< Rodzaju 4 >

1 Potem Adam poznał Ewę, żonę swoję, która poczęła i porodziła Kaina, i rzekła: Otrzymałam męża od Pana.
Adamu sì bá aya rẹ̀ Efa lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Kaini. Ó wí pé, “Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Olúwa ni mo bí ọmọ ọkùnrin.”
2 I porodził zasię brata jego Abla; i był Abel pasterzem owiec, a Kain był rolnikiem.
Lẹ́yìn náà, ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn tí a pè ní Abeli. Abeli jẹ́ darandaran, Kaini sì jẹ́ àgbẹ̀.
3 I stało się po wielu dni, iż przyniósł Kain z owocu ziemi ofiarę Panu.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Kaini mú ọrẹ wá fún Olúwa nínú èso ilẹ̀ rẹ̀.
4 Także i Abel przyniósł z pierworodztw trzód swoich i z tłustości ich; i wejrzał Pan na Abla i na ofiarę jego.
Ṣùgbọ́n Abeli mú ẹran tí ó sanra wá fún Olúwa nínú àkọ́bí ẹran ọ̀sìn rẹ̀. Olúwa sì fi ojúrere wo Abeli àti ọrẹ rẹ̀,
5 Ale na Kaina i na ofiarę jego nie wejrzał; i rozgniewał się Kain bardzo, i spadła twarz jego.
ṣùgbọ́n Olúwa kò fi ojúrere wo Kaini àti ẹbọ rẹ̀. Nítorí náà inú bí Kaini gidigidi, ojú rẹ̀ sì fàro.
6 Tedy rzekł Pan do Kaina: Przeczżeś się zapalił gniewem a czemu spadła twarz twoja?
Nígbà náà ni Olúwa bi Kaini pé, “Èéṣe tí ìwọ ń bínú? Èéṣe tí ojú rẹ sì fàro?
7 Azaż, jeźli dobrze czynić będziesz, nie będziesz wywyższon? a jeźli nie będziesz dobrze czynił, we drzwiach grzech leży; a do ciebie chuć jego będzie, a ty nad nim panować będziesz.
Bí ìwọ bá ṣe ohun tí ó tọ́, ṣé ìwọ kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà? Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ṣe ohun tí ó tọ́, ẹ̀ṣẹ̀ ń bẹ ní ẹnu-ọ̀nà rẹ, ó fẹ́ ní ọ ní ìní, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ ṣe àkóso rẹ̀.”
8 I rozmawiał Kain z Ablem bratem swoim. I stało się, gdy byli na polu, że powstał Kain na Abla brata swego, i zabił go.
Kaini wí fún Abeli arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ kí a lọ sí oko.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti wà ní oko; Kaini da ojú ìjà kọ Abeli arákùnrin rẹ̀, ó sì pa á.
9 I rzekł Pan do Kaina: Gdzież jest Abel brat twój? który odpowiedział: Nie wiem; izalim ja stróżem brata mego?
Nígbà náà ni Olúwa béèrè lọ́wọ́ Kaini pé, “Níbo ni Abeli arákùnrin rẹ wà?” Ó sì dáhùn pé, “Èmi kò mọ ibi tí ó wà, èmí ha ń ṣe olùṣọ́ arákùnrin mi bí?”
10 I rzekł Bóg: Cóżeś uczynił? Głos krwi brata twego woła do mnie z ziemi.
Olúwa wí pé, “Kín ni ohun tí ìwọ ṣe yìí? Gbọ́! Ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ ń kígbe pè mí láti ilẹ̀ wá.
11 Teraz tedy przeklętym będziesz na ziemi, która otworzyła usta swe, aby przyjęła krew brata twego z ręki twojej.
Láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ ti wà lábẹ́ ègún, a sì ti lé ọ lórí ilẹ̀ tí ó ya ẹnu gba ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ lọ́wọ́ rẹ.
12 Gdy będziesz sprawował ziemię, nie wyda więcej mocy swej tobie; tułaczem, i biegunem będziesz na ziemi.
Bí ìwọ bá ro ilẹ̀, ilẹ̀ kì yóò fi agbára rẹ̀ so èso rẹ̀ fún ọ mọ́. Ìwọ yóò sì jẹ́ ìsáǹsá àti alárìnkiri ni orí ilẹ̀ ayé.”
13 Tedy rzekł Kain do Pana: Większa jest nieprawość moja, niżby mi ją odpuścić miano.
Kaini wí fún Olúwa pé, “Ẹrù ìyà ẹ̀ṣẹ̀ mi pọ̀ ju èyí tí mo le rù lọ.
