< Rodzaju 19 >

1 I przyszli dwaj Aniołowie do Sodomy w wieczór, a Lot siedział w bramie Sodomskiej. Gdy je tedy ujrzał Lot, wstawszy szedł przeciwko nim, i skłonił się twarzą ku ziemi, i rzekł:
Ní àṣálẹ́, àwọn angẹli méjì sì wá sí ìlú Sodomu, Lọti sì jókòó ní ẹnu ibodè ìlú. Bí ó sì ti rí wọn, ó sì dìde láti pàdé wọn, ó kí wọn, ó sì foríbalẹ̀ fún wọn.
2 Oto proszę panowie moi, wstąpcie teraz do domu sługi swego, a bądźcie tu na noc, i umyjcie nogi swe; potem rano wstawszy pójdziecie w drogę waszę. Którzy odpowiedzieli: Bynajmniej; ale na ulicy będziemy nocowali.
Ó wí pé, “Ẹ̀yin olúwa mi, èmi bẹ̀ yín, ẹ yà sí ilé ìránṣẹ́ yín kí ẹ sì wẹ ẹsẹ̀ yín, kí n sì gbà yín lálejò, ẹ̀yin ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ láti máa bá ìrìnàjò yín lọ.” Wọ́n sì wí pé, “Rárá o, àwa yóò dúró ní ìgboro ní òru òní.”
3 Ale on przymuszał ich bardzo, iż się skłonili do niego, i weszli w dom jego; zaczem sprawił im ucztę, i napiekł chleba przaśnego, i jedli.
Ṣùgbọ́n Lọti rọ̀ wọ́n gidigidi tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n gbà láti bá a lọ sì ilé. Ó sì ṣe àsè fún wọn, ó sì dín àkàrà aláìwú fún wọ́n, wọ́n sì jẹ.
4 Lecz pierwej niż oni poszli spać, oto obywatele miasta, mężowie Sodomscy, obstąpili dom, od młodego aż do starego, wszystek lud zewsząd.
Ṣùgbọ́n kí ó tó di pé wọ́n lọ sùn, àwọn ọkùnrin ìlú Sodomu tọmọdé tàgbà yí ilé náà ká.
5 I wołali na Lota, i rzekli mu: Gdzie są mężowie, którzy przyszli do ciebie w nocy? wywiedź je do nas, abyśmy je poznali.
Wọ́n pe Lọti pé, “Àwọn ọkùnrin tí ó wọ̀ sí ilé rẹ lálẹ́ yìí ń kọ́? Mú wọn jáde fún wa, kí a le ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú wọn.”
6 Tedy wyszedł do nich Lot ze drzwi, i zamknął drzwi za sobą.
Lọti sì jáde láti pàdé wọn, ó sì ti ìlẹ̀kùn lẹ́yìn rẹ̀ bí ó ti jáde.
7 I rzekł: Nie czyńcie proszę, bracia moi, nic złego.
Ó sì wí pé, “Rárá, ẹ̀yin ará mi, ẹ má ṣe ṣe ohun búburú yìí,
8 Oto teraz mam dwie córki, które nie poznały męża; wywiodę je teraz do was, a czyńcie z niemi, co się wam podoba, tylko mężom tym nic nie czyńcie; bo dlatego weszli pod cień dachu mego.
kíyèsi i, mo ní ọmọbìnrin méjì tí kò mọ ọkùnrin rí, ẹ jẹ́ kí n mú wọn tọ̀ yín wá kí ẹ sì ṣe ohun tí ẹ fẹ́ pẹ̀lú wọn. Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣe àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ní ibi kan nítorí wọ́n wá wọ̀ lábẹ́ ààbò ní ilé mi.”
9 A oni rzekli: Pójdźże tam; i mówili: Ten sam przyszedł, aby tu gościem był, a miałby nas sądzić? przetoż gorzej uczynimy tobie, niż onym i czynili gwałt wielki mężowi onemu Lotowi, i przystąpili, aby drzwi wyłamali.
