< Izajasza 10 >

1 Biada tym, którzy stanowią prawa niesprawiedliwe! i pisarzom, którzy ucisk na innych spisują!
Ègbé ni fún àwọn ti ń ṣe òfin àìṣòdodo,
2 Aby odpychali ubogiego od sądu, a wydzierali sprawiedliwość ubogich ludu mego; aby wdowy były korzyścią ich, a sierotki łupem ich.
láti dún àwọn aláìní ní ẹ̀tọ́ wọn àti láti fa ọwọ́ ìdájọ́ sẹ́yìn kúrò níwájú àwọn olùpọ́njú ènìyàn mi, wọ́n sọ àwọn ọ̀pọ̀ di ìjẹ fún wọn, wọ́n sì ń ja àwọn aláìní baba lólè.
3 Cóż uczynicie w dzień nawiedzenia, i spustoszenia, które z daleka przyjdzie? do kogoż się ucieczecie o wspomożenie? a gdzie zostawicie sławę waszę?
Kí ni ìwọ yóò ṣe ní ọjọ́ ìṣirò nígbà tí ìparun bá ti ọ̀nà jíjìn wá? Ta ni ìwọ yóò sá tọ̀ fún ìrànlọ́wọ́? Níbo ni ìwọ yóò fi ọrọ̀ rẹ sí?
4 Aby się nie miała między więźniami uniżyć, i między pobitymi upaść. A wszakże w tem wszystkiem nie odwróci się zapalczywość jego; ale jeszcze ręką jego będzie wyciągniona.
Ohunkóhun kò ní ṣẹ́kù mọ́ bí kò ṣe láti tẹ̀ ba láàrín àwọn ìgbèkùn tàbí kí o ṣubú sáàrín àwọn tí a pa. Pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ìbínú rẹ̀ kò kúrò, ọwọ́ rẹ̀ sì tún gbé sókè.
5 Biada Assurowi, rózdze gniewu mego! chociaż kij rozgniewania mego jest w ręku jego.
“Ègbé ni fún àwọn ará Asiria, ọ̀gọ ìbínú mi, ní ọwọ́ ẹni tí kùmọ̀ ìbínú mi wà!
6 Na naród obłudny poślę go, a o ludu zapalczywości mojej przykażę mu, aby brał łup i wydzierał korzyści a położył go na podeptanie, jako błoto na ulicach.
Mo rán an sí orílẹ̀-èdè aláìní Ọlọ́run, mo dojú rẹ̀ kọ àwọn ènìyàn tí ó mú mi bínú láti já ẹrù gbà, àti láti kó ìkógun láti tẹ̀ mọ́lẹ̀ bí amọ̀ ní ojú òpópó.
7 Lecz on nie tak będzie mniemał, i serce jego nie tak będzie myślało, ponieważ w sercu swem ułożył, aby wytracił i wykorzenił niemało narodów.
Ṣùgbọ́n, èyí kì í ṣe ohun tí ó fẹ́ ṣe, èyí kọ́ ni ohun tí ó ní lọ́kàn; èrò rẹ̀ ni láti parun, láti fi òpin sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè.
8 Albowiem rzecze: Izali książęta moi nie są też i królmi?
‘Kì í ha ṣe pé ọba ni gbogbo àwọn aláṣẹ mi?’ ni Olúwa wí.
9 Izali Chalmo nie jest jako Karchemis? Izali Arfat nie jest jako Emat? Izali Samaryja nie jest jako Damaszek?
‘Kì í ha ṣe pé Kalno dàbí i Karkemiṣi? Hamati kò ha dàbí i Arpadi, àti Samaria bí i Damasku?
10 Jako ręka moja znalazła królestwa bałwańskie, chociaż bałwany ich większe były, niż w Jeruzalemie i w Samaryi.
Gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ mi ti gbá ìjọba àwọn òrìṣà mú, ìjọba tí ère rẹ̀ pọ̀ ju ti Jerusalẹmu àti Samaria lọ.
11 Izali Jeruzalemowi i bałwanom jego tak nie uczynię, jakom uczynił Samaryi i bałwanom jej?
Èmi kì yóò a bá Jerusalẹmu wí àti àwọn ère rẹ̀?’” Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ṣe sí Samaria àti àwọn ère rẹ̀?
