< Ezdrasza 4 >

1 A gdy usłyszeli nieprzyjaciele Judy i Benjamina, iż lud, który przyszedł z pojmania, budowali kościół Panu, Bogu Izraelskiemu;
Nígbà tí àwọn ọ̀tá Juda àti Benjamini gbọ́ wí pé àwọn ìgbèkùn tí ó padà dé ń kọ́ tẹmpili fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli,
2 Tedy przyszli do Zorobabela i do przedniejszych z domów ojcowskich, mówiąc im: Będziemy budować z wami, a jako i wy będziemy szukać Boga waszego, gdyżeśmy mu ofiary czynili ode dni Asarhaddona, króla Assyryjskiego, który nas tu przywiódł.
wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Serubbabeli àti sí ọ̀dọ̀ àwọn olórí àwọn ìdílé, wọ́n sì wí pé, “Jẹ́ kí a bá a yín kọ́ nítorí pé, bí i tiyín, a ń wá Ọlọ́run yín, a sì ti ń rú ẹbọ sí i láti ìgbà Esarhadoni ọba Asiria, tí ó mú wa wá sí ibi yìí.”
3 Ale im rzekł Zorobabel, i Jesua, i inni przedniejsi domów ojcowskich z Izraela: Nie wam, ale nam należy budować dom Bogu naszemu; przetoż my sami budować będziemy Panu, Bogu Izraelskiemu, jako nam rozkazał Cyrus, król Perski.
Ṣùgbọ́n Serubbabeli, Jeṣua àti ìyókù àwọn olórí àwọn ìdílé Israẹli dáhùn pé, “Ẹ kò ní ohunkóhun pẹ̀lú wa ní kíkọ́ ilé fún Ọlọ́run wa. Àwa nìkan yóò kọ́ ọ fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, bí Kirusi, ọba Persia, ti pàṣẹ fún wa.”
4 A tak lud onej krainy wątlił ręce ludu Judzkiego, i przeszkadzał im, aby nie budowali.
Nígbà náà ni àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú ọwọ́ àwọn ènìyàn Juda rọ, wọ́n sì dẹ́rùbà wọ́n ní ti kíkọ́ ilé náà.
5 Nadto przenajmowali przeciwko nim radców, aby rozrywali radę ich po wszystkie dni Cyrusa, króla Perskiego, aż do królowania Daryjusza, króla Perskiego.
Wọ́n gba àwọn olùdámọ̀ràn láti ṣiṣẹ́ lòdì sí wọn àti láti sọ ète wọn di asán ní gbogbo àsìkò ìjọba Kirusi ọba Persia àti títí dé ìgbà ìjọba Dariusi ọba Persia.
6 Bo gdy królował Aswerus, tedy na początku królestwa jego, napisali skargę przeciwko obywatelom Judzkim i Jeruzalemskim,
Ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Ahaswerusi wọ́n fi ẹ̀sùn kan àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu.
7 Tak jako za dni Artakserksesa pisał Bislan, Mitrydates, Tabeel, i inni towarzysze jego do Artakserksesa króla Perskiego; a pismo listu tego napisane było po syryjsku, i wyłożone też było po syryjsku.
Àti ní àkókò ìjọba Artasasta ọba Persia, Biṣilami, Mitredati, Tabeli àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ yòókù kọ̀wé sí Artasasta. A kọ ìwé náà ní ìlànà ìkọ̀wé Aramaiki èdè Aramaiki sì ní a fi kọ ọ́.
8 Rechum kanclerz, i Symsaj pisarz napisali list jeden przeciwko Jeruzalemowi do Artakserksesa króla w ten sposób:
Rehumu balógun àti Ṣimṣai akọ̀wé jùmọ̀ kọ́ ìwé láti dojúkọ Jerusalẹmu sí Artasasta ọba báyìí:
9 To uczynili natenczas Rechum kanclerz, i Symsaj pisarz, i inni towarzysze ich, Dynajczycy, i Afarsadchajczycy, Tarpelajczycy, Afarsajczycy, Arkiewajczycy, Babilończycy, Susanchajczycy, Dehawejczycy i Elmajczycy;
Rehumu balógun àti Ṣimṣai akọ̀wé, pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn tókù—àwọn ará Dina, ti Afarsatki, ti Tarpeli, ti Afarsi, Ereki àti Babeli, àwọn ará Elamu ti Susa,
10 I inne narody, które był przyprowadził Asnapar wielki i sławny, a osadził nimi miasta Samaryjskie; i inni, którzy byli za rzeką, i Cheenetczycy.
pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn tí ẹni ọlá àti ẹni ọ̀wọ̀ Asnappari kó jáde, tí ó sì tẹ̀ wọ́n dó sí ìlú Samaria àti níbòmíràn ní agbègbè e Eufurate.
11 A tenci jest przepis listu, który posłali do Artakserksesa króla:
(Èyí ni ẹ̀dà ìwé tí wọ́n fi ránṣẹ́ sí i.) Sí ọba Artasasta, láti ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọkùnrin agbègbè Eufurate.
12 Słudzy twoi, ludzie mieszkający za rzeka, i Cheenetczycy. Niech będzie wiadomo królowi, że Żydowie, którzy się wrócili od ciebie, przyszedłszy do nas do Jeruzalemu, miasto odporne i złe budują, i mury zakładają, a z gruntu je wywodzą.
Ọba gbọdọ̀ mọ̀ pé àwọn ará Júù tí ó gòkè wá sọ́dọ̀ wa láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ti lọ sí Jerusalẹmu wọ́n sì ń tún ìlú búburú àti ìlú ọlọ̀tẹ̀ ẹ nì kọ́. Wọ́n ń tún àwọn ògiri náà kọ́, wọ́n sì ń tún àwọn ìpìlẹ̀ náà ṣe.
