< Rodzaju 22 >

1 To gdy się stało, kusił Bóg Abrahama, i rzekł do niego: Abrahamie! A on odpowiedział: Owom ja.
Nígbà tí ó ṣe, Ọlọ́run dán Abrahamu wò, ó pè é, ó sì wí pé, “Abrahamu.” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
2 I rzekł Bóg: Weźmij teraz syna twego, jedynego twego, którego miłujesz, Izaaka, a idź do ziemi Moryja, i tam go ofiaruj na ofiarę paloną, na jednej górze, o którejć powiem.
Ọlọ́run sì wí pé, “Mú ọmọ rẹ, àní Isaaki ọmọ rẹ kan ṣoṣo nì, tí ìwọ fẹ́ràn, lọ sí ilẹ̀ Moria, kí o sì fi rú ẹbọ sísun níbẹ̀ lórí ọ̀kan nínú àwọn òkè tí èmi yóò sọ fún ọ.”
3 Tedy wstawszy Abraham bardzo rano, osiodłał osła swego, i wziął dwóch sług swoich z sobą, i Izaaka syna swego, a narąbawszy drew na ofiarę paloną, wstał i szedł na miejsce, o którem mu Bóg powiedział.
Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì mú méjì nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì ṣẹ́ igi fún ẹbọ sísun, ó sì gbéra lọ sí ibi tí Ọlọ́run ti sọ fún un.
4 A dnia trzeciego, podniósłszy Abraham oczy swe, ujrzał ono miejsce z daleka.
Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹta, Abrahamu gbé ojú sókè, ó sì rí ibi tí ó ń lọ ní òkèrè,
5 I rzekł Abraham do sług swoich: Zostańcie wy tu z osłem, a ja z dziecięciem pójdziemy aż do onąd, a odprawiwszy modlitwy, wrócimy się do was.
Abrahamu sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin, ẹ dúró níhìn-ín pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, èmi àti ọmọ yìí yóò lọ sí ohunkóhun láti sin Ọlọ́run, a ó sì tún padà wá bá a yín.”
6 Wziął tedy Abraham drwa na ofiarę paloną, i włożył je na Izaaka, syna swego, a sam wziął w rękę swoję ogień i miecz, i szli obaj pospołu.
Abrahamu sì gbé igi ẹbọ sísun náà ru Isaaki, òun fúnra rẹ̀ sì mú iná àti ọ̀bẹ. Bí àwọn méjèèjì ti ń lọ,
7 I rzekł Izaak do Abrahama, ojca swego, mówiąc: Ojcze mój! A on odpowiedział: Owom ja, synu mój. I rzekł Izaak: Oto ogień i drwa, a gdzież baranek na ofiarę paloną?
Isaaki sì sọ fún Abrahamu baba rẹ̀ wí pé, “Baba mi.” Abrahamu sì dalóhùn pé, “Èmi nìyí ọmọ mi.” Isaaki sì tún wí pé, “Wò ó iná àti igi nìyí, ṣùgbọ́n níbo ni ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà wà?”
8 Odpowiedział Abraham: Bóg sobie obmyśli baranka na ofiarę paloną, synu mój; i szli obaj pospołu.
Abrahamu sì dáhùn pé, “Ọmọ mi, Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni yóò pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì jùmọ̀ ń lọ.
9 A gdy przyszli na miejsce, o którem mu Bóg powiedział, zbudował tam Abraham ołtarz, i ułożył drwa, a związawszy Izaaka, syna swego, włożył go na ołtarz na drwa.
Nígbà tí wọn sì dé ibi tí Ọlọ́run sọ fún Abrahamu, ó mọ pẹpẹ kan, ó sì to igi lé e lórí, ó sì di Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì da dùbúlẹ̀ lórí pẹpẹ náà.
10 I wyciągnął Abraham rękę swoję, i wziął miecz, aby zabił syna swego.
Abrahamu sì nawọ́ mú ọ̀bẹ, láti dúńbú ọmọ rẹ̀.
11 Lecz zawołał nań Anioł Pański z nieba, i rzekł: Abrahamie! Abrahamie! A on rzekł: Owom ja.
Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa ké sí i láti ọ̀run wá wí pé “Abrahamu! Abrahamu!” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
12 I rzekł Anioł: Nie wyciągaj ręki twej na dziecię, i nie czyń mu nic; bom teraz doznał, iż się ty boisz Boga, i nie sfolgowałeś synowi twemu, jedynemu twemu, dla mnie.
