< Izajasza 56 >

1 Tak mówi Pan: Strzeżcie sądu, a czyńcie sprawiedliwość; bo blisko tego, że zbawienie moje przyjdzie, a sprawiedliwość moja objawiona będzie.
Èyí ni ohun ti Olúwa sọ: “Ẹ pa ìdájọ́ mọ́ ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ̀nà, nítorí ìgbàlà mi súnmọ́ tòsí àti òdodo mi ni a ó fihàn láìpẹ́ jọjọ.
2 Błogosławiony człowiek, który to czyni, i syn człowieczy, który się trzyma tego, przestrzegając sabatu, aby go nie splugawił, a strzegąc ręki swej, aby nie uczyniła nic złego.
Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣe èyí, àti fún ọmọ ènìyàn tí ó dìímú ṣinṣin, tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́, tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi ṣíṣe.”
3 Niech tedy nie mówi cudzoziemiec, który przystaje do Pana, mówiąc: Zaiste Pan mię odłączył od ludu swego; niech też nie mówi trzebieniec: Otom ja drzewo suche.
Má ṣe jẹ́ kí àjèjì kan tí ó ti di ara rẹ̀ mọ́ Olúwa sọ wí pé, “Olúwa yóò yà mí sọ́tọ̀ kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.” Àti kí ìwẹ̀fà kan ṣe àròyé pé, “Igi gbígbẹ lásán ni mí.”
4 Albowiem tak mówi Pan o trzebieńcach, którzyby przestrzegali sabatów moich, a obrali to, co mi się podoba, i trzymali przymierze moje:
Nítorí pé báyìí ni Olúwa wí: “Sí àwọn ìwẹ̀fà yìí tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́, tí wọ́n yan ohun tí ó dùn mọ́ mi tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin
5 Żeć im dam w domu swym i między murami mojemi miejsce, i imię lepsze niżeli synów i córek; dam im imię wieczne, które nie będzie wygładzone.
fún wọn ni Èmi yóò fún nínú tẹmpili àti àgbàlá rẹ̀ ìrántí kan àti orúkọ kan tí ó sàn ju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin, Èmi yóò fún wọn ní orúkọ ayérayé tí a kì yóò ké kúrò.
6 A cudzoziemców, którzyby przystali do Pana, aby mu służyli, a miłowali imię Pańskie, będąc u niego za sługi, wszystkich przestrzegających sabaty, aby go nie splugawili, i zachowujących przymierze moje;
Àti àwọn àjèjì tí ó so ara wọn mọ́ Olúwa láti sìn ín, láti fẹ́ orúkọ Olúwa àti láti foríbalẹ̀ fún un gbogbo àwọn tí ń pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́ àti tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin—
7 Tych przywiodę na górę świętobliwości mojej, a uweselę ich w domu modlitwy mojej; całopalenia ich i ofiary ich przyjemne będą na ołtarzu moim; bo dom mój domem modlitwy nazwany będzie u wszystkich narodów.
àwọn wọ̀nyí ni èmi yóò mú wá òkè mímọ́ mi, èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀ nínú ilé àdúrà mi. Ẹbọ sísun wọn àti ìrúbọ wọn, ni a ó tẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi; nítorí a ó máa pe ilé mi ní ilé àdúrà fún gbogbo orílẹ̀-èdè.”
8 Tak mówi panujący Pan, który zgromadza rozpędzonych z Izraela: Jeszcze zgromadzę do niego, i do zgromadzonych jego.
Olúwa Olódùmarè sọ wí pé— ẹni tí ó kó àwọn àtìpó Israẹli jọ: “Èmi yóò kó àwọn mìíràn jọ pẹ̀lú wọn yàtọ̀ sí àwọn tí a ti kójọ.”
9 Wszystkie zwierzęta polne przyjdźcie na pożarcie, i wszystkie zwierzęta leśne.
Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin ẹranko inú pápá, ẹ wá jẹ àwọn ẹranko inú igbó run!
10 Stróżowie jego ślepi, wszyscy zgoła nic nie umieją, wszyscy są psami niememi, nie mogą szczekać; ospałymi są, leżą, kochają się w drzemaniu.
Àwọn olùṣọ́ Israẹli fọ́jú, gbogbo wọn ṣe aláìní ìmọ̀; gbogbo wọn jẹ́ adití ajá, wọn kò lè gbó; wọ́n sùn sílẹ̀ wọ́n ń lálàá, wọ́n fẹ́ràn láti máa sùn.
11 A są psami obżartemi, nie mogą się nigdy nasycić; sami się pasąc nie umieją nauczać. Wszyscy się za drogą swoją udali, każdy za łakomstwem swojem z strony swej, mówiąc:
Wọ́n jẹ́ àwọn ajá tí ó kúndùn púpọ̀; wọn kì í ní ànító. Wọ́n jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn tí kò ní òye; olúkúlùkù ń yà ṣọ́nà ara rẹ̀, ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn sì wá ère tirẹ̀.
12 Pójdźcie, nabiorę wina, a upijemy się mocnym napojem, a będzie nam jako dziś tak i jutro, i jeszcze daleko obficiej.
Igbe ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn ni wí pé, “Wá, fún mi ní ọtí wáìnì! Jẹ́ kí a mu ọtí líle wa lámu yó ọ̀la yóò sì dàbí òní, tàbí kí ó dára jù bẹ́ẹ̀ lọ.”

< Izajasza 56 >