< Jeremiasza 25 >

1 Słowo, które się stało do Jeremijasza przeciwko wszystkiemu ludowi Judzkiemu roku czwartego Joakima, syna Jozyjaszowego, króla Judzkiego, (który jest rok pierwszy Nabuchodonozora, króla Babilońskiego; )
Ọ̀rọ̀ sì tọ Jeremiah wá nípa àwọn ènìyàn Juda ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kìn-ín-ní Nebukadnessari ọba Babeli.
2 Które mówił Jeremijasz prorok do wszystkiego ludu Judzkiego, i do wszystkich obywateli Jeruzalemskich mówiąc;
Nítorí náà, Jeremiah wòlíì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti sí àwọn olùgbé Jerusalẹmu.
3 Od trzynastego roku Jozyjasza, syna Amonowego, króla Judzkiego, aż do dnia tego, już to przez dwadzieścia i trzy lata bywało słowo Pańskie do mnie, którem do was mawiał, rano wstawając i opowiadając; aleście nie słuchali.
Fún odidi ọdún mẹ́tàlélógún, bẹ̀rẹ̀ láti ọdún kẹtàlá Josiah, ọmọ Amoni ọba Juda, títí di ọjọ́ yìí, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, mo sì ti sọ ọ́ fún un yín láti ìgbà dé ìgbà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
4 Posyłał też Pan do was wszystkich sług swoich proroków, rano wstawając, i posyłając, (którycheście nie usłuchali, aniście nakłonili ucha swego, abyście słyszeli; )
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn wòlíì sí i yín láti ìgbà dé ìgbà, ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
5 Którzy mówili: Nawróćcie się teraz każdy od złej drogi swojej, i od złości spraw waszych; a tak będziecie mieszkali w tej ziemi, którą wam dał Pan, i ojcom waszym od wieku aż na wieki.
Wọ́n sì wí pé, “Ẹ yípadà olúkúlùkù yín kúrò ní inú ibi rẹ̀ àti ní ọ̀nà ibi rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì lè dúró ní ilẹ̀ tí Olúwa fún un yín àti àwọn baba yín títí láéláé.
6 A nie chodźcie za bogami cudzymi, abyście im służyli, i kłaniali się im, ani mię gniewajcie sprawą rąk waszych, a Ja wam źle nie uczynię.
Má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn láti sìn wọ́n tàbí bọ wọ́n; ẹ má ṣe mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ ti fi ọwọ́ yín ṣe. Nígbà náà ni Èmi kò ní ṣe yín ní ibi.”
7 Aleście mię nie usłuchali, mówi Pan, abyście mię pobudzali do gniewu sprawą rąk swioch na swe złe.
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni ẹ sì ti mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ fi ọwọ́ yín ṣe, ẹ sì ti mú ibi wá sórí ara yín.”
8 Przetoż tak mówi Pan zastępów: Dlatego, iżeście nie usłuchali słów moich,
Nítorí náà, Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ èyí: “Nítorí wí pé ẹ̀yin kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi,
9 Oto Ja poślę i pobiorę wszystkie narody północne, mówi Pan, i do Nabuchodonozora króla Babilońskiego, sługi mego, i przywiodę je na tę ziemię, i na obywateli jej, i na te wszystkie narody okoliczne, które do szczętu wygładzę, i położę je na podziw, i na poświstanie, i na spustoszenie wieczne.
Èmi yóò pe gbogbo àwọn ènìyàn àríwá, àti ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò sì mú wọn dìde lòdì sí ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé rẹ̀ àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè àyíká rẹ̀. Èmi yóò pa wọ́n run pátápátá, Èmi yóò sọ wọ́n di nǹkan ẹ̀rù àti yẹ̀yẹ́ àti ìparun ayérayé.
10 I sprawię to, aby im zginął głos wesela, i głos radości, głos oblubieńca, i głos oblubienicy, głos żarn, i światłość pochodni,
Èmi yóò sì mú ìró ayọ̀ àti inú dídùn kúrò lọ́dọ̀ wọn; ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó, ìró ọlọ òkúta àti ìmọ́lẹ̀ fìtílà.
11 I będzie ta wszystka ziemia spustoszeniem, i zdumieniem, a służyć będą te narody królowi Babilońskiemu siedmdziesiąt lat.
Gbogbo orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì sìn ọba Babeli ní àádọ́rin ọdún.
12 Ale potem, gdy się wypełni siedmdzisiśąt lat, nawiedzę na królu Babilońskim i na tym narodzie, mówi Pan, nieprawość ich, i na ziemi Chaldejskiej, tak, że ją obrócę w pustynie wieczne.
