< Rodzaju 8 >

1 I wspomniał Bóg na Noego i na wszystkie zwierzęta, i na wszystko bydło, które było z nim w korabiu; i przywiódł Bóg wiatr na ziemię, a zastanowiły się wody.
Ọlọ́run sì rántí Noa àti ohun alààyè gbogbo tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, bí àwọn ẹranko igbó àti ohun ọ̀sìn, ó sì mú kí afẹ́fẹ́ fẹ́ sórí ilẹ̀, omi náà sì fà.
2 I zawarte są źródła przepaści, i okna niebieskie, i zahamowany jest deszcz z nieba.
Gbogbo ìsun ibú àti fèrèsé ìṣàn ọ̀run tì, òjò pẹ̀lú sì dáwọ́ rírọ̀ dúró.
3 I wróciły się wody z wierzchu ziemi idąc, i wracając się; i opadły wody po skończeniu stu i pięćdziesięciu dni.
Omi sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gbẹ kúrò lórí ilẹ̀, lẹ́yìn àádọ́jọ ọjọ́, ó sì ti ń fà.
4 I odpoczął korab miesiąca siódmego, siedemnastego dnia tegoż miesiąca, na górach Ararad.
Ní ọjọ́ kẹtàdínlógún oṣù kejì ni ọkọ̀ náà gúnlẹ̀ sórí òkè Ararati.
5 A wody ściekały i opadały, aż do dziesiątego miesiąca, dziesiątego bowiem miesiąca, pierwszego dnia, okazały się wierzchy gór.
Omi náà sì ń gbẹ si títí di oṣù kẹwàá. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹwàá, orí àwọn òkè sì farahàn.
6 I stało się po skończeniu czterdziestu dni, otworzył Noe okno korabia, które był uczynił.
Lẹ́yìn ogójì ọjọ́, Noa sí fèrèsé tí ó ṣe sára ọkọ̀.
7 I wypuścił kruka, który tam i sam latając, zasię się wracał, aż oschły wody na ziemi.
Ó sì rán ẹyẹ ìwò kan jáde, tí ó ń fò káàkiri síwá àti sẹ́yìn títí omi fi gbẹ kúrò ní orí ilẹ̀.
8 Potem wypuścił gołębicę od siebie, aby obaczył, jeźli opadły wody z wierzchu ziemi.
Ó sì rán àdàbà kan jáde láti wò ó bóyá omi ti gbẹ kúrò lórí ilẹ̀.
9 Ale nie znalazłszy gołębica odpocznienia stopie nogi swojej, wróciła się do niego do korabia; jeszcze bowiem wody były po wszystkiej ziemi; i wyciągnąwszy rękę swoję, wziął ją, i wniósł ją do siebie do korabia.
Ṣùgbọ́n àdàbà náà kò rí ìyàngbẹ ilẹ̀ bà lé nítorí omi kò tí ì tan lórí ilẹ̀, ó sì padà sọ́dọ̀ Noa. Noa na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú ẹyẹ náà wọlé sọ́dọ̀ ara rẹ̀ nínú ọkọ̀.
10 A poczekawszy jeszcze drugie siedem dni, po wtóre wypuścił gołębicę z korabia.
Ó sì dúró fún ọjọ́ méje sí i; ó sì tún rán àdàbà náà jáde láti inú ọkọ̀.
11 I wróciła do niego gołębica pod wieczór; a oto, różdżka oliwy urwana w uściech jej; a tak poznał Noe, że opadły wody z wierzchu ziemi.
Nígbà tí àdàbà náà padà sọ́dọ̀ rẹ̀ ní àṣálẹ́, ó já ewé igi olifi tútù há ẹnu! Nígbà náà ni Noa mọ̀ pé omi ti ń gbẹ kúrò lórí ilẹ̀.
12 I czekał jeszcze drugie siedem dni, i wypuścił gołębicę, która się więcej nie wróciła do niego.
Noa tún mú sùúrù fún ọjọ́ méje, ó sì tún rán àdàbà náà jáde, ṣùgbọ́n àdàbà náà kò padà sọ́dọ̀ rẹ̀ mọ́.
