< Izajasza 36 >

1 I stło się czternastego roku królowania Ezechyjasza, że przyciągnął Sennacheryb, król Assyryjski, przeciwko wszystkim miastom Judzkim obronnym, i pobrał je.
Ní ọdún kẹrìnlá ìjọba Hesekiah, Sennakeribu ọba Asiria kọlu gbogbo àwọn ìlú olódi ní ilẹ̀ Juda ó sì kó gbogbo wọn.
2 I posłał król Assyryjski Rabsacesa z Lachys, do Jeruzalemu, do króla Ezechyjasza z wielkiem wojskiem, który stanął u rur sadzawki wyższej przy drodze pola blecharzowego.
Lẹ́yìn náà, ọba Asiria rán olórí ogun rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ-ogun láti Lakiṣi sí ọba Hesekiah ní Jerusalẹmu. Nígbà tí ọ̀gágun náà dúró níbi ojúṣàn adágún ti apá òkè, ní ojú ọ̀nà sí pápá alágbàfọ̀,
3 Tedy wyszedł do niego Elijakim, syn Helkijaszowy, przełożony nad domem, i Sobna pisarz, i Joach, syn Asafowy, kanclerz.
Ṣebna Eliakimu ọmọ Hilkiah alábojútó ààfin, Ṣebna akọ̀wé, àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé jáde lọ pàdé rẹ̀.
4 I rzekł do nich Rabsaces: Proszę, powiedzcie Ezechyjaszowi: Tak mówi król wielki, król Assyryjski: Cóż to za ufność, którą ufasz?
Ọ̀gágun náà sọ fún wọn wí pé, “Ẹ sọ fún Hesekiah, “‘Èyí yìí ni ohun tí ọba ńlá, ọba Asiria sọ pé: Lórí i kí ni ìwọ gbé ìgbẹ́kẹ̀lé tìrẹ yìí lé?
5 Rzekłbym: (Acz to rzecz daremna) Snać rady i mocy do wojny dosyć masz; ale w kimże ufasz, że mi się sprzeciwiasz?
Ìwọ sọ wí pé ìwọ ní ète àti agbára ogun—ṣùgbọ́n ìwọ ń sọ ọ̀rọ̀ asán. Ta ni ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tí ìwọ fi ṣọ̀tẹ̀ sí mi?
6 Otoś spoległ na lasce tej trzciny nałamanej, na Egipcie, którą jeźliby się kto podparł, wnijdzie w rękę jego, i przekole ją. Takić jest Farao, król Egipski, wszystkim, którzy w nim ufają.
Wò ó nísinsin yìí, ìwọ gbẹ́kẹ̀lé Ejibiti ẹ̀rún igi ọ̀pá lásán tí í gún ni lọ́wọ́ tí í sì í dọ́gbẹ́ sí ni lára tí a bá gbára lé e! Bẹ́ẹ̀ ni Farao ọba Ejibiti sí àwọn tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé e.
7 A jeźli mi rzeczesz: W Panu, Bogu naszym, ufamy; azaż nie ten jest, którego zniósł Ezechyjasz wyżyny i ołtarze, i przykazał Judzie i Jeruzalemowi mówiąc: Przed tym ołtarzem kłaniać się będziecie?
Bí o bá sì sọ fún mi pé, “Àwa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run wa,” kì í ṣe òun ni Hesekiah ti mú àwọn ibi gíga àti pẹpẹ rẹ̀ kúrò, tí ó sì wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, “Ẹ̀yin gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ yìí”?
8 Przetoż teraz proszę, zaręcz się Panu memu, królowi Assyryjskiemu, a ja tobie dam dwa tysiące koni, będzieszli je mógł osadzić jezdnymi.
“‘Ẹ wá nísinsin yìí, bá ọ̀gá mi pa ìmọ̀ pọ̀, ọba Asiria, èmi yóò fún ọ ní ẹgbẹ̀rún méjì ẹṣin bí ìwọ bá le è fi agẹṣin lé wọn lórí!
9 I jakoż się ty możesz oprzeć hetmanowi jednemu najmniejszemu z sług pana mego, choć ufasz w Egipcie dla wozów i jezdnych?
Báwo ni ẹ ṣe lè lé ẹyọ kan ṣoṣo padà nínú èyí tí ó kéré jù nínú àwọn balógun olúwa mi, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ gbẹ́kẹ̀lé Ejibiti fún kẹ̀kẹ́-ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin?
10 Nadto czy bez woli Pańskiej przyciągnąłem do tej ziemi, abym ją spustoszył? Pan rzekł do mnie: Ciągnij do tej ziemi, a spustosz ją.
Síwájú sí i, ǹjẹ́ mo wa lè wá bá ilẹ̀ yìí jà kí n sì pa á run láìsí Olúwa? Olúwa fún rara rẹ̀ ló sọ pé kí n bá orílẹ̀-èdè yìí jà kí n sì pa á run.’”
11 Tedy rzekł Elijakim, i Sobna, i Joach do Rabsacesa: Proszę, mów do sług twoich po syryjsku, wszak rozumiemy, a nie mów do nas po żydowsku przed tym ludem, który jest na murze.
