< Habakuka 3 >

1 Modlitwa Abakuka proroka według rozmaitych pieśni złożona.
Àdúrà wòlíì Habakuku gẹ́gẹ́ bí sígónótì. Ohun èlò orin.
2 O Panie! usłyszawszy wyrok twój ulękłem się. O Panie! zachowaj sprawę twoję w pośrodku lat, i objaw ją w pośrodku lat; w gniewie wspomnij na miłosierdzie.
Olúwa mo tí gbọ́ ohùn rẹ; ẹ̀rù sì ba mi fún iṣẹ́ rẹ Olúwa sọ wọn di ọ̀tún ní ọjọ́ ti wa, ní àkókò tiwa, jẹ́ kó di mí mọ̀; ni ìbínú, rántí àánú.
3 Gdy Bóg szedł od południa, a Święty z góry Faran, (Sela) okryła niebiosa sława jego, a chwały jego ziemia pełna była.
Ọlọ́run yóò wa láti Temani, ibi mímọ́ jùlọ láti òkè Parani ògo rẹ̀ sí bo àwọn ọ̀run, ilé ayé sì kún fún ìyìn rẹ.
4 Jasność jego była jako światłość, rogi były na bokach jego, a tam była skryta siła jego.
Dídán rẹ sí dàbí ìmọ́lẹ̀ oòrùn ìtànṣán ìmọ́lẹ̀ jáde wa láti ọwọ́ rẹ, níbi tí wọn fi agbára rẹ̀ pamọ́ sí.
5 Przed obliczem jego szedł mór, a węgle pałające szły przed nogami jego.
Àjàkálẹ̀-ààrùn ń lọ ni iwájú rẹ; ìyọnu sí ń tọ ẹsẹ̀ rẹ lọ.
6 Stanął i rozmierzył ziemię, wejrzał i rozproszył narody, skruszone są góry wieczne, i skłoniły się pagórki dawne: drogi jego są wieczne.
Ó dúró, ó sì mi ayé; ó wò, ó sì mú àwọn orílẹ̀-èdè wárìrì a sì tú àwọn òkè ńlá ayérayé ká, àwọn òkè kéékèèké ayérayé sì tẹríba: ọ̀nà rẹ ayérayé ni.
7 Widziałem namioty Chusan próżności poddane, a opony ziemi Madyjańskiej drżały.
Mo rí àgọ́ Kuṣani nínú ìpọ́njú àti àwọn ibùgbé Midiani nínú ìrora.
8 Izali się na rzeki, o Panie! izali się na rzeki rozpalił gniew twój? Izali na morze rozgniewanie twoje, gdyś jechał na koniach twoich, i na wozach twoich zbawiennych?
Ǹjẹ́ ìwọ ha ń bínú sí àwọn odò nì, Olúwa? Ǹjẹ́ ìbínú rẹ wa lórí àwọn odò ṣíṣàn bí? Ìbínú rẹ ha wá sórí Òkun tí ìwọ fi ń gun ẹṣin, àti kẹ̀kẹ́ ìgbàlà rẹ?
9 Jawnie odkryty jest łuk twój dla przysięgi pokoleniom wyrzeczonej, (Sela)
A ṣí ọrun rẹ sílẹ̀ pátápátá, gẹ́gẹ́ bí ìbúra àwọn ẹ̀yà, àní ọ̀rọ̀ rẹ, ìwọ sì fi odò pín ilẹ̀ ayé.
10 Rozdzieliłeś rzeki ziemi: widziały cię góry i zadrżały, powódź wód przeminęła; przepaść wydała głos swój, głębokość ręce swoje podniosła.
Àwọn òkè ńlá ri ọ wọn sì wárìrì àgbàrá òjò ń sàn án kọjá lọ; ibú ń ké ramúramù ó sì gbé irú omi sókè.
11 Słońce i miesiąc zastanowił się w mieszkaniu swojem, przy jegoż świetle latały strzały twe, i przy blasku lśniącej się włóczni twojej.
Òòrùn àti Òṣùpá dúró jẹ́ẹ́jẹ́ ni ibùgbé wọn, pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ ọfà rẹ ni wọn yára lọ, àti ni dídán ọ̀kọ̀ rẹ ti ń kọ mànà.
12 W zagniewaniu podeptałeś ziemię, w zapalczywości młóciłeś pogan;
Ní ìrunú ni ìwọ rin ilẹ̀ náà já, ní ìbínú ni ìwọ tí tẹ́ àwọn orílẹ̀-èdè rẹ.
13 Wyszedłeś na wybawienie ludu swego, na wybawienie z pomazańcem twoim; przebiłeś głowę z domu niezbożnika, odkrywszy grunt aż do szyi, (Sela)
Ìwọ jáde lọ láti tú àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀, àti láti gba ẹni àmì òróró rẹ là, Ìwọ ti run àwọn olórí kúrò nínú ilẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ó sì bọ ìhámọ́ra rẹ láti orí de ẹsẹ̀.
14 Potłukłeś kijmi jego głowę wsi jego, gdy się burzyli jako wicher, aby mię rozproszyli; weselili się, jakoby pożreć mieli ubogiego w skrytości.
Pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀ kí ó fi gún orí rẹ nígbà tí àwọn jagunjagun rẹ̀ jáde láti tú wá ká, ayọ̀ wọn sì ni láti jẹ tálákà run ní ìkọ̀kọ̀.
15 Jechałeś przez morze na koniach twoich, przez gromadę wód wielkich.
Ìwọ fi ẹṣin rẹ rìn Òkun já, ó sì da àwọn omi ńlá ru.
16 Gdym to słyszał, zatrząsnął się brzuch mój! na ten głos drżały wargi moje, zgniłość weszła w kości moje, i wszystekem się trząsł, słysząc, że mam odpocząć w dzień utrapienia, gdy przyciągnie na ten lud nieprzyjaciel, aby go przez wojnę wygładził.
Mo gbọ́, ọkàn mi sì wárìrì, ètè mi sì gbọ̀n sí ìró náà; ìbàjẹ́ sì wọ inú egungun mi lọ, ẹsẹ̀ mi sì wárìrì, mo dúró ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ fún ọjọ́ ìdààmú láti de sórí àwọn ènìyàn tó ń dojúkọ wá.
17 Choćby figowe drzewo nie zakwitnęło i nie było urodzaju na winnicach, choćby i owoc oliwy pochybił, i role nie przyniosłyby pożytku, i z owczarniby owce wybite były, a nie byłoby bydła w oborach;
Bí igi ọ̀pọ̀tọ́ ko tilẹ̀ tanná, tí èso kò sí nínú àjàrà; tí igi olifi ko le so, àwọn oko ko sì mú oúnjẹ wá; tí a sì ké agbo ẹran kúrò nínú agbo, tí kò sì sí ọwọ́ ẹran ni ibùso mọ́,
18 Wszakże się ja w Panu weselić będę, rozraduję się w Bogu zbawienia mego.
síbẹ̀, èmi ó láyọ̀ nínú Olúwa, èmi yóò sí máa yọ nínú Ọlọ́run ìgbàlà mi.
19 Panujący Pan jest siłą moją, który czyni nogi moje, jako nogi łani, i po miejscach wysokich poprowadzi mię. Przedniejszemu nad śpiewakami na muzycznem naczyniu mojem.
Olúwa Olódùmarè ni agbára mi, òun yóò sí ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín, yóò sí mú mi rìn lórí ibi gíga.

< Habakuka 3 >