< Jeremiasza 18 >

1 Słowo, które się stało do Jeremijasza od Pana mówiąc:
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wá wí pe:
2 Wstań, a wstąp do domu garncarzowego, a tam sprawię, że usłyszysz słowa moje.
“Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé amọ̀kòkò, níbẹ̀ ni èmi yóò ti bá ọ sọ̀rọ̀.”
3 I wstąpiłem do domu garncarzowego, a oto on robił robotę na kręgu.
Nígbà náà ni mo lọ sí ilé amọ̀kòkò mo sì rí i tí ó ń ṣiṣẹ́ kan lórí kẹ̀kẹ́.
4 A gdy się zepsuło naczynie w ręce garncarzowej, które on czynił z gliny, tedy zaś uczynił z niej naczynie insze, jako się mu najlepiej zdało uczynić.
Ṣùgbọ́n ìkòkò tí ó ń mọ láti ara amọ̀ bàjẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀, nítorí náà ni amọ̀kòkò fi ṣe ìkòkò mìíràn, ó mọ ọ́n bí èyí tí ó dára jù ní ojú rẹ̀.
5 I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
6 Izalibym tak nie mógł z wami postąpić, jako ten garncarz, o domie Izraelski? mówi Pan. Oto jako glina w ręce garncarzowej, takeście wy w ręce mojej, o domie Izraelski!
“Ẹyin ilé Israẹli, èmi kò ha lè ṣe fún un yín gẹ́gẹ́ bí amọ̀kòkò yìí ti ṣe?” ni Olúwa wí. “Gẹ́gẹ́ bí amọ̀ ní ọwọ́ amọ̀kòkò bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin rí ní ọwọ́ mi, ẹ̀yin ilé Israẹli.
7 Jeźlibym rzekł nagle przeciwko narodowi, i przeciwko królestwu, że je wykorzenię, i zepsuję, i wygubię;
Bí ó bá jẹ́ ìgbà kan, tí èmi kéde kí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan di fífà tu láti dojúdé àti láti parun,
8 Wszakże jeźliby się odwrócił on naród od złości swojej, przeciw któremum mówił; i Jabym żałował tego złego, którem mu umyślił uczynić.
tí orílẹ̀-èdè ti mo kìlọ̀ fún bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú wọn, nígbà náà ni Èmi yóò yí ọkàn mi padà nínú àjálù tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.
9 Zasię, jeźlibym rzekł nagle o narodzie i o królestwie, że je pobuduję i wszczepię;
Ní ìgbà mìíràn tí èmi bá tún kéde láti tẹ̀dó tàbí gbin orílẹ̀-èdè kan tàbí ìjọba kan.
10 Wszakże jeźliby czynił, co złego jest przed oczyma memi, nie słuchając głosu mego: i Jabym żałował tego dobrodziejstwa, którem mu obiecał uczynić.
Bí ó bá sì ṣe búburú níwájú mi, tí kò sì gba ohùn mi gbọ́, nígbà náà ni èmi yóò yí ọkàn mi padà ní ti rere, èyí tí mo wí pé, èmi ó ṣe fún wọn.
11 A przetoż rzecz teraz do mężów Judzkich, i do obywateli Jeruzalemskich, mówiąc: Tak mówi Pan: Oto Ja gotuję na was złą rzecz, i myślę coś przeciwko wam. Nawróćcież się już każdy od złej drogi swojej, a poprawcie każdy dróg waszych, i spraw waszych.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, sọ fún àwọn ènìyàn Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa wí: Wò ó! Èmi ń gbèrò ibi sí yin, èmi sì ń ṣe ìpinnu kan lórí yín. Nítorí náà ẹ yípadà kúrò lọ́nà búburú yín kí olúkúlùkù yín sì tún ọ̀nà àti ìṣe rẹ̀ ṣe.’
12 Ale oni rzekli: Nic z tego; bo za myślami naszemi pójdziemy, a każdy upór serca swojego złego czynić będziemy.
Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Kò ṣe nǹkan kan, àwa yóò tẹ̀síwájú nínú èrò wa, ẹnìkọ̀ọ̀kan wa, yóò hùwà agídí ọkàn búburú rẹ̀.’”
13 Przetoż tak mówi Pan: Pytajcie teraz między poganami, któż słyszał co takowego? Sprosność wielką popełniła panna Izraelska.
Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: “Ẹ béèrè nínú orílẹ̀-èdè, ẹni tí ó bá ti gbọ́ irú nǹkan wọ̀nyí ri? Ohun tí ó burú gidi ni wúńdíá Israẹli ti ṣe.
14 Izali kto opuści pola moje dla skał i dla śniegu na Libanie? Izali kto opuści wody ciekące dla wody bardzo zimnej?
Ǹjẹ́ omi ojo dídì Lebanoni yóò ha dá láti máa sàn láti ibi àpáta? Tàbí odò tí ó jìnnà, tí ó tútù, tí ó ń sàn, yóò ha gbẹ bí?