14 Oto mię dziś wyganiasz z oblicza tej ziemi, a przed twarzą twoją skryję się, i będę tułaczem, i biegunem na ziemi; i stanie się, że ktokolwiek mię znajdzie, zabije mię.
Lónìí, ìwọ lé mi kúrò lórí ilẹ̀, mó sì di ẹni tí ó fi ara pamọ́ kúrò ní ojú rẹ, èmi yóò sì di ìsáǹsá àti alárìnkiri ní ayé, ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi, yóò sì pa mí.”
15 I rzekł mu Pan: Zaiste, ktobykolwiek zabił Kaina, siedmioraką odniesie pomstę. I włożył Pan na Kaina piętno, aby go nie zabijał, ktobykolwiek znalazł.
Ṣùgbọ́n, Olúwa wí fún pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ẹnikẹ́ni bá pa Kaini, èmi yóò gbẹ̀san ní ara onítọ̀hún ní ìgbà méje.” Nígbà náà ni Ọlọ́run fi àmì sí ara Kaini, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá ri má ba à pa á.
16 Tedy odszedł Kain od oblicza Pańskiego, i mieszkał w ziemi Nod, na wschód słońca od Eden.
Kaini sì kúrò níwájú Olúwa, ó sì ń gbé ilẹ̀ Nodi ní ìhà ìlà-oòrùn Edeni.
17 I poznał Kain żonę swą, która poczęła, i porodziła Enocha; i zbudował miasto, i nazwał imię miasta tego imieniem syna swego, Enoch.
Kaini sì bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Enoku. Kaini sì tẹ ìlú kan dó, ó sì fi orúkọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Enoku sọ ìlú náà.
18 I urodził się Enochowi Irad, a Irad spłodził Mawiaela, a Mawiael spłodził Matusaela, a Matusael spłodził Lamecha.
Enoku sì bí Iradi, Iradi sì ni baba Mehujaeli, Mehujaeli sì bí Metuṣaeli, Metuṣaeli sì ni baba Lameki.
19 I pojął sobie Lamech dwie żony; imię jednej, Ada, a imię drugiej, Sella.
Lameki sì fẹ́ aya méjì, orúkọ èkínní ni Adah, àti orúkọ èkejì ni Silla.
20 Tedy urodziła Ada Jabala, który był ojcem mieszkających w namieciech, i pasterzów.
Adah sì bí Jabali, òun ni baba irú àwọn tí ń gbé inú àgọ́, tí wọ́n sì ń sin ẹran ọ̀sìn.
21 A imię brata jego było Jubal, który był ojcem wszystkich grających na harfie, i na muzyckiem naczyniu.
Orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Jubali, òun ni baba irú àwọn tí ń tẹ dùùrù tí wọ́n sì ń fọn fèrè.
22 Sella też urodziła Tubalkaina, rzemieślnika wszelkiej roboty, od miedzi i od żelaza. A siostra Tubalkainowa była Noema.
Silla náà sì bí ọmọkùnrin tí ń jẹ́ Tubali-Kaini, tí ó ń rọ oríṣìíríṣìí ohun èlò láti ara idẹ àti irin. Arábìnrin Tubali-Kaini ni Naama.
23 Tedy rzekł Lamech żonom swym, Adzie i Selli: Słuchajcie głosu mego, żony Lamechowe, posłuchajcie słów moich; zabiłbym ja męża za zranienie moje, i młodzieńca za siność moję.
Lameki wí fún àwọn aya rẹ̀, “Adah àti Silla, ẹ tẹ́tí sí mi; ẹ̀yin aya Lameki, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi. Mo ti pa ọkùnrin kan tí ó kọlù mí, ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó pa mí lára.
24 Jeźlić siedmiokroć mścić się będą za Kaina, tedyć za Lamecha siedemdziesiąt i siedem kroć.
Bí a ó bá gbẹ̀san Kaini ní ìgbà méje, ǹjẹ́ kí a gba ti Lameki nígbà mẹ́tàdínlọ́gọ́rin.”
25 I poznał jeszcze Adam żonę swą, która urodziła syna, i nazwała imię jego Set, mówiąc: Dał mi Bóg inne potomstwo miasto Abla, którego zabił Kain.
Adamu sì tún bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Seti, tí ó túmọ̀ sí pé, “Ọlọ́run fún mi ní ọmọkùnrin mìíràn ní ipò Abeli tí Kaini pa.”
26 Setowi też urodził się syn, i nazwał imię jego Enos. Na ten czas poczęto wzywać imienia Pańskiego.
Seti náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Enoṣi. Láti àkókò náà lọ ni àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní ké pe orúkọ Olúwa.

< Rodzaju 4 >