< Izajasza 59 >

1 Oto nie jest ukrócona ręka Pańska, aby zbawić nie mogła; a nie jest obciążone ucho jego, aby wysłuchać nie mogło.
Lódodo ọwọ́ Olúwa kò kúrú láti gbàlà, tàbí kí etí rẹ̀ wúwo láti gbọ́.
2 Ale nieprawości wasze roździał uczyniły między wami i między Bogiem waszym, a grzechy wasze sprawiły, że ukrył twarz przed wami, aby nie słyszał.
Ṣùgbọ́n ẹ̀ṣẹ̀ yín ló ti yà yín kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run yín; ẹ̀ṣẹ̀ yín ti fi ojú u rẹ̀ pamọ́ fún un yín tó bẹ́ẹ̀ tí òun kò fi le gbọ́.
3 Bo ręce wasze krwią są zmazane, a palce wasze nieprawością; wargi wasze mówią kłamstwo, a język wasz nieprawość świegoce.
Nítorí ọwọ́ yín di aláìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀, àti ìka ọwọ́ yín fún ẹ̀bi. Ètè yín ń pa irọ́ púpọ̀, ahọ́n yín sì ń sọ̀rọ̀ nǹkan ibi.
4 Niemasz ktoby się zastawiał o sprawiedliwość, ani jest ktoby się zasadzał o prawdę. Ufają w próżności, a mówią kłamstwo; poczynają ucisk, a rodzą nieprawość.
Kò sí ẹni tí ó béèrè fún ìdájọ́ òdodo; kò sí ẹni tí ó ro ẹjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú òtítọ́. Wọ́n gbẹ́kẹ̀lé àwíjàre asán àti ọ̀rọ̀ irọ́; wọ́n lóyún ìkà, wọn sì bí wàhálà.
5 Jaja bazyliszkowe wylęgli, a płótna pajęczego natkali. Ktoby jadł jaja ich, umrze, a jeźli je stłucze, wynijdzie jaszczórka.
Wọn ń pa ẹ̀yin paramọ́lẹ̀ wọn sì ń ta owú aláǹtakùn. Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹyin wọn yóò kú, àti nígbà tí a pa ọ̀kan, paramọ́lẹ̀ ni ó jáde.
6 Płótna ich nie godzą się na szatę, ani się przyodzieją robotami swemi. Uczynki ich są uczynki nieprawości, a sprawa łupiestwa jest w rękach ich.
Òwú wọn kò wúlò fún aṣọ rírán; wọn kò lè fi aṣọ tí wọ́n hun bo ara wọn. Iṣẹ́ wọn jẹ́ ti ibi, ìwà jàǹdùkú sì kún ọwọ́ wọn.
7 Nogi ich bieżą do złego, i kwapią się na wylanie krwi niewinnej. Myśli ich są myśli nieprawości; spustoszenie i starcie jest na drogach ich.
Ẹsẹ̀ wọn yára bọ́ sínú ẹ̀ṣẹ̀; wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀. Èrò wọn sì jẹ́ èrò ibi; ìparun àti ìdahoro ni ó wà ní ṣíṣe àmì ọ̀nà wọn.
8 Drogi pokoju nieznają, i niemasz sprawiedliwości w drogach ich; ścieszki swe sami pokrzywili u siebie; każdy, kto po nich chodzi, nie zna pokoju.
Ọ̀nà àlàáfíà èyí ni wọn kò mọ̀; kò sí òdodo ní ojú ọ̀nà wọn wọ́n ti sọ wọ́n dì ọ̀nà kọ́rọkọ̀rọ, kò sí ẹni tí ó tọ ọ̀nà yìí tí yóò rí àlàáfíà.
9 Dlatego oddalił się sąd od nas, a nie dochodzi nas sprawiedliwość; czekamy na światłość, a oto ciemność; na jasność, ale w ćmie chodzimy.
Nítorí èyí ni ẹ̀tọ́ fi jìnnà sí wa, àti tí òdodo kò fi tẹ̀ wá lọ́wọ́. A ń wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n gbogbo rẹ̀ jẹ́ òkùnkùn; ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n à ń rìn nínú òjìji.
10 Macamy ściany jako ślepi, a macamy, jakobyśmy oczów nie mieli. Potykamy się w południe jako w zmierzk; w wielkich dostatkach podobniśmy umarłym.
Gẹ́gẹ́ bí afọ́jú à ń táràrà lọ lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri tí a ń wá ọ̀nà wa gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí kò ní ojú. Ní ọ̀sán gangan ni à ń kọsẹ̀ bí ẹni pé alẹ́ ni; láàrín alágbára àwa dàbí òkú.
11 Mruczymy wszyscy jako niedźwiedź, jako gołębica ustawicznie stękamy; oczekujemy na sąd, ale go niemasz; na wybawienie, ale dalekie jest od nas.
Gbogbo wa là ń ké bí i beari; àwa pohùnréré ẹkún bí àdàbà. A ń wá ìdájọ́ òdodo ṣùgbọ́n kò sí; à ń wọ́nà fún ìtúsílẹ̀, ṣùgbọ́n ó jìnnà réré.