Wọ́n sì wí fún pé, “Bì sẹ́yìn fún wa. Èyí yìí wá ṣe àtìpó láàrín wa, òun sì fẹ́ ṣe onídàájọ́! Aburú tí a ó fi ṣe ọ́ yóò pọ̀ ju tí wọn lọ.” Wọn rọ́ lu Lọti, wọ́n sì súnmọ́ ọn láti fọ́ ìlẹ̀kùn.
10 Ale mężowie oni, wyciągnąwszy rękę swoję, wwiedli Lota do siebie w dom, i zamknęli drzwi.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà nawọ́ fa Lọti wọlé, wọ́n sì ti ìlẹ̀kùn.
11 A męże one, którzy byli u drzwi domu, pozarażali ślepotą, od najmniejszego, aż do największego; tak, iż się spracowali, szukając drzwi.
Wọ́n sì bu ìfọ́jú lu àwọn ọkùnrin tí ó wà ní ẹnu-ọ̀nà ilé náà, àti èwe àti àgbà: wọ́n kò sì rí ẹnu-ọ̀nà mọ́.
12 Tedy rzekli mężowie oni do Lota: Maszli tu jeszcze kogo, zięcia, albo syny twe, albo córki twoje, i wszystko, co masz w mieście, wyprowadź z miejsca tego.
Àwọn ọkùnrin náà sì wí fún Lọti pé, “Ǹjẹ́ ó ní ẹlòmíràn ní ìlú yìí bí? Àna rẹ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ lọ́kùnrin àti lóbìnrin, tàbí ẹnikẹ́ni tí ìwọ ní ní ìlú yìí, kó wọn jáde kúrò ní ibí yìí,
13 Skazimy bowiem to miejsce, przeto, że się wzmógł krzyk ich przed Panem, i posłał nas Pan, abyśmy je skazili.
nítorí a ó pa ìlú yìí run, nítorí igbe iṣẹ́ búburú wọn ń dí púpọ̀ níwájú Olúwa, Olúwa sì rán wa láti pa á run.”
14 Tedy wyszedłszy Lot mówił do zięciów swoich, którzy mieli pojąć córki jego, i rzekł: Wstańcie, wynijdźcie z miejsca tego, bo skazi Pan to miasto; ale się zdało w oczach zięciów jego, jakoby żartował.
Nígbà náà ni Lọti jáde, ó sì wí fún àwọn àna rẹ̀ ọkùnrin tí ó ti bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fẹ́ àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ ṣe kánkán, kí ẹ jáde ní ìlú yìí, nítorí Olúwa fẹ́ pa ìlú yìí run!” Ṣùgbọ́n àwọn ọkọ ọmọ rẹ̀ wọ̀nyí rò pé àwàdà ló ń ṣe.
15 A gdy weszła zorza, przymuszali Aniołowie Lota, mówiąc: Wstań, weźmij żonę twoję, i dwie córki twoje, które tu są, byś snać nie zginął w nieprawości miasta tego.
Ní àfẹ̀mọ́júmọ́, àwọn angẹli náà rọ Lọti pé, “Ṣe wéré, mú aya rẹ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ méjèèjì tí ó wà níhìn-ín, àìṣe bẹ́ẹ̀, ìwọ yóò parun pẹ̀lú ìlú yìí nígbà tí wọ́n bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
16 A gdy się ociągał, ujęli mężowie oni rękę jego, i rękę żony jego, i rękę dwóch córek jego, ( albowiem mu Pan folgował, ) i wywiedli go, i postawili go przed miastem.
Nígbà tí ó ń jáfara, àwọn ọkùnrin náà nawọ́ mú un lọ́wọ́, wọ́n sì nawọ́ mú aya rẹ̀ náà lọ́wọ́ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ méjèèjì, wọ́n sì mú wọn jáde sẹ́yìn odi ìlú, nítorí Olúwa ṣàánú fún wọn.
17 I gdy je wywiedli precz, rzekł jeden: Jeźli chcesz, zachowaj duszę twoję, a nie oglądaj się nazad, ani stawaj na tej wszystkiej równinie; uchodź na górę, byś snać nie zginął.