“Ṣùgbọ́n, nígbà tí àádọ́rin ọdún náà bá pé, Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Babeli àti orílẹ̀-èdè rẹ, ilẹ̀ àwọn ará Babeli nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò sọ ọ́ di ahoro títí láé.
13 A przywiodę na tę ziemię wszystkie słowa moje, którem mówił o niej, mianowicie to wszystko, co napisano w tych księgach, cokolwiek prorokował Jaremijasz o wszystkich narodach.
Èmi yóò sì mú gbogbo ohun tí mo ti sọ wọ̀nyí wá sórí ilẹ̀ náà, gbogbo ohun tí a ti sọ àní gbogbo èyí tí a ti kọ sínú ìwé yìí, èyí tí Jeremiah ti sọtẹ́lẹ̀ sí gbogbo orílẹ̀-èdè.
14 Gdyż w niewolę podbici będą od narodów, także jako i oni możnych, i od królów wielkich, tedy im oddam według spraw ich i według uczynków rąk ich.
Àwọn fúnra wọn yóò sì sin orílẹ̀-èdè púpọ̀ àti àwọn ọba ńlá. Èmi yóò sì sán fún oníkálùkù gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”
15 Bo tak rzekł Pan, Bóg Izraelski, do mnie: Weźmij kubek wina tej popędliwości z ręki mojej, a napawaj nim wszystkie narody, do których Ja ciebie poślę;
Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí fún mi: “Gba ago yìí ní ọwọ́ mí tí ó kún fún ọtí wáìnì ìbínú mi, kí o sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè ti mo rán ọ sí mu ún.
16 Aby pili i potaczli się, owszem, aby szaleli od ostrza miecza, który Ja poślę między nich.
Nígbà tí wọ́n bá mu ún, wọn yóò ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n: bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n di aṣiwèrè nítorí idà tí yóò ránṣẹ́ sí àárín wọn.”
17 Wziąłem tedy kubek z ręki Pańskiej, i napoiłem wszystkie one narody, do których mię Pan posłał:
Mo sì gba ago náà lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó rán mi sí mu ún.
18 Jeruzalem, i miasta ziemi Judzkiej, i królów jej, i książąt jej, abym ich podał na spustoszenie, na zdumienie, na poświstanie, i na przeklęstwo, jako się to dziś okazuje.
Jerusalẹmu àti àwọn ìlú Juda, àwọn ọba wọn pẹ̀lú àwọn aláṣẹ wọn, láti sọ wọ́n di ohun ìparun, ohun ẹ̀rù, ẹ̀sìn àti ègún, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti rí lónìí yìí.
19 Faraona też, króla Egipskiego, i sług jego, i książąt jego, i wszystek lud jego;
Farao ọba Ejibiti, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn aláṣẹ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
20 I to wszystko pospólstwo, także wszystkich króli ziemi Uz, i wszystkich króli ziemi Filistyńskiej, i Aszkalon, i Gazę, i Akkaron, i ostatek Azotu;
Àti gbogbo àwọn ènìyàn àjèjì tí ó wà níbẹ̀; gbogbo àwọn ọba Usi, gbogbo àwọn ọba Filistini, gbogbo àwọn ti Aṣkeloni, Gasa, Ekroni àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kù sí Aṣdodu.
21 Edomczyków, i Moabczyków, i synów Ammonowych;
Edomu, Moabu àti Ammoni;
22 I wszystkich królów Tyrskich, i wszystkich królów Sydońskich, i królów tej krainy, która jest przy morzu;
gbogbo àwọn ọba Tire àti Sidoni; gbogbo àwọn ọba erékùṣù wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ìkọjá Òkun.
23 Dedana i Temę, i Buzę, i wszystkich, którzy mieszkają w ostatnich kątach:
Dedani, Tema, Busi àti gbogbo àwọn tí ń gbé lọ́nà jíjìn réré.
24 I wszystkich królów Arabskich, i wszystkich królów tego pospólstwa, które mieszka na puszczy;
Gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn ọba àwọn àjèjì ènìyàn tí ń gbé inú aginjù.
25 Także wszystkich królów Zymry i wszystkich królów Elam, i wszystkich królów Medskich;
Gbogbo àwọn ọba Simri, Elamu àti Media.
26 Owszem, wszystkich królów północnych, bliskich i dalekich, jednego jako drugiego; wszystkie też królestwa ziemi, którekolwiek są na obliczu ziemi; a król Sesak będzie pił po nich.
Àti gbogbo àwọn ọba àríwá ní tòsí àti lọ́nà jíjìn, ẹnìkínní lẹ́yìn ẹnìkejì; gbogbo àwọn ìjọba lórí orílẹ̀ ayé. Àti gbogbo wọn, ọba Ṣeṣaki náà yóò sì mu.