13 Przetoż niech będzie wiadomo królowi, Ze będzieli to miasto pobudowane, i mury jego z gruntu wywiedzione, tedy cła, czynszów, i dani dorocznej nie będą dawać, a tak dochodom królewskim ujma się stanie.
Síwájú sí i, ọba gbọdọ̀ mọ̀ pé tí a bá kọ́ ìlú yìí àti tí a sì tún àwọn ògiri rẹ̀ mọ, kò sí owó orí, owó òde tàbí owó ibodè tí a ó san, owó tí ó sì ń wọlé fún ọba yóò sì dínkù.
14 Teraz tedy, ponieważ używamy dobrodziejstw pałacu twego, na szkodę królewską nie godzi się nam patrzyć; dla tegośmy posłali, oznajmując to królowi,
Nísinsin yìí níwọ̀n ìgbà tí a ní ojúṣe sí ààfin ọba, kò sì bójúmu fún wa láti rí ìtàbùkù ọba, àwa ń rán iṣẹ́ yìí láti sọ fún ọba,
15 Abyś dał szukać w księgach historyj ojców swoich, a znajdziesz w księgach historyj, i dowiesz się, iż to miasto jest miasto odporne i szkodliwe królom i krainom, a iż się w niem wszczynały bunty od dawnych dni, przez co to miasto było zburzone.
kí a bá a lè ṣe ìwádìí ní inú ìwé ìrántí àwọn aṣíwájú rẹ̀. Nínú ìwé ìrántí wọn yìí, ìwọ yóò rí i wí pé, ìlú yìí jẹ́ ìlú aṣọ̀tẹ̀, oníwàhálà sí àwọn ọba àti àwọn ìgbèríko, ibi ìṣọ̀tẹ̀ láti ìgbà àtijọ́. Ìdí ni èyí tí a ṣe pa ìlú yìí run.
16 Nadto wiadomo czynimy królowi, że jeżli się to miasto pobuduje, i mury jego z gruntu wywiedzione będą, tedy już ta część za rzeką nie będzie twoja.
A fi dá ọba lójú wí pé tí a bá tún ìlú kọ́ àti ti àwọn ògiri rẹ̀ si di mímọ padà, kì yóò sì ohun ti yóò kù ọ́ kù ní agbègbè Eufurate.
17 Tedy dał odpowiedż król Rechumowi kanclerzowi, i Symsajemu pisarzowi, i innym towarzyszom ich, którzy mieszkali w Samaryi, także i innym za rzeką w Selam i w Cheet:
Ọba fi èsì yìí ránṣẹ́ padà. Sí Rehumu balógun, Ṣimṣai akọ̀wé àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn yòókù tí ń gbé ní Samaria àti ní òpópónà Eufurate. Ìkíni.
18 List, któryście posłali do nas, jawnie przedemną czytano.
A ti ka ìwé tí ẹ fi ránṣẹ́ sí wa, a sì ti túmọ̀ rẹ̀ níwájú mi.
19 Przetoż rozkazałem, aby szukano; i znaleziono, że to miasto z dawna powstawało przeciwko królom, a bunty i rozruchy bywały w niem;
Mo pa àṣẹ, a sì ṣe ìwádìí, nínú ìtàn ọjọ́ pípẹ́ àti ti ìsinsin yìí ti ìṣọ̀tẹ̀ sí àwọn ọba pẹ̀lú, ó sì jẹ́ ibi ìṣọ̀tẹ̀ àti ìrúkèrúdò.
20 Nadto królowie możni bywali w Jeruzalemie, którzy panowali nad wszystkiem, co jest za rzeką, którym cła, czynsze, i dani doroczne dawano.
Jerusalẹmu ti ní àwọn ọba alágbára tí ń jẹ ọba lórí gbogbo àwọn agbègbè Eufurate, àti àwọn owó orí, owó òde àti owó ibodè sì ni wọ́n ń san fún wọn.
21 Przetoż wydajcie wyrok, aby zabroniono onym mężom, aby to miasto nie było budowane, pókiby odemnie inszy rozkaz nie wyszedł.
Nísinsin yìí pa àṣẹ fún àwọn ọkùnrin yìí láti dá iṣẹ́ dúró, kí a má ṣe tún ìlú náà kọ títí èmi yóò fi pàṣẹ.
22 Patrzcież, abyście się w tem nie omylili. Przeczżeby urość miało co złego na szkodę królom?
Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe àìkọbi-ara sí ọ̀rọ̀ yìí. Èéṣe tí ìbàjẹ́ yóò fi pọ̀ sí i, sí ìpalára àwọn ọba?
23 A tak, gdy przepis listu Artakserksesa był czytany przed Rechumem, i Symsajem pisarzem, i przed towarzyszami ich, jechali prędko do Jeruzalemu do Żydów, a zabronili im gwałtem i mocą budować.
Ní kété tí a ka ẹ̀dà ìwé ọba Artasasta sí Rehumu àti Ṣimṣai akọ̀wé àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, wọ́n yára lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn Júù ní Jerusalẹmu pẹ̀lú, wọ́n fi agbára mú wọn láti dáwọ́ dúró.
24 A tak ustała robota około domu Bożego, który był w Jeruzalemie, i zaniechano jej aż do wtórego roku królestwa Daryjusza, króla Perskiego.
Báyìí, iṣẹ́ lórí ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu wá sí ìdúró jẹ́ẹ́ títí di ọdún kejì ìjọba Dariusi ọba Persia.

< Ezdrasza 4 >