Ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé:
2 Weźmij sobie księgi, a napisz na nich wszystkie słowa, którem mówił do ciebie przeciw Izraelowi, i przeciw Judzie, i przeciw wszystkim narodom, ode dnia, króregom mawiał z tobą, ode dni Jozyjaszowych aż do dnia tego;
“Mú ìwé kíká fún ará rẹ, kí o sì kọ sínú rẹ̀ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ nípa Israẹli àti ti Juda, àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè láti ìgbà tí mo ti sọ fún ọ láti ọjọ́ Josiah títí di òní.
3 Aza snać, gdy usłyszy dom Judzki o tem wszystkiem złem, które Ja im myślę uczynić, nawróci się każdy od złej drogi swej, abym był miłościw nieprawościom ich i grzechom ich.
Ó lè jẹ́ wí pé ilé Juda yóò gbọ́ gbogbo ibi tí mo ti pinnu láti ṣe fún wọn; kí wọn kí ó sì yípadà, olúkúlùkù wọn kúrò ní ọ̀nà búburú rẹ̀. Kí èmi kí ó lè dárí àìṣedéédéé àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n.”
4 Przetoż wezwał Jeremijasz Barucha, syna Neryjaszowego; i napisał Baruch w księgi z ust Jeremijaszowych wszystkie słowa Pańskie, które mówił do niego.
Nígbà náà ni Jeremiah pe Baruku ọmọ Neriah, ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run bá a sọ fún, Baruku sì kọ láti ẹnu Jeremiah, gbogbo ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti sọ fún un sórí ìwé kíká náà.
5 Potem przykazał Jeremijasz Baruchowi, mówiąc: Ja będąc zatrzymany nie mogę wnijść do domu Pańskiego;
Nígbà náà ni Jeremiah wí fún Baruku pé, “A sé mi mọ́! Èmi kò lè lọ sí ilé Olúwa.
6 Przetoż ty idź, a czytaj na tych księgach, coś napisał z ust moich, słowa Pańskie, przed uszyma ludu w domu Pańskim w dzień postu; także też przed uszyma wszystkich z Judy którzyby przyszli z miast swoich, czytaj je.
Nítorí náà, ìwọ lọ sí ilé Olúwa ní ọjọ́ àwẹ̀, kí o sì kà nínú ìwé kíká náà ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ ti ẹnu mi kọ; ìwọ ó sì kà á ní etí gbogbo Juda, tí wọ́n jáde wá láti ìlú wọn.
7 Owa snać przyjdzie modlitwa ich przed oblicze Pańskie, a nawróci się każdy od złej drogi swojej; bo wielka jest zapalczywość i gniew, w którym mówił Pan przeciwko temu ludowi.
Ó lè jẹ́ pé, ẹ̀bẹ̀ wọn yóò wá sí iwájú Olúwa, wọ́n ó sì yípadà kúrò ní ọ̀nà búburú wọn; nítorí pé títóbi ni ìbínú àti ìrunú tí Olúwa ti sọ sí àwọn ènìyàn yìí.”
8 Tedy uczynił Baruch, syn Neryjaszowy, według wszystkiego, co mu rozkazał Jeremijasz prorok, czytając z ksiąg słowa Pańskie w domu Pańskim.
Baruku ọmọ Neriah sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí wòlíì Jeremiah sọ fún, láti ka ọ̀rọ̀ Olúwa láti inú ìwé ní ilé Olúwa.
9 I stało się roku piątego za Joakima. syna Jozyjaszowego, króla Judzkiego, w miesiącu dziewiątym, że zapowiedziano post przed twarzą Pańską wszystkiemu ludowi w Jeruzalemie, i wszystkiemu ludowi, który się był zszedł z miast Judzkich do Jeruzalemu.
Ní oṣù kẹsànán ọdún karùn-ún Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda ni wọ́n kéde àwẹ̀ níwájú Olúwa fún gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu àti fún gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wá láti ìlú Juda.
10 I czytał Baruch z ksiąg słowa Jeremijaszowe w domu Pańskim, w pokoju Giemaryjasza, syna Safanowego, pisarza, w sieni wyższej, w wejściu bramy nowej domu Pańskiego przed uszyma wszystkiego ludu.
Láti inú yàrá Gemariah ọmọ Ṣafani akọ̀wé, ní àgbàlá òkè níbi ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tuntun. Baruku sì ka ọ̀rọ̀ Jeremiah láti inú ìwé ní ilé Olúwa sí etí gbogbo ènìyàn.
11 A gdy usłyszał Micheasz, syn Giemaryjasza, syna Safanowego, wszystkie słowa Pańskie z ksiąg,
Nígbà tí Mikaiah ọmọ Gemariah ọmọ Ṣafani gbọ́ gbogbo àkọsílẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa láti inú ìwé náà;
12 Zstąpił do domu królewskiego, do komory pisarzowej, a oto tam wszyscy książęta siedzieli: Elisama pisarz, i Delajasz, syn Semajaszowy, i Elnatan, syn Achborowy, i Giemaryjasz, syn Safanowy, i Sedekijasz, syn Chananijaszowy, i wszyscy książęta.
Ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé ọba sínú yàrá akọ̀wé; níbi tí gbogbo àwọn ìjòyè gbé jókòó sí: Eliṣama akọ̀wé, Delaiah ọmọ Ṣemaiah, Elnatani ọmọ Akbori, Gemariah ọmọ Ṣafani àti Sedekiah ọmọ Hananiah àti gbogbo àwọn ìjòyè.
13 I powiedział im Micheasz wszystkie słowa, które słyszał, gdy czytał Baruch z ksiąg przed uszyma ludu.
Lẹ́yìn tí Mikaiah sọ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀n-ọn-nì tí o ti gbọ́ fún wọn, nígbà tí Baruku kà láti inú ìwé kíkà náà ní etí àwọn ènìyàn.
14 Przetoż posłali wszyscy książęta do Barucha Jehudę, syna Natanijaszowego, syna Selemijaszowego, syna Chusowego, aby rzekł: Księgi, na którycheś czytał przed uszyma ludu, weźmij w rękę twą a pójdź. Wziął tedy Baruch, syn Neryjaszowy, księgi w rękę swą i przyszedł do nich.
Gbogbo àwọn ìjòyè sì rán Jehudu ọmọ Netaniah ọmọ Ṣelemiah ọmọ Kuṣi sí Baruku wí pé, mú ìwé kíká náà ní ọwọ́ rẹ láti inú èyí tí ìwọ kà ní etí àwọn ènìyàn; kí o si wá. Nígbà náà ni Baruku ọmọ Neriah wá sí ọ̀dọ̀ wọn pẹ̀lú ìwé kíká ní ọwọ́ rẹ̀.
15 I rzekli do niego: Siądź proszę, a czytaj to przed uszyma naszemi. I czytał Baruch przed uszyma ich.
Wọ́n sì wí fún pé, “Jókòó, jọ̀wọ́ kà á sí etí wa!” Nígbà náà ni Baruku sì kà á ní etí wọn.
16 A gdy usłyszeli wszystkie one słowa, ulękłszy się wejrzał jeden na drugiego, i rzekli do Barucha: Zaiste oznajmiemy królowi te wszystkie słowa.
Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ náà tan; wọ́n ń wo ara wọn lójú pẹ̀lú ẹ̀rù. Wọ́n sì wí fún Baruku pé, “Àwa gbọdọ̀ jábọ̀ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún ọba.”
17 I pytali Barucha, mówiąc: Powiedz nam teraz, jakoś pisał wszystkie te słowa z ust jego?
Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ Baruku pé, “Sọ fún wa báwo ni o ṣe kọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí? Ṣé Jeremiah ló sọ wọ́n?”
18 I rzekł im Baruch: Z ust swych mówił do mnie wszystkie te słowa, a jam pisał na księgach inkaustem.
Baruku sì dá wọn lóhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, láti ẹnu rẹ̀ ni, ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ báyìí fún mi, èmi sì fi tàdáwà kọ wọ́n sínú ìwé náà.”
19 Tedy rzekli książęta do Barucha: Idź, a skryj się, ty i Jeremijasz, a niech nikt nie wie, gdzieście.
Nígbà náà ni àwọn ìjòyè sọ fún Baruku wí pé, “Lọ fi ara rẹ pamọ́ àti Jeremiah, má sì ṣe jẹ́ kí ẹnìkan mọ ibi tí ẹ̀yin wà.”
20 Potem weszli do króla do sieni, a księgi dali schować do komory Elisama, pisarza, i oznajmili przed królem te wszystkie słowa.
Lẹ́yìn tí wọ́n fi ìwé kíká náà pamọ́ sí iyàrá Eliṣama akọ̀wé, wọ́n sì wọlé tọ ọba lọ nínú àgbàlá, wọ́n sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà ní etí ọba.
21 Posłał tedy król Juhudę, aby wziął one księgi; który je wziął z komory Elisama, pisarza. I czytał je Jehuda przed uszyma królewskiemi, i przed uszyma wszystkich książąt, którzy stali przed królem.
Ọba sì rán Jehudu láti lọ mú ìwé kíká náà wá, Jehudu sì mu jáde láti inú iyàrá Eliṣama akọ̀wé. Ó sì ka ìwé náà ní etí ọba àti ní etí gbogbo àwọn ìjòyè tí ó dúró ti ọba.
22 A król siedział w domu, w którym w zimie bywał, miesiąca dziewiątego, a na ognisku przed nim palił się ogień.
Ó sì jẹ́ ìgbà òtútù nínú oṣù kẹsànán, ọba sì jókòó ní ẹ̀bá iná ààrò, iná náà sì ń jó ní iwájú rẹ̀.
