< Ezechiela 7 >

1 Potem stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Słuchaj ty, synu człowieczy: Tak mówi panujący Pan o ziemi Izraelskiej: Koniec, koniec przyszedł na wszystkie cztery strony ziemi.
“Ọmọ ènìyàn, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ilé Israẹli: “‘Òpin! Òpin ti dé sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilẹ̀ náà!
3 Teraz przyjdzie koniec na cię; poślę na cię popędliwość moję, i będę cię sądził według dróg twoich, i zwalę na cię wszystkie obrzydliwości twoje.
Òpin tí dé sí ọ báyìí, èmi yóò sì tú ìbínú mi jáde sí ọ, èmi yóò dájọ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìwà rẹ, èmi yóò sì san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìwà ìríra rẹ.
4 A nie sfolgujeć oko moje, i nie zmiłuję się, ale drogi twoje zwalę na cię, a obrzydliwości twoje będą w pośrodku ciebie, i poznacie, żem Ja Pan.
Ojú mi kò ní i dá ọ sì, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò ṣàánú; ṣùgbọ́n èmi yóò san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gbogbo ìwà ìríra tó wà láàrín rẹ. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
5 Tak mówi panujący Pan: Utrapienie jedno, oto utrapienie straszne przychodzi;
“Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ibi! Ibi kan ṣoṣo. Kíyèsi, ó bọ̀ ní orí rẹ!
6 Koniec przychodzi, przychodzi koniec, ocknął się przeciwko tobie, oto przychodzi.
Òpin ti dé! Òpin ti dé! Ó ti dìde lòdì sí ọ. Kíyèsi, ó ti dé!
7 Przychodzi prędki poranek na cię, o obywatelu ziemi! przychodzi ten czas, przybliża się ten dzień grzmotu, a nie głosu rozlegającego się po górach.
Ìparun ti dé sórí rẹ, ìwọ tó ń gbé ní ilẹ̀ náà. Àkókò náà dé! Ọjọ́ wàhálà ti súnmọ́ etílé! Kì í ṣe ọjọ́ ariwo ayọ̀ lórí òkè.
8 Już prędko, już wyleję gniew mój na cię, a wykonam zapalczywość moję nad tobą, a osądzę cię według dróg twoich, i włożę na cię wszystkie obrzydliwości twoje.
Mo ṣetán láti tú ìbínú gbígbóná mi lé ọ lórí àti láti lo ìbínú mi lórí rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀nà rẹ, èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gẹ́gẹ́ bí ìwà ìríra rẹ ni èmi yóò sì san án fún ọ.
9 Nie sfolgujeć zaiste oko moje, ani się zlituję, ale według dróg twoich nagrodzęć, i obrzydliwości twoje w pośrodku ciebie będą; a tak poznacie, żem Ja Pan, który biję.
Ojú mi kò ní i dá ọ sí, Èmi kò sì ní wò ọ́ pẹ̀lú àánú; èmi yóò san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti fún gbogbo ìwà ìríra tí wà láàrín rẹ. “‘Nígbà náà ní ẹ o mọ̀ pé Èmi Olúwa lo kọlù yín.
10 Oto ten dzień, oto przyszedł; przyszedł prędki poranek, zakwitnęła rózga, wybija się pycha.
“‘Ọjọ́ náà dé! Kíyèsi ó ti dé! Ìparun ti bú jáde, ọ̀pá ti tanná, ìgbéraga ti rúdí!
11 Okrucieństwo wyrosło w rózgę niezbożności; nie zostanie z nich nic, ani z mnóstwa ich, ani z huku ich, i nie będzie żadnego narzekania nad nimi.
Ìwà ipá ti di ọ̀pá ìwà búburú; ọ̀pá láti jẹ ẹni búburú ní ìyà. Kò sí nínú wọn tí yóò ṣẹ́kù, tàbí nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn, kò sí nínú ọrọ̀ wọn, kò sí ohun tí ó ní iye.
12 Idzie czas, przybliża się dzień. Kto kupi, nie będzie się weselił, a kto sprzeda, nie będzie żałował; bo popędliwość przyjdzie na wszystko mnóstwo jej.
Àkókò náà dé! Ọjọ́ náà ti dé! Kí òǹrajà má ṣe yọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ki òǹtajà má ṣe ṣọ̀fọ̀; nítorí, ìbínú gbígbóná wà lórí gbogbo ènìyàn.
13 Bo kto sprzedał, nie wróci się do rzeczy sprzedanej choćby jeszcze między żyjącymi był żywot ich; ponieważ widzenie na wszystko mnóstwo jej nie wróci się, a żaden w nieprawości żywota swego nie zmocni się.
Nítorí pé òǹtajà kì yóò rí gbà padà dúkìá èyí tó tà níwọ̀n ìgbà ti àwọn méjèèjì bá wà láààyè. Nítorí ìran tó kan gbogbo ènìyàn yìí kò ní yí padà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, kò sí ọ̀kan nínú wọn tí yóò gba ara rẹ̀ là.
14 Trąbić będą w trąbę, i wszystko przygotują, jednak nie będzie kto miał iść na wojnę; bo popędliwość moja oburzy się na wszystko mnóstwo jej.
“‘Wọ́n ti fọn ìpè ogun, tí wọ́n sì pèsè ohun gbogbo sílẹ̀, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò lọ ojú ogun, nítorí ìbínú gbígbóná mi ti wà lórí gbogbo ènìyàn.