12 I stanie się, gdy Pan wykona wszystkę sprawę swoję na górze Syońskiej i w Jeruzalemie, że nawiedzę owoc wyniosłego serca króla Assyryjskiego, i pychę wysokich oczów jego;
Nígbà tí Olúwa ti ṣe iṣẹ́ rẹ̀ sí òkè Sioni àti Jerusalẹmu, yóò sọ wí pé, “Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Asiria nítorí gààrù àyà rẹ̀ àti ìgbéraga ojú rẹ̀.
13 Bo rzecze: W mocy ręki mojej uczyniłem to, i w mądrości mojej; bom był mądry, i odjąłem granice narodów, a skarby ich zabrałem, i wytraciłem obywateli jako mocarz.
Nítorí ó sọ pé: “‘Pẹ̀lú agbára ọwọ́ mi ni mo fi ṣe èyí àti pẹ̀lú ọgbọ́n ọ̀n mi, nítorí mo ní òye. Mo mú ààlà àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, mo sì ti kó ìṣúra wọn. Gẹ́gẹ́ bí alágbára kan, mo borí àwọn ọba wọn.
14 Owszem ręka moja znalazła majętność narodów jako gniazdo; a jako zbierają jajka, które są opuszczone, takiem ja wszystkę ziemię zebrał, a nie był ktoby skrzydłem ruszył, albo otworzył usta, i coby mruczał.
Bí ènìyàn ti í tọwọ́ bọ ìtẹ́ ẹyẹ, bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi tẹ ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè. Bí ènìyàn ti í kó ẹyin tí a kọ̀sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni mo kó àwọn orílẹ̀-èdè kò sí èyí tí ó fi apá lu apá, tàbí kí ó ya ẹnu láti dún.’”
15 Izali się będzie przechwalała siekiera przeciw temu, który nią rąbie? Izali się będzie wynosiła piła przeciw temu, który nią trze? jakożby się wynosiła rózga przeciw temu, który ją podniósł? jakożby się przechwalał kij, że nie jest drewnem?
Ǹjẹ́ àáké le gbé ara rẹ̀ sókè kọjá ẹni tí ó ń fì í, tàbí kí ayùn fọ́nnu sí ẹni tí ó ń lò ó? Àfi bí ẹni pé ọ̀pá ó na ẹni tí ó gbé e sókè, tàbí kí kùmọ̀ lu èyí tí kì í ṣe igi.
16 Przetoż Pan, Pan zastępów, pośle na tłustych jego suchoty, a pod sławą jego z prędka się zapali, jako gwałtowny ogień;
Nítorí náà, ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò rán ààrùn ìrẹ̀dànù sórí àwọn akíkanjú jagunjagun, lábẹ́ ògo rẹ̀ ni iná kan yóò ti sọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun.
17 Bo Światłość Izraelowa będzie ogniem, a Święty jego płomieniem, który spali i pożre ciernie jego i oset jego dnia jednego.
Ìmọ́lẹ̀ Israẹli yóò di iná, Ẹni Mímọ́ rẹ̀ yóò jẹ́ ọ̀wọ́-iná, ní ọjọ́ kan ṣoṣo yóò jó yóò sì run àti ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n.
18 Także wspaniałość lasu jego i urodzajnych pól jego, od duszy aż do ciała zniszczy, i stanie się jako chorąży od strachu uciekający.
Gbogbo ẹwà igbó o rẹ̀, àti àwọn pápá ọlọ́ràá gbogbo rẹ̀ ni yóò run pátápátá, gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó ṣàìsàn ti í ṣòfò dànù.
19 A pozostałych drzew lasu jego mała liczba będzie, tak, że je i dziecię będzie popisać mogło.
Àwọn igi tí yóò kù nínú igbó o rẹ̀ yóò kéré níye, tí ọ̀dọ́mọdé yóò fi le kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
20 I stanie się dnia onego, że ostatki Izraelskie, i ci, którzy zostali z domu Jakóbowego, nie będą więcej spolegać na tym, co ich bije; ale prawdziwie spolegać będą na Panu, Świętym Izraelskim.
Ní ọjọ́ náà, àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli, àwọn tí ó yè ní ilé e Jakọbu, kò ní gbẹ́kẹ̀lé ẹni náà tí ó lù wọ́n bolẹ̀, ṣùgbọ́n ní òtítọ́ yóò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, Ẹni Mímọ́ Israẹli.
21 Ostatek nawróci się, ostatek Jakóbowy do Boga mocnego.
Àwọn ìyókù yóò padà, àwọn ìyókù ti Jakọbu yóò padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Alágbára.
