< Izajasza 6 >

1 Roku, którego umarł król Uzyjasz, widziałem Pana, siedzącego na stolicy wysokiej i wyniosłej, a podołek jego napełniał kościół.
Ní ọdún tí ọba Ussiah kú, mo rí Olúwa tí ó jókòó lórí ìtẹ́ tí ó ga tí a gbé sókè, ìṣẹ́tí aṣọ ìgúnwà rẹ̀ sì kún inú tẹmpili.
2 Serafinowie stali nad nim, sześć skrzydeł miał każdy z nich; dwoma zakrywał twarz swoję, a dwoma przykrywał nogi swoje, a dwoma latał.
Àwọn Serafu wà ní òkè rẹ̀, ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní ìyẹ́ mẹ́fà, wọ́n fi ìyẹ́ méjì bo ojú wọn, wọ́n fi méjì bo ẹsẹ̀ wọn, wọ́n sí ń fi méjì fò.
3 I wołał jeden do drugiego, mówiąc: Święty, święty, święty, Pan zastępów; pełna jest wszystka ziemia chwały jego.
Wọ́n sì ń kọ sí ara wọn wí pé, “Mímọ́, mímọ́, mímọ́ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun gbogbo ayé kún fún ògo rẹ̀.”
4 I poruszyły się podwoje u drzwi od głosu wołającego, a dom pełny był dymu.
Nípa ìró ohùn un wọn, òpó ìlẹ̀kùn àti gbogbo ògiri ilé náà sì mì tìtì, gbogbo inú tẹmpili sì kún fún èéfín.
5 I rzekłem: Biada mnie! jużem zginął, przeto, żem człowiek splugawionych warg, a mieszkam w pośrodku ludu, który ma splugawione wargi; a iż króla, Pana zastępów, widziały oczy moje.
Mo kígbe pé, “Ègbé ni fún mi! Mo ti gbé!” Nítorí mo jẹ́ ènìyàn aláìmọ́ ètè, mo sì ń gbé láàrín àwọn ènìyàn aláìmọ́ ètè, ojú mi sì ti rí ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ.
6 I przyleciał do mnie jeden z Serafinów, mając w ręce swej węgiel rozpalony, który kleszczykami wziął z ołtarza;
Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn Serafu wọ̀nyí fò wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹ̀yín iná ní ọwọ́ rẹ̀, èyí tí ó ti fi ẹ̀mú mú ní orí pẹpẹ.
7 I dotknął się ust moich, a rzekł: Oto się dotknął ten węgiel warg twoich, a odejdzie nieprawość twoja, a grzech twój zgładzony będzie.
Èyí ni ó fi kàn mí ní ẹnu tí ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ti kan ètè rẹ; a ti mú ẹ̀bi rẹ kúrò, a sì ti wẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nù.”
8 Potemem słyszał głos Pana mówiącego: Kogoż poślę? a kto nam pójdzie? Tedym rzekł: Otom ja, poślij mię.
Nígbà náà ni mo sì gbọ́ ohùn Olúwa wí pé, “Ta ni èmi yóò rán? Ta ni yóò sì lọ fún wa?” Nígbà náà ni èmi sì wí pé, “Èmi nìyí, rán mi!”
9 A on rzekł: Idź, a powiedz ludowi temu: Słuchajcie słuchając, a nie rozumijcie, a widząc patrzajcie, a nie poznawajcie.
Òun sì wí pé, “Tọ àwọn ènìyàn yìí lọ kí o sì wí fún wọn pé, “‘Ní gbígbọ́ ẹ̀yin yóò gbọ́, kì yóò sì yé e yín; ní rí rí ẹ̀yin yóò ri, ẹ̀yin kì yóò mọ òye.’
10 Zatwardź serce ludu tego, a uszy jego obciąż, i oczy jego zawrzyj, aby nie widział oczyma swemi, a uszyma swemi nie słyszał, i sercem swem nie zrozumiał, a nie nawrócił się, i nie był uzdrowion.
Mú kí àyà àwọn ènìyàn wọ̀nyí yigbì, mú kí etí wọn kí ó wúwo, kí o sì dìwọ́n ní ojú. Kí wọn kí ó má ba fi ojú wọn ríran, kí wọn kí ó má ba fi etí wọn gbọ́rọ̀, kí òye kí ó má ba yé ọkàn wọn, kí wọn kí ó má ba yípadà kí a má ba mú wọn ní ara dá.”
11 A gdym rzekł: Dokądże Panie? A on rzekł: Dokąd nie spustoszeją miasta, tak aby nie było obywatela; i domy, aby nie było w nich człowieka, a ziemia do szczętu nie spustoszeje;
Nígbà náà ni mo wí pé, “Báwo ni yóò ti pẹ́ tó Olúwa?” Òun sì dáhùn pé: “Títí àwọn ìlú ńlá yóò fi dahoro, láìsí olùgbé nínú rẹ̀ mọ́, títí tí àwọn ilé yóò fi wà láìsí ènìyàn, títí tí ilẹ̀ yóò fi dahoro pátápátá.
12 Dokąd Pan daleko nie zapędzi wszelkiego człowieka, a nie będzie doskonałe spustoszenie w pośród ziemi;
Títí tí Olúwa yóò fi rán gbogbo wọn jìnnà réré tí ilẹ̀ náà sì di ìkọ̀sílẹ̀ pátápátá.
13 Dokąd jeszcze na nią dziesiąta zguba nie przyjdzie, a dopiero skażona będzie, A wszakże jako one dęby, które są przy bramie Zallechet podporą, tak nasienie święte jest podporą jej.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìdámẹ́wàá ṣẹ́kù lórí ilẹ̀ náà, yóò sì tún pàpà padà di rírun. Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí igi tẹrẹbinti àti igi óákù, ti í fi kùkùté sílẹ̀ nígbà tí a bá gé wọn lulẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni irúgbìn mímọ́ náà yóò di kùkùté ní ilẹ̀ náà.”

< Izajasza 6 >