< Jeremiasza 19 >

1 Tak mówi Pan: Idź, a kup dzban gliniany od garncarza, a wziąwszy niektórych z starszych ludu i z starszych kapłanów;
Èyí ní ohun tí Olúwa wí: “Lọ ra ìkòkò lọ́dọ̀ alámọ̀, mú dání lára àwọn àgbàgbà ọkùnrin àti wòlíì.
2 Wnijdź do doliny syna Hennomowego, która jest u wrót bramy wschodniej, a tam opowiadaj słowa, które do ciebie mówić będę.
Kí o sì lọ sí àfonífojì ọmọ Beni-Hinnomu, níwájú ẹnu ibodè Harsiti, níbẹ̀ ni kí o sì kéde gbogbo ọ̀rọ̀ tí èmi yóò sọ fún ọ.
3 A rzecz: Słuchajcie słowa Pańskiego, królowie Judzcy i obywatele Jeruzalemscy! Tak mówi pan zastępów, Bóg Izraelski: Oto Ja przywiodę złe na to miejsce, o którem ktokolwiek usłyszy, zabrzmi mu w uszach jego.
Kí o sì wí pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba àwọn Juda àti ẹ̀yin ará Jerusalẹmu. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli sọ. Dẹtí sí mi! Èmi yóò mú ìparun wá síbí, etí gbogbo wọn tó bá gbọ́ ọ yóò hó yaya.
4 Przeto, że mię opuścili, a splugawili to miejsce, kadząc na niem bogom cudzym, których nie znali oni i ojcowie ich, i królowie Judzcy, i napełnili to miejsce krwią niewinnych;
Nítorí wọ́n ti gbàgbé mi, wọ́n sì ti sọ ibí di ilé fún òrìṣà àjèjì; wọ́n ti sun ẹbọ nínú rẹ̀ fún òrìṣà tí àwọn baba wọn tàbí tí ọba Juda kò mọ̀ rí, wọ́n ti fi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kún ilẹ̀ yìí.
5 I pobudowali wyżyny Baalowi, aby palili synów swych ogniem na całopalenie Baalowi, czegom nie rozkazał, anim oto mówił, ani to wstąpiło na serce moje:
Wọ́n ti kọ́ ibi gíga fún Baali láti sun ọmọkùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí ohun ẹbọ sísun sí Baali—èyí tí èmi kò pàṣẹ láti ṣe, tí èmi kò sì sọ, tàbí tí kò sì ru sókè láti inú ọkàn mi.
6 Dlatego oto dni idą, mówi Pan, w których nie będzie nazywane więcej to miejsce Tofet, ani doliną syna Hennomowego, ale doliną mordu.
Nítorí náà ṣọ́ra ọjọ́ ń bọ̀ ni Olúwa wí nígbà tí àwọn ènìyàn kì yóò pe ibí ní Tofeti mọ́ tàbí àfonífojì ọmọ Hinnomu, ṣùgbọ́n àfonífojì Ìpakúpa.
7 Bo wniwecz obrócę radę Judzką i Jeruzalemską na tem miejscu, a sprawię, że oni upadną od miecza przed twarzą nieprzyjaciół swoich, i od ręki szukających duszy ich; i dam trupy ich na pokarm ptastwu niebieskiemu, i zwierzowi ziemskiemu;
“‘Ní ibí yìí ni èmi yóò ti pa èrò Juda àti Jerusalẹmu run. Èmí yóò mú wọn ṣubú nípa idà níwájú àwọn ọ̀tá wọn, lọ́wọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn. Èmi yóò sì fi òkú wọn ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.
8 Podam także to miasto na spustoszenie i na świstanie; każdy idący mimo nie zdumieje się, a świstać będzie nad wszystkiemi plagami jego.
Èmi yóò sọ ìlú yìí di ahoro àti ohun ẹ̀gàn, gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò bẹ̀rù wọn yóò sì máa fòyà nítorí gbogbo ọgbẹ́ rẹ̀.
9 I sprawię to, że będą jeść ciała synów swoich, i ciała córek swoich, a każdy z nich ciało bliźniego swego jeść będzie w oblężeniu i w uciśnieniu, którem ich ucisną nieprzyjaciele ich, i ci, którzy szukają duszy ich.
Èmi yóò mú kí wọ́n jẹ ẹran-ara ọmọ wọn ọkùnrin àti ẹran-ara ọmọ wọn obìnrin, ẹnìkínní yóò sì jẹ ẹran-ara ẹnìkejì, nígbà ìdótì àti ìhámọ́ láti ọwọ́ ọ̀tá wọn, àti àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn.’
10 Potem stłucz ten dzban przed oczyma mężów, którzy pójdą z tobą,
“Nígbà náà ni ìwọ yóò fọ́ ìkòkò náà ní ojú àwọn tí ó bá ọ lọ.
11 A rzecz do nich: Tak mówi Pan zastępów: Tak stłukę ten lud, i to miasto, jako gdy kto tłucze naczynie garncarskie, które więcej naprawione być nie może: a w Tofet pogrzebywać będą, iż miejsca inszego nie będzie ku pogrzebowi.
Kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. Èmi a fọ́ orílẹ̀-èdè yìí àti ìlú yìí gẹ́gẹ́ bí ìkòkò amọ̀ yìí ṣe fọ́ tí kò sì ní sí àtúnṣe. Wọn a sì sin àwọn òkú sí Tofeti títí tí kò fi ní sí ààyè mọ́.
12 Tak uczynię temu miejscu, mówi Pan, i obywatelom jego, i postąpię sobie z tem miastem, tak jako z Tofet.
Èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí ibí yìí àti àwọn tí ń gbé ní ibí yìí ni Olúwa wí. Èmi yóò mú ìlú yìí dàbí Tofeti.
13 Bo będą domy Jeruzalemskie i domy królów Judzkich, jako to miejsce Tofet, nieczyste ze wszystkiemi domami temi, na których dachach kadzili wszystkiemu wojsku niebieskiemu, i sprawowali ofiary mokre bogom cudzym.
Àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu àti ti ọba ìlú Juda ni a ó sọ di àìmọ́ bí Tofeti, gbogbo ilé tí wọ́n ti ń sun tùràrí ni orí òrùlé sí gbogbo ogun ọ̀run, tí a sì ń rú ẹbọ mímu sí ọlọ́run mìíràn.’”
14 Tedy wróciwszy się Jeremijasz z Tofet, gdzie go był Pan posłał, aby tam prorokował, stanął w sieni domu Pańskiego, i rzekł do wszystkiego ludu:
Jeremiah sì padà láti Tofeti níbi tí Olúwa rán an sí láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ó sì dúró ní gbangba tẹmpili Olúwa, ó sì sọ fún gbogbo ènìyàn pé,
15 Tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski: Oto Ja przywiodę na to miasto i na wszystkie miasto jego wszystko to złe, którem wyrzekł przeciw niemu; bo zatwardzili kark swój, aby nie słuchali słów moich.
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò mú ìdààmú tí mo ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ bá ìlú yìí àti ìgbèríko tí ó yí i ká, nítorí ọlọ́rùn líle ni wọ́n, wọn kò si ní fẹ́ fetí sí ọ̀rọ̀ mi.’”

< Jeremiasza 19 >