< Rodzaju 44 >

1 Rozkazał tedy Józef temu, który był sprawcą domu jego, mówiąc: Napełnij wory mężów tych zbożem, jako mogą znieść, a włóż pieniądze każdego na wierzch woru jego.
Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Di oúnjẹ kún inú àpò àwọn ọkùnrin náà tó ìwọ̀n èyí tí wọ́n le rù, kí o sì mú owó olúkúlùkù àwọn ọkùnrin náà padà sí ẹnu àpò rẹ̀.
2 Kubek też mój, kubek srebrny, włóż na wierzch woru młodszego z pieniędzmi za zboże jego; i uczynił według słów Józefowych, jako mu rozkazał.
Nígbà náà ni kí o mú kọ́ọ̀bù idẹ mi sí ẹnu àpò èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn nínú wọn pẹ̀lú owó tí ó fi ra ọkà,” ó sì ṣe bí Josẹfu ti sọ.
3 A gdy było rano, mężowie oni puszczeni są, sami i osłowie ich.
Bí ilẹ̀ ti ń mọ́, wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà lọ pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.
4 Wyszedłszy tedy z miasta, gdy nie daleko byli, rzekł Józef do tego, który był sprawcą domu jego: Wstań, goń te męże, a dogoniwszy ich, mów do nich: Czemuście oddali złe za dobre?
Wọn kò tí ì rìn jìnnà sí ìlú náà tí Josẹfu fi wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Lépa àwọn ọkùnrin náà, nígbà tí o bá sì bá wọn, kí o wí pé, ‘Èéṣe ti ẹ fi búburú san rere?
5 Azaż nie ten jest kubek, z którego pija pan mój? i azaż on pewnie nie zgadnie przezeń, jacyście wy? źleście uczynili, coście uczynili.
Èyí ha kọ́ ni kọ́ọ̀bù tí olúwa mi ń lò fún ohun mímu tí ó sì tún ń fi í ṣe àyẹ̀wò? Ohun tí ẹ ṣe yìí burú púpọ̀.’”
6 Dogoniwszy ich tedy, mówił do nich te słowa.
Nígbà tí ó sì bá wọn, o sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún wọn.
7 Ale oni odpowiedzieli mu: Czemu mówi pan mój takowe słowa? nie daj tego Boże, aby to słudzy twoi uczynić mieli.
Ṣùgbọ́n wọ́n dá a lóhùn pé, “Kí ló dé tí olúwa mi sọ irú nǹkan wọ̀nyí? Ká má rí i! Àwọn ìránṣẹ́ rẹ kò le ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀!
8 Oto pieniądze, któreśmy byli znaleźli na wierzchu worów naszych, odnieśliśmy zaś do ciebie z ziemi Chananejskiej; a jakoż byśmy kraść mieli z domu pana twego srebro albo złoto?
A tilẹ̀ mú owó tí a rí lẹ́nu àpò wa padà tọ̀ ọ́ wá láti ilẹ̀ Kenaani. Nítorí náà èéṣe tí àwa yóò fi jí wúrà tàbí idẹ ní ilé olúwa à rẹ?
9 U którego by to znaleziono z sług twoich, niechaj umrze; a my będziemy pana mego niewolnikami.
Bí a bá rí i lọ́wọ́ èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ, kíkú ni yóò kú, àwọn tí ó kù yóò sì di ẹrú fún olúwa à rẹ.”
10 Tedy on rzekł: Niechże tak będzie, jako mówicie; jednak przy którym się znajdzie kubek, ten niech będzie niewolnikiem, a wy będziecie niewinnymi.
Ó wí pé, “Ó dára, kí ó rí bí ẹ ti ṣe sọ. Ẹnikẹ́ni tí mo bá rí i lọ́wọ́ rẹ̀ yóò di ẹrú mi. Ẹ̀yin tí ó kù yóò sì wà láìlẹ́bi.”
11 Prędko tedy każdy złożył wór swój na ziemię; i rozwiązali każdy wór swój.
Olúkúlùkù wọn yára sọ àpò rẹ̀ kalẹ̀, wọ́n sì tú u.
12 I szukał od starszego począwszy; a u młodszego przestał; i znalazł kubek w worze Benjaminowym.
Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà bẹ̀rẹ̀ sí ní í wá a, bẹ̀rẹ̀ láti orí ẹ̀gbọ́n títí lọ sórí àbúrò pátápátá. Ó sì rí kọ́ọ̀bù náà nínú àpò ti Benjamini.
