< Izajasza 50 >

1 Tak mówi Pan: Gdzie jest list rozwodny matki waszej, którymem ją wolno puścił? albo kto jest z pożyczalników moich, któremum was zaprzedał? Otoście nieprawościami swojemi sami siebie zaprzedali, a dla przestępstw waszych wolno puszczona jest matka wasza.
Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Níbo ni ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ ìyá rẹ wà èyí tí mo fi lé e lọ? Tàbí èwo nínú àwọn olùyánilówó mi ni mo tà ọ́ fún? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ni a fi tà ọ́; nítorí àìṣedéédéé rẹ ni a fi lé ìyá rẹ lọ.
2 Przeczże, gdy przychodzę, niemasz nikogo? a gdy wołam, nikt się nie ozywa? Izali tak jest ukrócona ręka moja, aby nie mogła odkupić? Izali niemasz we mnie mocy ku wybawieniu? Oto fukiem moim osuszam morze, obracam rzeki w pustynie, tak iż zaśmier dną ryby ich dla niedostatku wody, i zdychają od pragnienia.
Nígbà tí mo wá, èéṣe tí a kò fi rí ẹnìkan? Nígbà tí mo pè, èéṣe tí kò fi sí ẹnìkan láti dáhùn? Ọwọ́ mi a kúrú láti gbà ọ́? Èmi kò ha ní agbára láti gbà ọ́ bí? Nípa ìbáwí lásán, Èmi gbẹ omi òkun, Èmi yí àwọn odò sí aṣálẹ̀; àwọn ẹja wọn rà fún àìsí omi wọ́n sì kú fún òǹgbẹ.
3 Obłoczę niebiosa w ciemności, a wór daję za odzienie ich.
Èmi fi òkùnkùn bo sánmọ̀ mo sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ ṣe ìbòrí rẹ̀.”
4 Panujący Pan dał mi język umiejętny, abym umiał czasu przygodnego mówić słowo upracowanemu. Budzi mię na każdy zaranek, pobudza uszy moje, abym słuchał tak jako uczący się pilnie.
Olúwa Olódùmarè ti fún mi ni ahọ́n tí a fi iṣẹ́ rán, láti mọ àwọn ọ̀rọ̀ tí ó lè gbé àwọn aláàárẹ̀ ró. O jí mi láràárọ̀, o jí etí mi láti gbọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹni tí à ń kọ́.
5 Panujący Pan otwiera mi uszy, a Ja się nie sprzeciwiam, ani się na wstecz wracam.
Olúwa Olódùmarè ti ṣí mi ní etí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ṣọ̀tẹ̀ rí; Èmi kò sì padà sẹ́yìn.
6 Ciała mego nadstawiam bijącym, a policzków moich tym, którzy mię targają; twarzy mojej nie zakrywam od obelżenia i plwania.
Mo ṣí ẹ̀yìn mi sílẹ̀ fún àwọn tí ó ń nà mí, àti ẹ̀rẹ̀kẹ́ mi fún àwọn tí ń fa irùngbọ̀n mi; Èmi kò fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹlẹ́yà àti ìyọṣùtì sí.
7 Bo panujący Pan wspomaga mię; przetoż nie bywam pohańbiony. Dla tego postawiłem twarz moję jako krzemień, gdyż wiem, że pohańbiony nie będę.
Nítorí Olúwa Olódùmarè ràn mí lọ́wọ́, a kì yóò dójútì mí. Nítorí náà ni mo ṣe gbé ojú mi ró bí òkúta akọ èmi sì mọ pé, ojú kò ní tì mí.
8 Bliskoć jest ten, który mię usprawiedliwia. Któż się sprzeczać będzie ze mną? Stańmy społem; kto ma prawo ze mną, niech przystąpi ku mnie.
Ẹni tí ó dá mi láre wà nítòsí. Ta ni ẹni náà tí yóò fẹ̀sùn kàn mí? Jẹ́ kí a kojú ara wa! Ta ni olùfisùn mi? Jẹ́ kí ó kò mí lójú!
9 Oto panujący Pan pomagać mi będzie; któż jest, coby mię potępił? Oto wszyscy takowi jako odzienie zwiotszeją, a mól zgryzie ich.
Olúwa Olódùmarè ni ó ń ràn mí lọ́wọ́. Ta ni ẹni náà tí yóò dá mi lẹ́bi? Gbogbo wọn yóò gbó bí aṣọ; kòkòrò ni yóò sì jẹ wọn run.
10 Kto jest między wami bojący się Pana, posłuchaj głosu sługi jego; kto jest, co chodzi w ciemnościach a nie ma światłości? ufaj w imieniu Pańskiem, a spolegaj na Bogu swoim.
Ta ni nínú yín tí ó bẹ̀rù Olúwa tí ó sì ń gbọ́rọ̀ sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lẹ́nu? Jẹ́ kí ẹni tí ń rìn ní òkùnkùn tí kò ní ìmọ́lẹ̀, kí ó gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa kí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run rẹ̀.
11 Oto wy wszyscy, którzy rozniecacie ogień, a przepasujecie się iskrami, chodźcież w światłości ognia waszego, i w iskrach, któreście rozniecili; z ręki mojej wam się to stanie, że w boleści leżeć będziecie.
Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí, gbogbo ẹ̀yin ti ń tanná tí ẹ sì ń fi pèsè iná ìléwọ́ fún ara yín, ẹ lọ, kí ẹ sì máa rìn nínú ìmọ́lẹ̀ iná yín, àti nínú ẹta iná tí ẹ ti dá. Èyí ni yóò jẹ́ tiyín láti ọwọ́ mi wá. Ẹ̀yin ó dùbúlẹ̀ nínú ìrora.

< Izajasza 50 >