< Jeremiasza 12 >

1 Sprawiedliwym zostaniesz, Panie! jeźli się z tobą rozpierać będę; a wszakże o sądach twoich z tobą mówić będę. Czemuż się droga niezbożnych szczęści? Czemuż spokojnie żyją wszyscy, którzy bardzo wystąpili przeciwko tobie?
Olúwa, olódodo ni ọ́ nígbàkígbà, nígbà tí mo mú ẹjọ́ kan tọ̀ ọ́ wá. Síbẹ̀ èmi yóò bá ọ sọ̀rọ̀ nípa òdodo rẹ. Èéṣe tí ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú fi ń ṣe déédé? Èéṣe tí gbogbo àwọn aláìṣòdodo sì ń gbé ní ìrọ̀rùn?
2 Wszczepiłeś ich, i rozkorzenili się; rosną i owoc wydawają ci, którycheś ust bliskim, ale dalekim od nerek ich.
Ó ti gbìn wọ́n, wọ́n sì ti fi egbò múlẹ̀, wọ́n dàgbà wọ́n sì so èso. Gbogbo ìgbà ni ó wà ní ètè wọn, o jìnnà sí ọkàn wọn.
3 Ale ty, Panie, znasz mię, wypatrujesz mię, a doświadczyłeś serca mego, że z tobą jest; ale onych ciągniesz jako owce na rzeź i gotujesz ich na dzień zabicia, i mówisz:
Síbẹ̀ o mọ̀ mí ní Olúwa, o ti rí mi o sì ti dán èrò mi nípa rẹ wò. Wọ, wọ́n lọ bí àgùntàn tí a fẹ́ pa. Yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ọjọ́ pípa.
4 Dokądżeby ziemia płakać, a trawa na wszystkich polach schnąć miała? Dla złości mieszkających w niej giną wszystkie zwierzęta i ptastwo; bo mówią: Nie widzić Pan skończenia naszego.
Yóò ti pẹ́ tó tí ọ̀gbẹlẹ̀ yóò fi wà, tí gbogbo ewéko igbó sì ń rọ? Nítorí àwọn ènìyàn búburú ni ó ń gbé ibẹ̀. Àwọn ẹranko àti àwọn ẹyẹ ti ṣègbé, pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ènìyàn ń sọ pé, “Kò lè rí ohun tó ṣẹlẹ̀ sí wa.”
5 Ponieważ cię z pieszymi bieżącego do ustania przywodzą, jakożbyś miał zdążyć przy koniach? a ponieważ w ziemi pokoju, w którejś ufał, ustawasz, a cóż sprawisz przy tej nadętości Jordanu?
Bí ìwọ bá ń bá ẹlẹ́ṣẹ̀ sáré, tí àárẹ̀ sì mú ọ, báwo ni ìwọ yóò ṣe bá ẹṣin díje? Bí ìwọ bá kọsẹ̀ ní ilẹ̀ àlàáfíà, bí ìwọ bá ní ìgbẹ́kẹ̀lé, kí ni ìwọ ó ṣe nínú ẹkùn odò Jordani?
6 Bo i bracia twoi i dom ojca twego przeniewierzyli się tobie, i ci także wołają za tobą pełnemi usty; ale nie wierzz im, choćby mówili z tobą po przyjacielsku.
Àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn ìdílé ti dà ọ́, kódà wọ́n ti kẹ̀yìn sí ọ, wọ́n ti hó lé ọ lórí. Má ṣe gbà wọ́n gbọ́ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ń sọ̀rọ̀ rẹ dáradára.
7 Opuściłem dom swój, odrzuciłem dziedzictwo moje; dałem to, co miłowała dusza moja, w ręce nieprzyjaciół jego.
Èmi yóò kọ ilé mi sílẹ̀, èmi yóò fi ìní mi sílẹ̀. Èmi yóò fi ẹni tí mo fẹ́ lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.
8 Stało mi się dziedzictwo moje jako lew w lesie; wydaje przeciwko mnie głos swój, przetoż go nienawidzę.
Ogún mi ti rí sí mi bí i kìnnìún nínú igbó. Ó ń bú ramúramù mọ́ mi; nítorí náà mo kórìíra rẹ̀.
9 Izali ptakiem drapieżnym jest mi dziedzictwo moje? Izali ptastwo będzie w około przeciwko niemu? Idźcież, zbierzcie się wszystkie zwierzęta polne, zejdźci się do żeru.