13 Tedy oni rozdarli szaty swoje, i włożywszy brzemię każdy z nich na osła swego, wrócili się do miasta.
Nígbà tí wọ́n rí èyí, wọ́n fa aṣọ wọn ya, wọ́n sì banújẹ́ gidigidi, wọn tún ẹrù wọn dì sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọ́n sì padà sí inú ìlú.
14 Przyszedł tedy Judas, i bracia jego do domu Józefa, który tam jeszcze był, i upadli przed obliczem jego na ziemię.
Josẹfu sì wà nínú ilé nígbà tí Juda àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wọlé wá. Gbogbo wọn sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
15 I rzekł do nich Józef: Cóżeście to uczynili? azaście nie wiedzieli, że pewnie zgadnie mąż taki, jakim ja jest?
Josẹfu wí fún wọn pé, “Èwo ni èyí tí ẹ ṣe yìí? Ṣe ẹ kò mọ pé, ènìyàn bí èmi le è rí ìdí nǹkan nípa ṣíṣe àyẹ̀wò?”
16 Tedy odpowiedział Judas: Cóż odpowiemy panu memu, cóż rzeczemy? i jako się my usprawiedliwić mamy? Bóg znalazł nieprawość sług twoich; otośmy niewolnikami pana mego, i my, i ten, w którego ręku znaleziony jest kubek.
Juda dáhùn pé, “Kí ni à bá sọ fún olúwa mi? Báwo ni a ṣe lè wẹ ara wa mọ́? Ọlọ́run ti tú àṣírí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, a ti di ẹrú olúwa à mi báyìí àwa fúnra wa àti ẹni náà tí a rí kọ́ọ̀bù lọ́wọ́ rẹ̀.”
17 A on rzekł: Nie daj Boże, abym to uczynić miał! mąż, w którego ręku znaleziony jest kubek, ten będzie niewolnikiem moim; a wy jedźcie w pokoju do ojca waszego.
Ṣùgbọ́n Josẹfu dáhùn pé, “Ká má rí i pé mo ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀! Ẹni tí a bá kọ́ọ̀bù mi lọ́wọ́ rẹ̀ nìkan ni yóò di ẹrú mi, ẹ̀yin tí ó kù, ẹ máa lọ sọ́dọ̀ baba yín ní àlàáfíà.”
18 Zatem przystąpił do niego Judas i rzekł: Słuchaj mię panie mój; niechaj przemówi proszę sługa twój które słowo w uszy pana mego, a niech się nie zapala gniew twój na sługę twego, gdyżeś ty jest jako sam Farao.
Nígbà náà ni Juda súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó sọ ọ̀rọ̀ kan fún olúwa mi, má ṣe bínú sí ìránṣẹ́ rẹ bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ pẹ̀lú láṣẹ bí i ti Farao.
19 Pan mój pytał sług swoich mówiąc: Macież ojca albo brata?
Olúwa mi béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ǹjẹ́ ó ní baba tàbí arákùnrin?’
20 Tedyśmy odpowiedzieli panu swemu: Mamyć ojca starego, i chłopię w starości jego spłodzone małe, a brat jego umarł, a został sam tylko po matce swej, i ojciec jego miłuje go.
Àwa sì wí fún olúwa mi pé, ‘A ni baba tí ó ti darúgbó, ọmọkùnrin kan sì wà pẹ̀lú tí a bí fún un ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀, baba rẹ̀ sì fẹ́ràn án rẹ̀.’
21 Potem mówiłeś do nas sług swoich: Przywiedźcie go do mnie, abym go oglądał oczyma memi:
“Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ mu un tọ̀ mí wá kí n le fojú ara mi rí i.’
22 I mówiliśmy do pana mego: Nie będzie mogło chłopię opuścić ojca swego; bo gdyby opuściło ojca swego, umarłby.
A sì sọ fún olúwa à mi pé, ‘Ọmọkùnrin náà kò le è fi baba rẹ̀ sílẹ̀, bí ó bá dán an wò baba rẹ̀ yóò kú.’
23 Tedyś rzekł do sług swoich: Jeźli nie przyjdzie brat wasz młodszy z wami, nie ujrzycie więcej oblicza mojego.
Ṣùgbọ́n ìwọ wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ má ṣe padà tọ̀ mí wá àyàfi bí àbíkẹ́yìn yín bá bá yín wá.’
