< Jeremiasza 28 >

1 I stało się roku onego, na początku królowania Sedekijasza, króla Judzkiego, roku czwartego, miesiąca piątego: Hananijasz, syn Asurowy, prorok, który był z Gabaonu, rzekł do mnie w domu Pańskim przed kapłanami i przed wszystkim ludem, mówiąc:
Ní oṣù karùn-ún ní ọdún kan náà, ọdún kẹrin ní ìbẹ̀rẹ̀ ìṣèjọba Sedekiah ọba Juda, wòlíì Hananiah ọmọ Assuri, tí ó wá láti Gibeoni, sọ fún mi ní ilé Olúwa tí ó wà ní iwájú àwọn àlùfáà àti gbogbo ènìyàn:
2 Tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski: Połamałem jarzmo króla Babilońskiego;
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Èmi yóò mú àjàgà ọba Babeli rọrùn.
3 Po dwóch latach przywrócę zasię na to miejsce wszystkie naczynia domu Pańskiego, które pobrał Nabuchodonozor, król Babiloński, z tego miejsca, a zawiózł je do Babilonu.
Láàrín ọdún méjì, Èmi yóò mú gbogbo ohun èlò tí ọba Nebukadnessari; ọba Babeli kó kúrò ní ilé Olúwa tí ó sì kó lọ sí Babeli padà wá.
4 Także Jechonijasza, syna Joakimowego, króla Judzkiego, i wszystkich, którzy są w niewolę zaprowadzeni z Judy, którzy się dostali do Babilonu, Ja zasię przywiodę na to miejsce, mówi Pan; bo skruszę jarzmo króla Babilońskiego.
Èmi á tún mú ààyè Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda padà, àti gbogbo àwọn tí ń ṣe àtìpó láti Juda ní Babeli,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa pé, ‘àjàgà yín láti ọwọ́ ọba Babeli yóò rọrùn.’”
5 Tedy rzekł Jeremijasz prorok do Hananijasza proroka przed oczyma kapłanów, i przed oczyma wszystkiego ludu, którzy stali w domu Pańskim;
Wòlíì Jeremiah wí fún wòlíì Hananiah ní iwájú ọmọ àlùfáà àti àwọn ènìyàn tí wọ́n dúró ní ilé Olúwa.
6 Rzekł, mówię, Jeremijasz prorok: Amen, niech tak uczyni Pan; niech utwierdzi Pan słowa twoje, któreś prorokował o przywróceniu z Babilonu na to miejsce naczynia domu Pańskiego, i wszystkich, którzy są zaprowadzeni w niewolę.
Jeremiah wòlíì wí pé, “Àmín! Kí Olúwa kí ó ṣe bẹ́ẹ̀! Kí Olúwa kí ó mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí ìwọ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ṣẹ, láti mú ohun èlò ilé Olúwa àti gbogbo àwọn ìgbèkùn láti ilẹ̀ Babeli padà wá sí ibí yìí.
7 Wszakże posłuchaj teraz słowa tego, które ja mówię w uszy twoje, i w uszy tego wszystkiego ludu.
Nísinsin yìí, ìwọ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí tí mo sọ sí etí rẹ àti sí etí gbogbo ènìyàn.
8 Prorocy, którzy byli przedemną i przed tobą z dawna, ci prorokowali przeciwko ziemiom zacnym, i przeciwko królestwom wielkim o wojnie, i o uciśnieniu, i o morze.
Ní ìbẹ̀rẹ̀ àwọn wòlíì tí ó ṣáájú rẹ àti èmi ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ogun, ibi àti àjàkálẹ̀ sí ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè.
9 Ten prorok, który prorokuje o pokoju, ten prorok, mówię, wtenczas poznany bywa, że go Pan prawdziwie posłał, gdy się iści słowo jego.
Ṣùgbọ́n, àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ àlàáfíà ni a mọ̀ gẹ́gẹ́ bí wòlíì olóòtítọ́ tí Olúwa rán, tí àsọtẹ́lẹ̀ rẹ bá wá sí ìmúṣẹ.”
10 Tedy zdjął Hananijasz prorok jarzmo z szyi Jeremijasza proroka, i połamał je.
Wòlíì Hananiah gbé àjàgà ọrùn wòlíì Jeremiah kúrò, ó sì fọ́ ọ.
11 I rzekł Hananijasz przed oczyma wszystkiego ludu, mówiąc: Tak mówi Pan: Tak połamię jarzmo Nabuchodonozora, króla Babilońskiego, po dwóch latach z szyi wszystkich narodów. I poszedł Jeremijasz prorok w drogę swoję.
Hananiah sọ níwájú gbogbo ènìyàn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Bákan náà ni Èmi yóò fọ́ àjàgà ọrùn Nebukadnessari, ọba Babeli láàrín ọdún méjì.’” Wòlíì Jeremiah sì bá ọ̀nà tirẹ̀ lọ.
12 Ale stało się słowo Pańskie do Jeremijasza, gdy połamał Hananijasz prorok ono jarzmo z szyi Jeremijasza proroka, mówiąc:
Láìpẹ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wòlíì wá lẹ́yìn ìgbà tí wòlíì Hananiah ti gbé àjàgà kúrò ní ọrùn wòlíì Jeremiah wí pé:
13 Idź; a rzecz do Hananijasza, mówiąc: Tak mówi Pan: Połamałeś jarzma drewniane; przetoż uczyń na to miejsce jarzmo żelazne.
“Lọ sọ fún Hananiah, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ìwọ ti wó àjàgà onígi, ṣùgbọ́n ní ààyè wọn, wà á bá àjàgà onírin.
14 Bo tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski: Jarzmo żelazne włożę na szyję tych wszystkich narodów, aby służyły Nabuchodonozorowi, królowi Babilońskiemu, i będą mu służyły; także i zwierzęta polne podałem mu.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi yóò fi àjàgà onírin sí ọrùn gbogbo orílẹ̀-èdè láti lè máa sin Nebukadnessari ọba Babeli, àti pé gbogbo yín ni ẹ̀ ó máa sìn ín. Èmi yóò tún fún un ní àṣẹ lórí àwọn ẹranko búburú.’”
15 Zatem rzekł Jeremijasz prorok do Hananijasza proroka: Słuchaj teraz Hananijaszu! Nie posłał cię Pan, a tyś kazał nadzieję mieć temu ludowi w kłamstwie.
Wòlíì Jeremiah sọ fún wòlíì Hananiah pé, “Gbọ́ ọ, Hananiah! Olúwa kò rán ọ, síbẹ̀, ìwọ jẹ́ kí orílẹ̀-èdè yìí gba irọ́ gbọ́.
16 Przetoż tak mówi Pan: Oto Ja ciebie uprzątnę z tej ziemi, tego roku umrzesz; boś radził, aby odstąpił lud od Pana.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Mo ṣetán láti mú ọ kúrò nínú ayé, ní ọdún yìí ni ìwọ yóò kú nítorí o ti wàásù ọ̀tẹ̀ sí Olúwa.’”
17 I umarł Hananijasz prorok onegoż roku, miesiąca siódmego.
Ní oṣù keje ọdún yìí ni Hananiah wòlíì kú.

< Jeremiasza 28 >