< Jeremiasza 30 >

1 Słowo, które się stało do Jeremijasza od Pana, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, wí pé:
2 Tak powiada Pan, Bóg Izraelski, mówiąc: Napisz sobie wszystkie słowa, którem mówił do ciebie, na księgach.
“Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Ìwọ kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti bá ọ sọ sínú ìwé kan.
3 Albowiem oto dni idą, mówi Pan, a przywrócę więźniów ludu swego Izraelskiego i Judzkiego, mówi Pan, i przyprowadzę ich do ziemi, którąm był dał ojcom ich, i posiędą ją.
Ọjọ́ ń bọ̀ nígbà tí ń ó mú àwọn ènìyàn mi, àwọn ọmọ Israẹli àti Juda kúrò nínú ìgbèkùn, tí n ó sì dá wọn padà sí orí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá wọn láti ní,’ ni Olúwa Ọlọ́run wí.”
4 A teć są słowa, które mówił Pan o Izraelu i o Judzie;
Ìwọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run sí Israẹli àti Juda:
5 Tak zaiste mówi Pan: Słyszeliśmy głos strachu i lękania, i że niemasz pokoju.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Igbe ẹ̀rù àti ìwárìrì ni a gbọ́ láìṣe igbe àlàáfíà.
6 Pytajcież się teraz, a obaczcie, jeźli rodzi mężczyzna; przeczże tedy widzę, że każdy mąż rękami swemi trzyma się za biodra swe jako rodząca, i że się obróciły wszystkich oblicza w bladość?
Béèrè kí o sì rí. Ǹjẹ́ ọkùnrin le dá ọmọ bí? Èéṣe tí mo fi ń rí àwọn alágbára ọkùnrin tí wọ́n fi ọwọ́ wọn mú inú wọn bí obìnrin tó ń rọbí, tí ojú gbogbo wọ́n sì fàro fún ìrora?
7 Biada! bo wielki jest ten dzień, tak, że mu nie było podobnego; ale jakiżkolwiek jest czas utrapienia Jakóbowego, przecie z niego wybawiony będzie.
Ọjọ́ náà yóò ha ti burú tó! Kò sí ọjọ́ tí yóò dàbí rẹ̀, Ọjọ́ náà yóò jẹ́ àkókò ìdààmú fún Jakọbu ṣùgbọ́n yóò rí ìgbàlà kúrò nínú ìdààmú náà.
8 Stanie się bowiem dnia onego, mówi Pan zastępów, iż skruszę jarzmo jego z szyi twojej, a związki twoje potargam, i nie będą go więcej cudzoziemcy w niewolę podbijać;
“‘Ní ọjọ́ náà,’ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò gbé àjàgà kúrò lọ́rùn wọn, Èmi yóò sì tú ìdè wọn sọnù. Àwọn àjèjì kì yóò sì mú ọ sìn wọ́n mọ́.
9 Ale służyć będą Panu, Bogu swemu, i Dawidowi, królowi swemu, którego im wzbudzę.
Dípò bẹ́ẹ̀ wọn yóò máa sin Olúwa Ọlọ́run wọn àti Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba wọn, ẹni tí èmi yóò gbé dìde fún wọn.
10 Przetoż nie bój się ty, sługo mój Jakóbie! mówi Pan, ani się strachaj o Izraelu! bo oto Ja cię wybawię z daleka, i nasienie twoje z ziemi pojmania ich. I wróci się Jakób, aby odpoczywał i pokój miał, a nie będzie, ktoby go ustraszył;
“‘Nítorí náà, má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má sì ṣe jẹ́ kí ẹ̀rù bà ọ́, ìwọ Israẹli,’ ni Olúwa wí. ‘Èmi yóò gbà ọ́ kúrò láti ọ̀nà jíjìn wá, àní àwọn ìran rẹ láti ilẹ̀ àtìpó wọn. Jakọbu yóò sì tún ní àlàáfíà àti ààbò rẹ̀ padà, kò sì ṣí ẹni tí yóò ṣẹ̀rù bà á mọ́.
11 Bom Ja z tobą, mówi Pan, abym cię wybawił. Ponieważ uczynię koniec wszystkim narodom, między które cię rozproszę, wszakże tobie nie uczynię końca, ale cię miernie karać będę, a cale cię bez karania nie zaniecham.
Èmi wà pẹ̀lú rẹ, n ó sì gbà ọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, nínú èyí tí mo ti fọ́n ọn yín ká, síbẹ̀ èmi kì yóò pa yín run pátápátá. Èmi yóò bá yín wí pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo nìkan; Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìjìyà.’
12 Tak zaiste mówi Pan: Ciężkie bardzo będzie skruszenie twoje, nader bolesna rana twoja.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Ọgbẹ́ yín kò gbóògùn, bẹ́ẹ̀ ni egbò yín kọjá ìwòsàn.
13 Nie będzie, ktoby sądził sprawę twoję ku uleczeniu; lekarstwa ku uleczeniu mieć nie będziesz.
Kò sí ẹnìkan tí yóò bẹ̀bẹ̀ fún àìṣedéédéé yín, kò sí ètùtù fún ọgbẹ́ yín, a kò sì mú yín láradá.
