< Izajasza 35 >

1 Weselić się z tego będzie pustynia i miejsce leśne, a rozraduje się i zakwitnie jako róża.
Aginjù àti ìyàngbẹ ilẹ̀ yóò yọ̀ fún wọn; aginjù yóò ṣe àjọyọ̀ yóò sì kún fún ìtànná. Gẹ́gẹ́ bí ewéko,
2 Ślicznie zakwitnie, i radując się weselić się będzie z wykrzykaniem; chwała Libanu będzie jej dana, i ozdoba Karmelu i Saronu. One ujrzą chwałę Pańską i ozdobę Boga naszego.
ní títanná yóò tanná; yóò yọ ayọ̀ ńlá ńlá yóò sì kọrin. Ògo Lebanoni ni a ó fi fún un, ẹwà Karmeli àti Ṣaroni; wọn yóò rí ògo Olúwa, àti ẹwà Ọlọ́run wa.
3 Umacniajcie ręce osłabiałe, a kolana zemdlałe posilajcie.
Fún ọwọ́ àìlera lókun, mú orúnkún tí ń yẹ̀ lókun.
4 Mówcie do zatrwożonych w sercu: Zmocnijcie się, nie bójcie się; oto Bóg wasz z pomstą przyjdzie; z nagrodą Bóg sam przyjdzie, i zbawi was.
Sọ fún àwọn oníbẹ̀rù ọkàn pé, “Ẹ ṣe gírí, ẹ má bẹ̀rù; Ọlọ́run yín yóò wá, òun yóò wá pẹ̀lú ìgbẹ̀san; pẹ̀lú ìgbẹ̀san mímọ́ òun yóò wá láti gbà yín là.”
5 Tedy się otworzą oczy ślepych, a uszy głuchych tworzone będą.
Nígbà náà ni a ó la ojú àwọn afọ́jú àti etí àwọn odi kì yóò dákẹ́.
6 Tedy poskoczy chromy jako jeleń, a niemych język śpiewać będzie; albowiem wody na puszczy wynikną, a potoki na pustyniach.
Nígbà náà ni àwọn arọ yóò máa fò bí àgbọ̀nrín, àti ahọ́n odi yóò ké fún ayọ̀. Odò yóò tú jáde nínú aginjù àti àwọn odò nínú aṣálẹ̀.
7 I stanie się miejsce suche jeziorem, a bezwodne źródłami wód; w łożyskach smoków, kędy legali, trawa, trzcina, i sitowie rość będzie.
Ilẹ̀ iyanrìn yíyan yóò di àbàtà, ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ yóò di orísun omi. Ní ibùgbé àwọn dragoni, níbi tí olúkúlùkù dùbúlẹ̀, ni ó jẹ́ ọgbà fún eèsún àti papirusi.
8 I będzie tam droga i ścieszka, która drogą świętą słynąć będzie; nie pójdzie po niej nieczysty, ale będzie dla onych samych. Którzy tą drogą pójdą, i głupi nawet, nie zbłądzą.
Àti òpópónà kan yóò wà níbẹ̀: a ó sì máa pè é ní ọ̀nà ìwà mímọ́. Àwọn aláìmọ́ kì yóò tọ ọ̀nà náà; yóò sì wà fún àwọn tí ń rìn ní ọ̀nà náà, àwọn ìkà búburú kì yóò gba ibẹ̀ kọjá.
9 Nie będzie tam lwa, a okrutny zwierz nie będzie chodził po niej, ani się tam znajdzie; ale wybawieni po niej chodzić będą.
Kì yóò sí kìnnìún níbẹ̀, tàbí kí ẹranko búburú kí ó dìde lórí i rẹ̀; a kì yóò rí wọn níbẹ̀. Ṣùgbọ́n àwọn ẹni ìràpadà nìkan ni yóò rìn níbẹ̀,
10 Odkupieni, mówię, Pańscy nawrócą się, i przyjdą na Syon z śpiewaniem, a wesele wieczne będzie na głowie ich; radość i wesele otrzymają, a żałość i smutek uciecze.
àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá. Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin; ayọ̀ ayérayé ni yóò dé wọn ní orí. Ìdùnnú àti ayọ̀ ni yóò borí i wọn, ìkorò àti ìtìjú yóò sì sá kúrò lọ́dọ̀ wọn.

< Izajasza 35 >