< Izajasza 61 >

1 Duch Panującego Pana jest nademną; przeto mię pomazał Pan, abym opowiadał Ewangeliję cichym, posłał mię, abym związał rany tych, którzy są skruszonego serca, abym zwiastował pojmanym wyzwolenie, a więźniom otworzenie ciemnicy;
Ẹ̀mí Olúwa Olódùmarè wà lára mi nítorí Olúwa ti fi àmì òróró yàn mí láti wàásù ìyìnrere fún àwọn tálákà. Ó ti rán mi láti ṣe àwòtán oníròbìnújẹ́ láti kéde ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn àti ìtúsílẹ̀ kúrò nínú òkùnkùn fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n,
2 Abym ogłosił miłościwy rok Pański, i dzień pomsty Boga naszego; abym cieszył wszystkich płaczących;
láti kéde ọdún ojúrere Olúwa àti ọjọ́ ẹ̀san ti Ọlọ́run wa, láti tu àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú,
3 Abym sprawił radość płaczącym w Syonie, a dał im ozdobę miasto popiołu, olejek wesela miasto smutku, odzienie chwały miasto ściśnionego; i będą nazwani drzewami sprawiedliwości, szczepieniem Pańskiem, abym był uwielbiony.
àti láti pèsè fún àwọn tí inú wọn bàjẹ́ ní Sioni láti dé wọn ládé ẹwà dípò eérú, òróró ayọ̀ dípò ọ̀fọ̀, àti aṣọ ìyìn dípò ìpòrúru ọkàn. A ó sì pè wọ́n ní igi óákù òdodo, irúgbìn Olúwa láti fi ọláńlá rẹ̀ hàn.
4 Tedy pobudują spustoszenie starodawne, pustynie stare naprawią, a odnowią miasta spustoszone, puste za wielu narodów.
Wọn yóò tún àwọn ahoro àtijọ́ kọ́ wọn yóò sì mú àwọn ibi ìparun àtijọ́-tijọ́ náà bọ̀ sípò; wọn yóò jí àwọn ahoro ìlú náà padà tí a ti parun láti ìrandíran sẹ́yìn.
5 Bo się stawią cudzoziemcy, a paść będą stada wasze, a synowie cudzoziemców oraczami waszymi i winiarzami waszymi będą.
Àwọn àjèjì ni yóò máa da ọ̀wọ́ ẹran rẹ; àwọn àlejò yóò sì ṣiṣẹ́ nínú oko àti ọgbà àjàrà rẹ.
6 Ale wy kapłanami Pańskimi nazwani będziecie, sługami Boga naszego zwać was będą; majętności pogan używać będziecie, a w sławie ich wywyższeni będziecie.
A ó sì máa pè yín ní àlùfáà Olúwa, a ó pè yín ní ìránṣẹ́ Ọlọ́run wa. Ẹ ó máa jẹ nínú ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè àti nínú ọrọ̀ wọn ni ẹ̀yin yóò máa ṣògo.
7 Za dwojakie pohańbienie i zelżywość waszę śpiewać będziecie; z działu ich, i w ziemi ich dwojakie dziedzictwo posiądziecie, a tak wesele wieczne mieć będziecie.
Dípò àbùkù wọn àwọn ènìyàn mi yóò gba ìlọ́po méjì, àti dípò àbùkù wọn wọn yóò yọ̀ nínú ìní wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jogún ìlọ́po méjì ní ilẹ̀ wọn, ayọ̀ ayérayé yóò sì jẹ́ tiwọn.
8 Ja Pan miłuję sąd, a mam w nienawiści łupiestwo przy całopaleniu; przetoż sprawię, aby uczynki ich działy się w prawdzie, a przymierze wieczne postanowię z nimi.
“Nítorí Èmi, Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òdodo; mo kórìíra olè jíjà àti ẹ̀ṣẹ̀. Ní òtítọ́ mi èmi yóò sẹ̀san fún wọn èmi yóò sì dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú wọn.
9 I znajome będzie między poganami nasienie ich, a potomstwo ich w pośrodku narodów; wszyscy, którzy ich ujrzą, poznają ich, że są nasieniem, któremu Pan pobłogosławił.
A ó mọ ìrandíran wọn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ìran wọn láàrín àwọn ènìyàn. Gbogbo àwọn tí ó bá rí wọn yóò mọ̀ pé wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tí Olúwa ti bùkún.”
10 Weseląc weselić się będą w Panu, a dusza moja rozraduje się w Bogu moim; bo mię oblókł w szaty zbawienia, a płaszczem sprawiedliwości przyodział mię, jako oblubieńca ozdobnego chwałą, i jako oblubienicę ozdobioną w klejnoty swoje.
Èmi yọ̀ gidigidi nínú Olúwa; ọkàn mi yọ̀ nínú Ọlọ́run mi. Nítorí ó ti wọ̀ mí ní aṣọ ìgbàlà ó sì ṣe mí lọ́ṣọ̀ọ́ nínú aṣọ òdodo; gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ti ṣe orí rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ bí àlùfáà, àti bí ìyàwó ṣe ń ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́.
11 Bo jako ziemia wydaje płód swój, a jako ogród nasienie swoje wywodzi, tak panujący Pan wywiedzie sprawiedliwość i chwałę swoję przed wszystkie narody.
Gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ti í mú irúgbìn jáde àti bí ọgbà ṣe ń mú irúgbìn dàgbà, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè yóò ṣe mú òdodo àti ìyìn kí ó ru sókè níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè.

< Izajasza 61 >