Ní kété tí wọ́n mú wọn jáde sẹ́yìn odi tán, ọ̀kan nínú wọn wí pé, “Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe wo ẹ̀yìn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó má ṣe dúró ní gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀! Sá àsálà lọ sí orí òkè, kí ìwọ ó má ba ṣègbé!”
18 A Lot rzekł do nich: Nie tak, proszę, panowie moi;
Ṣùgbọ́n Lọti wí fún wọn pé, “Rárá, ẹ̀yin Olúwa mi, ẹ jọ̀wọ́!
19 Oto teraz znalazł sługa twój łaskę w oczach twoich, i okazałeś obficie miłosierdzie twoje, któreś uczynił ze mną, zachowawszy duszę moję; aleć ja nie będę mógł ujść na tę górę, by mię snać nie zachwyciło to złe, i umarłbym.
Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ ti rí ojúrere rẹ, tí o sì ti fi àánú rẹ hàn nípa gbígba ẹ̀mí mi là, èmi kò le è sálọ sórí òkè, kí búburú yìí má ba à lé mi bá, kí n sì kú.
20 Ale oto tu jest miasto nie daleko, do którego bym uciekł, małeć jest; proszę niech tam ujdę, ( wszak małe jest, ) a będzie żywa dusza moja.
Wò ó, ìlú kékeré kan nìyí ní tòsí láti sá sí: jẹ́ kí n sálọ síbẹ̀, ìlú kékeré ha kọ́? Ẹ̀mí mi yóò sì yè.”
21 Tedy rzekł do niego: Oto, i wtem wysłuchałem cię, abym nie wywrócił miasta tego, o któremeś mówił.
Ó sì wí fún un pé, “Ó dára, mo gba ẹ̀bẹ̀ rẹ. Èmi kì yóò run ìlú náà tí ìwọ sọ̀rọ̀ rẹ̀.
22 Śpieszże się a uchodź tam, bo nie będę mógł nic uczynić, aż ty tam dojdziesz; przetoż nazwane jest imię miasta onego Zoar.
Tètè! Sálọ síbẹ̀, nítorí èmi kò le ṣe ohun kan àyàfi tí ó bá dé ibẹ̀.” (ìdí nìyí tí a fi ń pe ìlú náà ní Soari).
23 Wtem słońce weszło na ziemię, a Lot wszedł do Zoar.
Nígbà tí Lọti yóò fi dé ìlú Soari, oòrùn ti yọ.
24 Tedy Pan spuścił jako deszcz na Sodomę i na Gomorrę siarkę i ogień, od Pana z nieba.
Nígbà náà ni Olúwa rọ̀jò iná àti sulfuru sórí Sodomu àti Gomorra láti ọ̀run lọ́dọ̀ Olúwa wá.
25 I wywrócił miasta one, i wszystkę onę równinę, wszystkie obywatele miast onych, i urodzaje onej ziemi.
Báyìí ni ó run àwọn ìlú náà àti gbogbo ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó wà ní ìlú ńlá ńlá wọ̀n-ọn-nì àti ohun gbogbo tí ó hù jáde nílẹ̀.
26 I obejrzała się żona jego idąc za nim, a obróciła się w słup solny.
Ṣùgbọ́n aya Lọti bojú wo ẹ̀yìn, ó sì di ọ̀wọ́n iyọ̀.
27 Wstawszy tedy Abraham rano, pospieszył się na ono miejsce, kędy stał przed Panem.
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Abrahamu sì dìde ó sì padà lọ sí ibi tí ó gbé dúró níwájú Olúwa.
28 I spojrzał ku Sodomie i Gomorze, i ku wszystkiej ziemi onej równiny, i obaczył, a oto wychodził dym z onej ziemi, jako dym z pieca.
Ó sì wo ìhà Sodomu àti Gomorra àti àwọn ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, ó sì rí èéfín tí ń ti ibẹ̀ jáde bí èéfín iná ìléru.