15 Miecz zewnątrz, a mór i głód będzie wewnątrz; kto będzie na polu, od miecza umrze; a kto w mieście, głód i mór go pożre.
Idà wà ní ìta, àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìyàn wà nílé, idà yóò pa ẹni tó bá wà ní orílẹ̀-èdè, àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìyàn yóò pa ẹni tó bá wà ní ìlú.
16 A którzy z nich uciekną, ci będą na górach jako gołębice w dolinie; wszyscy będą narzekali, każdy nad nieprawością swoją.
Gbogbo àwọn tí ó bọ́ nínú wọn yóò sálà, wọn yóò sì wà lórí òkè. Bí i àdàbà inú àfonífojì, gbogbo wọn yóò máa ṣọ̀fọ̀, olúkúlùkù nítorí àìṣedéédéé rẹ̀.
17 Wszystkie ręce osłabieją, i wszystkie się kolana rozpłyną jako woda.
Gbogbo ọwọ́ yóò rọ, gbogbo orúnkún yóò di aláìlágbára bí omi.
18 I obloką się w wory, i okryje ich strach, i na wszelkiej twarzy będzie wstyd, i na wszystkich głowach ich łysina.
Wọn yóò wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ẹ̀rù yóò sì bò wọ́n mọ́lẹ̀, ìtìjú yóò mù wọn, wọn yóò sì fá irun wọn.
19 Srebro swoje po ulicach rozrzucą, a złoto ich będzie jako nieczystość; srebro ich i złoto ich nie będzie ich mogło wybawić w dzień popędliwości Pańskiej; nie nasycą duszy swojej, i wnętrzności swych nie napełnią, przeto, że im jest ku obrażeniu nieprawość ich;
“‘Wọn yóò dà fàdákà wọn sí ojú pópó, wúrà wọn yóò sì dàbí èérí fàdákà àti wúrà wọn kò ní le gbà wọ́n ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná Olúwa. Wọn kò ní le jẹun tẹ́ ra wọn lọ́rùn tàbí kí wọn kún ikùn wọn pẹ̀lú oúnjẹ nítorí pé ó ti di ohun ìkọ̀sẹ̀ fún wọn.
20 A iż w sławie ozdoby swojej, którą na chwałę swoją Bóg wystawił, obrazów obrzydliwości swoich i sprosności swoich naczynili, przetożem im je w nieczystość obrócił;
Wọ́n ń ṣe ìgbéraga pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ wọn tí ó lẹ́wà, wọn sì ti fi ṣe òrìṣà, wọn sì tún ya àwòrán ìríra wọn níbẹ̀. Nítorí náà, èmi yóò sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí di aláìmọ́ fún wọn.
21 I podam je w ręce cudzoziemców na rozchwycenie, i niezbożnych w ziemi na łup, którzy ją splugawią;
Èmi yóò sì fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣe ìjẹ fún àjèjì àti ìkógun fún àwọn ènìyàn búburú ayé, wọn yóò sì sọ ọ́ di aláìmọ́.
22 Odwrócę też twarz moję od nich, a zgwałcą świątnicę moję, a wnijdą do niej rozbójnicy, i splugawią ją.
Èmi yóò gbójú mi kúrò lára wọn, àwọn ọlọ́ṣà yóò sì sọ ibi ìṣúra mi di aláìmọ́; àwọn ọlọ́ṣà yóò wọ inú rẹ̀, wọn yóò sì bà á jẹ́.
23 Uczyń łańcuch; bo ziemia pełna jest krwawych sądów, a miasto pełne jest krzywd.
“‘Rọ ẹ̀wọ̀n irin! Nítorí pé ilẹ̀ náà kún fún ẹ̀ṣẹ̀ ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìlú náà sí kún fún ìwà ipá.
24 Przetoż najgorszych z pogan przywiodę, aby posiedli domy ich; i uczynię wstręt pysze mocarzów, a splugawieni będą, którzy je poświęcają.
Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè ti ó búburú jùlọ láti jogún ilé wọn. Èmi yóò sì fi òpin sí ìgbéraga àwọn alágbára, ibi mímọ́ wọn yóò sì di bíbàjẹ́.
25 Zginienie przyszło; przetoż szukać będą pokoju, ale go nie będzie.
Nígbà tí ìpayà bá dé, wọn yóò wá àlàáfíà, lórí asán.
26 Ucisk za uciskiem przyjdzie, a wieść za wieścią przypadnie; i będą szukać widzenia od proroka! ale zakon zginie od kapłana, a rada od starców.
Wàhálà lórí wàhálà yóò dé, ìdágìrì lórí ìdágìrì. Nígbà náà ni wọn yóò wá ìran lọ́dọ̀ wòlíì, ṣùgbọ́n ẹ̀kọ́ òfin yóò parun lọ́dọ̀ àlùfáà, bẹ́ẹ̀ ni ìmọ̀ràn yóò ṣègbé lọ́dọ̀ àwọn àgbàgbà.
27 Król płakać będzie, a książę w smutek obleczony będzie, a ręce ludu w ziemi przestraszone będą. Według drogi ich uczynię im, i według sądów ich osądzę ich, i poznają, żem Ja Pan.
Ọba yóò ṣọ̀fọ̀, ọmọ-aládé yóò wà láìní ìrètí, ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà yóò wárìrì. Èmi yóò ṣe é fún wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, èmi yóò ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìgbékalẹ̀ wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa.’”

< Ezechiela 7 >