14 Wszyscy miłośnicy twoi zapomną cię, ani cię nawiedzą, gdy cię zranię raną nieprzyjacielską, i okrutnem karaniem, dla wielkości nieprawości twojej i niezliczonych grzechów twoich.
Gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ ti gbàgbé rẹ, wọn kò sì náání rẹ mọ́ pẹ̀lú. Mo ti nà ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá rẹ yóò ti nà ọ, mo sì bá a ọ wí gẹ́gẹ́ bí ìkà, nítorí tí ẹ̀bi rẹ pọ̀ púpọ̀, ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lóǹkà.
15 Przeczże wołasz nad skruszeniem swem i ciężką boleścią swoją? Dla wielkości nieprawości twojej, i dla niezliczonych grzechów twoich uczyniłem ci to.
Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń kígbe nítorí ọgbẹ́ yín, ìrora yín èyí tí kò ní oògùn? Nítorí ọ̀pọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ yín àti ẹ̀bi yín tó ga ni mo fi ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí i yín.
16 A wszakże wszyscy, którzy cię pożerają, pożarci będą; a wszyscy, którzy cię ciemiężą, wszyscy, mówię, w niewolę pójdą; a którzy cię plundrują, splundrowani będą; a wszystkich, którzy cię łupią, podam na łup.
“‘Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe yín ní ibi ni ibi yóò bá, àní gbogbo àwọn ọ̀tá yín ni a ó sọ di àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; gbogbo àwọn tí wọ́n bà yín jẹ́ ni a ó bàjẹ́.
17 Tedyć zdrowie przywrócę, i od ran twoich uleczę cię, mówi Pan, przeto, że wygnaną nazwali cię (mówiąc: ) Tać jest Syon, niemasz nikogo, ktoby ją nawiedził.
Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìlera fún yín, èmi yóò sì wo ọ̀gbẹ́ yín sàn,’ ni Olúwa wí, ‘nítorí tí a pè yín ní alárìnkiri, Sioni tí gbogbo ènìyàn dágunlá sí.’
18 Tak mówi Pan: Oto Ja przywrócę pojmanych z namiotów Jakóbowych, a nad przybytkami jego zmiłuję się; i będzie zaś zbudowane miasto na pagórku swoim, a pałac według porządku swego wystawiony będzie.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Èmi yóò dá gbogbo ìre àgọ́ Jakọbu padà, èmi yóò sì ṣe àánú fún olùgbé àgọ́ rẹ̀; ìlú náà yóò sì di títúnṣe tí ààfin ìlú náà yóò sì wà ní ipò rẹ̀.
19 I wynijdzie od nich dziękczynienie, i głos weselących się; bo ich rozmnożę, a nie ubędzie ich, i uwielbię ich, a nie będą poniżeni.
Láti ẹnu wọn ni orin ọpẹ́ àti ìyìn yóò sì ti máa jáde. Èmi yóò sọ wọ́n di púpọ̀, wọn kì yóò sì dínkù ní iye, Èmi yóò fi ọlá fún wọn, wọn kò sì ní di ẹni àbùkù.
20 I będą synowie jego, jako i przedtem, a zgromadzenie jego przedemną utwierdzone będzie; ale nawiedzę wszystkich, którzy ich trapią.
Ọmọ ọmọ wọn yóò wà bí i ti ìgbàanì níwájú mi ni wọn yóò sì tẹ àwùjọ wọn dúró sí. Gbogbo ẹni tó bá ni wọ́n lára, ni èmi yóò fì ìyà jẹ.
21 I powstanie z niego najzacniejszy jego, a panujący nad nim z pośrodku jego wynijdzie, któremu się rozkażę przybliżyć, aby przystąpił przed mię; bo któż jest ten, coby ręczył za się, że przystąpi przed mię? mówi Pan.
Ọ̀kan nínú wọn ni yóò jẹ́ olórí wọn, ọba wọn yóò dìde láti àárín wọn. Èmi yóò mú un wá sí ọ̀dọ̀ mi, òun yóò sì súnmọ́ mi, nítorí ta ni ẹni náà tí yóò fi ara rẹ̀ jì láti súnmọ́ mi?’ ni Olúwa wí.
22 I będziecie ludem moim, a Ja będę Bogiem waszym.
‘Nítorí náà, ẹ̀yin yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.’”
23 Oto wicher Pański z popędliwością wynijdzie, wicher trwający nad głową niezbożników zostanie.
Wò ó, ìbínú Olúwa yóò tú jáde, ìjì líle yóò sì sọ̀kalẹ̀ sórí àwọn ènìyàn búburú.
24 Nie odwróci się zapalczywość gniewu Pańskiego, póki nie uczyni tego, a póki nie wykona umysłu serca swego; w ostatnie dni zrozumiecie to.
Ìbínú ńlá Olúwa kò ní dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ìkà títí yóò fi mú èrò ọkàn rẹ̀ ṣẹ. Ní àìpẹ́ ọjọ́, òye rẹ̀ yóò yé e yín.

< Jeremiasza 30 >