24 I stało się, gdyśmy odeszli do sługi twego, ojca mojego, i powiedzieliśmy mu te słowa pana mego:
Nígbà tí a padà lọ sọ́dọ̀ baba wa, tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ, a sọ ohun tí olúwa à mi wí fún un.
25 Tedy rzekł ojciec nasz: Jedźcie znowu, a kupcie nam trochę żywności.
“Nígbà náà ni baba wa wí pé, ‘Ẹ padà lọ láti lọ ra oúnjẹ díẹ̀ wá.’
26 I powiedzieliśmy: Nie możemy tam iść: lecz jeźli brat nasz młodszy będzie z nami, tedy pojedziemy; bo inaczej nie będziemy mogli oglądać oblicza męża onego, jeźli brat nasz młodszy nie będzie z nami.
Ṣùgbọ́n a wí pe, ‘Àwa kò le è padà lọ, àyàfi bí àbúrò wa pátápátá yóò bá bá wa lọ. A kò le è rí ojú ọkùnrin náà àyàfi tí àbúrò wa bá lọ pẹ̀lú wa.’
27 I rzekł sługa twój, ojciec mój, do nas: Wy wiecie, że dwóch synów urodziła mi żona moja;
“Baba mi, ìránṣẹ́ rẹ wí fún wa pé, ‘Ẹ mọ̀ pé ìyàwó mi bí ọmọkùnrin méjì fún mi.
28 I wyszedł jeden ode mnie, i rzekłem: Zaiste od zwierza rozdarty jest, i nie widziałem go do tych miast;
Ọ̀kan nínú wọn lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, mo sì wí pé, “Dájúdájú a ti fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.” N kò sì tí ì ri láti ọjọ́ náà.
29 A weźmiecieli i tego od oblicza mego, a przypadnie nań śmierć, tedy doprowadzicie sędziwość moję z żałością do grobu. (Sheol h7585)
Tí ẹ bá tún mú èyí lọ, kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ohunkóhun bá ṣe é, ìbànújẹ́ ni ẹ ó fi mú ewú orí mi lọ sí ipò òkú.’ (Sheol h7585)
30 Przetoż teraz jeślibym przyszedł do sługi twego, ojca mojego, a dziecięcia by z nami nie było, (ponieważ dusza jego jest przywiązana do duszy jego),
“Nítorí náà, bí a bá padà tọ baba wa lọ láìsí ọmọ náà pẹ̀lú wa nígbà tí a mọ̀ pé, ọmọ náà ni ẹ̀mí baba wa.
31 Stanie się, skoro ujrzy, iż dziecięcia nie będzie, że umrze; a odprowadzą słudzy twoi sędziwość sługi twego, ojca naszego, z żałością do grobu. (Sheol h7585)
Tí ó bá ri pé ọmọkùnrin náà kò wá pẹ̀lú wa, yóò kùú. Àwọn ìránṣẹ́ rẹ yóò wá mú baba wa tòun ti ewú orí lọ sí ipò òkú ní ìbànújẹ́. (Sheol h7585)
32 Bo sługa twój przyrzekł za to dziecię, gdy je brał od ojca swego, mówiąc: Jeźlić go zaś nie przywiodę, tedy będę winien grzechu przeciw ojcu memu po wszystkie dni.
Ìránṣẹ́ rẹ ló ṣe onídùúró fún ààbò ọmọ náà lọ́dọ̀ baba mi. Mo wí pé, ‘Bí n kò bá mú un padà tọ̀ ọ́ wá, baba mi, èmi ó ru ẹ̀bi rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé mi!’
33 Teraz tedy niech zostanie proszę sługa twój miasto dziecięcia tego niewolnikiem pana mego, a dziecię niech idzie z bracią swoją.
“Nítorí náà, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó dúró ní ìhín lọ́dọ̀ olúwa à mi bí ẹrú dípò ọmọ náà. Kí ọmọ náà bá àwọn arákùnrin rẹ̀ padà.
34 Bo jakoż ja mam wrócić się do ojca mego, gdy tego dziecięcia ze mną nie będzie? chybabym chciał patrzyć na żałość, która by przyszła na ojca mego.
Báwo ni mo ṣe lè padà tọ baba mi lọ láì bá ṣe pé ọmọ náà wà pẹ̀lú mi? Rárá, èmi kò fẹ́ kí n rí ìbànújẹ́ tí yóò dé bá baba mi.”

< Rodzaju 44 >