23 A gdy przeczytał Jehuda trzy albo cztery karty, porzezał je król nożykiem pisarskim, i wrzucił je w ogień, który był na ognisku, aż zgorzały wszystkie księgi w ogniu, który był na ognisku;
Nígbà tí Jehudu ka ojú ìwé mẹ́ta sí mẹ́rin nínú ìwé náà, ọba fi ọ̀bẹ gé ìwé, ó sì sọ sínú iná tí ó wà nínú ìdáná, títí tí gbogbo ìwé kíká náà fi jóná tán.
24 Ale się nie ulękli, ani rozdarli szat swoich, król i wszyscy słudzy jego, którzy słyszeli wszystkie te słowa.
Síbẹ̀, ọba àti gbogbo àwọn ẹ̀mẹwà rẹ̀ tí wọ́n gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí kò bẹ̀rù; wọn kò sì fa aṣọ wọn yá.
25 Owszem, jeszcze gdy Elnatan, i Delajasz, i Giemaryjasz przyczyniali się do króla, aby nie palił onych ksiąg, tedy ich nie usłuchał;
Elnatani, Delaiah àti Gemariah sì bẹ ọba kí ó má ṣe fi ìwé kíká náà jóná, ṣùgbọ́n ọba kọ̀ láti gbọ́ tiwọn.
26 Ale rozkazał król Jerameelowi, synowi królewskiemu, i Sarajaszowi, synowi Abdeelowemu, aby pojmali Barucha pisarza, i Jeremijasza proroka; ale ich Pan skrył.
Dípò èyí ọba pàṣẹ fún Jerahmeeli ọmọ Hameleki, Seraiah ọmọ Asrieli àti Ṣelemiah ọmọ Abdeeli láti mú Baruku akọ̀wé àti Jeremiah wòlíì ṣùgbọ́n Olúwa fi wọ́n pamọ́.
27 I stało się słowo Pańskie do Jeremijasza, gdy król spalił one księgi i słowa, które był spisał Baruch z ust Jeremijaszowych, mówiąc:
Lẹ́yìn tí ọba fi ìwé kíká náà tí ọ̀rọ̀ tí Baruku kọ láti ẹnu Jeremiah jóná tán, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá:
28 Weźmij sobie zasię księgi inne, a napisz na nich wszystkie słowa pierwsze, które były w onych księgach pierwszych, które spalił Joakim, król Judzki.
“Wí pé, tún mú ìwé kíká mìíràn kí o sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé kíká èkínní tí Jehoiakimu ọba Juda fi jóná.
29 A o Joakimie, królu Judzkim, rzeczesz: Tak mówi Pan: Tyś spalił te księgi, mówiąc: Czemuś pisał na nich, rzekłszy: Zapewne przyciągnie król Babiloński, i spustoszy tę ziemię, i wygładzi z niej człowieka i bydlę.
Kí o sì wí fún Jehoiakimu ọba Juda pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, ìwọ ti fi ìwé kíká náà jóná, o sì wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi kọ̀wé sínú rẹ̀, pé lóòtítọ́ ni ọba Babeli yóò wá, yóò sì pa ilẹ̀ run, àti ènìyàn, àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀.”
30 Przetoż tak mówi Pan o Joakimie, królu Judzkim: Nie będzie miał, ktoby siedział na stolicy Dawidowej, a trup jego wyrzucony będzie na gorącość we dnie, a na mróz w nocy.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí ní ti Jehoiakimu ọba Juda pé, Òun kì yóò ní ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi, à ó sì sọ òkú rẹ̀ nù fún ooru ní ọ̀sán àti fún òtútù ní òru.
31 Bo nawiedzę na nim, i na nasieniu jego, i na sługach jego nieprawość ich, i przywiodę na nich i na obywateli Jeruzalemskich, i na mężów Judzkich to wszystko złe, o któremem mawiał do nich; ale nie słuchali.
Èmi ó sì jẹ òun àti irú-ọmọ rẹ̀, ìránṣẹ́ rẹ̀ ní ìyà nítorí àìṣedéédéé wọn; èmi ó sì mú gbogbo ibi tí èmi ti sọ sí wọn wá sórí wọn, àti sórí àwọn olùgbé Jerusalẹmu àti àwọn ènìyàn Juda, nítorí tí wọn kò fetísí mi.’”
32 Tedy Jeremijasz wziął księgi inne, i dał je Baruchowi, synowi Neryjaszowemu, pisarzowi, który na nich spisał z ust Jeremijaszowych wszystkie słowa onych ksiąg, które był spalił ogniem Joakim, król Judzki; a nadto przydano do onych słów wiele rzec zy tym podobnych.
Nígbà náà ni Jeremiah mú ìwé kíká mìíràn fún Baruku akọ̀wé ọmọ Neriah, ẹni tí ó kọ̀wé sínú rẹ̀ láti ẹnu Jeremiah gbogbo ọ̀rọ̀ inú ìwé tí Jehoiakimu ọba Juda ti sun níná. A sì fi onírúurú ọ̀rọ̀ bí irú èyí kún pẹ̀lú.

< Jeremiasza 36 >