27 I rzecz do nich: Tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski: Pijcie, a popijcie się, owszem zwracajcie, i padajcie tak, abyście nie powstali dla miecza, który Ja poślę między was.
“Nígbà náà, sọ fún wọn, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí. Mu, kí o sì mú àmuyó kí o sì bì, bẹ́ẹ̀ ni kí o sì ṣubú láì dìde mọ́ nítorí idà tí n ó rán sí àárín yín.
28 A jeźliby nie chcieli wziąć kubka z ręki twojej, aby pili, tedy rzeczesz do nich: Tak mówi Pan zastępów: Koniecznie pić musicie.
Ṣùgbọ́n bí wọ́n ba kọ̀ láti gba ago náà ní ọwọ́ rẹ kí wọ́n sì mu ún, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹyin gbọdọ̀ mu ún!
29 Bo ponieważ na to miasto, które nazwane jest od imienia mego, Ja zaczynam przywodzić złe rzecz, a wybyście bez karania być mieli? Nie będziecie bez karania; bom Ja miecz przyzwał na wszystkich obywateli tej ziemi, mówi Pan zastępów.
Wò ó, èmi ń mú ibi bọ̀ sí orí orílẹ̀-èdè tí ó ń jẹ́ orúkọ mi; ǹjẹ́ yóò ha a lè lọ láìjìyà? Ẹ̀yin ń pe idà sọ̀kalẹ̀ sórí gbogbo àwọn olùgbé ayé, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ.’
30 Przetoż ty prorokuj przeciwko nim te wszyskie słowa, a mów do nich: Pan z wysoka zaryczy, a mieszkania świętobliwości swojej wyda głos swój, rycząc zaryczy z mieszkania swego; krzyk pobudzających się jako tłoczących prasę, rozlegać się będzie prze ciwko wszystkim obywatelom tej ziemi.
“Nísinsin yìí, sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí nípa wọn: “‘Kí o sì sọ pé, Olúwa yóò bú láti òkè wá, yóò sì bú kíkankíkan sí ilẹ̀ náà. Yóò parí gbogbo olùgbé ayé, bí àwọn tí ń tẹ ìfúntí.
31 I przejdzie huk aż do kończyn ziemi; bo się Pan rozpiera z tymi narodami, w sąd sam wchodzi ze wszelkiem ciałem, niezbożnych poda pod miecz, mówi Pan.
Ìrọ́kẹ̀kẹ̀ yóò wà títí dé òpin ilẹ̀ ayé, nítorí pé Olúwa yóò mú ìdààmú wá sí orí àwọn orílẹ̀-èdè náà, yóò mú ìdájọ́ wá sórí gbogbo ènìyàn, yóò sì fi àwọn olùṣe búburú fún idà,’” ni Olúwa wí.
32 Tak mówi Pan zastępów: Oto udręczenie pójdzie z narodu do narodu, a wicher wielki powstanie od kończyn ziemi;
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Wò ó! Ibi ń tànkálẹ̀ láti orílẹ̀-èdè kan sí òmíràn; ìjì ńlá yóò sì ru sókè láti òpin ayé.”
33 I będą pobici od Pana czasu onego od końca ziemi aż do końca ziemi; nie będą ich płakać, ani zbierać, ani chować; będą jako gnój na polu.
Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò ṣọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.
34 Narzekajcie pasterze i wołajcie, a walajcie się w popiele, wy najzacniejsi tej trzody! bo się wypełniły dni wasze, zabicia i rozproszenia waszego, i upadniecie jako naczynie drogie.
Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, ẹ yí nínú eruku, ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran. Nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé, ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.
35 I zginie ucieczka pasterzom, a ujście najzacniejszym tej trzody.
Àwọn olùṣọ́-àgùntàn kì yóò rí ibi sálọ kì yóò sì ṣí àsálà fún olórí agbo ẹran.
36 Głos wołania pasterzy, i narzekanie najzacniejszych tej trzody słychać będzie; bo Pan spustoszy pastwiska ich.
Gbọ́ igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn, àti ìpohùnréré ẹkún àwọn olórí agbo ẹran; nítorí pé Olúwa ń pa pápá oko tútù wọn run.
37 I zagubione będą spokojne pastwiska dla zapalczywości gniewu Pańskiego,
Ibùgbé àlàáfíà yóò di ahoro, nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
38 Który opuści jako lew jaskinię swoję; bo ziemia ich przyjdzie na spustoszenie dla zapalczywości pustoszyciela, i dla popędliwości gniewu jego.
Gẹ́gẹ́ bí kìnnìún yóò fi ibùba rẹ̀ sílẹ̀, ilẹ̀ wọn yóò sì di ahoro, nítorí idà àwọn aninilára, àti nítorí ìbínú ńlá Olúwa.

< Jeremiasza 25 >