12 Bo się rozmnożyły przestępstwa nasze przed tobą, a grzechy nasze świadczą przeciwko nam, ponieważ nieprawości nasze są przy nas, i złości nasze uznajemy;
Nítorí àwọn àṣìṣe wa pọ̀ níwájú rẹ, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa sì ń jẹ́rìí takò wá. Àwọn àìṣedéédéé wa sì wà pẹ̀lú wa, àwa pẹ̀lú sì mọ àìṣedéédéé wa,
13 Żeśmy wystąpili, i kłamali przeciw Panu, i odwróciliśmy się, abyśmy nie szli za Bogiem naszym; żeśmy mówili o potwarzy i o odstąpieniu, żeśmy zmyślali i wywierali z serca swego słowa kłamliwe.
ọ̀tẹ̀ àti àrékérekè wa sí Olúwa, kíkọ ẹ̀yìn wa sí Ọlọ́run, dídá yánpọnyánrin àti ìnilára sílẹ̀, pípààrọ̀ tí ọkàn wa ti gbèrò síta.
14 Tak, że się sąd opak obrócił, a sprawiedliwość z daleka stoi; bo na ulicy prawda szwankowała, a prawość przejścia nie ma.
Nítorí èyí ni a ṣe lé ìdájọ́ òdodo sẹ́yìn, àti ti òdodo dúró lókèèrè; òtítọ́ ti ṣubú ní òpópó ọ̀nà, òdodo kò sì le è wọlé.
15 Owszem, prawda zginęła, a ten, co odstępuje od złego, na łup podany bywa. To widzi Pan, i nie podoba się to w oczach jego, że niemasz sądu.
A kò rí òtítọ́ mọ́, àti ẹni tí ó bá sá fun ibi tì di ìjẹ. Olúwa wò ó ọkàn rẹ̀ sì bàjẹ́ pé kò sí ìdájọ́ òdodo.
16 Gdy tedy widział, że niemasz żadnego męża, aż się zdumiał, że niemasz żadnego, coby się zastawił, a przetoż wybawienie sprawiło mu ramię jego, a sprawiedliwość jego sama go podparła.
Òun rí i pé kò sí ẹnìkan, àyà fò ó pé kò sí ẹnìkan láti ṣèrànwọ́; nítorí apá òun tìkára rẹ̀ ló ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún ara rẹ̀, àti òdodo òun tìkára rẹ̀ ló gbé e ró.
17 Bo się przyoblókł w sprawiedliwość jako w pancerz, a hełm zbawienia na głowie jego; oblókł się w odzienie pomsty jako w szatę, a odział się zapalczywością jako płaszczem;
Ó gbé òdodo wọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbàyà rẹ̀, àti àṣíborí ìgbàlà ní orí rẹ̀; ó gbé ẹ̀wù ẹ̀san wọ̀ ó sì yí ara rẹ̀ ní ìtara bí ẹ̀wù.
18 Aby według uczynków, aby według nich odpłacił popędliwością przeciwnikom swoim, aby nagrodę nieprzyjaciołom swoim, a wyspom zapłatę oddał.
Gẹ́gẹ́ bí ohun tí wọ́n ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni yóò san án ìbínú fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ àti ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá rẹ̀; òun yóò san án fún àwọn erékùṣù ẹ̀tọ́ wọn.
19 I będą się bali, którzy są na zachód, imienia Pańskiego, i którzy na wschód słońca, sławy jego. Gdy przypadnie nieprzyjaciel jako rzeka, tedy go duch Pański precz zapędzi.
Láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn ènìyàn yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa, àti láti ìlà-oòrùn, wọn yóò bọ̀wọ̀ fún ògo rẹ̀. Nítorí òun yóò wá gẹ́gẹ́ bí i rírú omi èyí tí èémí Olúwa ń tì lọ.
20 Bo przyjdzie do Syonu odkupiciel, i do tych, którzy się odwracają od występków w Jakóbie, mówi Pan.
“Olùdáǹdè yóò wá sí Sioni, sí àwọn tí ó wà ní Jakọbu tí ó ronúpìwàdà ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí.
21 A toć będzie przymierze moje z nimi, mówi Pan: Duch mój, który jest w tobie, i słowa moje, którem włożył w usta twoje, nie odstąpią od ust twoich, ani od ust nasienia twego, ani od ust potomków nasienia twego, mówi Pan, odtąd aż na wieki.
“Àti fún èmi, májẹ̀mú mi pẹ̀lú wọn nìyìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ̀mí mi, tí ó wà nínú yín, àti ọ̀rọ̀ mi tí mo ti fi sí ẹnu yín, kì yóò kúrò lẹ́nu yín, tàbí lẹ́nu àwọn ọmọ yín, tàbí láti ẹnu àwọn ìrandíran wọn láti àkókò yìí lọ àti títí láéláé,” ni Olúwa wí.

< Izajasza 59 >