22 Bo choćby lud twój, o Izraelu! był jako piasek morski, ostatek tylko z niego nawróci się. Wytracenie naznaczone sprawi, że ziemia będzie opływała sprawiedliwością.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ Israẹli dàbí yanrìn ní Òkun, ẹni díẹ̀ ni yóò padà. A ti pàṣẹ ìparun, àkúnwọ́sílẹ̀ àti òdodo.
23 Wytracenie mówię naznaczone uczyni Pan, Pan zastępów, w pośrodku tej wszystkiej ziemi.
Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú un ṣẹ, ìparun tí a ti pàṣẹ rẹ̀ lórí gbogbo ilẹ̀ náà.
24 Przetoż tak mówi Pan, Pan zastępów: Nie bój się Assyryjczyka, ludu mój! który mieszkasz w Syonie; rózgą ubije cię, a laskę swą podniesie na cię, jako na drodze Egipskiej.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Ẹ̀yin ènìyàn mi tí ó ń gbé Sioni, ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn Asiria, tí ó ń fi ọ̀pá lù yín, tí wọ́n sì ń gbé ọ̀gọ tì yín bí Ejibiti ti ṣe.
25 Albowiem po maluczkim czasie skończy się gniew mój przeciwko tobie, a na wygładzenie ich zapalczywość moja powstanie.
Láìpẹ́, ìbínú mi sí i yín yóò wá sí òpin n ó sì dojú ìrunú mi kọ wọ́n, fún ìparun wọn.”
26 Gdyż bicz nań wzbudzi Pan zastępów, jako porażkę Madyjańczyków na skale Horeb; a jako podniósł rózgę swoję na morze na drodze Egipskiej tak ją nań podniesie.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò nà wọ́n ní ẹgba. Gẹ́gẹ́ bí ó ṣe lu Midiani ní òkè Orebu, yóò sì gbé ọ̀pá rẹ̀ lé orí omi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Ejibiti.
27 A dnia onego zdjęte będzie brzemię jego z ramienia twego, i jarzmo jego z szyi twojej; owszem, skażone będzie jarzmo od przytomności pomazanego.
Ní ọjọ́ náà, a ó gbé ẹrù wọn kúrò ní èjìká a yín, àti àjàgà a wọn kúrò ní ọrùn un yín a ó fọ́ àjàgà náà, nítorí pé ẹ̀yin ó ti sanra.
28 Przyciągnie do Ajat, przejdzie przez Migron, w Machmas złoży oręż swój.
Wọ́n wọ Aiati, wọ́n gba Migroni kọjá, wọ́n kó nǹkan pamọ́ sí Mikmasi.
29 Przejdą bród, w Gieba jako w gospodzie nocować będą; ulęknie się Rama, Gabaa Saulowe uciecze.
Wọ́n ti rékọjá ọ̀nà, wọ́n wí pé, “Àwa ó tẹ̀dó sí Geba lóru yìí.” Rama mì tìtì Gibeah ti Saulu sálọ.
30 Podnieś głos twój, córko Gallim! niech słyszą w Lais, o ubogie Anatot!
Gbé ohùn rẹ sókè, ìwọ ọmọbìnrin Galimu! Dẹ etí sílẹ̀, ìwọ Laiṣa! Ìwọ òtòṣì Anatoti!
31 Ustąpi Madmena; obywatele Gabim zbiorą się do uciekania.
Madmena ti fẹsẹ̀ fẹ́ ẹ, àwọn ènìyàn Gebimu ti fi ara pamọ́.
32 Jeszcze przez dzień zastanowiwszy się w Nobie, pogrozi ręką swą górze córki Syońskiej, i pagórkowi Jeruzalemskiemu.
Ní ọjọ́ yìí, wọn yóò dúró ní Nobu wọn yóò kan sáárá, ní òkè ọmọbìnrin Sioni ní òkè Jerusalẹmu.
33 Oto Pan, Pan zastępów, okrzesze wszystkę siłę latorośli, a te, którzy są wysokiego wzrostu, podetnie; i będą wysocy poniżeni.
Wò ó, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò kán ẹ̀ka náà sọnù pẹ̀lú agbára. Àwọn igi ọlọ́lá ni a ó gé lulẹ̀ àwọn tí ó ga gogoro ni a ó rẹ̀ sílẹ̀.
34 Gęstwiny także lasów siekiera wytnie, a Liban od wielmożnego upadnie.
Òun yóò gé igbó dídí pẹ̀lú àáké, Lebanoni yóò ṣubú níwájú Alágbára náà.

< Izajasza 10 >