< Ozeasza 5 >

1 Słuchajcie tego, o kapłani! a miejcie wzgląd na to, domie Izraelski! i ty, domie królewski! słuchajcie; bo przeciwko wam sąd jest, przeto, żeście sidłem w Masfa, a siecią rozciągnioną na wierzchu Tabor.
“Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yìn àlùfáà! Ẹ fetísílẹ̀ ẹ̀yin ọmọ Israẹli! Ẹ gbọ́, ẹ̀yìn ilé ọba! Ìdájọ́ yìí kàn yín. Ẹ ti jẹ́ ẹ̀bìtì ní Mispa àwọ̀n ti a nà sílẹ̀ lórí Tabori.
2 Owszem, udawając się na zabijanie, przypadają do ziemi; ale Ja pokarzę każdego z nich.
Àwọn ọlọ̀tẹ̀ ti gbilẹ̀ nínú ìpànìyàn gbogbo wọn ni èmi ó bá wí,
3 Ja znam Efraima, i Izrael nie jest skryty przedemną; bo teraz nierząd płodzisz, Efraimie! a Izrael splugawił się.
mo mọ ohun gbogbo nípa Efraimu Israẹli kò sì pamọ́ fún mi Efraimu, ní báyìí ó ti ṣe àgbèrè Israẹli sì ti díbàjẹ́.
4 Nie mają się do tego, aby się nawrócili do Boga swego, przeto, że duch wszeteczeństwa jest w pośrodku nich, a Pana nie poznali.
“Ìṣe wọn kò gbà wọ́n láààyè láti padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wọn. Ẹ̀mí àgbèrè wà ni ọkàn wọn, wọn kò sì mọ Olúwa.
5 Świadczyć też będzie hardość Izraelska przeciwko niemu; przetoż Izrael i Efraim upadną dla nieprawości swojej, upadnie też i Juda z nimi.
Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí lé wọn; àwọn ọmọ Israẹli, àti Efraimu pàápàá kọsẹ̀ nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Juda náà sì kọsẹ̀ pẹ̀lú wọn.
6 Z trzodami swemi i z bydłem swojem pójdą szukać Pana; wszakże go nie znajdą; bo odstąpił od nich.
Nígbà tí wọ́n bá lọ pẹ̀lú agbo ẹran àti ọ̀wọ́ ẹran wọn láti wá Olúwa, wọn kò ní rí i, ó ti yọ ara rẹ̀ kúrò láàrín wọn.
7 Wystąpili przeciwko Panu, bo synów cudzych napłodzili; a tak teraz pożre ich miesiąc z majętnościami ich.
Wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Olúwa wọ́n sì bí àwọn àjèjì ọmọ. Nísinsin yìí, ọdún oṣù tuntun wọn, ni yóò pa wọn run pẹ̀lú ìpín wọn.
8 Zatrąbcie w trąbę w Gabaa, i w trąbę w Rama; krzyczcie w Bet Awen: Nieprzyjaciel za tobą, o Benjaminie!
“Fọn fèrè ní Gibeah, kí ẹ sì fun ìpè ní Rama. Ẹ pariwo ogun ní Beti-Afeni; máa wárìrì, ìwọ Benjamini.
9 Efraim spustoszony będzie w dzień karania, w pokoleniach Izraelskich oznajmiłem, że to prawda.
Efraimu yóò di ahoro ní ọjọ́ ìbáwí láàrín àwọn ẹ̀yà Israẹli, Mo sọ ohun tí ó dájú.
10 Książęta Judzcy stali się jako ci, którzy granice przenoszą; wyleję na nich popędliwość moję jako wodę.
Àwọn olórí Juda dàbí àwọn tí í máa yí òkúta ààlà kúrò. Èmi ó tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí bí ìkún omi.
11 Uciśniony jest Efraim, pokruszony sądem; wszakże przecie ma wolę chodzić za rozkazaniem ludzkiem.
A ni Efraimu lára, a sì tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ìdájọ́, nítorí pé, ó pinnu láti tẹ̀lé òrìṣà.
12 Przetoż i Ja byłem Efraimowi jako mól, a domowi Judzkiemu jako spróchniałość.
Mo dàbí kòkòrò aṣọ sí Efraimu, Mo sì dàbí ìdin ara Juda.
13 Skąd widząc Efraim mdłość swoję a Juda ranę swoję, uciekł się Efraim do Assura, i posłał do króla Jareba; ale on was nie będzie mógł uzdrowić, ani was uleczy od rany waszej.
“Nígbà ti Efraimu ri àìsàn rẹ̀, tí Juda sì rí ojú egbò rẹ̀ ni Efraimu bá tọ ará Asiria lọ, ó sì ránṣẹ́ sí ọba ńlá náà fún ìrànlọ́wọ́. Ṣùgbọ́n kò le è wò ó sàn bẹ́ẹ̀ ni kò le wo ojú egbò rẹ̀ jinná.
14 Bom Ja jest Efraimowi jako lew srogi, a domowi Judzkiemu jako lwię; Ja, Ja porwę, i odejdę; wezmę, a nikt mi nie wydrze;
Nítorí pé, èmi ó dàbí kìnnìún sí Efraimu, bí i kìnnìún ńlá sí ilé Juda. Èmi ó fà wọ́n ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ èmi ó sì lọ; Èmi ó gbé wọn lọ, láìsí ẹni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀.
15 Pójdę, wrócę się do miejsca mego, aż się winnymi dadzą a szukać będę oblicza mojego.
Nígbà náà ni èmi ó padà lọ sí ààyè mi títí di ìgbà tí wọn ó fi gbà pé àwọn jẹ̀bi wọn yóò sì wá ojú mi nínú ìpọ́njú wọn, wọn ó fi ìtara wá mi.”

< Ozeasza 5 >