Ogún mi kò ha ti rí sí mi bí ẹyẹ kannakánná tí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ dòyì ka, tí wọ́n sì kọjú ìjà sí i? Ẹ lọ, kí ẹ sì kó gbogbo ẹranko igbó jọ, ẹ mú wọn wá jẹ.
10 Wiele pasterzy popsuje winnicę moję, podepczą dział mój; dział mój bardzo miły obrócą w pustynię srogą.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùṣọ́-àgùntàn ni yóò sì ba ọgbà àjàrà mi jẹ́, tí wọn yóò sì tẹ oko mi mọ́lẹ̀; wọ́n ó sọ oko dídára mi di ibi tí a ń da ìdọ̀tí sí.
11 Obrócą go w pustynię; płakać będzie, spustoszony będąc odemnie; ta wszystka ziemia spustoszeje, bo niemasz, ktoby to składał do serca.
A ó sọ ọ́ di aṣálẹ̀ ilẹ̀ tí kò wúlò níwájú mi, gbogbo ilẹ̀ ni yóò di ahoro nítorí kò sí ẹnìkankan tí yóò náání.
12 Na wszystkie miejsca wysokie w pustyniach przyjdą burzyciele, bo miecz Pański pożre wszystko od końca ziemi aż do końca ziemi; nie będzie miało pokoju żadne ciało.
Gbogbo ibi gíga tí ó wà nínú aṣálẹ̀ ni àwọn apanirun ti gorí, nítorí idà Olúwa yóò pa láti ìkangun kìn-ín-ní dé ìkangun èkejì ilẹ̀ náà; kò sí àlàáfíà fún gbogbo alààyè.
13 Nasieją pszenicy, ale ciernie żąć będą; frasować się będą, ale nic nie sprawią, i wstydzić się będą za urodzaje swoje dla gniewu popędliwości Pańskiej.
Àlìkámà ni wọn yóò gbìn, ṣùgbọ́n ẹ̀gún ni wọn yóò ká, wọn yóò fi ara wọn ṣe wàhálà, ṣùgbọ́n òfo ni èrè wọn. Kí ojú kí ó tì yín nítorí èrè yín, nítorí ìbínú gbígbóná Olúwa.
14 Tak mówi Pan o wszystkich złych sąsiadach moich, którzy się dotykają dziedzictwa, którem dał w dziedzictwo ludowi memu Izraelskiemu: Oto Ja wykorzenię ich z ziemi ich, kiedy dom Judzki wyplenię z pośrodku ich.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Ní ti gbogbo àwọn aládùúgbò mi búburú tí wọ́n gbẹ́sẹ̀ lé ogún tí mo fún àwọn ènìyàn Israẹli mi, Èmi yóò fà wọ́n tu kúrò lórí ilẹ̀ wọn, èmi yóò fa ìdílé Juda tu kúrò ní àárín wọn.
15 Wszakże gdy ich wyplenię, nawrócę się i zmiłuję się nad nimi, a przywiodę zasię każdego z nich do dziedzictwa jego, i każdego z nich do ziemi jego.
Ṣùgbọ́n tí mo bá fà wọ́n tu tán, Èmi yóò padà yọ́nú sí wọn. Èmi yóò sì padà fún oníkálùkù ní ogún ìní rẹ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ ìní oníkálùkù.
16 I stanie się, jeźli się ucząc nauczą dróg ludu mojego, a przysięgać będą w imieniu mojem, mówiąc: Jako żyje Pan, jako oni nauczali lud mój przysięgać przez Baala, tedy pobudowani będą w pośrodku ludu mego.
Bí wọ́n bá sì kọ ìwà àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì fi orúkọ mi búra wí pé, ‘Níwọ̀n bí Olúwa ń bẹ láààyè,’ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti kọ́ àwọn ènìyàn mi láti fi Baali búra, nígbà náà ni a ó gbé wọn ró láàrín àwọn ènìyàn mi.
17 Ale jeźliby nie usłuchali, tedy wykorzenię ten naród, wyplenię i wytracę go, mówi Pan.
Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kan kò bá gbọ́, Èmi yóò fà á tu pátápátá, èmi yóò sì pa wọ́n run,” ni Olúwa wí.

< Jeremiasza 12 >