< Izajasza 52 >

1 Ocuć się, ocuć się, oblecz się w moc twoję, Syonie! oblecz się w szatę ochędóstwa twego, o Jeruzalemie, miasto święte! Albowiem nie natrze na cię nieobrzezany i nieczysty.
Jí, jí, ìwọ Sioni, wọ ara rẹ ní agbára. Gbé aṣọ ògo rẹ wọ̀, ìwọ Jerusalẹmu, ìlú mímọ́ n nì. Àwọn aláìkọlà àti aláìmọ́ kì yóò wọ inú rẹ mọ́.
2 Otrząśnij się z prochu, powstań, siądź, Jeruzalemie! dobądź się z oków szyi swojej, o pojmana córko Syońska!
Gbọn eruku rẹ kúrò; dìde sókè, kí o sì gúnwà, ìwọ Jerusalẹmu. Bọ́ ẹ̀wọ̀n tí ń bẹ lọ́rùn rẹ kúrò, ìwọ ọ̀dọ́mọbìnrin ìgbèkùn Sioni.
3 Tak zaista Pan mówi: Darmoście się zaprzedali, przetoż bez pieniędzy odkupieni będziecie.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Ọ̀fẹ́ ni a tà ọ́, láìsanwó ni a ó sì rà ọ́ padà.”
4 Bo tak mówi panujący Pan: Do Egiptu wstąpił lud mój przedtem, aby tam pielgrzymował; ale Assyryjczyk bez przyczyny go trapi.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí. “Ní ìgbà àkọ́kọ́ àwọn ènìyàn mi sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti gbé; láìpẹ́ ni Asiria pọ́n wọn lójú.
5 A teraz cóż mam czynić? mówi Pan, ponieważ lud mój darmo jest pojmany, a ci, którzy panują nad nim, do wzdychania go przywodzą, mówi Pan; nadto ustawicznie każdego dnia imię moje bluźnione bywa.
“Àti ní àkókò yìí, kí ni mo ní níbí?” ni Olúwa wí. “Nítorí a ti kó àwọn ènìyàn mi lọ lọ́fẹ̀ẹ́, àwọn tí ó sì ń jẹ ọba lórí wọn fi wọ́n ṣẹlẹ́yà,” ni Olúwa wí. “Àti ní ọjọọjọ́ orúkọ mi ni asọ̀rọ̀-òdì sí nígbà gbogbo.
6 Przetoż pozna lud mój imię moje, przetoż pozna, mówię, dnia onego, żem Ja jest ten, który mówię; otom Ja przytomny.
Nítorí náà àwọn ènìyàn mi yóò mọ orúkọ mi; nítorí ní ọjọ́ náà, wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni ó ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni, Èmi ni.”
7 O jako piękne są na górach nogi tego, co pocieszne rzeczy zwiastuje, i opowiada pokój; tego, co zwiastuje dobre, i opowiada zbawienie, a mówi do Syonu: Bóg twój króluje!
Báwo ni ó ṣe dára tó lórí òkè ẹsẹ̀ àwọn tí ó mú ìyìnrere ayọ̀ wá, tí wọ́n kéde àlàáfíà, tí ó mú ìyìnrere wá, tí ó kéde ìgbàlà, tí ó sọ fún Sioni pé, “Ọlọ́run rẹ ń jẹ ọba!”
8 Wynoszą głos stróżowie twoi, głos wynoszą, a społem wykrzykać będą; bo okiem w oko ujrzą, że zasię Pan Syon przywiedzie.
Tẹ́tí sílẹ̀! Àwọn olùṣọ́ rẹ gbé ohùn wọn sókè wọ́n kígbe papọ̀ fún ayọ̀. Nígbà tí Olúwa padà sí Sioni, wọn yóò rí i pẹ̀lú ojú u wọn.
9 Wykrzykajcie a śpiewajcie społem, pustynie Jeruzalemskie! bo pocieszył Pan lud swój, odkupił Jeruzalem.
Ẹ bú sí orin ayọ̀ papọ̀, ẹ̀yin ahoro Jerusalẹmu, nítorí Olúwa ti tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú, ó sì ti ra Jerusalẹmu padà.
10 Wysmuknął Pan ramię świętobliwości swojej przed oczyma wszystkich narodów, aby oglądały wszystkie kończyny ziemi zbawienie Boga naszego.
Olúwa yóò ṣí apá mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀ ní ojú gbogbo orílẹ̀-èdè, àti gbogbo òpin ilẹ̀ ayé yóò rí ìgbàlà Ọlọ́run wa.
11 Odstąpcie, odstąpcie wynijdźcie z Babilonu, nieczystego się nie dotykajcie, wynijdźcie z pośrodku jego; oczyście się wy, którzy nosicie naczynie Pańskie.
Ẹ túká, ẹ túká, ẹ jáde kúrò níhìn-ín yìí! Ẹ má fọwọ́ kan ohun àìmọ́ kan! Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ kí ẹ sì di mímọ́, ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé ohun èlò Olúwa.
12 Bo nie z trzaskiem wynijdziecie, ani uciekając pójdziecie; pójdzie zaiste Pan przed wami, a zgromadzi was Bóg Izraelski.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kì yóò yára kúrò tàbí kí ẹ sáré lọ; nítorí Olúwa ni yóò síwájú yín lọ, Ọlọ́run Israẹli ni yóò sì ṣe ààbò lẹ́yìn ín yín.
13 Oto się szczęśliwie powiedzie słudze memu. Wywyższony i podniesiony i bardzo uwielbiony będzie.
Kíyèsi i, ìránṣẹ́ mi yóò hùwà ọlọ́gbọ́n; òun ni a ó gbé sókè tí a ó sì gbéga a ó sì gbé e lékè gidigidi.
14 Jako wiele ich zdumieją się nad nim, że przemierzła jest nad innych ludzi osoba jego, a kształt jego nad synów ludzkich:
Gẹ́gẹ́ bí a ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ tí wọ́n ń bu ọlá fún un— ìwò ojú rẹ ni a ti bàjẹ́ kọjá ti ẹnikẹ́ni àti ìrísí rẹ̀ ní a ti bàjẹ́ kọjá ohun tí ènìyàn ń fẹ́.
15 Tak zasię pokropi wiele narodów, i królowie przed nim zatulą usta swe, przeto, że czego im nie powiadano, to oglądają, a to, o czem nie słyszeli, wyrozumieją.
Bẹ́ẹ̀ ni yóò ṣe bomirin àwọn orílẹ̀-èdè ká, àwọn ọba yóò sì pa ẹnu wọn mọ́ nítorí rẹ̀. Nítorí ohun tí a kò sọ fún wọn, wọn yóò rí i, àti ohun tí wọn kò tí ì gbọ́, ni yóò sì yé wọn.

< Izajasza 52 >