15 Ale lud mój zapomniawszy na mię, marności kadzą i potykają się na drogach swych, na ścieszkach starodawnych, chodząc ścieszkami drogi nieutorowanej;
Nítorí àwọn ènìyàn mi gbàgbé mi, wọ́n sun tùràrí fún òrìṣà asán, tí ó mú wọn kọsẹ̀ ní ọ̀nà wọn, àti ọ̀nà wọn àtijọ́. Wọ́n mú wọn rìn ní ọ̀nà àtijọ́, àti ní ojú ọ̀nà ti a kò ṣe.
16 Tak, abym podał ziemię ich na spustoszenie, na świstanie wieczne, aby każdy, ktoby szedł przez nią, zdumiał się, i kiwał głową swoją.
Ilẹ̀ wọn yóò wà lásán yóò sì di nǹkan ẹ̀gàn títí láé, gbogbo àwọn tí ó ń kọjá yóò bẹ̀rù, wọn yóò sì mi orí wọn.
17 Wiatrem wschodnim rozproszę ich przed nieprzyjacielem; tył a nie twarz ukażę im w dzień zatracenia ich.
Gẹ́gẹ́ bí afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn, Èmi yóò tú wọn ká lójú àwọn ọ̀tá wọn. Èmi yóò sì kọ ẹ̀yìn sí wọn, n kì yóò kọjú sí wọn ní ọjọ́ àjálù wọn.”
18 I rzekli: Pójdźcie a wymyślmy co przeciwko Jeremijaszowi; bo nie zginie zakon od kapłana, ani rada od mądrego, ani słowo od proroka; pójdźcież, a ubijmy go językiem, a nie dbajmy na żadne słowa jego.
Wọ́n sọ wí pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ ṣọ̀tẹ̀ sí Jeremiah, nítorí òfin ìkọ́ni láti ẹnu àwọn àlùfáà kì yóò jásí asán, tàbí ìmọ̀ràn fún àwọn ọlọ́gbọ́n tàbí ọ̀rọ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì. Nítorí náà wá, ẹ jẹ́ kí a kọlù ú pẹ̀lú ahọ́n wa, kí a má sì ṣe tẹ́tí sí ohunkóhun tí ó bá sọ.”
19 Pilnuj mię Panie! a słuchaj głosu tych, którzy się spierają ze mną.
Dẹtí sí ọ̀rọ̀ mi Olúwa, gbọ́ ohun tí àwọn tí ó fi mí sùn ń sọ.
20 Izali się ma oddawać złem za dobre, że ukopali dół duszy mojej? Wspomnij, żem stawał przed obliczem twojem, abym za nimi mówił ku ich dobremu, i odwrócił zapalczywość twoję od nich.
Ṣe kí a fi rere san búburú? Síbẹ̀ wọ́n ti gbẹ́ kòtò fún mi. Rántí pé mo dúró níwájú rẹ, mo sì sọ̀rọ̀ nítorí wọn, láti yí ìbínú rẹ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
21 Dlatego dopuść głód na synów ich, a spraw, że okrutnie będą pobici od miecza, że będą żony ich osierociałe i owdowiałe, a mężowie ich że będą haniebnie zamordowani, a dzieci ich pobite mieczem na wojnie.
Nítorí náà, jẹ́ kí ìyàn mú ọmọ wọn jọ̀wọ́ wọn fún ọwọ́ idà jẹ́ kí ìyàwó wọn kí ó di aláìlọ́mọ àti opó jẹ́ kí a pa àwọn ọkùnrin wọn kí a sì fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn lójú ogun.
22 Niech będzie słyszany krzyk z domów ich, gdy na nich nagle wojsko przywiedziesz; bo ukopali dół, aby mię ułapili a sidła ukryli na nogi moje.
Jẹ́ kí a gbọ́ ohùn ẹkún láti ilé wọn nígbà tí ó bá mu àwọn jagunjagun kọlù wọ́n lójijì nítorí wọ́n ti gbẹ́ kòtò láti mú mi. Wọ́n ti dẹ okùn fún ẹsẹ̀ mi.
23 Aleś ty, Panie! powiadomy wszystkiej rady ich przeciwko mnie na śmierć: nie bądź miłościw nieprawościom ich, a grzechu ich przed obliczem twojem nie zagładzaj; ale niech się potkną przed oblicznością twoją, czasu zapalczywośli twojej surowo się o bchodź z nimi.
Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa mọ gbogbo ète wọn láti pa mí, má ṣe dárí ẹ̀bi wọn jì wọ́n bẹ́ẹ̀ ni má ṣe pa ẹ̀ṣẹ̀ wọn rẹ́ kúrò lójú rẹ. Jẹ́ kí wọn kí ó ṣubú níwájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó sì ṣe sí wọn nígbà ìbínú rẹ.

< Jeremiasza 18 >