13 I stało się sześćsetnego i pierwszego roku, miesiąca pierwszego, dnia pierwszego, oschły wody z ziemi; i zdjął Noe przykrycie korabia, a ujrzał, że osechł wierzch ziemi.
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ní ọdún kọ́kànlélẹ́gbẹ̀ta ni omi náà gbẹ kúrò lórí ilẹ̀; Noa sì ṣí ọkọ̀, ó sì ri pé ilẹ̀ ti gbẹ.
14 A miesiąca wtórego, dwudziestego siódmego dnia tegoż miesiąca, oschła ziemia.
Ní ọjọ́ kẹtàdínlọ́gbọ̀n oṣù kejì, ilẹ̀ ti gbẹ pátápátá.
15 I rzekł Bóg do Noego, mówiąc:
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Noa pé.
16 Wynijdź z korabia, ty, i żona twoja, i synowie twoi, i żony synów twoich z tobą.
“Jáde kúrò nínú ọkọ̀, ìwọ àti aya rẹ, pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ àti àwọn aya wọn.
17 Wszystkie zwierzęta, które są z tobą, z wszelkiego ciała, z ptastwa i z bydła, i z wszelkiej gadziny, płazającej się po ziemi, wywiedź z sobą, a niech się rozpładzają na ziemi, i niech rosną, i rozmnażają się na ziemi.
Kó gbogbo àwọn ẹ̀dá alààyè tí ó wà pẹ̀lú rẹ jáde: àwọn ẹyẹ, ẹranko àti gbogbo àwọn ẹ̀dá tí ń rìn nílẹ̀, kí wọn lè bí sí i, kí wọn sì pọ̀ sí i, kí wọn sì máa gbá yìn lórí ilẹ̀.”
18 I wyszedł Noe, i synowie jego, i żona jego, i żony synów jego z nim.
Noa, àwọn ọmọ rẹ̀, aya rẹ̀ àti àwọn aya ọmọ rẹ̀ sì jáde.
19 Wszelkie zwierzę, wszelka gadzina, i wszelkie ptactwo, wszystko co się płaza po ziemi, według rodzajów swoich, wyszły z korabia.
Gbogbo àwọn ẹranko àti àwọn ẹ̀dá tí ń rìn nílẹ̀ àti gbogbo ẹyẹ pátápátá ni ó jáde kúrò nínú ọkọ̀, ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ní irú tiwọn.
20 Zatem zbudował Noe ołtarz Panu, i wziął z każdego bydła czystego, i z każdego ptastwa czystego, i ofiarował całopalenia na ołtarzu onym.
Noa sì mọ pẹpẹ fún Olúwa, ó sì mú lára àwọn ẹran tí ó mọ́ àti ẹyẹ tí ó mọ́, ó sì fi rú ẹbọ sísun lórí pẹpẹ.
21 I zawoniał Pan wonności wdzięcznej, i rzekł Pan w sercu swem: Nie będę więcej przeklinał ziemi dla człowieka: albowiem myśl serca człowieczego zła jest od młodości jego, nie zatracę więcej wszystkiego co żyje, jakom teraz uczynił.
Olúwa sì gbọ́ òórùn dídùn; ó sì wí ní ọkàn rẹ̀ pé, “Èmi kì yóò tún fi ilẹ̀ ré nítorí ènìyàn mọ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo èrò inú rẹ̀ jẹ́ ibi láti ìgbà èwe rẹ̀ wá, èmi kì yóò pa gbogbo ohun alààyè run mọ́ láé, bí mo ti ṣe.
22 A póki ziemia trwać będzie, siew i żniwo, i zimno, i gorąco, i lato, i zima, i dzień, i noc nie ustaną.
“Níwọ́n ìgbà tí ayé bá sì wà, ìgbà ọ̀gbìn àti ìgbà ìkórè ìgbà òtútù àti ìgbà ooru, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn àti ìgbà òjò, ìgbà ọ̀sán àti ìgbà òru, yóò wà títí láé.”

< Rodzaju 8 >

A Dove is Sent Forth from the Ark
A Dove is Sent Forth from the Ark