29 A gdy wywracał Bóg miasta onej równiny, wspomniał Bóg na Abrahama i wybawił Lota z pośrodku wywrócenia, gdy wywracał one miasta, w których Lot mieszkał.
Ọlọ́run sì rántí Abrahamu, nígbà tí ó run ìlú pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀n-ọn-nì tan, ó sì mú Lọti jáde kúrò láàrín ìparun náà, tí ó kọlu ìlú tí Lọti ti gbé.
30 Potem wyszedł Lot z Zoar, i mieszkał na górze, i dwie córki jego z nim, albowiem się bał mieszkać w Zoar; ale mieszkał w jaskini, on i dwie córki jego.
Lọti àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin méjèèjì sì kúrò ní Soari, wọ́n sì ń lọ gbé ní orí òkè ní inú ihò àpáta, nítorí ó bẹ̀rù láti gbé ní ìlú Soari.
31 Tedy rzekła starsza do młodszej: Ojciec nasz stary a nie masz męża na ziemi, który by wszedł do nas, według zwyczaju wszystkiej ziemi.
Ní ọjọ́ kan, èyí ẹ̀gbọ́n sọ fún àbúrò rẹ̀ pé, “Baba wa ti dàgbà, kò sì sí ọkùnrin kankan ní agbègbè yìí tí ìbá bá wa lòpọ̀, bí ìṣe gbogbo ayé.
32 Pójdź, upójmy ojca naszego winem, a śpijmy z nim, abyśmy zachowały z ojca naszego nasienie.
Wá, jẹ́ kí a mú baba wa mu ọtí yó, kí ó ba à le bá wa lòpọ̀, kí àwa kí ó lè bí ọmọ, kí ìran wa má ba à parẹ́.”
33 Dały tedy pić ojcu swemu wina onej nocy. I wszedłszy starsza spała z ojcem swym; ale on nie czuł ani kiedy się układła, ani kiedy wstała.
Ní òru ọjọ́ náà, wọ́n rọ baba wọn ní ọtí yó. Èyí ẹ̀gbọ́n sì wọlé tọ̀ ọ́, ó sì bá a lòpọ̀, baba wọn kò mọ̀ ìgbà tí ó sùn ti òun àti ìgbà tí ó dìde.
34 I stało się nazajutrz, że rzekła starsza do młodszej: Otom ja spała przeszłej nocy z ojcem swym, dajmyż mu pić wina jeszcze tej nocy, i wnijdziesz, i będziesz spała z nim, a zachowamy z ojca naszego nasienie.
Ní ọjọ́ kejì èyí ẹ̀gbọ́n wí fún àbúrò rẹ̀ pé, “Ní àná mo sùn ti baba mi. Jẹ́ kí a tún wọlé tọ̀ ọ́, kí a lè ní irú-ọmọ láti ọ̀dọ̀ baba wa.”
35 Tedy dały pić i onej nocy ojcu swemu wina; i przyszedłszy młodsza spała z nim; ale on nie czuł, ani kiedy się układła, ani kiedy wstała.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tún fún baba wọn ní ọtí mu yó ni alẹ́ ọjọ́ náà, èyí àbúrò náà sì wọlé tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bá a lòpọ̀, kò sì tún mọ ìgbà tí ó wọlé sùn ti òun tàbí ìgbà tí ó dìde.
36 A tak poczęły obie córki Lotowe z ojca swego.
Àwọn ọmọbìnrin Lọti méjèèjì sì lóyún fún baba wọn.
37 I urodziła starsza syna, a nazwała imię jego Moab; ten jest ojcem Moabitów, aż do dnia tego.
Èyí ẹ̀gbọ́n sì bí ọmọkùnrin, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Moabu. Òun ni baba ńlá àwọn ará Moabu lónìí.
38 Młodsza też urodziła syna, i nazwała imię jego Benammi; ten jest ojcem synów Ammonowych, aż do dnia tego.
Èyí àbúrò náà sì bí ọmọkùnrin, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Bene-Ami. Òun ni baba ńlá àwọn ará Ammoni lónìí.

< Rodzaju 19 >