Lẹ́yìn náà ni Eliakimu, Ṣebna àti Joah sọ fún ọ̀gágun náà pé, “Jọ̀wọ́ máa bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ sọ̀rọ̀ ní èdè Aramaiki, nítorí pé àwa gbọ́ ọ. Má ṣe bá wa sọ̀rọ̀ ní èdè Heberu ní etí àwọn ènìyàn tí ó wà lórí ògiri mọ́.”
12 I odpowiedział Rabsaces: Azaż mię do Pana twego albo do ciebie posłał Pan mój, abym te słowa mówił? Posłał mię raczej do mężów, którzy siedzą na murze, aby jedli łajna swoje, a mocz swój pospołu z wami pili.
Ṣùgbọ́n aláṣẹ dáhùn pé, “Ṣé fún ọ̀gá rẹ àti ìwọ nìkan ní ọ̀gá mi rán mi sí láti sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí kì í sì í ṣe fún àwọn ọkùnrin tí ó jókòó lórí odi ni gẹ́gẹ́ bí ìwọ, ni yóò ní láti jẹ ìgbẹ́ ará wọn kí wọ́n sì mu ìtọ̀ ará wọn?”
13 A tak stanął Rabsaces i wołał głosem wielkim po żydowsku, mówiąc: Słuchajcie słów króla wielkiego, króla Assyryjskiego.
Lẹ́yìn náà ni ọ̀gágun náà dìde tí ó sì ké síta ní èdè Heberu pé, “Ẹ gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ ọba ńlá, ọba Asiria!
14 Tak mówi król: Niech was nie zwodzi Ezechyjasz: bo was nie będzie mógł wybawić.
Ohun tí ọba wí nìyìí, Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah tàn yín jẹ. Òun kò le è gbà yín sílẹ̀!
15 A niech wam nie rozkazuje Ezechyjasz ufać w Panu, mówiąc: Zapewne nas Pan wybawi, a nie będzie to miasto podane w rękę króla Assyryjskiego.
Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah rọ̀ yín láti gbẹ́kẹ̀lé Olúwa nígbà tí ó sọ pé, ‘Olúwa yóò kúkú gbà wá; a kì yóò fi ìlú yìí lé ọba Asiria lọ́wọ́.’
16 Nie słuchajcież Ezechyjasza; albowiem tak powiedział król Assyryjski: Uczyńcie zemną przymierze, a wynijdźcie do mnie, a jedz każdy z was z winnicy swojej, i każdy z figowego drzewa swego, a pij każdy z was wodę z studni swojej;
“Ẹ má ṣe tẹ́tí sí Hesekiah. Ohun tí ọba Asiria wí nìyìí. Ẹ fi ẹ̀bùn bá mi rẹ́, kí ẹ sì jáde tọ̀ mí wá. Lẹ́yìn náà, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín yóò sì jẹ nínú àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni yóò sì mu omi nínú kànga rẹ̀,
17 Aż przyjdę a pobiorę was do ziemi podobnej ziemi waszej, do ziemi zboża i wina, do ziemi chleba i winnic.
títí tí èmi yóò fi mú un yín lọ sí ilẹ̀ kan tí ó dàbí i tiyín, ilẹ̀ tí ó ní irúgbìn oníhóró àti wáìnì tuntun, ilẹ̀ tí ó ní àkàrà àti ọgbà àjàrà.
18 Niech was nie zwodzi Ezechyjasz, mówiąc: Pan nas wybawi. Izaż mogli bogowie narodów wybawić każdy ziemię swoję z ręki króla Assyryjskiego?
“Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah ṣì yín lọ́nà nígbà tí ó sọ wí pé, ‘Olúwa yóò gbà wá.’ Ǹjẹ́ ọlọ́run orílẹ̀-èdè kan ha ti gbà á kúrò lọ́wọ́ ọba Asiria bí?
19 Gdzież są bogowie Emat i Arfad? Gdzie są bogowie Sefarwaim? Azaż wybawił Samaryję z ręki mojej?
Níbo ni àwọn òrìṣà Hamati àti Arpadi ha wà? Níbo ni àwọn òrìṣà Sefarfaimi ha wà? Ǹjẹ́ wọn ti já Samaria gbà kúrò lọ́wọ́ mi bí?
20 Którzyż są między wszystkimi bogami tych ziem, którzyby wydarli ziemię swoję z ręki mojej? A miałby Pan wybawić Jeruzalem z ręki mojej?
Èwo nínú àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ló ha ti dáàbò bo ilẹ̀ ẹ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi? Báwo ni Olúwa ṣe wá le gba Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ mi?”
21 Ale oni milczeli, i nie odpowiedzieli mu i słowa; bo takie było rozkazanie królewskie, mówiąc: Nie odpowiadajcie mu.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà dákẹ́ rọ́rọ́ wọn kò sì mú èsì kankan wá, nítorí ọba ti pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá a lóhùn.”
22 I przyszedł Elijakim, syn Helkijaszowy, przełożony domu, i Sobna pisarz, i Joach, syn Asafowy, kanclerz, do Ezechyjasza, rozdarłszy szaty swe, i oznajmili mu słowa Rabsacesowe.
Lẹ́yìn náà ni Eliakimu ọmọ Hilkiah alákòóso ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé àkọsílẹ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah pẹ̀lú aṣọ wọn ní fífàya, wọ́n sì sọ ohun tí ọ̀gágun ti wí.

< Izajasza 36 >