Angẹli Olúwa sì wí pé, “Má ṣe fọwọ́ kan ọmọ náà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣe é ni ohun kan. Nísinsin yìí ni mo mọ̀ pé o bẹ̀rù Ọlọ́run, nítorí pé ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí.”
13 A podniósłszy Abraham oczy swe, ujrzał, a oto baran za nim uwiązł w cierniu za rogi swoje; a szedłszy Abraham, wziął barana i ofiarował go na ofiarę paloną, miasto syna swego.
Abrahamu sì gbójú sókè, ó sì rí àgbò kan tí ó fi ìwo há pàǹtírí, ó sì lọ mú un, ó sì fi rú ẹbọ sísun dípò ọmọ rẹ̀.
14 I nazwał Abraham imię miejsca onego: Pan obmyśli; stądże po dziś dzień mówią: Na górze Pańskiej będzie obmyślono.
Abrahamu sì pe orúkọ ibẹ̀ ni, Jehofah Jire. Bẹ́ẹ̀ ni a sì ń wí títí di òní olónìí pé, “Ní orí òkè Olúwa, ni a ó ti pèsè.”
15 Tedy zawołał Anioł Pański na Abrahama po wtóre z nieba mówiąc:
Angẹli Olúwa sì tún pe Abrahamu láti ọ̀run wá lẹ́ẹ̀kejì.
16 Przez siebie samego przysiągłem, mówi Pan: Ponieważeś to uczynił, a nie sfolgowałeś synowi twemu, jedynemu twemu;
Ó sì wí pé, Olúwa wí pé, “Mo fi ara mi búra, níwọ̀n bí ìwọ ti ṣe èyí, tí ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí,
17 Błogosławiąc, błogosławić ci będę, a rozmnażając rozmnożę nasienie twoje, jako gwiazdy niebieskie, i jako piasek, który jest na brzegu morskim; a odziedziczy nasienie twoje bramy nieprzyjaciół twoich.
nítòótọ́, ní bíbùkún èmi ó bùkún fún ọ, àti ní bíbísí èmi ó sì mú ọ bí sí i bí i ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti bí iyanrìn etí Òkun. Irú-ọmọ rẹ yóò sì gba ẹnu ibodè àwọn ọ̀tá wọn,
18 I błogosławione będą w nasieniu twojem wszystkie narody ziemi, dla tego, żeś usłuchał głosu mego.
àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó ti bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nítorí tí ìwọ gbọ́rọ̀ sí mi lẹ́nu.”
19 Wrócił się tedy Abraham do sług swych, i wstawszy, przyszli pospołu do Beerseba; bo mieszkał Abraham w Beerseba.
Nígbà náà ni Abrahamu padà tọ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ. Gbogbo wọn sì padà lọ sí Beerṣeba. Abrahamu sì jókòó ní Beerṣeba.
20 I stało się potem, iż oznajmiono Abrahamowi, mówiąc: Oto narodziła i Melcha synów Nachorowi, bratu twemu.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni a wí fún Abrahamu pé, “Milka aya Nahori bí àwọn ọmọkùnrin fún un.
21 Husa, pierworodnego swego, i Buza, brata jego, i Chemuela, ojca Aramczyków.
Usi àkọ́bí rẹ̀, Busi arákùnrin rẹ̀, Kemueli (baba Aramu).
22 I Kaseda, i Kasana, i Feldasa, i Jedlafa, i Batuela.
Kesedi, Haso, Pildasi, Jidlafi, àti Betueli.”
23 A Batuel spłodził Rebekę; ośmioro tych dzieci urodziła Melcha Nachorowi, bratu Abrahamowemu.
Betueli sì ni baba Rebeka. Milka sì bí àwọn ọmọ mẹ́jọ wọ̀nyí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
24 A założnica jego, której imię Reuma, urodziła też Tabę, i Gahama, i Tahasa, i Maacha.
Àlè rẹ̀ tí ń jẹ́ Reuma náà bí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí fun un: Teba, Gahamu, Tahasi àti Maaka.

< Rodzaju 22 >